< Atiirĩrĩri 15 >
1 Thuutha ũcio, ihinda-inĩ rĩa magetha ma ngano-rĩ, Samusoni akĩoya koori na agĩthiĩ gũceerera mũtumia wake. Akiuga atĩrĩ, “Ngũthiĩ ndoonye kanyũmba-inĩ ka mũtumia wakwa.” No ithe wa mũtumia ũcio akĩmũgiria atoonye kuo.
Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ní àkókò ìkórè alikama, Samsoni mú ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan láti bẹ ìyàwó rẹ̀ wò. Ó ní, “Èmi yóò wọ yàrá ìyàwó mi lọ.” Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ kò gbà á láààyè láti wọlé.
2 Ithe akĩmwĩra atĩrĩ, “Niĩ ndaarĩ na ma atĩ nĩwamũthũũrire biũ, ngĩkĩmũheana kũrĩ mũrataguo. Githĩ mwarĩ wa nyina ũrĩa mũnini ndakĩrĩ mũthaka kũrĩ we? Kĩmuoe ithenya rĩake.”
Baba ìyàwó dá a lóhùn pé, “Ó dá mi lójú pé o kórìíra rẹ̀, torí náà mo ti fi fún ọ̀rẹ́ rẹ, ṣe bí àbúrò rẹ̀ obìnrin kò ha lẹ́wà jùlọ? Fẹ́ ẹ dípò rẹ̀.”
3 Samusoni akĩmeera atĩrĩ, “Rĩu ndĩ na kĩhooto gĩa kwĩrĩhĩria harĩ Afilisti; ti-itherũ nĩngũmeka ũũru biũ.”
Samsoni dáhùn pé, “Ní àkókò yìí tí mo bá ṣe àwọn Filistini ní ibi èmi yóò jẹ́ aláìjẹ̀bi.”
4 Nĩ ũndũ ũcio akiumagara, akĩnyiita mbwe magana matatũ, agĩciohithania mĩtingʼoe igĩrĩ igĩrĩ. Agĩcooka akĩoherera gĩcinga harĩ o mĩtingʼoe ĩyo ĩĩrĩ ĩĩrĩ,
Samsoni sì jáde lọ, ó mú ọ̀ọ́dúnrún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ ó so ìrù wọn mọ́ ara wọn ní méjì méjì. Ó mú ètùfù iná, ó so ó mọ́ àwọn ìrù tí ó so pọ̀.
5 akĩgwatia icinga icio mwaki na akĩrekereria mbwe icio ngano-inĩ ya Afilisti ĩrĩa yarĩ mĩgũnda. Agĩcina itĩĩa cia ngano ĩrĩa yarũgamĩtio mũgũnda na ngano ĩrĩa ĩtaarĩ ngethe, na agĩcina mĩgũnda ya mĩthabibũ na ya mĩtamaiyũ.
Ó fi iná ran àwọn ètùfù tí ó so náà, ó sì jọ̀wọ́ wọn lọ́wọ́ lọ sínú àwọn oko ọkà àwọn Filistini. Ó jó àwọn pòpóòrò ọkà tí ó dúró àti àwọn tí a dì ní ìtí, ìtí, pẹ̀lú àwọn ọgbà àjàrà àti olifi.
6 Rĩrĩa Afilisti mooririe atĩrĩ, “Nũũ wĩkĩte ũũ?” Makĩĩrwo atĩrĩ, “Nĩ Samusoni, mũthoni-we wa mũndũ ũrĩa Mũtimina, tondũ mũtumia wake nĩaheirwo mũratawe.” Nĩ ũndũ ũcio Afilisti makĩambata na magĩcina mũtumia ũcio o na ithe nginya magĩkua.
Nígbà tí àwọn Filistini béèrè pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Wọ́n dá wọn lóhùn pé, “Samsoni ará Timna ni, nítorí a gba ìyàwó rẹ̀ fún ọ̀rẹ́ rẹ̀.” Nítorí náà àwọn Filistini lọ wọ́n sì sun obìnrin náà àti baba rẹ̀.
7 Nake Samusoni akĩmeera atĩrĩ, “Kuona atĩ nĩ ũguo mweka, ndikũmũtigithĩria nginya ndĩĩrĩhĩrie kũrĩ inyuĩ.”
Samsoni sọ fún un pé, “Nítorí pé ẹ̀yin ṣe èyí, èmi ó gbẹ̀san lára yín, lẹ́yìn náà èmi yóò sì dẹ́kun.”
8 Agĩkĩmatharĩkĩra na ũũru mũnene na akĩũraga aingĩ ao. Agĩcooka agĩikũrũka na agĩikara ngurunga-inĩ ya ihiga rĩa Etamu.
Ó kọlù wọ́n pẹ̀lú ìbínú àti agbára ńlá, ó sì pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú wọn. Lẹ́yìn náà ni ó lọ, ó sì dúró nínú ihò àpáta kan nínú àpáta Etamu.
9 Nao Afilisti makĩambata na makĩamba hema kũu Juda, makĩaragana gũkuhĩ na Lehi.
Àwọn ará Filistini sì dìde ogun sí Juda, wọ́n ti tan ara wọn ká sí agbègbè Lehi.
10 Nao andũ a Juda makĩũria atĩrĩ, “Mũũkĩte kũhũũrana na ithuĩ nĩkĩ?” Nao magĩcookia atĩrĩ, “Tũũkĩte kũnyiita Samusoni, tũmwĩke o ta ũrĩa aatwĩkire.”
Àwọn ọkùnrin Juda sì béèrè pé, “Èéṣe tí ẹ fi wá gbóguntì wá?” Ìdáhùn wọn ni pé, “A wá láti mú Samsoni ní ìgbèkùn, kí a ṣe sí i bí òun ti ṣe sí wa.”
11 Hĩndĩ ĩyo andũ ngiri ithatũ kuuma Juda magĩikũrũka nginya ngurunga-inĩ ya ihiga rĩa Etamu na makĩĩra Samusoni atĩrĩ, “Kaĩ wee ũtakũũranĩte atĩ Afilisti nĩo matwathaga? Nĩ atĩa ũtwĩkĩte?” Nake agĩcookia atĩrĩ, “Niĩ ndĩmekĩte o ta ũrĩa maanjĩkire.”
Nígbà náà ni ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin láti Juda sọ̀kalẹ̀ lọ sí ihò àpáta nínú àpáta Etamu, wọ́n sì sọ fún Samsoni pé, “Kò ti yé ọ pé àwọn Filistini ní ń ṣe alákòóso lórí wa? Kí ni o ṣe sí wa?” Òun sì dáhùn pé, “Ohun tí wọ́n ṣe sí mi ni èmi náà ṣe sí wọn.”
12 Nao makĩmwĩra atĩrĩ, “Tũũkĩte gũkuoha tũkũneane kũrĩ Afilisti.” Samusoni akiuga atĩrĩ, “Mwĩhĩtei atĩ ti inyuĩ mũkũnjũraga.”
Wọ́n wí pé, “Àwa wá láti dè ọ́, kí a sì fi ọ́ lé àwọn Filistini lọ́wọ́.” Samsoni wí pé, “Ẹ búra fún mi pé, ẹ̀yin kì yóò fúnra yín pa mí.”
13 Nao magĩcookia atĩrĩ, “Nĩtwetĩkĩra, ithuĩ no gũkuoha tũgũkuoha tũkũneane kũrĩ o. Ithuĩ tũtigũkũũraga.” Nĩ ũndũ ũcio makĩmuoha na mĩkanda ĩĩrĩ mĩerũ na makĩmwambatia kuuma rwaro-inĩ rũu rwa ihiga.
“Àwa gbà,” ni ìdáhùn wọn. “Àwa yóò kàn dè ọ́, àwa yóò sì fi ọ́ lé wọn lọ́wọ́, àwa kì yóò pa ọ́.” Wọ́n sì dé pẹ̀lú okùn tuntun méjì, wọ́n sì mú u jáde wá láti ihò àpáta náà.
14 Rĩrĩa aakuhĩrĩirie Lehi-rĩ, Afilisti acio magĩũka na kũrĩ we makĩanagĩrĩra. Roho wa Jehova agĩũka igũrũ rĩake na hinya mũno. Mĩkanda ĩrĩa oohetwo moko nayo ĩgĩtuĩkanga o ta ũguta mũhiũ, nayo mĩhĩndo ĩyo ĩkĩgũa kuuma moko-inĩ make.
Bí ó ti súnmọ́ Lehi, àwọn Filistini ń pariwo bí wọ́n ṣe ń tò bọ̀. Ẹ̀mí Olúwa bà lé e pẹ̀lú agbára. Àwọn okùn ọwọ́ rẹ̀ dàbí òwú tí ó jóná, ìdè ọwọ́ rẹ̀ já kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
15 Akĩona rũkambucu rwa ndigiri rũtaarĩ rũkũrũ, akĩrũhuria na akĩũraga andũ ngiri ĩmwe.
Nígbà tí ó rí egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tuntun kan, ó mú un, ó sì fi pa ẹgbẹ̀rún ọkùnrin.
16 Hĩndĩ ĩyo Samusoni akiuga atĩrĩ, “Njũragĩte andũ na rũkambucu rwa ndigiri hĩba na hĩba. Njũragĩte andũ ngiri ĩmwe na rũkambucu rwa ndigiri.”
Samsoni sì wí pé, “Pẹ̀lú egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, mo sọ wọ́n di òkìtì kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Pẹ̀lú egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, mo ti pa ẹgbẹ̀rún ọkùnrin.”
17 Rĩrĩa aarĩkirie kwaria-rĩ, agĩte rũkambucu rũu; naho handũ hau hagĩĩtwo Ramathu-Lehi.
Nígbà tí ó dákẹ́ ọ̀rọ̀ í sọ, ó ju egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ náà nù, wọ́n sì pe ibẹ̀ ní Ramati-Lehi (ìtumọ̀ rẹ̀ jẹ́ egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ pa).
18 Na tondũ aarĩ mũnyootu mũno, agĩkaĩra Jehova, akiuga atĩrĩ, “Nĩũheete ndungata yaku ũhootani mũnene ũũ. No nginya rĩu ngue nĩ nyoota ngwe moko-inĩ ma andũ arĩa mataruaga?”
Nítorí tí òǹgbẹ gbẹ ẹ́ gidigidi, ó ké pe Olúwa, wí pé, “Ìwọ ti fún ìránṣẹ́ ní ìṣẹ́gun tí ó tóbi yìí. Ṣé èmi yóò ha kú pẹ̀lú òǹgbẹ, kí èmi sì ṣubú sí ọwọ́ àwọn aláìkọlà ènìyàn?”
19 Hĩndĩ ĩyo Ngai agĩthikũria irima kũu Lehi, rĩkiuma maaĩ. Rĩrĩa Samusoni aanyuire, agĩcookererwo nĩ hinya na akĩarahũka. Nĩ ũndũ ũcio gĩthima kĩu gĩgĩtwo Eni-Hakore. Na kĩrĩ o ho kũu Lehi.
Nígbà náà ni Ọlọ́run la kòtò ìsun omi tí ó wà ní Lehi, omi sì tú jáde láti inú rẹ̀. Nígbà tí Samsoni mú mi tan, agbára rẹ̀ sì padà, ọkàn sì sọjí, fún ìdí èyí wọ́n pe ìsun omi náà ni. Ẹni Hakkore (orísun ẹni tí ó pe Ọlọ́run) èyí tí ó sì wà ní Lehi di òní.
20 Samusoni aatiirĩrĩire Isiraeli mĩaka mĩrongo ĩĩrĩ matukũ-inĩ ma Afilisti.
Samsoni ṣe ìdájọ́ Israẹli fún ogún ọdún ní àkókò àwọn ará Filistini.