< Mariko 9 >
1 Jesũ agĩcooka akĩmeera atĩrĩ, “Ngũmwĩra atĩrĩ na ma, amwe marũngiĩ haha matigacama gĩkuũ matonete ũthamaki wa Ngai ũgĩũka wĩ na hinya!”
Ó sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún un yín àwọn mìíràn wa nínú àwọn tó dúró níhìn-ín yìí, tí kì yóò tọ́ ikú wò, títí yóò fi rí ìjọba Ọlọ́run tí yóò fi dé pẹ̀lú agbára.”
2 Thuutha wa mĩthenya ĩtandatũ, Jesũ nĩmathiire na Petero na Jakubu na Johana, akĩmatwara kĩrĩma-inĩ kĩraaya, marĩ oiki. Na rĩrĩ, arĩ hau mbere yao akĩgarũrũka ũrĩa aahaanaga.
Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́fà tí Jesu sọ̀rọ̀ yìí, Jesu mú Peteru, Jakọbu àti Johanu lọ sí orí òkè gíga ní apá kan. Kò sí ẹlòmíràn pẹ̀lú wọn, ara rẹ̀ sì yípadà níwájú wọn.
3 Nguo ciake ikĩerũha cua; gũtirĩ mũndũ gũkũ thĩ ũngĩahotire gũcithambia cierũhe ũguo.
Aṣọ rẹ̀ sì di dídán, ó sì funfun gbòò, tí alágbàfọ̀ kan ní ayé kò lè sọ di funfun bẹ́ẹ̀.
4 Na marĩ o hau makiumĩrĩrwo nĩ Elija na Musa, makĩaranĩria na Jesũ.
Nígbà náà ni Elijah àti Mose farahàn fún wọn, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀ pẹ̀lú Jesu.
5 Nake Petero akĩĩra Jesũ atĩrĩ, “Rabii, nĩtwagĩrĩirwo nĩ gũikara gũkũ. Reke twake ithũnũ ithatũ, kĩmwe gĩaku, na kĩmwe kĩa Musa, na kĩmwe kĩa Elija.”
Peteru sì wí fún Jesu pé, “Rabbi, ó dára fún wa láti máa gbé níhìn-ín, si jẹ́ kí a pa àgọ́ mẹ́ta, ọ̀kan fun ọ, ọ̀kan fún Mose, àti ọ̀kan fún Elijah.”
6 (Petero oigire ũguo tondũ nĩarigĩtwo nĩ ũrĩa ekuuga, nĩ tondũ wa ũrĩa maamakĩte.)
Nítorí òun kò mọ ohun tí òun ìbá sọ, nítorí ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.
7 Ningĩ hagĩũka itu, rĩkĩmahumbĩra, na mũgambo ũkiuma itu-inĩ rĩu, ũkiuga atĩrĩ, “Ũyũ nĩwe Mũrũ wakwa, ũrĩa nyendete. Mũiguagei!”
Ìkùùkuu kan sì bò wọ́n, ohùn kan sì ti inú ìkùùkuu náà wá wí pé, “Èyí ni àyànfẹ́ ọmọ mi. Ẹ máa gbọ́ ti rẹ̀!”
8 Na kahinda o kau makĩĩhũgũra, no mationire mũndũ ũngĩ arĩ hamwe nao, tiga o Jesũ.
Lójijì, wọ́n wo àyíká wọn, wọn kò sì rí ẹnìkankan mọ́, bí kò ṣe Jesu nìkan ṣoṣo ni ó sì wà pẹ̀lú wọn.
9 Na rĩrĩa maikũrũkaga kuuma kĩrĩma-inĩ, Jesũ akĩmaatha matikeere mũndũ o na ũrĩkũ ũrĩa monete, nginya rĩrĩa Mũrũ wa Mũndũ agaakorwo ariũkĩte akoima kũrĩ arĩa akuũ.
Bí wọ́n ti ń sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, Jesu kìlọ̀ fún wọn kí wọ́n má ṣe sọ ohun tí wọ́n ti rí fún ẹnikẹ́ni títí Ọmọ Ènìyàn yóò fi jíǹde kúrò nínú òkú.
10 Nao magĩkira na ũhoro ũcio, no makooranagia o ene atĩrĩ, “kũriũka kuuma kũrĩ akuũ nĩ kuuga atĩa.”
Nítorí náà, wọ́n pa nǹkan náà mọ́ ní ọkàn wọn. Ṣùgbọ́n wọ́n ń béèrè lọ́wọ́ ara wọn ohun tí àjíǹde kúrò nínú òkú túmọ̀ sí.
11 Nao makĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩtũmaga arutani a watho moige atĩ Elija no nginya ambe ooke?”
Nísinsin yìí, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, èéṣe tí àwọn olùkọ́ òfin ń sọ wí pé, “Elijah ní yóò kọ́kọ́ dé.”
12 Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Ti-itherũ Elija no nginya ambe ooke ahaarĩrie maũndũ mothe. Ningĩ nĩ kĩĩ gĩgĩtũmĩte kwandĩkwo atĩ Mũrũ wa Mũndũ no nginya athĩĩnĩke mũno na aregwo nĩ andũ?
Ó sì dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni Elijah yóò kọ́kọ́ dé yóò sì mú nǹkan gbogbo padà bọ̀ sípò. Àní gẹ́gẹ́ bí a ti kọ̀wé rẹ nípa ti Ọmọ Ènìyàn pé kò le ṣàìmá jìyà ohun púpọ̀ àti pé a ó sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
13 No ngũmwĩra atĩrĩ, Elija nĩarĩkĩtie gũũka na andũ makamwĩka o ũrĩa wothe meendaga kũmwĩka, o ta ũrĩa ũhoro wake wandĩkĩtwo.”
Ṣùgbọ́n mo wí fún yín pé, Elijah ti wa ná, wọ́n sì ti ṣe ohunkóhun tí ó wù wọ́n sí i, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ̀wé nípa rẹ̀.”
14 Na rĩrĩa maakinyire harĩ arutwo arĩa angĩ, makĩona kĩrĩndĩ kĩnene kĩmarigiicĩirie, na arutani a watho magĩkararania nao.
Nígbà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ pátápátá sí ẹsẹ̀ òkè náà, wọ́n bá ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn tí wọ́n yí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mẹ́sàn-án ìyókù ká. Àwọn olùkọ́ òfin díẹ̀ sì ń bá wọn jiyàn.
15 Na rĩrĩa andũ othe moonire Jesũ, makĩgega mũno magĩtengʼera makamũgeithie.
Bí Jesu ti ń súnmọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn wọ̀nyí ni wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí í wò ó pẹ̀lú ìbẹ̀rù, nígbà náà ni wọ́n sáré lọ kí i.
16 Nake akĩmooria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ mũrakararanĩria nao?”
Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Kí ló fa àríyànjiyàn?”
17 Mũndũ ũmwe warĩ kĩrĩndĩ-inĩ kĩu akĩmũcookeria atĩrĩ, “Mũrutani, ngũkũreheire mũrũ wakwa, ũkoragwo arĩ na ngoma thũku na ndaaragia.
Ọkùnrin kan láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn dáhùn pé, “Olùkọ́, èmi ni mo mú ọmọ yìí wá fún ọ láti wò ó sàn. Kò lè sọ̀rọ̀ rárá, nítorí tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́.
18 Hĩndĩ ĩrĩa yothe yamũnyiita, ĩmũtungumanagia thĩ na akarutaga mũhũyũ na kanua, akahagarania magego na akomagara. Njũũririe arutwo aku maingate ngoma ĩyo thũku, no matinahota.”
Àti pé, nígbàkígbà tí ó bá mú un, á gbé e ṣánlẹ̀, a sì máa hó itọ́ lẹ́nu, a sì máa lọ́ eyín rẹ̀. Òun pàápàá a wá le gbagidi. Mo sì bẹ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ kí wọn lé ẹ̀mí àìmọ́ náà jáde, ṣùgbọ́n wọ́n kò lè ṣe é.”
19 Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Inyuĩ rũciaro rũrũ rũtetĩkagia, nĩ nginya rĩ ngũikarania na inyuĩ? Ngũmũkirĩrĩria nginya rĩ? Ndeherai kamwana kau.”
Ó sì dá wọn lóhùn, ó wí pé, “Ẹ̀yin ìran aláìgbàgbọ́ yìí, èmi yóò ti bá a yín gbé pẹ́ tó? Èmi yóò sì ti mú sùúrù fún un yín pẹ́ tó? Ẹ mú ọmọ náà wá sọ́dọ̀ mi.”
20 Nĩ ũndũ ũcio magĩgatwarĩra Jesũ. Rĩrĩa ngoma ĩyo thũku yoonire Jesũ, ĩgĩgathiorania o rĩmwe. Gagĩtungumana thĩ, gakĩgaragara, gakĩrutaga mũhũyũ na kanua.
Wọ́n sì mú un wá sọ́dọ̀ rẹ̀: nígbà tí ó sì rí i, lójúkan náà ẹ̀mí náà nà án tàntàn ó sì ṣubú lu ilẹ̀, ó sì ń fi ara yílẹ̀, ó sì ń yọ ìfófó lẹ́nu.
21 Nake Jesũ akĩũria ithe wa kamwana kau atĩrĩ, “Nĩ hĩndĩ ĩigana atĩa gakoretwo kahaana ũguo?” Nake agĩcookia atĩrĩ, “Nĩ kuuma arĩ o kaana.
Jesu béèrè lọ́wọ́ baba ọmọ náà pé, “Ó tó ìgbà wo tí ọmọ rẹ̀ ti wà nínú irú ipò báyìí?” Baba ọmọ náà dáhùn pé, “Láti kékeré ni.”
22 Na maita maingĩ yanagaikia mwaki-inĩ o na maaĩ-inĩ ĩkoorage. No akorwo nĩ harĩ ũndũ ũngĩka, tũiguĩre tha ũtũteithie.”
Nígbàkígbà ni ó sì máa ń gbé e sínú iná àti sínú omi, láti pa á run, ṣùgbọ́n bí ìwọ bá lè ṣe ohunkóhun, ṣàánú fún wa, kí o sì ràn wá lọ́wọ́.
23 Jesũ akĩmũũria atĩrĩ, “Atĩ ‘korwo ndahota’? Maũndũ mothe nĩmahotekaga kũrĩ mũndũ ũrĩa wĩtĩkĩtie.”
“Jesu sì wí fún un pé, ‘Bí ìwọ bá le gbàgbọ́: ohun gbogbo ni ó ṣe é ṣe fún ẹni tí ó bá gbàgbọ́.’”
24 O rĩmwe ithe wa kamwana kau akĩanĩrĩra, akiuga atĩrĩ, “Nĩndetĩkia, ndeithia harĩa njagĩte gwĩtĩkia.”
Lójúkan náà baba ọmọ náà kígbe ní ohùn rara, ó sì wí pé, “Olúwa, mo gbàgbọ́, ran àìgbàgbọ́ mi lọ́wọ́.”
25 Rĩrĩa Jesũ oonire atĩ kĩrĩndĩ nĩgĩatengʼerete gĩũke hau, agĩkũũma ngoma ĩyo thũku. Akĩmĩĩra atĩrĩ, “Wee ngoma ĩno thũku ũtaiguaga na ũtaaragia, nĩndagwatha uume thĩinĩ wa kamwana gaka, na ndũkanacooke gũtoonya thĩinĩ wako rĩngĩ.”
Nígbà tí Jesu rí i pé ọ̀pọ̀ ènìyàn ń péjọ sọ́dọ̀ wọn, ó bá ẹ̀mí àìmọ́ náà wí pé, “Ìwọ ẹ̀mí àìmọ́, adití àti odi, mo pàṣẹ fún ọ, kí ó jáde kúrò lára ọmọ yìí, kí ó má ṣe padà sí ibẹ̀ mọ́.”
26 Ngoma ĩyo thũku ĩgĩkayũrũrũka, ĩgĩgathiorania na hinya, na ĩkiuma. Kamwana kau gakĩhaana ta karĩ gakuũ, o nginya andũ aingĩ makiuga atĩrĩ, “Nĩ gakuũ.”
Òun sì kígbe ńlá, ó sì nà án tàntàn, ó sì jáde kúrò lára rẹ̀, ọmọ náà sì dàbí ẹni tí ó kú tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀pọ̀ ènìyàn ké wí pé, “Hé è, ọmọ náà ti kú.”
27 No Jesũ agĩkanyiita guoko, agĩgokĩria, nako gakĩrũgama.
Ṣùgbọ́n Jesu fà á lọ́wọ́, ó sì ràn án lọ́wọ́ láti dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀. Ó dìde dúró.
28 Thuutha wa Jesũ gũtoonya nyũmba, arutwo ake makĩmũũrĩria keheri-inĩ atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩtũmire ithuĩ tũremwo nĩ kũingata ngoma ĩyo?”
Nígbà tí ó sì wọ ilé, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ bi í léèrè níkọ̀kọ̀ wí pé, “Èéṣe tí àwa kò fi lè lé e jáde?”
29 Nake akĩmacookeria atĩrĩ, “Ngoma ya mũthemba ta ũcio ndĩngiuma na njĩra ĩngĩ tiga o ya mahooya (o na kwĩima irio).” (Nĩ harĩ maandĩko mangĩ matakoragwo na ũhoro ũyũ wa kwĩima irio).
Ó sì wí fún wọn pé, “Irú èyí kò le ti ipa ohun kan jáde, bí kò ṣe nípa àdúrà.”
30 Nao makiuma kũu magĩtuĩkanĩria bũrũri wa Galili, na Jesũ ndeendaga mũndũ o na ũrĩkũ amenye kũrĩa marĩ,
Wọ́n sì kúrò níbẹ̀, wọ́n gba Galili kọjá. Níbẹ̀ ni Jesu ti gbìyànjú láti yẹra kí ó bá à lè wà pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, kí ó lè ráàyè kọ́ wọn lẹ́kọ̀ọ́ sí i.
31 tondũ nĩarutaga arutwo ake. Nake akĩmeera atĩrĩ, “Mũrũ wa Mũndũ nĩegũkunyanĩrwo aneanwo moko-inĩ ma andũ, nao nĩmakamũũraga, no thuutha wa mĩthenya ĩtatũ nĩakariũka.”
Nítorí ó kọ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó sì wí fun wọn pe, “A ó fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn ènìyàn lọ́wọ́, wọn ó sì pa á, lẹ́yìn ìgbà tí a bá sì pa á tan yóò jíǹde ní ọjọ́ kẹta.”
32 No matiigana gũtaũkĩrwo nĩ ũrĩa oigaga, na magĩĩtigĩra kũmũũria ũhoro ũcio.
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ náà kò yé wọn, ẹ̀rù sì bà wọ́n láti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, ìtumọ̀ ohun tí ó sọ náà.
33 Nao magĩkinya Kaperinaumu. Na rĩrĩa aarĩ nyũmba thĩinĩ akĩmooria atĩrĩ, “Mũgũkararanagĩria kĩĩ tũrĩ njĩra-inĩ?”
Wọ́n dé sí Kapernaumu. Lẹ́yìn tí wọ́n sinmi tán nínú ilé tí wọ́n wọ̀, Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Kí ni ohun tí ẹ́ ń bá ara yín jiyàn lé lórí?”
34 No-o magĩkira tondũ marĩ njĩra-inĩ nĩmakararanagia makĩũranagia nũũ mũnene kũrĩ arĩa angĩ.
Ṣùgbọ́n wọ́n dákẹ́; nítorí wọn ti ń bá ara wọn jiyàn pé, ta ni ẹni tí ó pọ̀jù?
35 Na aikara thĩ, Jesũ agĩĩta arutwo arĩa ikũmi na eerĩ akĩmeera atĩrĩ, “Ũrĩa wothe ũngĩenda gũtuĩka wa mbere, no nginya akorwo arĩ wa thuutha wa arĩa angĩ na atuĩke ndungata ya andũ othe.”
Ó jókòó, ó sì pè àwọn méjìlá náà, ó sọ fún wọn pé, “Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ ṣe ẹni ìṣáájú, òun ni yóò ṣe ẹni ìkẹyìn gbogbo wọn. Ó ní láti jẹ́ ìránṣẹ́ gbogbo ènìyàn.”
36 Nake akĩrehe kaana agĩkarũgamia gatagatĩ kao. Na aarĩkia gũkaiyũkia moko-inĩ make, akĩmeera atĩrĩ,
Ó sì mú ọmọ kékeré kan, ó fi sáàárín wọn, nígbà tí ó sì gbé e sí apá rẹ̀, ó wí fún wọn pé,
37 “Ũrĩa wothe ũngĩamũkĩra kaana kamwe ta gaka thĩinĩ wa rĩĩtwa rĩakwa, nĩ niĩ aamũkagĩra; na ũrĩa ũngĩnyamũkĩra niĩ to niĩ aamũkagĩra, no nĩamũkagĩra ũrĩa wandũmire.”
“Ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ́wọ́gbà ọmọ kékeré bí èyí ní orúkọ mi, òun gbà mí. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì gbà mi, ó gba Baba mi, tí ó rán mi.”
38 Johana akĩmwĩra atĩrĩ, “Mũrutani, nĩtũronire mũndũ akĩingata ndaimono thĩinĩ wa rĩĩtwa rĩaku tũramwĩra atige, tondũ ti ũmwe witũ.”
Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Johanu sọ fún un ní ọjọ́ kan pé, “Olùkọ́, àwa rí ọkùnrin kan, tí ń fi orúkọ rẹ̀ lé àwọn ẹ̀mí àìmọ́ jáde, ṣùgbọ́n a sọ fún un pé kò gbọdọ̀ ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́, nítorí kì í ṣe ọ̀kan nínú wa.”
39 Nake Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Mũtikamũgirie! Gũtirĩ mũndũ ũngĩringa kĩama thĩinĩ wa rĩĩtwa rĩakwa na thuutha ũcio ahote gũcooka kwaria ũũru wakwa,
Jesu sì sọ fún un pé, “Má ṣe dá irú ènìyàn bẹ́ẹ̀ dúró, nítorí kò sí ẹnìkan ti ó fi orúkọ mi ṣe iṣẹ́ ìyanu tí yóò tún lè máa sọ ohun búburú nípa mi.
40 Nĩgũkorwo ũrĩa ũtarĩ ũthũ na ithuĩ nĩ ũmwe witũ.
Nítorí ẹni tí kò bá kọ ojú ìjà sí wa, ó wà ní ìhà tiwa.
41 Ngũmwĩra atĩrĩ na ma, mũndũ o wothe ũrĩa ũkaamũhe gĩkombe kĩa maaĩ thĩinĩ wa rĩĩtwa rĩakwa nĩ ũndũ mũrĩ a Kristũ, ndarĩ hĩndĩ akoorwo nĩ igai rĩake.”
Lóòótọ́ ni mo sọ fún ún yín bí ẹnikẹ́ni bá fún un yín ní ife omi kan nítorí pé ẹ jẹ́ ti Kristi, dájúdájú ẹni náà kì yóò sọ èrè rẹ̀ nù bí ó ti wù kí ó rí.
42 “Na mũndũ ũrĩa wothe ũgaatũma kamwe ga twana tũtũ tũnjĩtĩkĩtie kehie, wega nĩ mũndũ ũcio ohererwo ihiga rĩa gĩthĩi ngingo na aikio thĩinĩ wa iria.
“Ṣùgbọ́n ti ẹnikẹ́ni bá mú ọ̀kan nínú àwọn ọmọ kékeré wọ̀nyí tí ó gbà mí gbọ́ ṣìnà nínú ìgbàgbọ́ rẹ́, ó sàn fún un kí a so òkúta ńlá mọ́ ọn ni ọ̀run, kí a sì sọ ọ́ sínú òkun.
43 Guoko gwaku kũngĩtũma wĩhie, gũtinie. Nĩ kaba ũtoonye muoyo-inĩ wĩ kĩonje,
Bí ọwọ́ rẹ bá sì mú ọ kọsẹ̀, gé e sọnù, ó sàn fún ọ kí o ṣe akéwọ́ lọ sí ibi ìyè, ju kí o ní ọwọ́ méjèèjì, kí o lọ sí ọ̀run àpáàdì, sínú iná àjóòkú. (Geenna )
44 gũkĩra ũthiĩ Jehanamu kũrĩa kũrĩ mwaki ũtahoraga ũrĩ na moko meerĩ. (Geenna )
45 Nakuo kũgũrũ gwaku kũngĩtũma wĩhie, gũtinie. Nĩ kaba ũtoonye muoyo-inĩ ũrĩ gĩthua, gũkĩra ũikio Jehanamu ũrĩ na magũrũ meerĩ. (Geenna )
Bí ẹsẹ̀ rẹ bá sì mú ọ kọsẹ̀, gé é sọnù, ó sàn kí ó di akesẹ̀, kí o sì gbé títí ayé àìnípẹ̀kun ju kí o ní ẹsẹ̀ méjì tí ó gbé ọ lọ sí ọ̀run àpáàdì. (Geenna )
46 Kũu kĩgunyũ kĩrĩa kĩmarĩĩaga gĩtikuaga, naguo mwaki ũrĩa ũmacinaga ndũhoraga.
47 Na riitho rĩaku rĩngĩtũma wĩhie, rĩkũũre. Nĩ kaba ũtoonye ũthamaki-inĩ wa Ngai ũrĩ na riitho rĩmwe gũkĩra ũikio Jehanamu ũrĩ na maitho meerĩ, (Geenna )
Bí ojú rẹ bá sì mú ọ kọsẹ̀, yọ ọ́ sọnù, ó sàn kí o wọ ìjọba Ọlọ́run pẹ̀lú ojú kan ju kí ó ní ojú méjì kí ó sì lọ sínú iná ọ̀run àpáàdì. (Geenna )
48 kũu “‘kĩgunyũ kĩrĩa kĩmarĩĩaga gĩtikuaga, naguo mwaki ũrĩa ũmacinaga ndũhoraga.’
Níbi ti “‘kòkòrò wọn kì í kú, tí iná kì í sì í kú.’
49 Mũndũ o wothe agekĩrwo mũcamo wa cumbĩ nĩ mwaki, (na igongona o rĩothe rĩĩkĩrwo mũcamo na cumbĩ).
Níbẹ̀ ni a ó ti fi iná dán ẹnìkọ̀ọ̀kan wò.
50 “Cumbĩ nĩ mwega, no cumbĩ ũngĩkorwo nĩũthirĩte mũcamo waguo-rĩ, ũngĩcooka gũcamithio ta cumbĩ na kĩ? Tuĩkai cumbĩ, na mũikaranagie na thayũ.”
“Iyọ̀ dára, ṣùgbọ́n tí ó bá sọ adùn rẹ̀ nù, báwo ni ẹ ṣè lè padà mú un dùn? Ẹ ni iyọ̀ nínú ara yín, ki ẹ sì máa gbé ní àlàáfíà pẹ̀lú ara yín.”