< Luka 17 >

1 Nake Jesũ akĩĩra arutwo ake atĩrĩ, “Maũndũ marĩa matũmaga andũ mehie no nginya moke, no mũndũ ũrĩa ũtũmaga maũndũ macio moke kaĩ arĩ na haaro-ĩ!
Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Kò le ṣe kí ohun ìkọ̀sẹ̀ máa wa, ṣùgbọ́n ègbé ni fún ẹni tí ó ti ipasẹ̀ rẹ̀ dé.
2 Nĩ kaba mũndũ ta ũcio ohererwo ihiga rĩa gĩthĩi ngingo aikio iria-inĩ, gũkĩra atũme kamwe ga twana tũtũ tũnini keehie.
Ìbá sàn fún un kí a so ọlọ mọ́ ọn ní ọrùn, kí a sì gbé e jù sínú Òkun, ju kí ó mú ọ̀kan nínú àwọn kékeré wọ̀nyí kọsẹ̀.
3 Nĩ ũndũ ũcio-rĩ, ikaragai mwĩiguĩte. “Mũrũ wa thoguo kana mwarĩ wa thoguo angĩĩhia, mũkaanie, na angĩĩrira-rĩ, mũrekere.
Ẹ máa kíyèsára yín. “Bí arákùnrin rẹ bá ṣẹ̀, bá a wí; bí ó bá sì ronúpìwàdà, dáríjì ín.
4 Angĩkwĩhĩria maita mũgwanja o mũthenya ũmwe, na maita macio mothe mũgwanja agooka harĩ we agakwĩra atĩrĩ, ‘Nĩndahera,’ nĩ wega ũmũrekere.”
Bí ó bá sì ṣẹ̀ ọ́ ní igba méje ní òòjọ́, tí ó padà tọ̀ ọ́ wá ní ìgbà méje ní òòjọ́ pé, ‘Mo ronúpìwàdà,’ dáríjì ín.”
5 Nao atũmwo makĩĩra Mwathani atĩrĩ, “Tuongerere wĩtĩkio!”
Àwọn aposteli sì wí fún Olúwa pé, “Bù sí ìgbàgbọ́ wa.”
6 Nake akĩmacookeria atĩrĩ, “Mũngĩkorwo na wĩtĩkio o mũnini ta kabegũ ga karatarĩ-rĩ, mwera mũkũyũ ũyũ atĩrĩ, ‘Kũũrũka, ũkehaande iria-inĩ,’ naguo no ũmwathĩkĩre.
Olúwa sì wí pé, “Bí ẹ̀yin bá ní ìgbàgbọ́ bí hóró irúgbìn musitadi, ẹ̀yin yóò lè wí fún igi sikamine yìí pé, ‘Di fi fà á tu, kí a sì gbìn ọ́ sínú Òkun,’ yóò sì gbọ́ tiyín.
7 “Nĩ mũndũ ũrĩkũ wanyu ũngĩkorwo arĩ na ndungata ya kũmũrĩmĩra na mũraũ kana ya kũmũrĩithĩria ngʼondu, na ndungata ĩyo yoimĩra mũgũnda amĩĩre atĩrĩ, ‘Ũka ũikare thĩ ũrĩe?’
“Ṣùgbọ́n ta ni nínú yín, tí ó ní ọmọ ọ̀dọ̀, tí ó ń tulẹ̀, tàbí tí ó ń bọ́ ẹran, tí yóò wí fún un lójúkan náà tí ó bá ti oko dé pé, ‘Lọ í jókòó láti jẹun’?
8 Githĩ to amĩĩrire atĩrĩ, ‘Thondekera irio cia hwaĩ-inĩ, na wĩhaarĩrie ũnjikarie ngĩrĩa na ngĩnyua; na thuutha ũcio no ũrĩe na ũnyue’?
Tí kì yóò kúkú wí fún un pé, ‘Pèsè ohun tí èmi yóò jẹ, sì di àmùrè, kí ìwọ kí ó máa ṣe ìránṣẹ́ fún mi, títí èmi ó fi jẹ kí èmi ó sì mu tán; lẹ́yìn náà ni ìwọ ó sì jẹ, tí ìwọ ó sì mu’?
9 Ningĩ no agĩcookerie ndungata ĩyo ngaatho nĩ gwĩka ũrĩa ĩĩrĩtwo ĩĩke?
Òun ó ha máa dá ọpẹ́ lọ́wọ́ ọmọ ọ̀dọ̀ náà, nítorí ó ṣe ohun tí a pàṣẹ fún un bí? Èmi kò rò bẹ́ẹ̀.
10 Ũguo noguo o na inyuĩ, rĩrĩa mweka ũrĩa wothe mwĩrĩtwo mwĩke, ugagai atĩrĩ, ‘Tũrĩ o ndungata itarĩ kĩene; twaruta o wĩra witũ tu.’”
Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin pẹ̀lú, nígbà tí ẹ bá ti ṣe ohun gbogbo tí a pàṣẹ fún yín tán, ẹ wí pé, ‘Aláìlérè ọmọ ọ̀dọ̀ ni wá: èyí tí í ṣe iṣẹ́ wa láti ṣe, ní àwa ti ṣe.’”
11 Na rĩrĩ, Jesũ arĩ rũgendo-inĩ rwa gũthiĩ Jerusalemu nĩagereire mũhaka-inĩ wa Samaria na Galili.
Ó sì ṣe, bí ó ti ń lọ sí Jerusalẹmu, ó kọjá láàrín Samaria Galili.
12 Na rĩrĩa aatoonyaga gatũũra kamwe, agĩtũngwo nĩ andũ ikũmi maarĩ na mũrimũ wa mangũ. Makĩrũgama o haraaya,
Bí ó sì ti ń wọ inú ìletò kan lọ, àwọn ọkùnrin adẹ́tẹ̀ mẹ́wàá pàdé rẹ̀, wọ́n dúró ní òkèrè,
13 makĩanĩrĩra na mũgambo mũnene, makiuga atĩrĩ, “Jesũ, Mwathi witũ, tũiguĩre tha!”
wọ́n sì kígbe sókè wí pé, “Jesu, Olùkọ́, ṣàánú fún wa.”
14 Hĩndĩ ĩrĩa aamoonire, akĩmeera atĩrĩ, “Thiĩi mũkeyonanie kũrĩ athĩnjĩri-Ngai.” Na rĩrĩa maathiiaga-rĩ, magĩtherio.
Nígbà tí ó rí wọn, ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ í fi ara yín hàn fún àwọn àlùfáà.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, wọ́n sì di mímọ́.
15 Rĩrĩa ũmwe wao onire nĩahonio, akĩhũndũka akĩgooca Ngai na mũgambo mũnene,
Nígbà tí ọ̀kan nínú wọn rí i pé a mú òun láradá ó padà, ó sì fi ohùn rara yin Ọlọ́run lógo.
16 Akĩĩgũithia thĩ magũrũ-inĩ ma Jesũ, akĩmũcookeria ngaatho. Mũndũ ũcio aarĩ Mũsamaria.
Ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀, ó ń dúpẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀: ará Samaria ni òun í ṣe.
17 Jesũ akĩũria atĩrĩ, “Githĩ othe ikũmi matiatherio? Acio angĩ kenda marĩ ha?
Jesu sì dáhùn wí pé, “Àwọn mẹ́wàá kí a sọ di mímọ́? Àwọn mẹ́sàn-án ìyókù ha dà?
18 Gũtirĩ o na ũmwe ũngĩcooka kũhe Ngai ũgooci tiga o mũgeni ũyũ?”
A kò rí ẹnìkan tí ó padà wá fi ògo fún Ọlọ́run, bí kò ṣe àlejò yìí?”
19 Agĩcooka akĩmwĩra atĩrĩ, “Ũkĩra wĩthiĩre; gwĩtĩkia gwaku nĩkuo gwatũma ũhone.”
Ó sì wí fún un pé, “Dìde, kí o sì máa lọ, ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá.”
20 Na rĩrĩ, hĩndĩ ĩmwe Afarisai nĩmoririe Jesũ rĩrĩa ũthamaki wa Ngai ũgooka. Nake akĩmacookeria atĩrĩ, “Ũthamaki wa Ngai ndũũkaga na imenyithia iria mũngĩĩrorera,
Nígbà tí àwọn Farisi bi í pé, nígbà wo ni ìjọba Ọlọ́run yóò dé, ó dá wọn lóhùn pé, “Ìjọba Ọlọ́run kì í wá pẹ̀lú àmì.
21 kana andũ moige atĩrĩ, ‘Ũrĩ haha,’ kana ‘Ũrĩ harĩa,’ tondũ ũthamaki wa Ngai ũrĩ thĩinĩ wanyu.”
Bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò wí pé, ‘Kíyèsi i níhìn-ín!’ tàbí ‘Kíyèsi i lọ́hùn ún ni!’ sá à wò ó, ìjọba Ọlọ́run ń bẹ nínú yín.”
22 Agĩcooka akĩĩra arutwo ake atĩrĩ, “Ihinda nĩrĩroka rĩrĩa mũkeriragĩria kuona mũthenya ũmwe wa Mũrũ wa Mũndũ, no mũtikawona.
Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ọjọ́ ń bọ̀, nígbà tí ẹ̀yin yóò fẹ́ láti rí ọ̀kan nínú ọjọ́ Ọmọ Ènìyàn, ẹ̀yin kì yóò sì rí i.
23 Andũ nĩmakamwĩra atĩrĩ, ‘Arĩ harĩa!’ kana ‘Arĩ haha!’ Mũtikanatengʼere mũmarũmĩrĩre.
Wọ́n sì wí fún yín pé, ‘Wò ó níhìn-ín!’ tàbí ‘Wò ó lọ́hùn ún!’ Ẹ máa lọ, ẹ má ṣe tẹ̀lé wọn.
24 O ta ũrĩa rũheni rũhenũkaga rũkamũrĩka matu kuuma mũthia ũmwe nginya ũrĩa ũngĩ, no taguo gũũka kwa Mũrũ wa Mũndũ gũkahaana mũthenya ũcio wake.
Nítorí gẹ́gẹ́ bí mọ̀nàmọ́ná ti í kọ ní apá kan lábẹ́ ọ̀run, tí sì í mọ́lẹ̀ ní apá kejì lábẹ́ ọ̀run, bẹ́ẹ̀ ni Ọmọ Ènìyàn yóò sì rí ní ọjọ́ rẹ̀.
25 No rĩrĩ, no nginya ambe one mathĩĩna maingĩ na aregwo nĩ andũ a rũciaro rũrũ.
Ṣùgbọ́n kò lè ṣàìmá kọ́ jìyà ohun púpọ̀, kí a sì kọ̀ ọ́ lọ́dọ̀ ìran yìí.
26 “O ta ũrĩa gwatariĩ matukũ-inĩ ma Nuhu, noguo gũkaahaana matukũ-inĩ ma Mũrũ wa Mũndũ.
“Bí ó ti rí ní ọjọ́ Noa, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí ní ọjọ́ Ọmọ Ènìyàn.
27 Andũ acio maakorirwo makĩrĩa, na makĩnyua, na makĩhikania, na makĩhikio, o nginya mũthenya ũrĩa Nuhu aatoonyire thabina. Hĩndĩ ĩyo kĩguũ kĩnene gĩgĩũka gĩkĩmaniina othe.
Wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n ń gbéyàwó, wọ́n sì ń fa ìyàwó fún ni, títí ó fi di ọjọ́ ti Noa wọ inú ọkọ̀ lọ, kíkún omi sì dé, ó sì run gbogbo wọn.
28 “Ningĩ ũguo noguo gwatariĩ matukũ-inĩ ma Loti. Andũ acio maakorirwo makĩrĩa na makĩnyua, na makĩgũra na makĩendia, na makĩhaanda na magĩaka nyũmba.
“Bí ó sì ti rí ní ọjọ́ Lọti; wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n ń rà, wọ́n ń tà, wọ́n ń gbìn, wọ́n ń kọ́lé,
29 No mũthenya ũrĩa Loti oimire Sodomu, mwaki na ũbiriti ikiura ta mbura kuuma igũrũ, ikĩmaniina othe.
ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà tí Lọti jáde kúrò ní Sodomu, òjò iná àti sulfuru rọ̀ láti ọ̀run wá, ó sì run gbogbo wọn.
30 “Ũguo noguo gũkahaana mũthenya ũrĩa Mũrũ wa Mũndũ akaaguũranĩrio.
“Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni yóò rí ní ọjọ́ náà tí Ọmọ Ènìyàn yóò farahàn.
31 Mũthenya ũcio, mũndũ o wothe ũgaakorwo arĩ nyũmba igũrũ, na indo ciake irĩ nyũmba thĩinĩ, ndakanaharũrũke gũcigĩĩra. Ningĩ o na mũndũ ũrĩa ũgaakorwo arĩ mũgũnda ndakanahũndũke agĩĩre kĩndũ.
Ní ọjọ́ náà, ẹni tí ó bá wà lórí ilé, tí ẹrù rẹ̀ sì ń bẹ ní ilẹ̀, kí ó má ṣe sọ̀kalẹ̀ láti wá kó o; ẹni tí ó bá sì wà ní oko, kí ó má ṣe padà sẹ́yìn.
32 Ta ririkanai mũtumia wa Loti!
Ẹ rántí aya Lọti.
33 Mũndũ ũrĩa wothe ũgeragia gũtũũria muoyo wake nĩakoorwo nĩguo, nake ũrĩa wothe ũũragwo nĩ muoyo wake nĩakaũtũũria.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wá àti gba ẹ̀mí rẹ̀ là yóò sọ ọ́ nù; ẹnikẹ́ni tí ó bá sì sọ ọ́ nù yóò gbà á là.
34 Ngũmwĩra atĩrĩ, ũtukũ ũcio andũ eerĩ nĩmagakorwo makomete ũrĩrĩ ũmwe, nake ũmwe wao akuuo, na ũrĩa ũngĩ atigwo.
Mo wí fún yín, ní òru ọjọ́ náà, ènìyàn méjì yóò wà lórí àkéte kan; a ó mú ọ̀kan, a ó sì fi èkejì sílẹ̀.
35 Atumia eerĩ nĩmagakorwo magĩthĩa hamwe; ũmwe wao akuuo, na ũrĩa ũngĩ atigwo.
Ènìyàn méjì yóò sì máa lọ ọlọ pọ̀; a ó mú ọ̀kan, a ó sì fi èkejì sílẹ̀.”
36 (Ningĩ arũme eerĩ nĩmagakorwo makĩruta wĩra hamwe, ũmwe wao akuuo, ũrĩa ũngĩ atigwo.)”
37 Nao makĩmũũria atĩrĩ, “Kũu nĩ kũ Mwathani?” Nake akĩmacookeria atĩrĩ, “Nderi ciũnganaga harĩa hothe harĩ kĩimba.”
Wọ́n sì dá a lóhùn, wọ́n bi í pé, “Níbo, Olúwa?” Ó sì wí fún wọn pé, “Níbi tí òkú bá gbé wà, níbẹ̀ pẹ̀lú ni igún ìkójọpọ̀ sí.”

< Luka 17 >