< Luka 20 >
1 Na rĩrĩ, mũthenya ũmwe akĩruta andũ kũu hekarũ-inĩ na akĩhunjagia Ũhoro-ũrĩa-Mwega-rĩ, athĩnjĩri-Ngai arĩa anene, na arutani a watho, hamwe na athuuri magĩũka kũrĩ we.
Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń kọ́ àwọn ènìyàn ní tẹmpili tí ó sì ń wàásù ìyìnrere, àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà dìde sí i.
2 Makĩmũũria atĩrĩ, “Twĩre wĩkaga maũndũ maya na ũhoti ũrĩkũ. Nũũ wakũheire ũhoti ũcio?”
Wọ́n sì wí fún un pé, “Sọ fún wa, àṣẹ wo ni ìwọ fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí? Tàbí ta ni ó fún ọ ní àṣẹ yìí?”
3 Nake akĩmacookeria atĩrĩ, “O na niĩ nĩngũmũũria kĩũria.
Ó sì dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Èmi pẹ̀lú yóò sì bi yín léèrè ọ̀rọ̀ kan; ẹ sì fi ìdáhùn fún mi.
4 Ta njĩĩrai, ũbatithio wa Johana-rĩ, woimĩte igũrũ kana woimire kũrĩ andũ?”
Ìtẹ̀bọmi Johanu, láti ọ̀run wá ni tàbí láti ọ̀dọ̀ ènìyàn?”
5 Makĩaranĩria o ene ũhoro ũcio, makĩĩrana atĩrĩ, “Tũngiuga atĩ ‘Woimĩte igũrũ’ egũtũũria atĩrĩ, ‘Mwakĩregire kũmwĩtĩkia nĩkĩ?’
Wọ́n sì bá ara wọn gbèrò pé, “Bí àwa bá wí pé, ‘Láti ọ̀run wá ni,’ òun yóò wí pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi gbà á gbọ́?’
6 Ningĩ tuoiga atĩ ‘Woimĩte kũrĩ andũ’, andũ othe nĩmegũtũhũũra na mahiga nyuguto, nĩ ũndũ nĩmetĩkĩtie atĩ Johana aarĩ mũnabii.”
Ṣùgbọ́n bí àwa bá sì wí pé, ‘Láti ọ̀dọ̀ ènìyàn,’ gbogbo ènìyàn ni yóò sọ wá ní òkúta, nítorí wọ́n gbàgbọ́ pé, wòlíì ni Johanu.”
7 Nĩ ũndũ ũcio magĩcookeria Jesũ atĩrĩ, “Ithuĩ tũtiũĩ woimĩte kũ.”
Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Àwa kò mọ̀ ibi tí ó ti wá.”
8 Nake Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “O na niĩ ndikũmwĩra njĩkaga maũndũ maya na ũhoti ũrĩkũ.”
Jesu sì wí fún wọn pé, “Ǹjẹ́ èmi kì yóò wí fún yín àṣẹ tí èmi fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí.”
9 Agĩcooka akĩhe andũ ũhoro na ngerekano akĩmeera atĩrĩ, “Mũndũ ũmwe nĩahaandire mũgũnda wake mĩthabibũ, na akĩũkomborithia arĩmi angĩ, agĩcooka agĩthiĩ kũndũ kũraya na agĩikara kuo ihinda iraaya.
Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ sí í pa òwe yìí fún àwọn ènìyàn pé, “Ọkùnrin kan gbin ọgbà àjàrà kan, ó sì fi ṣe àgbàtọ́jú fún àwọn olùṣọ́gbà, ó sì lọ sí àjò fún ìgbà pípẹ́.
10 Na rĩrĩ, hĩndĩ ya magetha yakinya-rĩ, agĩtũma ndungata yake kũrĩ akombori acio nĩgeetha mamĩnengere maciaro mamwe ma mũgũnda ũcio wa mĩthabibũ. No akombori acio makĩmĩhũũra na makĩmĩingata ĩtarĩ na kĩndũ.
Nígbà tí ó sì tó àkókò, ó rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ kan sí àwọn olùṣọ́gbà náà, kí wọn lè fún un nínú èso ọgbà àjàrà náà, ṣùgbọ́n àwọn alágbàtọ́jú lù ú, wọ́n sì rán an padà lọ́wọ́ òfo.
11 Agĩcooka agĩtũma ndungata ĩngĩ, ĩyo o nayo makĩmĩhũũra makĩmĩconorithia na makĩmĩingata ĩtarĩ na kĩndũ.
Ó sì tún rán ọmọ ọ̀dọ̀ mìíràn, wọ́n sì lù ú pẹ̀lú, wọ́n sì jẹ ẹ́ ní yà, wọ́n sì rán an padà lọ́wọ́ òfo.
12 O rĩngĩ agĩtũma ndungata ya gatatũ, nao makĩmĩtiihangia na makĩmĩingata.
Ó sì tún rán ẹ̀kẹta: wọ́n sì sá a lọ́gbẹ́ pẹ̀lú, wọ́n sì tì í jáde.
13 “Nake mwene mũgũnda ũcio wa mĩthabibũ akĩĩyũria atĩrĩ, ‘Ngwĩka atĩa? Ngũtũma mũrũ wakwa, ũrĩa nyendete; hihi mahota kũmũhe gĩtĩĩo’.
“Nígbà náà ni Olúwa ọgbà àjàrà wí pé, ‘Èwo ni èmi ó ṣe? Èmi ó rán ọmọ mi àyànfẹ́ lọ: bóyá nígbà tí wọ́n bá rí i, wọn yóò bu ọlá fún un.’
14 “No rĩrĩa akombori acio maamuonire, makĩarĩrĩria ũhoro ũcio. Makĩĩrana atĩrĩ, ‘Ũyũ nĩwe ũkaagaya mũgũnda ũyũ. Nĩtũmũũragei nĩguo igai rĩake rĩtuĩke riitũ.’
“Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn alágbàtọ́jú náà rí i, wọ́n bá ara wọn gbèrò pé, ‘Èyí ni àrólé; ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á, kí ogún rẹ̀ lè jẹ́ ti wa.’
15 Nĩ ũndũ ũcio makĩmũruta nja ya mũgũnda ũcio wa mĩthabibũ, makĩmũũraga. “Rĩu-rĩ, mwene mũgũnda ũcio wa mĩthabibũ-rĩ, akaameka atĩa?
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tì í jáde sẹ́yìn ọgbà àjàrà, wọ́n sì pa á. “Ǹjẹ́ kín ni olúwa ọgbà àjàrà náà yóò ṣe sí wọn?
16 Agooka oorage akombori acio, acooke ahe andũ angĩ mũgũnda ũcio.” Rĩrĩa andũ maiguire ũguo, makiuga atĩrĩ, “Kũroaga gũtuĩka ũguo!”
Yóò wá, yóò sì pa àwọn alágbàtọ́jú náà run, yóò sì fi ọgbà àjàrà náà fún àwọn ẹlòmíràn.” Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, wọ́n ní, “Kí a má ri i!”
17 Jesũ akĩmarora, akĩmooria atĩrĩ, “Maandĩko marĩa mandĩkĩtwo atĩrĩ: “‘Ihiga rĩrĩa aaki maaregire, nĩrĩo rĩtuĩkĩte ihiga inene rĩa koine’, ũguo nĩ kuuga atĩa?
Nígbà tí ó sì wò wọ́n, ó ní, “Èwo ha ni èyí tí a ti kọ̀wé rẹ̀ pé: “‘Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, òun náà ni ó di pàtàkì igun ilé’?
18 Mũndũ ũrĩa wothe ũkaagwĩra ihiga rĩu, nĩrĩkamuunanga, no ũrĩa rĩkaagwĩra nĩrĩkamũhehenja.”
Ẹnikẹ́ni tí ó ṣubú lu òkúta náà yóò fọ́; ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí òun bá ṣubú lù, yóò lọ̀ ọ́ lúúlúú.”
19 Arutani a watho na athĩnjĩri-Ngai arĩa anene magĩcaria ũrĩa mangĩmũnyiitithia o na ihenya tondũ nĩmamenyire aaheanire ngerekano ĩyo akĩaria ũhoro wao. No nĩmetigagĩra andũ.
Àwọn olórí àlùfáà àti àwọn akọ̀wé ń wá ọ̀nà láti mú un ní wákàtí náà; ṣùgbọ́n wọ́n bẹ̀rù àwọn ènìyàn, nítorí tí wọ́n mọ̀ pé, ó pa òwe yìí mọ́ wọn.
20 O makĩmũtuĩragia-rĩ, makĩmũtũmĩra andũ a kũmũthigaana metuĩte andũ ega. Nao magĩthiĩ nĩgeetha mamũnyiite akiuga ũndũ mũũru, nĩguo mamũneane moko-inĩ ma wathani wa barũthi.
Wọ́n sì ń ṣọ́ ọ, wọ́n sì rán àwọn ayọ́lẹ̀wò tí wọ́n ṣe ara wọn bí ẹni pé olóòtítọ́ ènìyàn, kí wọn ba à lè gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú, kí wọn ba à lè fi í lé agbára àti àṣẹ Baálẹ̀ lọ́wọ́.
21 Nĩ ũndũ ũcio athigaani acio makĩmũũria atĩrĩ, “Mũrutani, nĩtũũĩ wee waragia na ũkarutana maũndũ marĩa magĩrĩire, na atĩ ndũtĩagĩra andũ maũthĩ, no wee ũrutanaga ũhoro wa Ngai na ma, ũrĩa kwagĩrĩire.
Wọ́n sì bí i, pé, “Olùkọ́ àwa mọ̀ pé, ìwọ a máa sọ̀rọ̀ fún ni, ìwọ a sì máa kọ́ni bí ó ti tọ́, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì í ṣe ojúsàájú ẹnìkan ṣùgbọ́n ìwọ ń kọ́ni ní ọ̀nà Ọlọ́run lóòtítọ́.
22 Atĩrĩrĩ, nĩtwagĩrĩirwo nĩ kũrutĩra Kaisari igooti kana ca?”
Ǹjẹ́ ó tọ́ fún wa láti máa san owó òde fún Kesari, tàbí kò tọ́?”
23 Nowe Jesũ akĩona ũhinga ũrĩa maarĩ naguo akĩmeera atĩrĩ,
Ṣùgbọ́n ó kíyèsi àrékérekè wọn, ó sì wí fún wọn pé,
24 “Ta nyoniai mbeeca cianyu. Mbica ĩno na rĩĩtwa rĩĩrĩ nĩ cia ũ?”
“Ẹ fi owó idẹ kan hàn mí. Àwòrán àti àkọlé ti ta ni ó wà níbẹ̀?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Ti Kesari ni.”
25 Makĩmũcookeria atĩrĩ, “Nĩ cia Kaisari.” Akĩmeera atĩrĩ, “Kĩrutagĩrei Kaisari kĩrĩa kĩrĩ gĩake, na mũrutagĩre Ngai kĩrĩa kĩrĩ gĩake.”
Ó sì wí fún wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ fi ohun tí i ṣe ti Kesari fún Kesari, àti ohun tí í ṣe ti Ọlọ́run fún Ọlọ́run.”
26 Nao makĩaga ũndũ wa kũmũnyiita naguo harĩ maũndũ marĩa aaririe arĩ mbere ya andũ. Na tondũ wa ũrĩa maagegirio nĩ ũrĩa aamacookeirie ũhoro-rĩ, magĩkira ki.
Wọn kò sì lè gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú níwájú àwọn ènìyàn: ẹnu sì yà wọ́n sí ìdáhùn rẹ̀, wọ́n sì pa ẹnu wọn mọ́.
27 Na rĩrĩ, andũ amwe a Asadukai, arĩa moigaga atĩ gũtirĩ ũhoro wa kũriũka, magĩũka kũrĩ Jesũ, makĩmũũria atĩrĩ,
Àwọn Sadusi kan sì tọ̀ ọ́ wá, àwọn tí wọ́n ń wí pé àjíǹde òkú kò sí wọ́n sì bi í,
28 “Mũrutani, Musa aatwandĩkĩire atĩ mũrũ wa nyina na mũndũ angĩkua atige mũtumia atarĩ na ciana-rĩ, mũndũ ũcio no nginya ahikie mũtumia ũcio watigwo nĩguo aciarĩre mũrũ wa nyina ciana.
wí pé, “Olùkọ́, Mose kọ̀wé fún wa pé, Bí arákùnrin ẹnìkan bá kú, ní àìlọ́mọ, tí ó sì ní aya, kí arákùnrin rẹ̀ ṣú aya rẹ̀ lópó, kí ó lè gbé irú-ọmọ dìde fún arákùnrin rẹ̀.
29 Na rĩrĩ, kwarĩ aanake mũgwanja a nyina ũmwe. Wa mbere akĩhikania na agĩkua, agĩtiga mũtumia atarĩ na ciana.
Ǹjẹ́ àwọn arákùnrin méje kan ti wà; èkínní gbé ìyàwó, ó sì kú ní àìlọ́mọ.
Èkejì sì ṣú u lópó: òun sì kú ní àìlọ́mọ.
31 na wa gatatũ makĩmũhikia, na makĩrũmanĩrĩra ũguo nginya wa mũgwanja; othe magĩkua, makĩmũtiga atarĩ na ciana.
Ẹ̀kẹta sì ṣú u lópó: gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn méjèèje pẹ̀lú: wọn kò sì fi ọmọ sílẹ̀, wọ́n sì kú.
32 Marigĩrĩrio-inĩ, mũtumia ũcio o nake agĩkua.
Nígbẹ̀yìn pátápátá obìnrin náà kú pẹ̀lú.
33 Rĩu-rĩ, hĩndĩ ya kũriũka agaakorwo arĩ mũtumia wa ũ harĩ acio mũgwanja, nĩgũkorwo othe nĩmamũhikĩtie?”
Ǹjẹ́ ní àjíǹde òkú, aya ti ta ni yóò ha ṣe nínú wọn? Nítorí àwọn méjèèje ni ó sá à ni í ní aya.”
34 Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Andũ a ihinda rĩĩrĩ nĩo mahikaga na makahikania. (aiōn )
Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Àwọn ọmọ ayé yìí a máa gbéyàwó, wọn a sì máa fa ìyàwó fún ni. (aiōn )
35 No rĩrĩ, arĩa magaatuuo aagĩrĩru a gũkinya ihinda rĩu o na gũkinyanĩrio ihinda rĩa kũriũka kwa arĩa akuũ-rĩ, acio matikahikanagia o na kana mahikanagie. (aiōn )
Ṣùgbọ́n àwọn tí a kà yẹ láti jogún ìyè ayérayé náà, àti àjíǹde kúrò nínú òkú, wọn kì í gbéyàwó, wọn kì í sì í fa ìyàwó fún ni. (aiōn )
36 Andũ acio matigacooka gũkua; nĩgũkorwo makahaana ta araika. Andũ acio magakorwo marĩ ciana cia Ngai, nĩgũkorwo nĩ ciana cia ũhoro ũcio wa kũriũka.
Nítorí wọn kò lè kú mọ́; nítorí tí wọn bá àwọn angẹli dọ́gba; àwọn ọmọ Ọlọ́run sì ni wọ́n, nítorí wọ́n di àwọn ọmọ àjíǹde.
37 Naguo ũhoro wa atĩ andũ arĩa akuũ nĩmariũkagio-rĩ, Musa o nake nĩawonanirie harĩa haarĩ kĩhinga kĩrĩa gĩakanaga mwaki na gĩtihĩe, rĩrĩa eetire Mwathani ‘Ngai wa Iburahĩmu, na Ngai wa Isaaka, na Ngai wa Jakubu.’
Ní ti pé a ń jí àwọn òkú dìde, Mose tìkára rẹ̀ sì ti fihàn nínú igbó, nígbà tí ó pe ‘Olúwa ni Ọlọ́run Abrahamu, àti Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu.’
38 We ti Ngai wa arĩa akuũ, no nĩ wa arĩa marĩ muoyo, nĩgũkorwo harĩ we andũ othe arĩa marĩ muoyo matũũragio nĩwe.”
Bẹ́ẹ̀ ni òun kì í ṣe Ọlọ́run àwọn òkú, bí kò ṣe ti àwọn alààyè, nítorí gbogbo wọn wà láààyè fún un.”
39 Nao andũ amwe a arutani a watho makĩmwĩra atĩrĩ, “Mũrutani, nĩwoiga wega!”
Nígbà náà ni àwọn kan nínú àwọn akọ̀wé dá a lóhùn, pé, “Olùkọ́ ìwọ wí rere!”
40 Na gũtirĩ mũndũ o na ũmwe wageririe kũmũũria ciũria ingĩ.
Wọn kò sì jẹ́ bi í léèrè ọ̀rọ̀ kan mọ́.
41 Jesũ agĩcooka akĩmooria atĩrĩ, “Andũ moigaga Kristũ nĩ mũriũ wa Daudi nĩ ũndũ wa kĩĩ?
Ó sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí wọ́n fi ń wí pé, ọmọ Dafidi ni Kristi?
42 Daudi we mwene nĩoigĩte ibuku-inĩ rĩa Thaburi atĩrĩ: “‘Mwathani nĩerire Mwathani wakwa atĩrĩ: “Ikara guoko-inĩ gwakwa kwa ũrĩo,
Dafidi tìkára rẹ̀ sì wí nínú ìwé Saamu pé: “‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé: “Ìwọ jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi
43 nginya ngaatũma thũ ciaku ituĩke gaturwa ka makinya maku.”’
títí èmi ó fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ.”’
44 Atĩrĩrĩ, Daudi aamwĩtire ‘Mwathani’. Angĩgĩcooka gũtuĩka mũriũ wake atĩa?”
Ǹjẹ́ bí Dafidi bá pè é ní ‘Olúwa.’ Òun ha sì ti ṣe jẹ́ ọmọ rẹ̀?”
45 O andũ acio othe mathikĩrĩirie, Jesũ akĩĩra arutwo ake atĩrĩ,
Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ní etí gbogbo ènìyàn pé,
46 “Mwĩmenyererei arutani a watho. O mendaga gũthiĩ mehumbĩte nguo ndaaya, na makenda kũgeithagio ndũnyũ-inĩ, na gũikaragĩra itĩ iria cia bata thunagogi-inĩ, o na gũikara handũ ha andũ arĩa atĩĩku maruga-inĩ.
“Ẹ máa kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn akọ̀wé, tí wọ́n fẹ́ láti máa rìn nínú aṣọ gígùn, tí wọ́n sì fẹ́ ìkíni ní ọjà, àti ibùjókòó ọlá nínú Sinagọgu, àti ipò ọlá ní ibi àsè;
47 No nĩo matoonyagĩrĩra atumia a ndigwa makamatunya nyũmba ciao, na nĩguo meyonanie, makahooya mahooya maraihu. Andũ ta acio nĩmakaherithio mũno makĩria.”
Àwọn tí ó jẹ ilé àwọn opó run, tí wọ́n sì ń gbàdúrà gígùn fún àṣehàn, àwọn wọ̀nyí náà ni yóò jẹ̀bi pọ̀jù.”