< Luka 9 >
1 Na rĩrĩ, Jesũ aarĩkia gwĩta arutwo arĩa ikũmi na eerĩ hamwe, nĩamaheire hinya na ũhoti wa kũingata ndaimono ciothe na kũhonia mĩrimũ,
Ó sì pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ méjìlá jọ, ó sì fún wọn ní agbára àti àṣẹ lórí àwọn ẹ̀mí èṣù gbogbo, àti láti wo ààrùn sàn.
2 na akĩmatũma mathiĩ makahunjie ũhoro wa ũthamaki wa Ngai na mahonagie andũ arĩa arũaru.
Ó sì rán wọn lọ wàásù ìjọba Ọlọ́run, àti láti mú àwọn ọlọkùnrùn láradá.
3 Nake akĩmeera atĩrĩ, “Mũtigakuue kĩndũ o nakĩ kĩa rũgendo; mũtigakuue mũtirima, kana mũhuko, kana irio, kana mbeeca o na kana nguo tiga o iria mwĩhumbĩte.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe mú nǹkan lọ́wọ́ fún àjò yín, ọ̀pá, tàbí àpò tàbí àkàrà, tàbí owó, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin má sì ṣe ní ẹ̀wù méjì.
4 Nyũmba ĩrĩa yothe mũrĩtoonyaga ikaragai kuo nginya rĩrĩa mũkoima itũũra rĩu.
Ní ilékílé tí ẹ̀yin bá sì wọ̀, níbẹ̀ ni kí ẹ̀yin gbé, láti ibẹ̀ ni kí ẹ̀yin sì ti jáde.
5 Andũ mangĩkaarega kũmũnyiita ũgeni-rĩ, mũkaaribariba magũrũ manyu rũkũngũ rũitĩke mũkiuma itũũra rĩao arĩ ũira wa kũmatuĩra ciira.”
Iye àwọn tí kò bá si gbà yín, nígbà tí ẹ̀yin bá jáde kúrò ní ìlú náà, ẹ gbọn eruku ẹsẹ̀ yín fún ẹ̀rí sí wọn.”
6 Nĩ ũndũ ũcio makiumagara magĩthiĩ kuuma gatũũra kamwe nginya karĩa kangĩ makĩhunjagia Ũhoro-ũrĩa-Mwega na makĩhonagia andũ kũrĩa guothe maathiiaga.
Wọ́n sì lọ, wọ́n ń la ìletò kọjá wọ́n sì ń wàásù ìyìnrere, wọ́n sì ń mú ènìyàn láradá níbi gbogbo.
7 Na rĩrĩ, rĩrĩa Herode ũrĩa mũthamaki aiguire ũhoro wa maũndũ mothe marĩa maathiiaga na mbere, nĩataangĩkire ngoro mũno tondũ andũ amwe moigaga atĩ Johana nĩariũkĩte kuuma kũrĩ arĩa akuũ,
Herodu tetrarki gbọ́ nǹkan gbogbo èyí tí a ṣe láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá: ó sì dààmú, nítorí tí àwọn ẹlòmíràn ń wí pé, Johanu ni ó jíǹde kúrò nínú òkú,
8 na angĩ makoiga atĩ Elija nĩonekanĩte, o na angĩ makoiga atĩ mũnabii ũmwe wa arĩa a tene nĩariũkĩte.
Àwọn ẹlòmíràn sì wí pé Elijah ni ó farahàn; àwọn ẹlòmíràn sì wí pé, ọ̀kan nínú àwọn wòlíì àtijọ́ ni ó jíǹde.
9 No Herode akiuga atĩrĩ, “Johana nĩndamũrengithirie mũtwe. Ũyũ ndĩraigua ũhoro wake-rĩ, nĩwe ũ?” Nake akĩĩrirĩria kũmuona.
Herodu sì wí pé, “Johanu ni mo ti bẹ́ lórí, ṣùgbọ́n ta ni èyí tí èmi ń gbọ́ irú nǹkan wọ̀nyí sí?” Ó sì ń fẹ́ láti rí i.
10 Nao atũmwo maacooka, makĩĩra Jesũ maũndũ marĩa mekĩte. Nake akĩehera kuo, agĩthiĩ nao itũũra rĩetagwo Bethisaida,
Nígbà tí àwọn aposteli sì padà dé, wọ́n ròyìn ohun gbogbo fún un tí wọ́n ti ṣe. Ó sì mú wọn, lọ sí apá kan níbi tí a ń pè ní Betisaida.
11 no andũ aingĩ makĩmenya ũhoro ũcio na makĩmũrũmĩrĩra. Nake akĩmaamũkĩra na akĩmahe ũhoro wa ũthamaki wa Ngai, na akĩhonia arĩa maabatarĩtio nĩ kũhonio.
Nígbà tí ọ̀pọ̀ ènìyàn sì mọ̀, wọ́n tẹ̀lé e: ó sì gbà wọ́n, ó sì sọ̀rọ̀ ìjọba Ọlọ́run fún wọn; àwọn tí ó fẹ́ ìmúláradá, ni ó sì mú láradá.
12 Hwaĩ-inĩ arutwo arĩa ikũmi na eerĩ magĩũka kũrĩ we makĩmwĩra atĩrĩ, “Ingata andũ aya nĩguo mathiĩ mĩciĩ ĩrĩa ĩrĩ hakuhĩ o na mĩgũnda-inĩ mageethe irio na gwa gũkoma, tondũ haha tũrĩ nĩ werũ ũtarĩ andũ.”
Nígbà tí ọjọ́ bẹ̀rẹ̀ sí rọlẹ̀, àwọn méjìlá wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Tú ìjọ ènìyàn ká, kí wọn lè lọ sí ìletò àti sí ìlú yíká, kí wọn lè wò, àti kí wọn lè wá oúnjẹ: nítorí ijù ni àwa sá wà níhìn-ín.”
13 Nake akĩmacookeria atĩrĩ, “Maheei kĩndũ gĩa kũrĩa.” Nao makĩmwĩra atĩrĩ, “Tũrĩ o na mĩgate ĩtano na thamaki igĩrĩ, no tũthiire tũkagũrĩre andũ aya othe irio.”
Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ fi oúnjẹ fún wọn jẹ!” Wọ́n sì wí fún un pé, “Àwa kò ní ju ìṣù àkàrà márùn-ún lọ, pẹ̀lú ẹja méjì: bí kò ṣe pé àwa lọ ra oúnjẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí.”
14 (Handũ hau haarĩ na arũme ta ngiri ithano.) Nowe akĩĩra arutwo ake atĩrĩ, “Maikariei thĩ marĩ ikundi cia andũ mĩrongo ĩtano ĩtano.”
Nítorí àwọn ọkùnrin náà tó ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún márùn-ún ènìyàn. Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Kí wọ́n mú wọn jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ̀gbẹ́, ní àràádọ́ta.”
15 Nao arutwo magĩĩka o ũguo, magĩikaria andũ othe thĩ.
Wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀, wọ́n sì mú gbogbo wọn jókòó.
16 Nake akĩoya mĩgate ĩyo ĩtano na thamaki icio igĩrĩ, akĩrora na igũrũ, agĩcookia ngaatho na agĩcienyũranga. Agĩcooka agĩcinengera arutwo ake magaĩre andũ.
Nígbà náà ni ó mú ìṣù àkàrà márùn-ún, àti ẹja méjì náà, nígbà tí ó gbé ojú sókè ọ̀run, ó súre sí i, ó sì bù ú, ó sì fi fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, kí wọn gbé e kalẹ̀ níwájú àwọn ènìyàn.
17 Othe makĩrĩa makĩhũũna, nao arutwo makĩiyũria ciondo ikũmi na igĩrĩ cia cienyũ iria ciatigarire.
Wọ́n sì jẹ, gbogbo wọn sì yó: wọ́n ṣa agbọ̀n méjìlá jọ nínú àjẹkù tí ó kù.
18 Na rĩrĩ, hĩndĩ ĩmwe Jesũ akĩhooya arĩ keheri-inĩ, arutwo ake magĩkorwo marĩ hamwe nake. Akĩmooria atĩrĩ, “Andũ moigaga niĩ nĩ niĩ ũ?”
Ó sì ṣe, nígbà tí ó ku òun nìkan ó gbàdúrà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀: ó sì bi wọ́n pé, “Ta ni àwọn ènìyàn ń fi mí pè?”
19 Nao makĩmũcookeria atĩrĩ, “Amwe moigaga nĩwe Johana Mũbatithania; angĩ makoiga nĩwe Elija; angĩ nao makoiga atĩ mũnabii ũmwe wa arĩa a tene nĩariũkĩte.”
Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Johanu Onítẹ̀bọmi; ṣùgbọ́n ẹlòmíràn ní Elijah ni, àti àwọn ẹlòmíràn wí pé, ọ̀kan nínú àwọn wòlíì àtijọ́ ni ó jíǹde.”
20 Nake akĩmooria atĩrĩ, “Inyuĩ na inyuĩ-rĩ, mugaga atĩa? Mugaga niĩ nĩ niĩ ũ?” Petero akĩmũcookeria atĩrĩ, “Wee nĩwe Kristũ ũrĩa wa Ngai.”
Ó sì bi wọ́n pé, “Ṣùgbọ́n ta ni ẹ̀yin ń fi èmi pè?” Peteru sì dáhùn, wí pe, “Kristi ti Ọlọ́run.”
21 Nake Jesũ akĩmakaania na hinya, akĩmeera matikeere mũndũ o na ũrĩkũ ũhoro ũcio.
Ó sì kìlọ̀ fún wọn, pé, kí wọn má ṣe sọ èyí fún ẹnìkan.
22 Nake akiuga atĩrĩ, “Mũrũ wa Mũndũ no nginya one mathĩĩna maingĩ, na aregwo nĩ athuuri, na athĩnjĩri-Ngai arĩa anene, o na arutani a watho, na no nginya ooragwo na thuutha wa mĩthenya ĩtatũ ariũkio.”
Ó sì wí pé, “Ọmọ ènìyàn yóò jìyà ohun púpọ̀, a ó sì kọ̀ ọ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn alàgbà, olórí àlùfáà àti láti ọ̀dọ̀ àwọn akọ̀wé, a ó sì pa á, ní ọjọ́ kẹta a ó sì jí i dìde.”
23 Agĩcooka akĩmeera othe atĩrĩ, “Mũndũ o wothe ũngĩenda kũnũmĩrĩra, no nginya eerege we mwene, na oyage mũtharaba wake o mũthenya, aanũmagĩrĩre.
Ó sì wí fún gbogbo wọn pé, “Bí ẹnìkan bá ń fẹ́ láti máa tọ̀ mí lẹ́yìn, kí ó sẹ́ ara rẹ̀, kí ó sì gbé àgbélébùú rẹ̀ ní ọjọ́ gbogbo, kí ó sì máa tọ̀ mí lẹ́yìn.
24 Nĩgũkorwo ũrĩa wothe wendaga kũhonokia muoyo wake nĩakoorwo nĩguo, no ũrĩa wothe ũkoorwo nĩ muoyo wake nĩ ũndũ wakwa nĩakaũhonokia.
Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ gba ọkàn rẹ̀ là, yóò sọ ọ́ nù: ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ ọkàn rẹ̀ nù nítorí mi, òun náà ni yóò sì gbà á là.
25 Mũndũ angĩĩguna nakĩ angĩĩgwatĩra thĩ yothe, no ate muoyo wake kana orwo nĩguo?
Nítorí pé èrè kín ni fún ènìyàn, bí ó jèrè gbogbo ayé, tí ó sì sọ ara rẹ̀ nù tàbí kí ó fi ṣòfò.
26 Mũndũ o wothe ũngĩconoka nĩ ũndũ wakwa na nĩ ũndũ wa ciugo ciakwa, o nake nĩagaconokerwo nĩ Mũrũ wa Mũndũ rĩrĩa agacooka arĩ na riiri wake, na riiri wa Ithe, o na wa araika arĩa atheru.
Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá tijú mi, àti ọ̀rọ̀ mi, òun ni Ọmọ Ènìyàn yóò tijú rẹ̀ nígbà tí ó bá dé inú ògo tirẹ̀, àti ti baba rẹ̀, àti ti àwọn angẹli mímọ́.
27 Ngũmwĩra atĩrĩ na ma, amwe a aya marũngiĩ haha matigacama gĩkuũ matonete ũthamaki wa Ngai.”
“Ṣùgbọ́n èmi wí fún yín nítòótọ́, ẹlòmíràn dúró níhìn-ín yìí, tí kì yóò rí ikú, títí wọn ó fi rí ìjọba Ọlọ́run.”
28 Mĩthenya ta ĩnana thuutha wa Jesũ kwaria ũhoro ũyũ nĩathiire na Petero, na Johana na Jakubu akĩambata nao kĩrĩma igũrũ makahooe.
Ó sì ṣe bí ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́jọ lẹ́yìn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó mú Peteru àti Johanu àti Jakọbu, ó gun orí òkè lọ láti lọ gbàdúrà.
29 Na rĩrĩa ahooyaga, mũhaanĩre wa ũthiũ wake ũkĩgarũrũka, nacio nguo ciake ikĩerũha igĩkenga o ta rũheni.
Bí ó sì ti ń gbàdúrà, àwọ̀ ojú rẹ̀ yípadà, aṣọ rẹ̀ sì funfun gbòò,
30 Na rĩrĩ, andũ eerĩ, nĩo Musa na Elija,
Sì kíyèsi i, àwọn ọkùnrin méjì, Mose àti Elijah, wọ́n ń bá a sọ̀rọ̀,
31 makiumĩrĩra Jesũ marĩ na riiri mũnene makĩaria nake. Maaragia ũhoro wa gũkua gwake, kũrĩa aakirie kũhingia akinya Jerusalemu.
tí wọ́n fi ara hàn nínú ògo, wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ ikú rẹ̀, tí òun yóò ṣe parí ní Jerusalẹmu.
32 Petero hamwe na arĩa maarĩ nake nĩmahĩtĩtwo nĩ toro, na rĩrĩa mookĩrire, makĩona riiri wake na andũ acio eerĩ maarũngiĩ hamwe nake.
Ṣùgbọ́n ojú Peteru àti ti àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ wúwo fún oorun. Nígbà tí wọ́n sì tají, wọ́n rí ògo rẹ̀, àti ti àwọn ọkùnrin méjèèjì tí ó bá a dúró.
33 Na rĩrĩa andũ acio maatiganaga na Jesũ, Petero akĩmwĩra atĩrĩ, “Mwathani, nĩ wega tũikare gũkũ. Reke twake ithũnũ ithatũ, kĩmwe gĩaku, na kĩmwe kĩa Musa, na kĩmwe kĩa Elija.” (Nowe ndaamenyaga ũrĩa oigaga.)
Ó sì ṣe, nígbà tí wọ́n lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, Peteru wí fún Jesu pé, “Olùkọ́, ó dára fún wa kí a máa gbé ìhín yìí, jẹ́ kí àwa pa àgọ́ mẹ́ta, ọ̀kan fún ìwọ, àti ọ̀kan fún Mose, àti ọ̀kan fún Elijah.” (Kò mọ èyí tí òun ń wí.)
34 Na o akĩaragia-rĩ, itu rĩkiumĩra na rĩkĩmahumbĩra, nao magĩĩtigĩra mũno nĩ kũhumbĩrwo nĩ itu rĩu.
Bí ó ti ń sọ báyìí, ìkùùkuu kan wá, ó síji bò wọ́n: ẹ̀rù sì bà wọ́n nígbà tí wọ́n ń wọ inú ìkùùkuu lọ.
35 Mũgambo ũkiuma itu-inĩ rĩu, ũkiuga atĩrĩ, “Ũyũ nĩwe Mũrũ wakwa, ũrĩa ndĩĩthuurĩire; mũiguagei.”
Ohùn kan sì ti inú ìkùùkuu wá wí pé, “Èyí yìí ni àyànfẹ́ ọmọ mi: ẹ máa gbọ́ tirẹ̀.”
36 Thuutha wa mũgambo ũcio kũiguĩka, makĩona atĩ Jesũ aarĩ wiki. Nao arutwo magĩkira ki na ũhoro ũcio, gũtirĩ mũndũ o na ũmwe meerire matukũ-inĩ macio maũndũ marĩa moonete.
Nígbà tí ohùn náà sì dákẹ́, Jesu nìkan ṣoṣo ni a rí. Wọ́n sì pa á mọ́, wọn kò sì sọ ohunkóhun tí wọ́n rí fún ẹnikẹ́ni ní ọjọ́ wọ̀nyí.
37 Mũthenya ũyũ ũngĩ, maikũrũka kuuma kĩrĩma-inĩ, Jesũ agĩtũngwo nĩ andũ aingĩ.
Ó sì ṣe, ní ọjọ́ kejì, nígbà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti orí òkè, ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn wá pàdé rẹ̀.
38 Na rĩrĩ, mũndũ warĩ gatagatĩ-inĩ ka andũ acio akĩanĩrĩra, akiuga atĩrĩ, “Mũrutani, ndagũthaitha ũrore mũriũ wakwa, nĩgũkorwo nĩ mwana wakwa wa mũmwe.
Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan nínú ìjọ ènìyàn kígbe sókè pé, “Olùkọ́ mo bẹ̀ ọ́, wo ọmọ mi: nítorí ọmọ mi kan ṣoṣo náà ni.
39 na ngoma thũku nĩĩmũnyiitaga na agakaya o rĩmwe; ningĩ ĩkamũrũnda na ĩkamũthiorania, ĩgatũma arute mũhũyũ na kanua. Ndĩmũrekagia o na hanini, na nĩĩramwananga.
Sì kíyèsi i, ẹ̀mí èṣù a máa mú un, a sì máa kígbe lójijì; a sì máa nà án tàntàn títí yóò fi yọ ìfófó lẹ́nu, a máa pa á lára, kì í tilẹ̀ ń fẹ́ fi í sílẹ̀ lọ.
40 Ndĩrathaithire arutwo aku maingate ngoma ĩyo, no mararemwo.”
Mo sì bẹ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ láti lé e jáde: wọn kò sì lè ṣe é.”
41 Nake Jesũ akĩmũcookeria atĩrĩ, “Rũciaro rũrũ rũtetĩkagia na rũremi, nĩ nginya rĩ ngũikara hamwe na inyuĩ, na ngũmũkirĩrĩria nginya rĩ? Rehe mũrũguo haha.”
Jesu sì dáhùn pé, “Ìran aláìgbàgbọ́ àti àrékérekè, èmi ó ti bá yín gbé pẹ́ tó? Èmi yóò sì ti ṣe sùúrù fún yín pẹ́ tó? Fa ọmọ rẹ wá níhìn-ín yìí.”
42 Rĩrĩa kamwana kau gaathiiaga harĩ Jesũ, ndaimono ĩyo ĩgĩgatungumania thĩ, na ĩgĩgathiorania. No Jesũ agĩkũũma roho ũcio mũũru, akĩhonia kamwana kau, agĩgacookeria ithe.
Bí ó sì ti ń bọ̀, ẹ̀mí èṣù náà gbé e ṣánlẹ̀, ó sì nà án tàntàn. Jesu sì bá ẹ̀mí àìmọ́ náà wí, ó sì mú ọmọ náà láradá, ó sì fà á lé baba rẹ̀ lọ́wọ́.
43 Nao othe makĩgegio nĩ ũnene wa Ngai. Hĩndĩ ĩrĩa andũ othe maagegetio nĩ ũrĩa wothe Jesũ eekĩte, akĩĩra arutwo ake atĩrĩ,
Ẹnu sì ya gbogbo wọn sí iṣẹ́ títóbi Ọlọ́run, ṣùgbọ́n nígbà tí hà sì ń ṣe gbogbo wọn sí ohun gbogbo tí Jesu ṣe, ó wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé,
44 “Thikĩrĩriai wega ũrĩa ngũmwĩra: Mũrũ wa Mũndũ nĩegũkunyanĩrwo aneanwo moko-inĩ ma andũ.”
“Ẹ jẹ́ kí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí wọ̀ yín létí, nítorí a ó fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn ènìyàn lọ́wọ́.”
45 No-o matiamenyire ũguo nĩ kuuga atĩa. Nĩmahithĩtwo ũhoro ũcio, nĩ ũndũ ũcio makĩaga kũũmenya, na magĩĩtigĩra kũmũũria ũhoro ũcio.
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ náà kò yé wọn, ó sì ṣú wọn lójú, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì mọ̀ ọ́n: ẹ̀rù sì ń bà wọ́n láti béèrè ìdí ọ̀rọ̀ náà.
46 Na gũkĩgĩa na ngarari gatagatĩ ka arutwo makĩũrania nũũ wao ũngĩtuĩka mũnene kũrĩ arĩa angĩ.
Iyàn kan sì dìde láàrín wọn, ní ti ẹni tí yóò ṣe olórí nínú wọn.
47 Nake Jesũ, tondũ nĩamenyaga meciiria mao, akĩoya kaana kanini agĩkarũgamia hakuhĩ nake.
Nígbà tí Jesu sì mọ èrò ọkàn wọn, ó mú ọmọdé kan, ó gbé e jókòó lọ́dọ̀ rẹ̀.
48 Agĩcooka akĩmeera atĩrĩ, “Ũrĩa wothe wamũkagĩra kaana gaka thĩinĩ wa rĩĩtwa rĩakwa, nĩ niĩ aamũkagĩra; na ũrĩa ũnyamũkagĩra ti niĩ aamũkagĩra, no nĩ ũrĩa wandũmire. Nĩgũkorwo ũrĩa mũnini gatagatĩ-inĩ kanyu inyuothe, ũcio nĩwe mũnene kũmũkĩra.”
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá gba ọmọdé yìí nítorí orúkọ mi, ó gbà mí: àti ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà mí, ó gba ẹni tí ó rán mi: nítorí ẹni tí ó bá kéré jù nínú gbogbo yín, òun náà ni yóò pọ̀jù.”
49 Nake Johana akĩmwĩra atĩrĩ, “Mwathi, nĩtũronire mũndũ akĩingata ndaimono na rĩĩtwa rĩaku, na ithuĩ tũrageria kũmũgiria tondũ ti ũmwe witũ.”
Johanu sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Olùkọ́, àwa rí ẹnìkan ó ń fi orúkọ rẹ lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde; àwa sì dá a lẹ́kun, nítorí tí kò bá wa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.”
50 Nake Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Mũtikamũgirie, nĩgũkorwo ũrĩa ũtarĩ ũthũ na inyuĩ, ũcio nĩ ũmwe wanyu.”
Jesu sì wí fún un, pé, “Má ṣe dá a lẹ́kun mọ́: nítorí ẹni tí kò bá lòdì sí i yín, ó wà fún yín.”
51 Na rĩrĩ, kahinda gake gaakuhĩrĩria ga kwambata matu-inĩ, Jesũ nĩatuire itua rĩa gũthiĩ Jerusalemu.
Nígbà tí ọjọ́ àti gbà á sókè ń súnmọ́, ó pinnu láti lọ sí Jerusalẹmu.
52 Nake agĩtũma andũ mathiĩ mbere yake kũhaarĩria maũndũ nĩ ũndũ wake, magĩthiĩ magĩtoonya gatũũra kamwe ga Samaria;
Ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ lọ sí iwájú rẹ̀. Nígbà tí wọ́n sì lọ wọ́n wọ ìletò kan tí í ṣe ti ará Samaria láti pèsè sílẹ̀ dè é.
53 no andũ a kũu matiamũnyiitire ũgeni, tondũ aathiiaga Jerusalemu.
Wọn kò sì gbà á, nítorí pé ó ń lọ sí Jerusalẹmu.
54 Rĩrĩa arutwo ake, Jakubu na Johana monire ũguo makĩũria atĩrĩ, “Mwathani, nĩũkwenda twĩtie mwaki uume igũrũ ũmaniine?”
Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ Jakọbu àti Johanu sì rí i, wọ́n ní, “Olúwa wa, jẹ́ kí a pe iná láti ọ̀run wá, kí a sì pa wọ́n run, bí Elijah ti ṣe?”
55 Nowe Jesũ akĩĩhũgũra akĩmakaania,
Ṣùgbọ́n Jesu yípadà, ó sì bá wọn wí.
56 nao magĩthiĩ gatũũra kangĩ.
Lẹ́yìn náà Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì lọ sí ìletò mìíràn.
57 Rĩrĩa maathiiaga na njĩra, mũndũ ũmwe akĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩndĩkũrũmagĩrĩra kũrĩa guothe ũrĩthiiaga.”
Bí wọ́n ti ń lọ lọ́nà, ọkùnrin kan wí fún un pé, “Olúwa, Èmi ń fẹ́ láti máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn ní ibikíbi tí ìwọ bá ń lọ.”
58 Nake Jesũ akĩmũcookeria atĩrĩ, “Mbwe nĩ irĩ marima na nyoni cia rĩera-inĩ nĩ irĩ itara, no rĩrĩ, Mũrũ wa Mũndũ ndarĩ handũ angĩigĩrĩra mũtwe wake.”
Jesu sì wí fún un pé, “Àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ ní ihò, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ní ìtẹ́; ṣùgbọ́n Ọmọ Ènìyàn kò ní ibi tí yóò fi orí rẹ̀ lé.”
59 Akĩĩra mũndũ ũngĩ atĩrĩ, “Nũmĩrĩra.” No mũndũ ũcio akĩmũcookeria atĩrĩ, “Mwathani, reke nyambe thiĩ ngathike baba.”
Ó sì wí fún ẹlòmíràn pé, “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn.” Ṣùgbọ́n èyí wí fún un pé, “Olúwa, jẹ́ kí èmi lọ sìnkú baba mi ná.”
60 Jesũ akĩmwĩra atĩrĩ, “Reke arĩa akuũ mathikage akuũ ao ene, no wee thiĩ ũkahunjie ũhoro wa ũthamaki wa Ngai.”
Jesu sì wí fún un pé, “Jẹ́ kí àwọn òkú máa sìnkú ara wọn, ṣùgbọ́n ìwọ lọ kí o sì máa wàásù ìjọba Ọlọ́run.”
61 Na mũndũ ũngĩ akĩmwĩra atĩrĩ, “Mwathani, niĩ nĩngũkũrũmĩrĩra, no reke nyambe thiĩ ngoigĩre andũ aitũ ũhoro.”
Ẹlòmíràn sì wí fún un pé, “Olúwa, èmi yóò tọ̀ ọ́ lẹ́yìn ṣùgbọ́n jẹ́ kí n kọ́kọ́ lọ dágbére fún àwọn ará ilé mi.”
62 Nake Jesũ akĩmũcookeria atĩrĩ, “Gũtirĩ mũndũ o na ũrĩkũ ũnyiitaga mũraũ na guoko gwake na agacooka kũrora na thuutha wagĩrĩire gũtungata ũthamaki-inĩ wa Ngai.”
Jesu sì wí fún un pé, “Kò sí ẹni, tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé ohun èlò ìtulẹ̀, tí ó sì wo ẹ̀yìn, tí ó yẹ fún ìjọba Ọlọ́run.”