< Alawii 3 >

1 “‘Iruta rĩa mũndũ rĩngĩkorwo nĩ iruta rĩa ũiguano-rĩ, nake arute nyamũ rũũru-inĩ rwa ngʼombe, ĩrĩ ya njamba kana ya nga, nĩakĩnengere Jehova nyamũ ĩtarĩ na kaũũgũ.
“‘Bí ọrẹ ẹnìkan bá jẹ́ ọrẹ àlàáfíà, tí ó sì mú ẹran wá láti inú agbo màlúù yálà akọ tàbí abo, kí ó mú èyí tí kò ní àbùkù wá síwájú Olúwa.
2 Mũndũ ũcio nĩaigĩrĩre guoko gwake igũrũ rĩa mũtwe wa nyamũ ĩyo ya iruta rĩake, na acooke amĩthĩnjĩre hau mũromo-inĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo. Nao ariũ a Harũni, athĩnjĩri-Ngai, nĩmakaminjaminjĩria kĩgongona thakame yayo mĩena yothe.
Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ. Nígbà náà ni àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà yóò wọ́n ẹ̀jẹ̀ ẹran náà yí pẹpẹ ká.
3 Kuuma iruta-inĩ rĩu rĩa ũiguano, nĩakarutĩra Jehova nyama imwe cia gũcinwo na mwaki: nacio nĩ rũambũ rũrĩa ruothe rũhumbĩire nyama cia nda na rũrĩa rũnyiitaine nacio,
Láti ara ọrẹ àlàáfíà ni kí ẹni náà ti mú ẹbọ tí a fi iná sun sí Olúwa, gbogbo ọ̀nà tí ó bo nǹkan inú ẹran náà àti gbogbo ọ̀rá tí ó so mọ́ wọn.
4 higo cierĩ hamwe na maguta marĩa macihumbĩire hakuhĩ na honge, na maguta marĩa mahumbĩire ini, amarutanĩrie na higo icio.
Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá ara rẹ̀ tí ń bẹ lẹ́bàá ìhà rẹ̀, àti gbogbo ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí ó yọ ọ́ jáde pẹ̀lú kíndìnrín.
5 Nao ariũ a Harũni macicinĩre kĩgongona-inĩ igũrũ, ciigĩrĩirwo igũrũ rĩa iruta rĩu rĩa njino rĩrĩa narĩo rĩigĩrĩirwo igũrũ rĩa ngũ irakana, rĩrĩ iruta rĩa gũcinwo na mwaki, rĩrĩ na mũtararĩko mwega wa gũkenia Jehova.
Nígbà náà ni àwọn ọmọ Aaroni yóò sun ún lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun tí a fi iná sun, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
6 “‘Mũndũ angĩkaaruta nyamũ rũũru-inĩ rwa mbũri, ĩrĩ ya kũrutĩra Jehova iruta rĩa ũiguano, nĩakaruta ndũrũme kana mwatĩ itarĩ na kaũũgũ.
“‘Bí ó bá ṣe inú agbo ewúrẹ́ àti àgùntàn ni ó ti mú ọrẹ àlàáfíà wá fún Olúwa kí ó mú akọ tàbí abo tí kò ní àbùkù.
7 Angĩkaaruta gatũrũme-rĩ, nĩagakaneana mbere ya Jehova.
Bí ó bá ṣe pé ọ̀dọ́-àgùntàn ni ó mú, kí ó mú un wá síwájú Olúwa.
8 Nĩakaigĩrĩra guoko gwake igũrũ rĩa mũtwe wa nyamũ ĩyo ya iruta rĩake, na acooke amĩthĩnjĩre mbere ya Hema-ya-Gũtũnganwo. Nao ariũ a Harũni moe thakame yako mamĩminjaminjĩrie kĩgongona kĩu mĩena yothe.
Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á níwájú àgọ́ ìpàdé, kí àwọn ọmọ Aaroni wọ́n ẹ̀jẹ̀ ẹran náà yí pẹpẹ ká.
9 Kuuma harĩ iruta rĩu rĩa ũiguano, nĩakarutĩra Jehova nyama imwe cia gũcinwo na mwaki: nacio nĩ maguta mako, na mũtingʼoe wothe ũrĩa mũnoru ũtinĩirio gĩtina-inĩ kĩa rũcuthĩ, na maguta ma rũambũ mothe marĩa mahumbĩire nyama cia nda, na marĩa manyiitaine nacio,
Kí o sì mú wá nínú ẹbọ àlàáfíà náà, fún ẹbọ tí a fi iná ṣe sí Olúwa; ọ̀rá rẹ̀ àti gbogbo ìrù rẹ̀ tí ó ní ọ̀rá, òun ni kí o mú kúrò súnmọ́ egungun ẹ̀yìn àti ọ̀rá tí ó bo ìfun lórí; àti gbogbo ọ̀rá tí ń bẹ lára ìfun.
10 higo cierĩ hamwe na maguta marĩa macihumbĩire hakuhĩ na honge, na marĩa mahumbĩire ini, amarutanĩrie na higo icio.
Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá tí ń bẹ lẹ́bàá ìhà rẹ̀ àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí o yọ ọ́ jáde pẹ̀lú kíndìnrín.
11 Nake mũthĩnjĩri-Ngai nĩagacicinĩra kĩgongona-inĩ irĩ irio, rĩĩrĩ nĩ iruta rĩrutĩirwo Jehova rĩa gũcinwo na mwaki.
Kí àlùfáà sun ún lórí pẹpẹ bí oúnjẹ ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa.
12 “‘Na angĩkorwo iruta rĩake nĩ mbũri, nĩamĩneane mbere ya Jehova.
“‘Bí ó bá ṣe pé ewúrẹ́ ni ó mú, kí ó mú un wá síwájú Olúwa.
13 Nĩaigĩrĩre guoko gwake igũrũ rĩa mũtwe wayo, na acooke amĩthĩnjĩre mbere ya Hema-ya-Gũtũnganwo. Nao ariũ a Harũni moe thakame yayo, mamĩminjaminjĩrie kĩgongona mĩena yothe.
Kí ó gbé ọwọ́ lé e lórí. Kí ó sì pa á ní iwájú àgọ́ ìpàdé. Nígbà náà ni àwọn ọmọ Aaroni yóò wọ́n ẹ̀jẹ̀ ẹran náà yí pẹpẹ ká.
14 Kuuma harĩ kĩrĩa akaaheana, nĩakarutĩra Jehova iruta rĩa gũcinwo na mwaki: na nĩ maguta mothe ma rũambũ marĩa mahumbĩrĩte nyama ciothe cia nda na marĩa manyiitaine nacio,
Lára ọrẹ tó mú wá, kí ó mú ẹbọ sísun fún Olúwa, gbogbo ọ̀rá tí ó bo nǹkan inú rẹ̀ àti ohun gbogbo tó so mọ́ ọn.
15 higo cierĩ na maguta marĩa macihumbĩire hakuhĩ na honge, na maguta marĩa mahumbĩire ini, amarutanĩrie na higo icio.
Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá ara rẹ̀ tí ń bẹ lẹ́bàá ìhà rẹ̀ àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí ó yọ ọ́ jáde pẹ̀lú kíndìnrín.
16 Nake mũthĩnjĩri-Ngai nĩagacicinĩra kĩgongona-inĩ irĩ irio, rĩĩrĩ nĩ iruta rĩa gũcinwo na mwaki, rĩrĩ na mũtararĩko mwega. Maguta mothe nĩ ma Jehova.
Kí àlùfáà sun ún lórí pẹpẹ bí oúnjẹ, ọrẹ tí a fi iná sun, ní òórùn dídùn. Gbogbo ọ̀rá rẹ̀ jẹ́ ti Olúwa.
17 “‘Ũndũ ũyũ ũgaatuĩka watho wa gũtũũra ũrũmagĩrĩrwo nĩ njiaro iria igooka, kũrĩa guothe mũgaatũũra: Mũtikanarĩe maguta kana thakame.’”
“‘Èyí jẹ́ ìlànà láéláé fún àwọn ìran tó ń bọ̀, ní gbogbo ibi tí ẹ bá ń gbé, ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ọ̀rá tàbí ẹ̀jẹ̀.’”

< Alawii 3 >