< Mariko 3 >
1 Ningĩ nĩatoonyire thunagogi rĩngĩ, na thĩinĩ nĩ kwarĩ na mũndũ wonjete guoko.
Nígbà tí Jesu wá sí Sinagọgu. Sì kíyèsi i ọkùnrin kan wà níbẹ̀, tí ọwọ́ rẹ̀ kan rọ.
2 Andũ amwe ao nĩmacaragia ũndũ mangĩthitangĩra Jesũ, nĩ ũndũ ũcio makĩmũrora mũno mone kana nĩekũhonia mũndũ ũcio mũthenya wa Thabatũ.
Àwọn kan nínú wọn sì ń wa ọ̀nà láti fi ẹ̀sùn kan Jesu. Nítorí náà, wọ́n ń ṣọ́ Ọ bí yóò mú un láradá ní ọjọ́ ìsinmi.
3 Nake Jesũ akĩĩra mũndũ ũcio warĩ mwonju guoko atĩrĩ, “Rũgama haha mbere ya andũ othe.”
Jesu wí fún ọkùnrin tí ọwọ́ rẹ̀ rọ náà pé, “Dìde dúró ní iwájú ìjọ ènìyàn.”
4 Ningĩ Jesũ akĩmooria atĩrĩ, “Nĩ ũndũ ũrĩkũ mwĩtĩkĩrie nĩ watho mũthenya wa Thabatũ; nĩ gwĩka wega kana nĩ gwĩka ũũru, nĩ kũhonokia muoyo kana nĩ kũũraga?” No-o magĩkira ki.
Nígbà náà ni Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ǹjẹ́ ó bá òfin mu ní ọjọ́ ìsinmi bóyá láti ṣe rere, tàbí láti ṣe búburú! Láti gbà ẹ̀mí là, tàbí pa á run?” Ṣùgbọ́n wọ́n dákẹ́ láìfèsì.
5 Akĩmarora arakaire, na aiguĩte ũũru nĩ ũndũ wa ũremi wa ngoro ciao, akĩĩra mũndũ ũcio atĩrĩ, “Tambũrũkia guoko gwaku.” Nake agĩgũtambũrũkia, nakuo guoko gũkĩhona biũ.
Nígbà tí ó sì wo gbogbo wọn yíká pẹ̀lú ìbínú, ọkàn rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí líle àyà wọn, ó sọ fún ọkùnrin náà pé, “Na ọwọ́ rẹ jáde.” Ó nà án jáde, ọwọ́ náà sì bọ̀ sípò padà pátápátá.
6 Hĩndĩ ĩyo Afarisai makiumagara na makĩambĩrĩria gũthugunda me hamwe na Aherodia ũrĩa mangĩũraga Jesũ.
Lójúkan náà, àwọn Farisi jáde lọ, láti bá àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Herodu gbìmọ̀ pọ̀, bí wọn yóò ṣe pa Jesu.
7 Nake Jesũ na arutwo ake makiuma kũu magĩthiĩ iria-inĩ, nakĩo gĩkundi kĩnene kĩa andũ kuuma Galili gĩkĩmũrũmĩrĩra.
Jesu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ yẹra kúrò níbẹ̀ lọ sí etí Òkun. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn láti Galili àti Judea sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
8 Na rĩrĩa maiguire ũrĩa wothe eekaga, andũ aingĩ magĩũka kũrĩ we moimĩte Judea, na Jerusalemu na Idumea o na mũrĩmo ũrĩa ũngĩ wa Jorodani, o na kuuma kũrĩa gwakuhĩrĩirie Turo na Sidoni.
Nígbà tí wọ́n gbọ́ ìròyìn iṣẹ́ ìyanu tí ó ṣe, ọ̀pọ̀ ènìyàn sì tọ̀ ọ́ wá láti Judea, Jerusalẹmu àti Idumea, àti láti apá kejì odò Jordani àti láti ìhà Tire àti Sidoni.
9 Na tondũ wa gĩkundi kĩu, akĩĩra arutwo ake mamũhaarĩrĩrie gatarũ nĩguo gĩkundi kĩu gĩtige kũmũhatĩka.
Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn, Jesu sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti ṣètò ọkọ̀ ojú omi kékeré kan sílẹ̀ fún un láti lọ, láti lé àwọn èrò sẹ́yìn.
10 Nĩgũkorwo nĩahonetie andũ aingĩ, nĩ ũndũ ũcio arĩa maarĩ na mĩrimũ nĩmatindĩkanaga nĩguo mamũhutie.
Nítorí tí ó mú ọ̀pọ̀ ènìyàn láradá, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn aláìsàn ló bí ara wọn lù ú láti fi ọwọ́ kàn án.
11 Na rĩrĩa rĩothe ngoma thũku ciamuonaga, ciegũithagia thĩ mbere yake, igakaya ikiugaga atĩrĩ, “Wee nĩwe Mũrũ wa Ngai.”
Ìgbàkúgbà tí àwọn tí ó ni ẹ̀mí àìmọ́ bá ti fojú ri, wọ́n á wólẹ̀ níwájú rẹ̀. Wọn a sì kígbe lóhùn rara wí pé, “Ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run.”
12 Nowe agĩcikaania na hinya mũno itikoige we nĩwe ũ.
Ṣùgbọ́n ó kìlọ̀ fún wọn gidigidi, kí wọn má ṣe fi òun hàn.
13 Jesũ agĩcooka akĩambata kĩrĩma-inĩ na agĩĩta arĩa eyendeire, nao magĩũka harĩ we.
Jesu gun orí òkè lọ, ó sì pe àwọn kan tí ó yàn láti wà pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá.
14 Akĩamũra ikũmi na eerĩ, akĩmatua atũmwo, nĩgeetha makoragwo nake, na nĩguo amatũmage makahunjie,
Ó yan àwọn méjìlá, kí wọn kí ó lè wà pẹ̀lú rẹ̀, àti kí ó lè rán wọn lọ láti wàásù
15 na magĩe na ũhoti wa kũingata ndaimono.
àti láti lágbára láti lé àwọn ẹ̀mí Èṣù jáde.
16 Andũ acio ikũmi na eerĩ aathuurire nĩ Simoni (ũrĩa aatuire Petero);
Wọ̀nyí ni àwọn méjìlá náà tí ó yàn: Simoni (ẹni ti ó sọ àpèlé rẹ̀ ní Peteru),
17 na Jakubu wa Zebedi na mũrũ wa nyina Johana (nao acio akĩmatua Boanerigesi, ũguo nĩ kuuga Ariũ a Marurumĩ);
Jakọbu ọmọ Sebede àti Johanu arákùnrin rẹ̀ (àwọn ẹni tí Jesu sọ àpèlé wọ́n ní Boanaji, èyí tí ó túmọ̀ sí “àwọn ọmọ àrá”).
18 na Anderea, na Filipu na Baritholomayo, na Mathayo, na Toma, na Jakubu wa Alufayo na Thadayo, na Simoni ũrĩa Mũzelote
Àti Anderu, Filipi, Bartolomeu, Matiu, Tomasi, Jakọbu ọmọ Alfeu, Taddeu, Simoni tí ń jẹ́ Sealoti
19 na Judasi Mũisikariota, ũrĩa wamũkunyanĩire.
àti Judasi Iskariotu, ẹni tí ó fi í hàn níkẹyìn.
20 Ningĩ Jesũ agĩtoonya nyũmba, na o rĩngĩ kĩrĩndĩ gĩkĩũngana o nginya we na arutwo ake makĩremwo nĩ kũrĩa irio.
Nígbà náà ni Jesu sì wọ inú ilé kan, àwọn èrò sì tún kórajọ, tó bẹ́ẹ̀ tí Òun àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kò rí ààyè láti jẹun.
21 Rĩrĩa andũ ao maiguire ũhoro ũcio, magĩthiĩ kũmũnyiita, nĩgũkorwo moigire atĩrĩ, “Nĩagũrũkĩte.”
Nígbà tí àwọn ẹbí rẹ̀ gbọ́ èyí, wọ́n wá láti mú un lọ ilé, nítorí tí wọn wí pé, “Orí rẹ̀ ti dàrú.”
22 Nao arutani a watho arĩa maikũrũkĩte kuuma Jerusalemu makiuga atĩrĩ, “Aiyũrĩtwo nĩ Beelizebuli! Araingata ndaimono na hinya wa mũnene wa ndaimono.”
Àwọn olùkọ́ni ní òfin sọ̀kalẹ̀ wá láti Jerusalẹmu, wọ́n sì wí pé, “Ó ni Beelsebulu, olórí àwọn ẹ̀mí èṣù, ni ó sì fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde!”
23 Nĩ ũndũ ũcio Jesũ akĩmeeta, na akĩmarĩria na ngerekano, akĩmeera atĩrĩ: “Shaitani angĩhota atĩa kũingata Shaitani?
Jesu pè wọ́n, ó sì fi òwe bá wọn sọ̀rọ̀: “Báwo ni Èṣù ṣe lè lé èṣù jáde?
24 Ũthamaki ũngĩamũkana guo mwene, ũthamaki ũcio ndũngĩtũũra.
Bí ìjọba kan bá yapa sí ara rẹ̀, ìjọba náà yóò wó lulẹ̀.
25 Nyũmba ĩngĩamũkana na andũ ayo mokanĩrĩre, nyũmba ĩyo ndĩngĩtũũra.
Bákan náà, bí ilé kan bá sì yapa sí ara rẹ, ilé náà kí yóò le è dúró.
26 Nake Shaitani angĩĩyũkĩrĩra we mwene na aamũkane-rĩ, ndangĩtũũra; nĩ gũthira egũthira.
Bí Èṣù bá sì dìde sí ara rẹ̀, tí ó sì yapa, òun kí yóò le è dúró ṣùgbọ́n òpin rẹ̀ yóò dé.
27 Na gũtirĩ mũndũ ũngĩhota gũtoonya nyũmba ya mũndũ njamba na amũtunye indo ciake, tiga ambire kuoha mũndũ ũcio njamba. Hĩndĩ ĩyo no rĩo angĩhota kũmũtunya indo cia nyũmba yake.
Kò sí ẹni tí ó le wọ ilé ọkùnrin alágbára kan lọ, kí ó sì kó o ní ẹrù lọ, bí kò ṣe pé ó kọ́kọ́ de ọkùnrin alágbára náà ní okùn, nígbà náà ni yóò lè kó ẹrù ní ilé rẹ̀.
28 Ndamwĩra atĩrĩ na ma, andũ nĩmakarekerwo mehia mao mothe o na irumi ciao ciothe iria magaakorwo marumĩte Ngai nacio.
Lóòótọ́ ní mo wí fún yín, gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ni a ó dáríjì àwọn ọmọ ènìyàn, àti gbogbo ọ̀rọ̀-òdì.
29 No ũrĩa wothe ũkaaruma Roho Mũtheru ndarĩ hĩndĩ akarekerwo, nĩehĩtie rĩĩhia rĩa gũtũũra tene na tene.” (aiōn , aiōnios )
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí Ẹ̀mí Mímọ́, kì yóò rí ìdáríjì títí ayé, ṣùgbọ́n ó wà nínú ewu ẹ̀bi àìnípẹ̀kun.” (aiōn , aiōnios )
30 Oigire ũguo tondũ moigaga atĩrĩ, “Arĩ na ngoma thũku.”
Òun sọ eléyìí fún wọn, nítorí tí wọ́n sọ pé, “Nípa agbára ẹ̀mí àìmọ́ ló ń ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.”
31 Hĩndĩ ĩyo, nyina wa Jesũ na ariũ a nyina na Jesũ magĩũka. Makĩrũgama nja, magĩtũma mũndũ atoonye akamwĩte.
Nígbà náà ni àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ìyá wá, wọ́n dúró lóde, wọ́n sì ránṣẹ́ sí i, wọ́n ń pè é.
32 Nakĩo gĩkundi kĩa andũ nĩgĩaikarĩte thĩ hau kĩmũrigiicĩirie, nao makĩmwĩra atĩrĩ, “Maitũguo na ariũ a maitũguo marĩ nja magĩgũcaria.”
Àwọn ènìyàn tí wọ́n jókòó lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Ìyá àti àwọn arákùnrin rẹ wà lóde.”
33 Nake akĩmooria atĩrĩ, “Maitũ na ariũ a maitũ nĩ a?”
Ṣùgbọ́n ó dá wọn lóhùn wí pé, “Ta ni í ṣe ìyá mi tàbí àwọn arákùnrin mi?”
34 Agĩcooka akĩrora arĩa maikarĩte mamũrigiicĩirie, akĩmeera atĩrĩ, “Maitũ na ariũ a maitũ nĩ aya!
Ó sì wò gbogbo àwọn tí ó jókòó lọ́dọ̀ rẹ̀ yíká, ó sì wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìyá mi àti àwọn arákùnrin mi.
35 Ũrĩa wothe wĩkaga maũndũ marĩa Ngai endaga, ũcio nĩwe mũrũ wa maitũ, na mwarĩ wa maitũ, o na maitũ.”
Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run, òun ni arákùnrin mi àti arábìnrin mi àti ìyá mi.”