< Alawii 24 >

1 Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 “Atha andũ a Isiraeli makũrehere maguta marĩa makeere wega ma ndamaiyũ hihe ma gũkũheaga ũtheri, nĩgeetha matawa maikarage maakanĩte hĩndĩ ciothe.
“Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli láti mú òróró tí ó mọ́ tí a fún láti ara olifi wá láti fi tan iná, kí fìtílà lè máa jò láì kú.
3 Nja ya gĩtambaya gĩa gũcuurio kĩrĩa kĩrĩ mbere ya ithandũkũ rĩa Ũira o kũu Hema-inĩ-ya-Gũtũnganwo-rĩ, Harũni nĩamenyagĩrĩre matawa macio mbere ya Jehova kuuma hwaĩ-inĩ o nginya rũciinĩ, hĩndĩ ciothe. Ũndũ ũyũ ũgaatuĩka watho mwandĩke wa gũtũũra wa njiarwa iria igooka.
Lẹ́yìn aṣọ ìkélé ti ibi àpótí ẹ̀rí tí ó wà ní inú àgọ́ ìpàdé, ni kí Aaroni ti tan iná náà níwájú Olúwa, láti ìrọ̀lẹ́ di àárọ̀ lójoojúmọ́. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀.
4 Matawa macio marĩ mbere ya Jehova, o macio maigĩrĩirwo mũtĩ-inĩ wa matawa wa thahabu ĩrĩa therie no nginya mamenyagĩrĩrwo hĩndĩ ciothe.
Àwọn Àtùpà tí wọ́n wà lórí ojúlówó ọ̀pá fìtílà tí a fi wúrà ṣe níwájú Olúwa ni kí ó máa jó lójoojúmọ́.
5 “Oya mũtu ũrĩa mũhinyu mũno, ũthondeke mĩgate ikũmi na ĩĩrĩ, o mũgate ũmwe ũrugwo na tũcunjĩ twĩrĩ twa ikũmi twa eba ĩmwe.
“Mú ìyẹ̀fun dáradára, kí o sì ṣe ìṣù àkàrà méjìlá, kí o lo ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) fún ìṣù kọ̀ọ̀kan.
6 Ũcooke ũmĩare mĩhari ĩĩrĩ, o mũhari mĩgate ĩtandatũ, ũmĩigĩrĩre igũrũ rĩa metha ya thahabu therie hau mbere ya Jehova.
Tò wọ́n sí ọ̀nà ìlà méjì, mẹ́fà mẹ́fà ní ìlà kọ̀ọ̀kan lórí tábìlì tí a fi ojúlówó wúrà bọ̀. Èyí tí ó wà níwájú Olúwa.
7 Na o mũhari-inĩ nĩhaigwo ũbani ũrĩa mũtherie ũtuĩke gĩcunjĩ gĩa kĩririkano ũrũgamĩrĩire mĩgate ĩyo, na ũtuĩke iruta rĩa njino rĩrutĩirwo Jehova na mwaki.
Ẹ fi ojúlówó tùràrí sí ọnà kọ̀ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí ìpín ìrántí láti dípò àkàrà, àti láti jẹ ẹbọ sísun sí Olúwa.
8 Mĩgate ĩyo nĩ ĩigagwo mbere ya Jehova hĩndĩ ciothe, o Thabatũ o Thabatũ, ĩrũgamagĩrĩre andũ a Isiraeli, ĩtuĩke kĩrĩkanĩro gĩa gũtũũra.
Àkàrà yìí ni kí ẹ gbé wá síwájú Olúwa nígbàkígbà, lọ́ṣọ̀ọ̀ṣẹ̀, nítorí tí àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí májẹ̀mú ayérayé.
9 Mĩgate ĩyo nĩ ya Harũni na ariũ ake, nao mamĩrĩagĩre handũ hatheru, nĩ tondũ mĩgate ĩyo nĩ gĩcunjĩ gĩtheru mũno harĩ rwĩga rwao rwa maruta marĩa marutĩirwo Jehova ma gũcinwo na mwaki.”
Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ló ni í. Wọ́n gbọdọ̀ jẹ ẹ́ ní ibi mímọ́ torí pé ó jẹ́ ipa tí ó mọ́ jùlọ ti ìpín wọn ojoojúmọ́ nínú ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa.”
10 Na rĩrĩ, mũrũ wa mũtumia Mũisiraeli, no ithe aarĩ Mũmisiri, nĩathiire gũceerera andũ a Isiraeli, nake mũndũ ũcio na Mũisiraeli makĩrũa marĩ kũu kambĩ.
Ọmọkùnrin kan wà tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọ Israẹli baba rẹ̀ sì jẹ́ ará Ejibiti. Ó jáde lọ láàrín àwọn ọmọ Israẹli, ìjà sì ṣẹlẹ̀ nínú àgọ́ láàrín òun àti ọmọ Israẹli kan.
11 Ũcio mũrũ wa mũtumia Mũisiraeli nĩarumire Rĩĩtwa rĩa Ngai na kĩrumi; nĩ ũndũ ũcio makĩmũtwarĩra Musa. (Nyina wa mũndũ ũcio eetagwo Shelomithu, mwarĩ wa Dibiri ũrĩa Mũdani.)
Ọmọkùnrin arábìnrin Israẹli náà sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa pẹ̀lú èpè, wọ́n sì mú un tọ Mose wá. (Orúkọ ìyá rẹ̀ ní Ṣelomiti, ọmọbìnrin Debiri, ti ẹ̀yà Dani.)
12 Makĩmũikia thĩinĩ, makĩmũrangĩra nginya rĩrĩa mangĩamenyire wega wendi wa Jehova.
Wọ́n fi í sínú túbú kí Olúwa to sọ ohun tí wọn yóò ṣe fún wọn.
13 Nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ:
Olúwa sì sọ fún Mose pé,
14 “Twara mũrumani ũcio nja ya kambĩ. Andũ arĩa othe maamũiguire akĩrumana mamũigĩrĩre moko mũtwe, nakĩo kĩũngano gĩothe kĩmũhũũre na mahiga nyuguto.
“Mú asọ̀rọ̀-òdì náà jáde wá sẹ́yìn àgọ́, kí gbogbo àwọn tí ó gbọ́ pé ó ṣépè gbé ọwọ́ wọn lórí ọkùnrin náà láti fihàn pé ó jẹ̀bi. Lẹ́yìn náà ni kí gbogbo àpéjọpọ̀, sọ ọ́ ní òkúta pa.
15 Ĩra andũ a Isiraeli atĩrĩ, ‘Mũndũ o na ũrĩkũ angĩkaaruma Ngai wake, no nginya agaacookererwo nĩ ũũru ũcio ekĩte:
Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Bí ẹnikẹ́ni bá ṣépè lé Ọlọ́run rẹ̀, yóò jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
16 Mũndũ o na ũrĩkũ ũkaaruma rĩĩtwa rĩa Jehova no nginya akooragwo. Kĩũngano gĩothe gĩa Isiraeli no nginya gĩkaamũhũũra na mahiga nyuguto. Aakorwo arĩ mũgeni kana arĩ mũndũ ũciarĩirwo bũrũri-inĩ wanyu, rĩrĩa akaaruma Rĩĩtwa rĩu rĩa Jehova, no nginya akooragwo.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa ni kí ẹ pa, kí gbogbo àpéjọpọ̀ sọ ọ́ ní òkúta pa, yálà àlejò ni tàbí ọmọ bíbí Israẹli, bí ó bá ti sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa, pípa ni kí ẹ pa á.
17 “‘Mũndũ o na ũrĩkũ angĩkooraga mũndũ ũngĩ, no nginya nake akooragwo.
“‘Ẹni tí ó bá gba ẹ̀mí ènìyàn pípa ni kí ẹ pa á.
18 Mũndũ o na ũrĩkũ angĩũraga nyamũ ya mũndũ ũrĩa ũngĩ, no nginya akaamĩrĩha, nyamũ ĩrĩhwo na nyamũ ĩngĩ.
Ẹni tí ó bá gba ẹ̀mí ẹran ọ̀sìn ẹlòmíràn, kí ó dá a padà—ẹ̀mí dípò ẹ̀mí.
19 Mũndũ o na ũrĩkũ angĩgatiihia ũrĩa ũngĩ, o ũrĩa ekanĩte no nginya nake ekwo o ũguo:
Bí ẹnìkan bá pa ẹnìkejì rẹ̀ lára, ohunkóhun tí ó ṣe ni kí ẹ ṣe sí i.
20 Mũndũ oina mũndũ ũrĩa ũngĩ ihĩndĩ, nake akoinwo ihĩndĩ, riitho rĩrĩhagio na riitho, igego rĩrĩhagio na igego. O ũrĩa mũndũ atiihĩtie mũndũ ũngĩ, o nake atiihio o ro ũguo.
Ẹ̀yà fún ẹ̀yà, ojú fún ojú, eyín fún eyín; bí òun ti ṣe àbùkù sí ara ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni kí a ṣe sí i.
21 Mũndũ ũrĩa ũkooraga nyamũ nĩakamĩrĩha, no ũrĩa ũkooraga mũndũ ũrĩa ũngĩ no nginya akooragwo.
Ẹni tí ó bá sì lu ẹran pa, kí ó sán an padà; ẹni tí ó bá sì lu ènìyàn pa, a ó pa á.
22 Mũrĩkoragwo na watho o ro ũmwe ũkoniĩ mũgeni na mũndũ ũrĩa ũciarĩirwo bũrũri wanyu. Niĩ nĩ niĩ Jehova Ngai wanyu.’”
Òfin kan náà ló wà fún àlejò àti fún ọmọ Israẹli. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
23 Nake Musa akĩarĩria andũ a Isiraeli, nao magĩtwara mũndũ ũcio warumĩte Ngai nja ya kambĩ, makĩmũhũũra na mahiga nyuguto. Nao andũ a Isiraeli magĩĩka o ta ũrĩa Jehova aathĩte Musa.
Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì mú asọ̀rọ̀-òdì náà lọ sí ẹ̀yìn àgọ́, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa. Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose.

< Alawii 24 >