< Mariko 2 >
1 Matukũ manini maathira, Jesũ agĩcooka Kaperinaumu rĩngĩ, nao andũ makĩigua atĩ nĩoka mũciĩ.
Lẹ́yìn ọjọ́ mélòó kan, nígbà tí Jesu tún padà wọ Kapernaumu, òkìkí kàn pé ó ti wà nínú ilé.
2 Nĩ ũndũ ũcio andũ aingĩ makĩũngana nginya hakĩaga handũ ha gũikarwo, o na nginya nja ya mũrango, nake akĩmahunjĩria ũhoro.
Láìpẹ́, ogunlọ́gọ̀ ènìyàn ti kún ilé tí ó dé sí tó bẹ́ẹ̀ tí inú ilé àti ẹ̀yìn ìlẹ̀kùn ní ìta kò gba ẹyọ ẹnìkan mọ́, ó sì wàásù ọ̀rọ̀ náà sí wọn.
3 Nĩhookire andũ, makĩmũrehera mũndũ warũarĩte mũrimũ wa gũkua ciĩga, akuuĩtwo nĩ andũ ana.
Àwọn ọkùnrin kan wá, wọ́n gbé arọ tọ̀ ọ́ wá, ẹni tí ọkùnrin mẹ́rin gbé.
4 Na tondũ matingĩahotire kũmũkinyia harĩa Jesũ aarĩ nĩ ũndũ wa ũingĩ wa andũ-rĩ, magĩtharũria nyũmba igũrũ wa hau Jesũ aarĩ na maarĩkia kũhatharia, makĩharũrũkia mũndũ ũcio wakuĩte ciĩga arĩ kĩbarĩ-inĩ kĩu aakomeire.
Nígbà tí wọn kò sì le dé ọ̀dọ̀ Jesu, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn, wọ́n dá òrùlé ilé lu ní ọ̀gangan ibi tí Jesu wà. Wọ́n sì sọ ọkùnrin arọ náà kalẹ̀ ti òun ti àkéte rẹ̀ níwájú Jesu.
5 Rĩrĩa Jesũ oonire wĩtĩkio wao, akĩĩra mũndũ ũcio wakuĩte ciĩga atĩrĩ, “Mũriũ, nĩwarekerwo mehia maku.”
Nígbà tí Jesu sì rí ìgbàgbọ́ wọn, ó sọ fún arọ náà pé, “Ọmọ, a dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì ọ́.”
6 Na rĩrĩ, arutani amwe a watho maarĩ ho, nao makĩĩyũria na ngoro atĩrĩ,
Ṣùgbọ́n díẹ̀ nínú àwọn olùkọ́ òfin tó jókòó níbẹ̀ sọ fún ara wọn pé,
7 “Mũndũ ũyũ ekwaria ũguo nĩkĩ? Nĩ araruma Ngai! Nũũ ũngĩ ũngĩhota kũrekanĩra mehia tiga Ngai wiki?”
“Èéṣe ti ọkùnrin yìí fi sọ̀rọ̀ báyìí? Ó ń sọ̀rọ̀-òdì. Ta ni ó lè darí ẹ̀ṣẹ̀ ji ni bí ko ṣe Ọlọ́run nìkan?”
8 O rĩmwe Jesũ akĩmenya thĩinĩ wa roho wake atĩ ũguo nĩguo meciiragia ngoro-inĩ ciao, nake akĩmooria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩgũtũma mwĩciirie maũndũ macio ngoro-inĩ cianyu?
Lójúkan náà bí Jesu tí wòye nínú ọkàn rẹ̀ pé wọn ń gbèrò bẹ́ẹ̀ ní àárín ara wọn, ó wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yìn fi ń ro nǹkan wọ̀nyí nínú ọkàn yín?
9 Nĩ ũndũ ũrĩkũ mũhũthũ: kwĩra mũndũ ũyũ ũkuĩte ciĩga atĩrĩ, ‘Nĩ warekerwo mehia maku,’ kana kũmwĩra atĩrĩ, ‘Ũkĩra woe kĩbarĩ gĩaku wĩtware’?
Èwo ni ó rọrùn jù láti wí fún arọ náà pé, ‘A dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jì ọ,’ tàbí wí pé, ‘Dìde sì gbé àkéte rẹ, kí o sì máa rìn?’
10 No nĩgeetha mũmenye atĩ Mũrũ wa Mũndũ arĩ na ũhoti gũkũ thĩ wa kũrekanĩra mehia-rĩ ….” Akĩĩra mũndũ ũcio wakuĩte ciĩga atĩrĩ,
Ṣùgbọ́n kí ẹ lè mọ̀ pé Ọmọ Ènìyàn ní agbára ní ayé láti dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ ji ni.” Ó wí fún ọkùnrin arọ náà pé,
11 “Ndakwĩra atĩrĩ, ũkĩra, oya kĩbarĩ gĩaku ũinũke mũciĩ.”
“Mo wí fún ọ, dìde, gbé àkéte rẹ kí ó sì máa lọ ilé rẹ.”
12 Nake agĩũkĩra, akĩoya kĩbarĩ gĩake, agĩĩthiĩra andũ othe mamwĩroreire. Ũndũ ũcio ũgĩtũma andũ othe magege, nao makĩgooca Ngai, makiuga atĩrĩ, “Kaĩ tũtirĩ tuona ũndũ ta ũyũ-ĩ!”
Lójúkan náà, ọkùnrin náà fò sókè fún ayọ̀. Ó gbé àkéte rẹ̀. Ó sì jáde lọ lójú gbogbo wọn. Èyí sì ya gbogbo wọn lẹ́nu tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n sì yin Ọlọ́run lógo wí pé, “Àwa kò rí irú èyí rí!”
13 O rĩngĩ Jesũ nĩoimagarire agĩthiĩ hũgũrũrũ-inĩ cia iria; nakĩo kĩrĩndĩ kĩnene gĩgĩũka kũrĩ we, nake akĩambĩrĩria gũkĩruta ũhoro.
Nígbà náà, Jesu tún jáde lọ sí etí Òkun. Ọ̀pọ̀ ènìyàn sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní kọ́ wọn.
14 Na hĩndĩ ĩrĩa aahĩtũkaga, akĩona Lawi mũrũ wa Alufayo aikarĩte harĩa heetagĩrio mbeeca cia igooti. Jesũ akĩmwĩra atĩrĩ, “Nũmĩrĩra,” nake Lawi agĩũkĩra akĩmũrũmĩrĩra.
Bí ó ti ń rin etí Òkun lọ sókè, ó rí Lefi ọmọ Alfeu tí ó jókòó nínú àgọ́ níbi tí ó ti ń gba owó orí, Jesu sì wí fún un pé, “Tẹ̀lé mi,” Lefi dìde, ó sì ń tẹ̀lé e.
15 Na rĩrĩa Jesũ aarĩĩaga irio cia hwaĩ-inĩ nyũmba kwa Lawi, etia mbeeca cia igooti aingĩ na ehia nĩmarĩĩanĩire nake na arutwo ake, tondũ maarĩ aingĩ nĩmamũrũmĩrĩire.
Ó sì ṣe, bí ó sì ti jókòó ti oúnjẹ ni ilé Lefi, ọ̀pọ̀ àwọn agbowó òde àti ẹlẹ́ṣẹ̀ wá bá Jesu jókòó pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, nítorí tiwọn pọ̀ tiwọn tẹ̀lé e.
16 Rĩrĩa arutani a watho arĩa maarĩ Afarisai moonire akĩrĩĩanĩra na andũ ehia na etia mbeeca cia igooti, makĩũria arutwo ake atĩrĩ, “Arĩĩanagĩra na etia mbeeca cia igooti na ehia nĩkĩ?”
Nígbà tí àwọn olùkọ́ òfin àti àwọn Farisi rí ì tí ó ń bá àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ jẹun, wọn wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Èétirí tí ó fi ń bá àwọn agbowó òde àti ẹlẹ́ṣẹ̀ jẹun?”
17 Nake Jesũ aigua ũguo akĩmeera atĩrĩ, “Andũ arĩa agima mĩĩrĩ ti o mabataragio nĩ ndagĩtarĩ, no nĩ arĩa arũaru. Ndiokire gwĩta andũ arĩa athingu, no nĩ arĩa ehia.”
Nígbà tí Jesu gbọ́, ó sọ fún wọn wí pé, “Àwọn tí ara wọ́n dá kò wa oníṣègùn, bí ko ṣe àwọn tí ara wọn kò dá. Èmi kò wá láti sọ fún àwọn ènìyàn rere láti ronúpìwàdà, bí kò ṣe àwọn ènìyàn ẹlẹ́ṣẹ̀.”
18 Na rĩrĩ, arutwo a Johana na Afarisai nĩmehingĩte kũrĩa irio. Andũ amwe magĩũka makĩũria Jesũ atĩrĩ, “Nĩkĩ gĩtũmaga arutwo a Johana na arutwo a Afarisai mehinge kũrĩa irio, no arutwo aku matiĩhingaga?”
Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu àti àwọn Farisi a máa gbààwẹ̀. Àwọn ènìyàn kan sì wá, wọ́n sì bi í pé, “Èéṣe tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Farisi fi ń gbààwẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ kò gbààwẹ̀?”
19 Nake Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Ageni a mũhikania mangĩĩhinga kũrĩa irio atĩa rĩrĩa arĩ hamwe nao? Matingĩhinga rĩrĩa rĩothe marĩ hamwe nake.
Jesu dáhùn wí pé, “Báwo ni àwọn àlejò ọkọ ìyàwó yóò ṣe máa gbààwẹ̀ nígbà tí ọkọ ìyàwó ṣì wà lọ́dọ̀ wọn?
20 No ihinda nĩrĩgakinya rĩrĩa mũhikania akeeherio kuuma kũrĩ o, na hĩndĩ ĩyo nĩmakehinga kũrĩa irio.”
Ṣùgbọ́n láìpẹ́ ọjọ́, a ó gba ọkọ ìyàwó kúrò lọ́dọ̀ wọn. Nígbà náà wọn yóò gbààwẹ̀ ni ọjọ́ wọ̀nyí.”
21 “Gũtirĩ mũndũ wĩkagĩra nguo ngũrũ kĩraka kĩerũ. Angĩĩka ũguo, kĩraka kĩu kĩerũ no kĩguucie nguo ĩyo ngũrũ, nakĩo gĩtũme hau hatarũku hatũrĩke makĩria.
“Kò sí ẹni tí ń fi ìrépé aṣọ tuntun lẹ ògbólógbòó ẹ̀wù, bí ó ba ṣe bẹ́ẹ̀, èyí tuntun tí a fi lẹ̀ ẹ́ yóò fàya kúrò lára ògbólógbòó, yíya rẹ̀ yóò sí burú púpọ̀ jù.
22 Ningĩ gũtirĩ mũndũ wĩkĩraga ndibei ya mũhihano mondo-inĩ ngũrũ. Angĩĩka ũguo, ndibei ĩyo no ĩtarũre mondo icio, nayo ndibei ĩyo ĩitĩke, nacio mondo ithũke. No rĩrĩ, ndibei ya mũhihano ĩĩkĩragwo thĩinĩ wa mondo njerũ.”
Kò sì sí ẹni tí ń fi ọtí wáìnì tuntun sínú ìgò wáìnì ògbólógbòó. Bí a bá ṣe bẹ́ẹ̀, ọtí wáìnì náà yóò fa ìgò náà ya, ọtí wáìnì a sì dàànù, bákan náà ni ìgò náà, ṣùgbọ́n ọtí wáìnì tuntun ni a n fi sínú ìgò wáìnì tuntun.”
23 Na mũthenya ũmwe warĩ wa Thabatũ-rĩ, Jesũ nĩatuĩkanĩirie mĩgũnda-inĩ ya ngano. Na rĩrĩa aathiiaga arĩ hamwe na arutwo ake, arutwo makĩambĩrĩria gũtua ngira cia ngano.
Ó sì ṣe ni ọjọ́ ìsinmi, bí Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ti ń kọjá lọ láàrín oko ọkà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í ya ìpẹ́ ọkà.
24 Nao Afarisai makĩmwĩra atĩrĩ, “Ta rora, nĩ kĩĩ kĩratũma arutwo aku meke ũrĩa watho ũtetĩkĩrĩtie mũthenya wa Thabatũ?”
Díẹ̀ nínú àwọn Farisi wí fún Jesu pé, “Wò ó, èéṣe tiwọn fi ń ṣe èyí ti kò yẹ ni ọjọ́ ìsinmi.”
25 Nake akĩmacookeria atĩrĩ, “Kaĩ mũtarĩ mwathoma ũrĩa Daudi we mwene na arĩa maarĩ nake meekire rĩrĩa maarĩ ahũtu na makabatario nĩ gĩa kũrĩa?
Ó dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin kò ti ka ohun tí Dafidi ṣe, nígbà tí ó ṣe aláìní, tí ebi sì ń pa á, òun àti àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀?
26 Aatoonyire nyũmba ya Ngai rĩrĩa Abiatharu aarĩ mũthĩnjĩri-Ngai ũrĩa mũnene, akĩrĩa mĩgate ĩrĩa yamũrĩirwo Ngai, o ĩrĩa yetĩkĩrĩtio kũrĩĩagwo nĩ athĩnjĩri-Ngai oiki. Na agĩcooka akĩhe arĩa maarĩ nake ĩmwe yayo.”
Bí ó tí wọ ilé Ọlọ́run lọ ni ọjọ́ Abiatari olórí àlùfáà, tí ó sì jẹ àkàrà ìfihàn ti kò tọ́ fún un láti jẹ bí kò ṣe fún àwọn àlùfáà, ó sì tún fi fún àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀.”
27 Ningĩ akĩmeera atĩrĩ, “Mũthenya wa Thabatũ wekĩrirwo ho nĩ ũndũ wa mũndũ, no mũndũ ndombirwo nĩ ũndũ wa Thabatũ.
Ó sì wí fún wọ́n pé, a dá ọjọ́ ìsinmi fún ènìyàn, “Ṣùgbọ́n a kò dá ènìyàn fún ọjọ́ ìsinmi.
28 Nĩ ũndũ ũcio, Mũrũ wa Mũndũ nĩ Mwathani o na wa mũthenya wa Thabatũ.”
Nítorí náà Ọmọ Ènìyàn ni Olúwa ọjọ́ ìsinmi pẹ̀lú.”