< Atiirĩrĩri 11 >

1 Na rĩrĩ, Jefitha aarĩ Mũgileadi warĩ njamba yarĩ hinya. Nake ithe wa Jefitha eetagwo Gileadi, na nyina aarĩ mũmaraya.
Jefta ará Gileadi jẹ́ akọni jagunjagun. Gileadi ni baba rẹ̀; ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ jẹ́ panṣágà.
2 Mũtumia wa Gileadi o nake akĩmũciarĩra aanake, na rĩrĩa maagimarire makĩingata Jefitha. Nao makiuga atĩrĩ, “Wee ndũkagaya igai thĩinĩ wa nyũmba iitũ, tondũ ũrĩ wa mũtumia ũngĩ.”
Ìyàwó Gileadi sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un, nígbà tí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí dàgbà, wọ́n rán Jefta jáde kúrò nílé, wọ́n wí pé, “Ìwọ kì yóò ní ogún kankan ní ìdílé wa, nítorí pé ìwọ jẹ́ ọmọ obìnrin mìíràn.”
3 Nĩ ũndũ ũcio Jefitha akĩũrĩra ariũ a ithe, agĩthiĩ gũtũũra bũrũri wa Tobu, kũrĩa gĩkundi kĩa andũ matarĩ kĩene kĩamũrigiicĩirie na gĩkĩmũrũmĩrĩra.
Jefta sì sá kúrò lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì pàgọ́ sí ilẹ̀ Tobu, ó sì ń gbé níbẹ̀, níbẹ̀ ni àwọn ènìyàn kan ti ń tẹ òfin lójú parapọ̀ láti máa tẹ̀lé e kiri.
4 Thuutha wa ihinda inini, hĩndĩ ĩrĩa Aamoni maahaarĩirie mbaara na Isiraeli,
Ní àsìkò kan, nígbà tí àwọn ará Ammoni dìde ogun sí àwọn Israẹli,
5 athuuri a Gileadi magĩthiĩ kũgĩĩra Jefitha kuuma bũrũri wa Tobu.
Ó sì ṣe nígbà tí àwọn Ammoni bá Israẹli jagun, àwọn àgbàgbà Gileadi tọ Jefta lọ láti pè é wá láti ilẹ̀ Tobu.
6 Nao makĩmwĩra atĩrĩ, “Ũka, ũtuĩke mũnene witũ wa ita, nĩgeetha tũhũũrane na Aamoni.”
Wọ́n wí fún Jefta wí pé, “Wá kí o sì jẹ́ olórí ogun wa kí a lè kọjú ogun sí àwọn ará Ammoni.”
7 Jefitha akĩmeera atĩrĩ, “Githĩ mũtiathũũrire mũkĩnyingata kuuma nyũmba ya baba? Nĩ kĩĩ kĩratũma mũũke kũrĩ niĩ rĩu mũrĩ na thĩĩna?”
Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Ṣé kì í ṣe pé ẹ kórìíra mi tí ẹ sì lé mi kúrò ní ilé baba mi? Kí ló dé tí ẹ fi tọ̀ mí wá báyìí nígbà tí ẹ wà nínú wàhálà?”
8 Athuuri a Gileadi makĩmwĩra atĩrĩ, “O na kũrĩ ũguo, nĩtwagũcookerera; twarana na ithuĩ tũkahũũrane na Aamoni, na nĩũgũtuĩka mũnene witũ wa gwathaga andũ othe arĩa matũũraga Gileadi.”
Àwọn àgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Nítorí rẹ̀ ni àwa fi yípadà sí ọ báyìí: tẹ̀lé wa, kí a lè dojú ìjà kọ àwọn ará Ammoni, ìwọ yóò sì jẹ olórí wa àti gbogbo àwa tí ń gbé ní Gileadi.”
9 Jefitha akĩmooria atĩrĩ, “Mũngĩnjookia ngahũũrane na Aamoni nake Jehova amaneane kũrĩ niĩ-rĩ, ti-itherũ niĩ nĩngatuĩka mũnene wanyu?”
Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Bí ẹ̀yin bá mú mi padà láti bá àwọn ará Ammoni jà àti tí Olúwa bá fi wọ́n lé mi lọ́wọ́: ṣe èmi yóò jẹ́ olórí yín nítòótọ́?”
10 Athuuri acio a Gileadi makĩmũcookeria atĩrĩ, “Jehova nĩwe mũira witũ; nĩtũgwĩka o ta ũrĩa ũkuuga.”
Àwọn àgbàgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Àwa fi Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí: àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá wí.”
11 Nĩ ũndũ ũcio Jefitha agĩthiĩ hamwe na athuuri a Gileadi, na andũ acio makĩmũtua mũnene na mwathi wao. Nake agĩcookera ciugo ciake ciothe mbere ya Jehova o kũu Mizipa.
Jefta sì tẹ̀lé àwọn àgbàgbà Gileadi lọ, àwọn ènìyàn náà sì fi ṣe olórí àti ọ̀gágun wọn. Jefta sì tún sọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ níwájú Olúwa ní Mispa.
12 Ningĩ Jefitha agĩtũmana kũrĩ mũthamaki wa Aamoni na kĩũria gĩkĩ: “Nĩ ũhoro ũrĩkũ ũrĩ naguo na ithuĩ nĩgeetha ũtharĩkĩre bũrũri witũ?”
Jefta sì rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba àwọn ará Ammoni pé, “Kí ni ẹ̀sùn tí o ní sí wa láti fi kàn wá tí ìwọ fi dojú ìjà kọ ilẹ̀ wa?”
13 Mũthamaki wa Aamoni agĩcookeria andũ a Jefitha atĩrĩ, “Hĩndĩ ĩrĩa Isiraeli maambatire kuuma Misiri, nĩmooire bũrũri wakwa kuuma Arinoni nginya Jaboku, o na nginya Jorodani. Rĩu njookeriai bũrũri ũcio na thayũ.”
Ọba àwọn Ammoni dá àwọn oníṣẹ́ Jefta lóhùn pé, “Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli jáde ti Ejibiti wá. Wọ́n gba ilẹ̀ mi láti Arnoni dé Jabbok, àní dé Jordani, nítorí náà dá wọn padà lọ ní àlàáfíà àti ní pẹ̀lẹ́ kùtù.”
14 Nake Jefitha agĩtũma andũ rĩngĩ kũrĩ mũthamaki wa Aamoni,
Jefta sì tún ránṣẹ́ padà sí ọba àwọn ará Ammoni
15 akiuga atĩrĩ: “Ũũ nĩguo Jefitha oiga: Isiraeli ndooire bũrũri wa Moabi kana bũrũri wa Aamoni.
ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Jefta wí: àwọn ọmọ Israẹli kò gba ilẹ̀ Moabu tàbí ilẹ̀ àwọn ará Ammoni.
16 No rĩrĩa maambatire makiuma Misiri, Isiraeli maatuĩkanĩirie werũ-inĩ nginya Iria Itune, magĩkinya Kadeshi.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde kúrò ní Ejibiti àwọn ọmọ Israẹli la aginjù kọjá lọ sí ọ̀nà Òkun Pupa wọ́n sì lọ sí Kadeṣi.
17 Ningĩ Isiraeli agĩtũma andũ kũrĩ mũthamaki wa Edomu, makamwĩre atĩrĩ, ‘Twĩtĩkĩrie tũtuĩkanĩrie bũrũri-inĩ waku,’ no mũthamaki wa Edomu ndaigana gũthikĩrĩria. Ningĩ magĩtũmana kũrĩ mũthamaki wa Moabi, nake akĩrega. Nĩ ũndũ ũcio Isiraeli magĩikara kũu Kadeshi.
Nígbà náà Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba Edomu pé, ‘Gbà fún wa láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kọjá,’ ṣùgbọ́n ọba Edomu kò fetí sí wọn. Wọ́n tún ránṣẹ́ sí ọba Moabu bákan náà òun náà kọ̀. Nítorí náà Israẹli dúró sí Kadeṣi.
18 “Magĩcooka magĩtuĩkanĩria werũ-inĩ, magĩthiũrũrũka bũrũri wa Edomu na Moabi, makĩgerera mwena wa irathĩro wa bũrũri wa Moabi, na makĩamba hema ciao mũrĩmo ũũrĩa ũngĩ wa Arinoni. Nao matiatoonyire bũrũri wa Moabi, nĩgũkorwo Rũũĩ rwa Arinoni nĩruo rwarĩ mũhaka wakuo.
“Wọ́n rin aginjù kọjá, wọ́n pẹ́ àwọn ilẹ̀ Edomu àti ti Moabu sílẹ̀, nígbà tí wọ́n gba apá ìlà-oòrùn Moabu, wọ́n sì tẹ̀dó sí apá kejì Arnoni. Wọn kò wọ ilẹ̀ Moabu, nítorí pé ààlà rẹ̀ ni Arnoni wà.
19 “Ningĩ Isiraeli agĩtũma andũ kũrĩ Sihoni mũthamaki wa Aamori, ũrĩa waathanaga Heshiboni, makĩmwĩra atĩrĩ, ‘Twĩtĩkĩrie tũhĩtũkĩre bũrũri-inĩ waku tũthiĩ bũrũri witũ.’
“Nígbà náà ni Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ń ṣe àkóso ní Heṣboni, wọ́n sì wí fún un pé, ‘Jẹ́ kí a la ilẹ̀ rẹ kọjá lọ sí ibùgbé wa.’
20 Na rĩrĩ, Sihoni ndaigana kwĩhoka Isiraeli mahĩtũkĩre bũrũri wake. Akĩũngania ita rĩake rĩothe na akĩamba hema kũu Jahazu, na akĩhũũrana na Isiraeli.
Ṣùgbọ́n Sihoni kò gba Israẹli gbọ́ (kò fọkàn tán an) láti jẹ́ kí ó kọjá. Ó kó gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ jọ, ó sì tẹ̀dó sí Jahisa láti bá Israẹli jagun.
21 “Nake Jehova, Ngai wa Isiraeli, akĩneana Sihoni na andũ ake othe moko-inĩ ma Isiraeli, makĩmahoota. Isiraeli makĩĩyoera bũrũri wothe wa Aamori arĩa maatũũraga bũrũri ũcio,
“Olúwa Ọlọ́run Israẹli sì fi Sihoni àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lé Israẹli lọ́wọ́, wọ́n sì ṣẹ́gun wọn. Israẹli sì gba gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Amori tí wọ́n ń gbé ní agbègbè náà,
22 magĩtunyana guothe kuuma Arinoni nginya Jaboku, na kuuma werũ-inĩ nginya Jorodani.
wọ́n gbà gbogbo agbègbè àwọn ará Amori, láti Arnoni tí ó fi dé Jabbok, àti láti aginjù dé Jordani.
23 “Na rĩrĩ, kuona atĩ Jehova, Ngai wa Isiraeli nĩwe ũingatĩte Aamori akameheria mbere ya andũ ake Isiraeli-rĩ, wee ũkĩrĩ na kĩhooto kĩrĩkũ gĩa kũwĩgwatĩra?
“Wàyí o, nígbà tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti lé àwọn ará Amori kúrò níwájú àwọn ènìyàn rẹ̀; Israẹli, ẹ̀tọ́ wo ni ẹ ní láti gba ilẹ̀ náà?
24 Kaĩ ũtangĩoya kĩrĩa Kemoshu ngai yaku ĩkũheete? Ithuĩ na ithuĩ twĩgwatĩre kĩrĩa gĩothe Jehova Ngai witũ atũheete.
Ǹjẹ́ ìwọ kì yóò ha gba èyí tí Kemoṣi òrìṣà rẹ fi fún ọ? Bákan náà àwa yóò gba èyíkéyìí tí Olúwa Ọlọ́run wa fi fún wa.
25 Anga wee nĩũkĩrĩte Balaki mũrũ wa Ziporu, mũthamaki wa Moabi? Nĩ kũrĩ hĩndĩ arĩ ahaarana na Isiraeli kana akĩrũa nao?
Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu lọ? Ǹjẹ́ òun ha ṣe gbólóhùn asọ̀ pẹ̀lú Israẹli bí? Tàbí òun dojú ìjà kọ wọ́n rí bí?
26 Handũ ha mĩaka magana matatũ Isiraeli matũũrĩte kũu Heshiboni, na Aroeri, na matũũra marĩa mothe magũthiũrũrũkĩirie, na matũũra mothe marĩa marĩ hũgũrũrũ-inĩ cia Arinoni. Nĩ kĩĩ kĩagiririe ũmeyoere rĩngĩ hĩndĩ ĩyo?
Fún ọ̀ọ́dúnrún ọdún ni Israẹli fi ṣe àtìpó ní Heṣboni, Aroeri àti àwọn ìgbèríko àti àwọn ìlú tí ó yí Arnoni ká. Èéṣe tí ìwọ kò fi gbà wọ́n padà ní àsìkò náà?
27 Niĩ ndikũhĩtĩirie, no wee nĩũranjĩka ũũru nĩ ũndũ wa kũndehera mbaara. Reke Jehova, ũrĩa mũtuithania, atuithanie ciira ũyũ ũmũthĩ gatagatĩ ka andũ a Isiraeli na Aamoni.”
Èmi kọ́ ni ó ṣẹ̀ ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ ni ó ṣẹ̀ mí nípa kíkógun tọ̀ mí wá. Jẹ́ kí Olúwa olùdájọ́, ṣe ìdájọ́ lónìí láàrín àwọn ọmọ Israẹli àti àwọn ará Ammoni.”
28 O na kũrĩ ũguo, mũthamaki wa Amoni ndaigana kũrũmbũiya ndũmĩrĩri ĩyo aatũmĩirwo nĩ Jefitha.
Ṣùgbọ́n ọba àwọn Ammoni kò fetí sí iṣẹ́ tí Jefta rán sí i.
29 Hĩndĩ ĩyo Roho wa Jehova agĩũka igũrũ rĩa Jefitha. Akĩringa Gileadi na Manase, akĩhĩtũkĩra Mizipa ya Gileadi, na kuuma kũu agĩthiĩ gũkora Aamoni.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jefta òun sì la Gileadi àti Manase kọjá. Ó la Mispa àti Gileadi kọjá láti ibẹ̀, ó tẹ̀síwájú láti bá àwọn ará Ammoni jà.
30 Nake Jefitha akĩĩhĩta mwĩhĩtwa mbere ya Jehova, akiuga atĩrĩ, “Ũngĩneana Aamoni moko-nĩ makwa-rĩ,
Jefta sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí ìwọ bá fi àwọn ará Ammoni lé mi lọ́wọ́,
31 o kĩrĩa gĩkoima nja na mũrango wa nyũmba yakwa kĩndũnge rĩrĩa ngaacooka hootanĩte kuuma kũrĩ Aamoni, gĩgaatuĩka kĩa Jehova, na nĩngakĩruta gĩtuĩke igongona rĩa njino.”
yóò sì ṣe, ohunkóhun tí ó bá jáde láti ẹnu-ọ̀nà ilé mi láti wá pàdé mi, nígbà tí èmi bá ń padà bọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ammoni ní àlàáfíà, yóò jẹ́ ti Olúwa, èmi yóò sì fi rú ẹbọ bí ọrẹ ẹbọ sísun.”
32 Nake Jefitha agĩthiĩ kũhũũrana na Aamoni, nake Jehova akĩmaneana moko-inĩ make.
Jefta sì jáde lọ láti bá àwọn ará Ammoni jagun, Olúwa sì fi wọ́n lé e lọ́wọ́.
33 Agĩthũkangia matũũra mĩrongo ĩĩrĩ kuuma Aroeri nginya gũkuhĩ na Minithu, o nginya Abeli-Karamimu. Ũguo nĩguo Isiraeli maatooririe Aamoni.
Òun sì ṣẹ́gun wọn, ó sì pa wọ́n ní à pa tán láti Aroeri títí dé agbègbè Minniti, ó jẹ́ ogún ìlú, títí dé Abeli-Keramimu. Báyìí ni Israẹli ti ṣẹ́gun àwọn ará Ammoni.
34 Hĩndĩ ĩrĩa Jefitha aacookire gwake mũciĩ kũu Mizipa-rĩ, nũũ wagĩũkire kũmũtũnga tiga mwarĩ, akĩmũinagĩra na akĩhũũraga tũhembe! Nake aarĩ mwana wa mũmwe. Tiga o we wiki, Jefitha ndaarĩ na kahĩĩ kana kairĩtu.
Nígbà tí Jefta padà sí ilé rẹ̀ ní Mispa, wò ó, ọmọ rẹ̀ obìnrin ń jáde bọ̀ wá pàdé rẹ̀ pẹ̀lú timbrili àti ijó. Òun ni ọmọ kan ṣoṣo tí ó ní: kò ní ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn yàtọ̀ sí òun nìkan.
35 Rĩrĩa aamuonire-rĩ, agĩtembũranga nguo ciake agĩkaya, akiuga atĩrĩ, “Ũũi! Mwarĩ wakwa! Nĩwandua mũndũ mũthĩĩnĩku na mũnyamarĩku nĩ ũndũ nĩndĩhĩtĩte mwĩhĩtwa harĩ Jehova ũrĩa itangĩaga kũhingia.”
Ní ìgbà tí ó rí i ó fa aṣọ rẹ̀ ya ní ìbànújẹ́, ó sì ké wí pé, “Háà! Ọ̀dọ́mọbìnrin mi, ìwọ fún mi ní ìbànújẹ́ ọkàn ìwọ sì rẹ̀ mí sílẹ̀ gidigidi, nítorí pé èmi ti ya ẹnu mi sí Olúwa ní ẹ̀jẹ́, èmi kò sì le sẹ́ ẹ̀jẹ́ mi.”
36 Nake akĩmũcookeria atĩrĩ, “Baba, wee nĩweehĩtire mwĩhĩtwa kũrĩ Jehova. Njĩka o ta ũrĩa weranĩire, kuona atĩ Jehova nĩakũrĩhĩria harĩ Aamoni thũ ciaku.”
Ọmọ náà sì dáhùn pé, “Baba mi bí ìwọ bá ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa, ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ, ní báyìí tí Olúwa ti gba ẹ̀san fún ọ lára àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ará Ammoni.
37 Ningĩ akiuga atĩrĩ, “No nĩngũkũũria ũnjĩtĩkĩrie ũndũ ũyũ ũmwe: Ũũhe mĩeri ĩĩrĩ ngacangacange irĩma-inĩ na ndĩre hamwe na arata akwa, tondũ ndikaahika.”
Ṣùgbọ́n yọ̀ǹda ìbéèrè kan yìí fún mi, gbà mí láààyè oṣù méjì láti rìn ká orí àwọn òkè, kí n sọkún pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ mi torí mo jẹ́ wúńdíá tí n kò sì ní lè ṣe ìgbéyàwó.”
38 Akĩmwĩra atĩrĩ, “No ũthiĩ.” Akĩmwĩtĩkĩria athiĩ mĩeri ĩĩrĩ. We marĩ na airĩtu acio angĩ magĩthiĩ irĩma-inĩ, makĩrĩranĩra tondũ ndarĩ hĩndĩ angĩkaahika.
Jefta dá lóhùn pé, “Ìwọ lè lọ.” Ó sì gbà á láààyè láti lọ fún oṣù méjì. Òun àti àwọn ọmọbìnrin yòókù lọ sí orí àwọn òkè, wọ́n sọkún nítorí pé kì yóò lè ṣe ìgbéyàwó.
39 Thuutha wa mĩeri ĩyo ĩĩrĩ, agĩcooka kũrĩ ithe, nake akĩmwĩka o ta ũrĩa eehĩtĩte. Nake aarĩ mũirĩtu gathirange. Kuumanagia na ũndũ ũcio, ũgĩtuĩka mũtugo wa andũ a Isiraeli,
Lẹ́yìn oṣù méjì náà, ó padà tọ baba rẹ̀ wá òun sì ṣe sí i bí ẹ̀jẹ́ tí ó ti jẹ́. Ọmọ náà sì jẹ́ wúńdíá tí kò mọ ọkùnrin rí. Èyí sì bẹ̀rẹ̀ àṣà kan ní Israẹli
40 atĩ o mwaka airĩtu a Isiraeli mathiiage nja mĩthenya ĩna kũririkana mwarĩ wa Jefitha ũcio Mũgileadi.
wí pé ní ọjọ́ mẹ́rin láàrín ọdún àwọn obìnrin Israẹli a máa lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti ṣe ìrántí ọmọbìnrin Jefta ti Gileadi.

< Atiirĩrĩri 11 >