< Alawii 22 >

1 Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 “Ĩra Harũni na ariũ ake matĩĩage maruta marĩa matheru marĩa andũ a Isiraeli maanyamũrĩire, nĩgeetha matikanathaahie rĩĩtwa rĩakwa itheru. Niĩ nĩ niĩ Jehova.
“Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ kí wọ́n fi ọ̀wọ̀ fún ọrẹ mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli yà sọ́tọ̀ fún mi, kí wọ́n má ba à ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́. Èmi ni Olúwa.
3 “Meere atĩrĩ, ‘Njiarwa iria igooka thuutha, mũndũ o na ũrĩkũ wa njiaro cianyu angĩgakorwo ethaahĩtie, nake akuhĩrĩrie maruta marĩa matheru marĩa andũ a Isiraeli maamũrĩire Jehova, mũndũ ũcio no nginya aingatwo, ehere mbere yakwa. Niĩ nĩ niĩ Jehova.
“Sọ fún wọn pé, ‘Fún àwọn ìran tí ń bọ̀. Bí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ yín tí kò mọ́ bá wá sí ibi ọrẹ mímọ́ tí àwọn ara Israẹli ti yà sọ́tọ̀ fún Olúwa, kí ẹ yọ ẹni náà kúrò nínú iṣẹ́ àlùfáà ní iwájú mi. Èmi ni Olúwa.
4 “‘Mũndũ wa njiaro cia Harũni angĩkorwo arĩ na mũrimũ wa ngoothi ũngĩgwatanio, kana mwĩrĩ wake ũkoira, ndakaarĩa indo iria theru irutĩtwo cia maruta, nginya agaathirwo nĩ thaahu. Ningĩ nĩakanyiitwo nĩ thaahu angĩkaahutia kĩndũ gĩthaahie nĩ kĩimba, kana ahutie mũndũ o wothe ũrĩa uumĩtwo nĩ hinya wa arũme,
“‘Bí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Aaroni bá ní ààrùn ara tí ń ran ni, tàbí ìtújáde nínú ara. Ó lè má jẹ ọrẹ mímọ́ náà títí di ìgbà tí a ó fi wẹ̀ ẹ́ mọ́. Òun tún lè di aláìmọ́ bí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí òkú nǹkan bá sọ di àìmọ́ tàbí bí ó bá farakan ẹnikẹ́ni tí ó ní ìtújáde.
5 o na kana angĩhutia kĩndũ o gĩothe kĩrĩa gĩtambaga thĩ kĩrĩa kĩngĩmũgwatia thaahu, kana ahutie mũndũ o na ũrĩkũ ũngĩtũma anyiitwo nĩ thaahu, o na thaahu ũcio ũngĩkorwo nĩ ũrĩkũ.
Tàbí bí ó bá fọwọ́ kan èyíkéyìí nínú ohun tí ń rákò, tí ó sọ ọ́ di aláìmọ́, tàbí ẹnikẹ́ni tí ó sọ ọ́ di àìmọ́, ohunkóhun yówù kí àìmọ́ náà jẹ́.
6 Mũndũ ũrĩa ũngĩhutia kĩndũ o na kĩrĩkũ ta kĩu nĩakanyiitwo nĩ thaahu o nginya hwaĩ-inĩ. Ndakanarĩe kĩndũ o na kĩrĩkũ kĩa maruta marĩa maamũre, no akorirwo ethambĩte mwĩrĩ na maaĩ.
Ẹni náà tí ó fọwọ́ kan irú nǹkan bẹ́ẹ̀ yóò di aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́. Kò gbọdọ̀ jẹ èyíkéyìí nínú ọrẹ mímọ́ àyàfi bí ó bá wẹ ara rẹ̀.
7 Riũa rĩathũa nĩagathirwo nĩ thaahu, na thuutha ũcio no arĩe maruta marĩa maamũre, tondũ nĩcio irio ciake.
Bí oòrùn bá wọ̀, ẹni náà di mímọ́, lẹ́yìn náà ni ó tó le jẹ ọrẹ mímọ́, torí pé wọ́n jẹ́ oúnjẹ rẹ̀.
8 Ndakanarĩe nyama cia nyamũ ĩkuĩte, kana nyama cia nyamũ ĩtambuurĩtwo nĩ nyamũ cia gĩthaka, nĩguo ndakae gũthaahio nĩcio. Niĩ nĩ niĩ Jehova.
Kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ó bá ti kú sílẹ̀, tàbí tí ẹranko fàya, kí ó sì tipa bẹ́ẹ̀ di aláìmọ́. Èmi ni Olúwa.
9 “‘Athĩnjĩri-Ngai nĩmarũmagie mawatho makwa nĩgeetha matikahĩtagie, nao makue nĩ ũndũ wa kwaga gũtĩĩa mawatho macio. Niĩ nĩ niĩ Jehova ũrĩa ũmatheragia.
“‘Kí àwọn àlùfáà pa ìlànà mi mọ́, kí wọn má ba à jẹ̀bi, kí wọn sì kú nítorí pé wọ́n ṣe ọrẹ wọ̀nyí pẹ̀lú fífojútẹ́ńbẹ́lú wọn. Èmi ni Olúwa tí ó sọ wọ́n di mímọ́.
10 “‘Gũtirĩ mũndũ o na ũrĩkũ ũtarĩ wa nyũmba ya mũthĩnjĩri-Ngai wagĩrĩirwo nĩ kũrĩa maruta marĩa matheru, o na mũgeni wa mũthĩnjĩri-Ngai, kana mũruti wa wĩra gwake o nao matigacirĩe.
“‘Kò sí ẹnikẹ́ni lẹ́yìn ìdílé àlùfáà tí ó le jẹ ọrẹ mímọ́ náà, bẹ́ẹ̀ ni, àlejò àlùfáà tàbí alágbàṣe rẹ̀ kò le jẹ ẹ́.
11 No mũthĩnjĩri-Ngai angĩgũra ngombo na mbeeca, kana ngombo ĩciarĩrwo gwake mũciĩ, ngombo ĩyo no ĩrĩe irio ciake.
Ṣùgbọ́n bí àlùfáà bá ra ẹrú, pẹ̀lú owó, tàbí tí a bí ẹrú kan nínú ìdílé rẹ̀, ẹrú náà lè jẹ oúnjẹ rẹ̀.
12 Mwarĩ wa mũthĩnjĩri-Ngai angĩhikio nĩ mũndũ ũtarĩ mũthĩnjĩri-Ngai, ndakanarĩe kĩndũ o na kĩmwe kĩa maruta macio matheru.
Bí ọmọbìnrin àlùfáà bá fẹ́ ẹni tí kì í ṣe àlùfáà, kò gbọdọ̀ jẹ nínú èyíkéyìí nínú ohun ọrẹ mímọ́.
13 No mwarĩ wa mũthĩnjĩri-Ngai angĩtuĩka mũtumia wa ndigwa, kana matigane na mũthuuriwe na ndarĩ ciana, nake acooke agaikare gwa ithe o ta rĩrĩa aarĩ mwĩthĩ, no arĩe irio icio nyamũre cia ithe. No mũndũ ũtetĩkĩrĩtio, ndakanarĩe kĩndũ o na kĩmwe gĩacio.
Ṣùgbọ́n bí ọmọbìnrin àlùfáà bá jẹ́ opó tàbí tí a ti kọ ọ́ sílẹ̀, ṣùgbọ́n tí kò lọ́mọ tí ó sì padà sínú ilé baba rẹ̀ láti máa gbé bẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀, ó le jẹ oúnjẹ baba rẹ̀. Bí ó ti wù kí ó rí, àlejò tí kò lẹ́tọ̀ọ́ kò gbọdọ̀ jẹ èyíkéyìí nínú oúnjẹ náà.
14 “‘Mũndũ o wothe angĩrĩa maruta matheru atekũmenya, no nginya acookerie mũthĩnjĩri-Ngai kĩndũ kĩu kĩamũre arĩĩte na ongerere gĩcunjĩ gĩa gatano gĩa thogora wakĩo.
“‘Bí ẹnikẹ́ni bá ṣèèṣì jẹ ọrẹ mímọ́ kan, ó gbọdọ̀ ṣe àtúnṣe lórí ẹbọ náà fún àlùfáà, kí ó sì fi ìdámárùn-ún ohun tí ọrẹ náà jẹ́ kún un.
15 Athĩnjĩri-Ngai matikanathaahie maruta marĩa matheru marĩa andũ a Isiraeli marutagĩra Jehova,
Àwọn àlùfáà kò gbọdọ̀ sọ ọrẹ mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli mú wá síwájú Olúwa di àìmọ́.
16 na ũndũ wa kũmetĩkĩria marĩe maruta macio matheru, na ũguo ũtũme mũcookererwo nĩ mahĩtia marĩa mũngĩrĩhio. Niĩ nĩ niĩ Jehova ũrĩa ũmatheragia.’”
Nípa fífi ààyè fún wọn láti jẹ ọrẹ mímọ́ náà, kí wọ́n sì tipa bẹ́ẹ̀ mú ẹ̀bi tí wọn yóò san nǹkan fún wá sórí wọn. Èmi ni Olúwa, tí ó sọ wọ́n di mímọ́.’”
17 Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
Olúwa sọ fún Mose pé,
18 “Arĩria Harũni na ariũ ake, na warĩrie andũ a Isiraeli othe, ũmeere atĩrĩ: ‘Mũndũ o na ũrĩkũ thĩinĩ wanyu, arĩ Mũisiraeli kana arĩ mũgeni ũtũũraga Isiraeli, angĩkaarutĩra Jehova kĩheo kĩa iruta rĩa njino nĩ ũndũ wa kũhingia mwĩhĩtwa, kana kĩrĩ kĩa iruta rĩa kwĩyendera,
“Sọ fún Aaroni, àwọn ọmọ rẹ̀ àti fún gbogbo Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Bí ẹnikẹ́ni nínú yín yálà ọmọ Israẹli ni tàbí àlejò tí ń gbé ní Israẹli bá mú ẹ̀bùn wá fún ọrẹ ẹbọ sísun sí Olúwa, yálà láti san ẹ̀jẹ́ tàbí ọrẹ àtinúwá.
19 no nginya akaaruta njamba ĩtarĩ na kaũũgũ kuuma kũrĩ ngʼombe, kana ngʼondu, kana mbũri, nĩgeetha kĩheo kĩu gĩĩtĩkĩrĩke handũ-inĩ hanyu.
Ẹ gbọdọ̀ mú akọ láìní àbùkù láti ara màlúù, àgùntàn tàbí ewúrẹ́, kí ó ba à lè jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
20 Mũtikanarehe kĩndũ o na kĩrĩkũ kĩrĩ na kaũũgũ, tondũ gĩtigeetĩkĩrĩka handũ-inĩ hanyu.
Ẹ má ṣe mú ohunkóhun tí ó ní àbùkù wá, torí pé kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
21 Rĩrĩa mũndũ arĩĩrutaga kĩndũ kiumĩte rũrũ-inĩ rwake rwa ngʼombe kana rwa mbũri, kĩrĩ kĩa iruta rĩa ũiguano rĩa kũrutĩrwo Jehova, nĩguo ahingie mwĩhĩtwa wa mwanya, kana kĩa iruta rĩa kwĩyendera, no nginya gĩkoragwo gĩtarĩ na kaũũgũ kana kameni nĩguo gĩĩtĩkĩrĩke.
Bí ẹnikẹ́ni bá mú ọrẹ àlàáfíà wá láti inú agbo màlúù tàbí ti àgùntàn, fún Olúwa láti san ẹ̀jẹ́ pàtàkì tàbí fún ọrẹ àtinúwá. Ó gbọdọ̀ jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà láìní àbùkù.
22 Mũtikanarutĩre Jehova nyamũ ndumumu kana ndihie, kana ĩrathua, kana kĩndũ o gĩothe kĩrĩ na mbatata, kana kĩrĩ na ironda iratogota kana iroira. Mũtikanaigĩrĩre o na ĩmwe ya icio kĩgongona-inĩ ĩtuĩke ya iruta rĩa gũcinwo na mwaki harĩ Jehova.
Ẹ má ṣe fi ẹranko tí ó fọ́jú, tí ó fi ara pa, tí ó yarọ, tí ó ní kókó, tí ó ní èkúkú, èépá àti egbò kíkẹ̀ rú ẹbọ sí Olúwa. Ẹ kò gbọdọ̀ gbé èyíkéyìí nínú wọn sórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bi ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa.
23 No rĩrĩ, no mũrute ndegwa, kana ngʼondu nyonju kana homu, ĩrĩ ya igongona rĩa kwĩyendera, no ĩyo ndĩngĩtĩkĩrwo ĩtuĩke ya kũhingia mwĩhĩtwa.
Ẹ le mú màlúù tàbí àgùntàn tí ó ní àbùkù tàbí tí ó yọ iké wá fún ọrẹ àtinúwá, ṣùgbọ́n kò jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún ọrẹ ẹ̀jẹ́.
24 Mũtikanarutĩre Jehova nyamũ ĩrĩa ĩtihĩtio nyee, kana ĩkamendereka, kana ndarũre, kana hakũre. Mũtikanarute magongona ta macio bũrũri-inĩ wanyu,
Ẹ má ṣe fi ẹranko tí kóró ẹpọ̀n rẹ̀ fọ́ tàbí tí a tẹ̀, tàbí tí a yà tàbí tí a là rú ẹbọ sí Olúwa. Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe èyí ní ilẹ̀ yín.
25 na mũtikanamũkĩre nyamũ ta icio kuuma kũrĩ mũndũ mũgeni atĩ nĩguo mũcirute ituĩke irio cia Ngai wanyu. Nyamũ ta icio itingĩtĩkĩrĩka handũ-inĩ hanyu, nĩ ũndũ nĩ nyonju, na irĩ na ũũgũ.’”
Ẹ kò gbọdọ̀ gba irú ẹranko bẹ́ẹ̀ lọ́wọ́ àlejò kankan láti fi rú ẹbọ gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ sí Ọlọ́run yín. A kò nígbà wọ́n fún yín nítorí pé wọ́n ní àbùkù, wọ́n sì díbàjẹ́.’”
26 Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
Olúwa sọ fún Mose pé,
27 “Rĩrĩa gacaũ, kana gatũrũme, kana koori gaaciarwo, karĩikaraga na nyina mĩthenya mũgwanja. Kuuma mũthenya wa kanana na thuutha ũcio, nĩgagetĩkĩrĩka gatuĩke iruta rĩa gũcinwo na mwaki harĩ Jehova.
“Nígbà tí màlúù bá bímọ, tí àgùntàn bímọ, tí ewúrẹ́ sì bímọ, ọmọ náà gbọdọ̀ wà pẹ̀lú ìyá rẹ̀ fún ọjọ́ méje. Láti ọjọ́ kẹjọ ni ó ti di ìtẹ́wọ́gbà fún ọrẹ àfinásun sí Olúwa.
28 Mũtikanathĩnje ngʼombe kana ngʼondu hamwe na mwana wayo mũthenya ũmwe.
Ẹ má ṣe pa màlúù àti ọmọ rẹ̀ tàbí àgùntàn àti ọmọ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà.
29 “Rĩrĩa mũkũruta igongona rĩa gũcookeria Jehova ngaatho, rĩrutagei na njĩra ya gũtũma rĩtĩkĩrĩke nĩ ũndũ wanyu.
“Nígbà tí ẹ bá rú ẹbọ ọpẹ́ sí Olúwa, ẹ rú u ní ọ̀nà tí yóò fi jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
30 No nginya rĩrĩĩo mũthenya o ro ũcio rĩarutwo; mũtikanatigie kĩndũ kĩarĩo gĩkinyie rũciinĩ. Niĩ nĩ niĩ Jehova.
Ẹ gbọdọ̀ jẹ ẹ́ ní ọjọ́ náà gan an, ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan kù di àárọ̀. Èmi ni Olúwa.
31 “Rũmagiai maathani makwa na mũmarũmagĩrĩre. Niĩ nĩ niĩ Jehova.
“Ẹ pa òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Èmi ni Olúwa.
32 Mũtikanathaahie rĩĩtwa rĩakwa itheru. No nginya andũ a Isiraeli mamenyage atĩ ndĩ mũtheru. Niĩ nĩ niĩ Jehova ũrĩa ũmũtheragia,
Ẹ má ṣe ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́. Àwọn ọmọ Israẹli gbọdọ̀ mọ̀ mí ní mímọ́. Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.
33 na ũrĩa wamũrutire bũrũri wa Misiri nduĩke Ngai wanyu. Niĩ nĩ niĩ Jehova.”
Tí ó sì mú yín jáde láti Ejibiti wá láti jẹ́ Ọlọ́run yín. Èmi ni Olúwa.”

< Alawii 22 >