< Joshua 7 >

1 No rĩrĩ, andũ a Isiraeli nĩmagire kwĩhokeka ũhoro-inĩ ũkoniĩ indo iria ciamũrĩtwo cia kũniinwo; nake Akani mũrũ wa Karimi, mũrũ wa Zimuri, mũrũ wa Zera, wa mũhĩrĩga wa Juda, nĩoire imwe ciacio. Nĩ ũndũ ũcio Jehova agĩcinwo nĩ marakara nĩ ũndũ wa Isiraeli.
Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, Akani ọmọ Karmi, ọmọ Sabdi, ọmọ Sera, ẹ̀yà Juda, mú nínú wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ìbínú Olúwa ru sí àwọn ará Israẹli.
2 Ningĩ Joshua agĩtũma andũ kuuma Jeriko mathiĩ Ai, itũũra rĩakuhanĩrĩirie na Bethi-Aveni mwena wa irathĩro wa Betheli, akĩmeera atĩrĩ, “Ambatai mũthiĩ mũgathigaane bũrũri ũcio.” Nĩ ũndũ ũcio andũ acio magĩthiĩ na magĩthigaana Ai.
Joṣua rán àwọn ọkùnrin láti Jeriko lọ sí Ai, tí ó súnmọ́ Beti-Afeni ní ìlà-oòrùn Beteli, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ gòkè lọ kí ẹ sì ṣe ayọ́lẹ̀wò.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn arákùnrin náà lọ, wọ́n sì yọ́ Ai wò.
3 Nao magĩcooka kũrĩ Joshua na makĩmwĩra atĩrĩ, “Hatirĩ bata wa andũ othe mambate makahũũre itũũra rĩa Ai. Rekia andũ 2,000 kana ithatũ makarĩtunyane; tiga kũnogia andũ othe, nĩgũkorwo no andũ anini marĩ kuo.”
Nígbà tí wọ́n padà sí ọ̀dọ̀ Joṣua, wọ́n wí pé, “Kì í ṣe gbogbo àwọn ènìyàn ni ó ni láti gòkè lọ bá Ai jà. Rán ẹgbẹ̀rún méjì tàbí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin láti gbà á, kí ó má ṣe dá gbogbo àwọn ènìyàn ní agara, nítorí ìba ọkùnrin díẹ̀ ní ó wà níbẹ̀.”
4 Nĩ ũndũ ũcio no andũ ta 3,000 maambatire, no magĩtoorio nĩ andũ a Ai,
Bẹ́ẹ̀ ní àwọn bí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin lọ; ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Ai lé wọn sá.
5 nao andũ acio a Ai makĩũraga ta andũ mĩrongo ĩtatũ na atandatũ a Isiraeli. Nĩmaingatire andũ a Isiraeli kuuma kĩhingo-inĩ gĩa itũũra rĩu makĩmakinyia o kũrĩa kwenjagwo mahiga, na makĩmahũũrĩra kũu igaragaro-inĩ. Ihũũra rĩu rĩgĩtũma ngoro cia andũ a Isiraeli iringĩke, na makĩiyũrwo nĩ maaĩ nda.
Àwọn ènìyàn Ai sì pa àwọn bí mẹ́rìndínlógójì nínú wọn. Wọ́n sì ń lépa àwọn ará Israẹli láti ibodè ìlú títí dé Ṣebarimu, wọ́n sì pa àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀. Àyà àwọn ènìyàn náà sì já, ọkàn wọn sì pami.
6 Nake Joshua agĩtembũranga nguo ciake, akĩĩgũithia thĩ, agĩturumithia ũthiũ wake thĩ mbere ya ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova, agĩikara hau nginya hwaĩ-inĩ. Nao athuuri a Isiraeli magĩĩka o ta ũguo na makĩĩhurĩria rũkũngũ mĩtwe.
Joṣua sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì dojúbolẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa títí di àṣálẹ́. Àwọn àgbà Israẹli sì ṣe bákan náà, wọ́n ku eruku sí orí wọn.
7 Nake Joshua akiuga atĩrĩ, “Hĩ, Mwathani Jehova, nĩ kĩĩ gĩatũmire ũrehe andũ aya mũrĩmo ũyũ wa Rũũĩ rwa Jorodani nĩguo ũtũneane moko-inĩ ma Aamori, matũniine? Naarĩ korwo nĩtwaiganĩire tũtũũre mũrĩmo ũrĩa ũngĩ wa Rũũĩ rwa Jorodani!
Joṣua sì wí pé, “Háà, Olúwa Olódùmarè, nítorí kín ni ìwọ ṣe mú àwọn ènìyàn yìí kọjá Jordani, láti fi wọ́n lé àwọn ará Amori lọ́wọ́, láti pa wọn run? Àwa ìbá mọ̀ kí a dúró ní òdìkejì Jordani?
8 Wee Mwathani, ingĩkiuga atĩa, kuona atĩ Isiraeli nĩmatooretio nĩ thũ ciao?
Olúwa, kín ni èmi yóò sọ nísinsin yìí tí Israẹli sì ti sá níwájú ọ̀tá a rẹ̀?
9 Andũ a Kaanani na andũ arĩa angĩ a bũrũri ũyũ nĩmarĩigua ũhoro ũcio, nao matũthiũrũrũkĩrie, matũniine biũ, meherie rĩĩtwa riitũ gũkũ thĩ. Nawe ũgaagĩĩka atĩa nĩ ũndũ wa rĩĩtwa rĩu rĩaku inene?”
Àwọn Kenaani àti àwọn ènìyàn ìlú tí ó kù náà yóò gbọ́ èyí, wọn yóò sì yí wa ká, wọn yóò sì ké orúkọ wa kúrò ní ayé. Kí ni ìwọ ó ha ṣe fún orúkọ ńlá à rẹ?”
10 Nake Jehova akĩĩra Joshua atĩrĩ, “Ũkĩra! Ũkwĩgũithia ũturumithĩtie ũthiũ waku thĩ nĩkĩ?
Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Dìde! Kín ni ìwọ ń ṣe tí ó fi dojúbolẹ̀?
11 Isiraeli nĩmehĩtie; nĩmathũkĩtie kĩrĩkanĩro gĩakwa kĩrĩa ndamaathire marũmagĩrĩre. Nĩmoete indo imwe iria ciamũrĩtwo cia kũniinwo; nĩmaiyĩte, na makaheenania, o na magaciiganĩria hamwe na indo ciao o ene.
Israẹli ti ṣẹ̀, wọ́n sì ti ba májẹ̀mú mi jẹ́, èyí tí mo pàṣẹ fún wọn pé kí wọn pamọ́. Wọ́n ti mú nínú ohun ìyàsọ́tọ̀, wọ́n ti jí, wọ́n pa irọ́, wọ́n ti fi wọ́n sí ara ohun ìní wọn.
12 Kĩu nĩkĩo gĩtũmi kĩrĩa kĩgirĩtie andũ a Isiraeli meetirie thũ ciao; na nĩkĩo marorĩra thũ ciao tondũ nĩmatuĩkĩte a kũniinwo. Na niĩ ndigũcooka gũkorwo hamwe na inyuĩ o tiga mũniinire kĩndũ kĩu kĩamũrĩtwo gĩa kũniinwo kĩehere thĩinĩ wanyu.
Ìdí nì èyí tí àwọn ará Israẹli kò fi lè dúró níwájú àwọn ọ̀tá wọn; wọ́n yí ẹ̀yìn wọn padà, wọ́n sì sálọ níwájú ọ̀tá a wọn nítorí pé àwọn gan an ti di ẹni ìparun. Èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín mọ́, bí kò ṣe pé ẹ̀yin pa ohun ìyàsọ́tọ̀ run kúrò ní àárín yín.
13 “Ũkĩra, ũthiĩ ũtherie andũ acio. Thiĩ ũmeere atĩrĩ, ‘Mwĩtheriei mwĩhaarĩrie nĩ ũndũ wa rũciũ; nĩgũkorwo Jehova Ngai wa Isiraeli ekuuga atĩrĩ: Nĩ harĩ kĩndũ kĩamũre gĩa kũniinwo kĩrĩ thĩinĩ wanyu, inyuĩ Isiraeli. Mũtingĩhota gwĩtiiria thũ cianyu o nginya rĩrĩa mũgaakĩeheria kiume thĩinĩ wanyu.
“Lọ, ya àwọn ènìyàn náà sí mímọ́. Sọ fún wọn pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ fún ọ̀la, nítorí báyìí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, ohun ìyàsọ́tọ̀ kan ń bẹ ní àárín yín, Israẹli. Ẹ̀yin kì yóò lè dúró níwájú àwọn ọ̀tá a yín títí ẹ̀yin yóò fi mú kúrò.
14 “‘Tondũ ũcio rũciũ kĩroko mũkeyumĩria inyuĩ ene o mũhĩrĩga, o mũhĩrĩga. Na rĩrĩ, mũhĩrĩga ũrĩa Jehova agaathuura nĩũkeyumĩria o mbarĩ, o mbarĩ; nayo mbarĩ ĩrĩa Jehova agaathuura nĩĩkeyumĩria o nyũmba, o nyũmba; nayo nyũmba ĩrĩa Jehova agaathuura nĩĩkeyumĩria o mũndũ, o mũndũ.
“‘Ní òwúrọ̀, kí ẹ mú ará yín wá síwájú ní ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Ẹ̀yà tí Olúwa bá mú yóò wá sí iwájú ní agbo ilé kọ̀ọ̀kan, agbo ilé tí Olúwa bá mú yóò wá sí iwájú ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, ìdílé tí Olúwa bá sì mú yóò wá sí iwájú ní ẹni kọ̀ọ̀kan.
15 Mũndũ ũrĩa ũkũnyiitwo na indo icio ciamũrĩtwo cia kũniinwo nĩagacinwo na mwaki hamwe na indo ciake ciothe. Nĩgũkorwo nĩathũkĩtie kĩrĩkanĩro kĩa Jehova, na nĩekĩte ũndũ wa thoni thĩinĩ wa Isiraeli!’”
Ẹnikẹ́ni tí a bá ká mọ́ pẹ̀lú ohun ìyàsọ́tọ̀ náà, a ó fi iná pa á run, pẹ̀lú gbogbo ohun tí ó ní. Ó ti ba májẹ̀mú Olúwa jẹ́, ó sì ti ṣe nǹkan ìtìjú ní Israẹli!’”
16 Mũthenya ũyũ ũngĩ rũciinĩ tene, Joshua akĩĩra andũ a Isiraeli moimĩre o ta ũrĩa mĩhĩrĩga yao yatariĩ, naguo mũhĩrĩga wa Juda ũgĩthuurwo.
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Joṣua mú Israẹli wá síwájú ní ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, a sì mú ẹ̀yà Juda.
17 Mbarĩ cia Juda ikiumĩra, nake agĩthuura mbarĩ ya Azera. Agĩcooka akiumĩria mbarĩ cia Azera mbere kũringana na nyũmba ciao, nake Zabedi agĩthuurwo.
Àwọn agbo ilé e Juda wá sí iwájú, ó sì mú agbo ilé Sera. Ó sì mú agbo ilé Sera wá síwájú ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, a sì mú ìdílé Sabdi.
18 Nake Joshua akiumĩria nyũmba yake mũndũ o mũndũ, nake Akani mũrũ wa Karimi, mũrũ wa Zimuri, mũrũ wa Zera, wa mũhĩrĩga wa Juda, agĩthuurwo.
Joṣua sì mú ìdílé Simri wá síwájú ní ọkùnrin kọ̀ọ̀kan, a sì mú Akani ọmọ Karmi, ọmọ Sabdi, ọmọ Sera ti ẹ̀yà Juda.
19 Nake Joshua akĩĩra Akani atĩrĩ, “Mũrũ wakwa, gooca Jehova, o we Ngai wa Isiraeli, na ũmũkumie. Njĩĩra ũrĩa wĩkĩte na ndũkaahithe.”
Nígbà náà ní Joṣua sọ fún Akani pé, “Ọmọ mi fi ògo fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, kí o sì fi ìyìn fún un. Sọ fún mi ohun tí ìwọ ti ṣe, má ṣe fi pamọ́ fún mi.”
20 Nake Akani agĩcookia akĩĩra Joshua atĩrĩ, “Ti-itherũ nĩnjĩhĩirie Jehova Ngai wa Isiraeli. Na ũũ nĩguo njĩkĩte:
Akani sì dáhùn pé, “Òtítọ́ ni! Mo ti ṣẹ̀ sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli. Nǹkan tí mo ṣe nìyìí,
21 Rĩrĩa ndonire kabuti gathaka koimĩte Babuloni, na cekeri magana meerĩ cia betha, na gĩkama gĩa thahabu kĩa ũritũ wa cekeri mĩrongo ĩtano thĩinĩ wa indo iria twatahĩte, nĩndaciĩrirĩirie na ngĩcioya, na ithikĩtwo thĩ kũu hema-inĩ yakwa, nayo betha ĩrĩ rungu wacio.”
nígbà tí mo rí ẹ̀wù Babeli kan tí ó dára nínú ìkógun, àti igba ṣékélì fàdákà àti odindi wúrà olóṣùnwọ́n àádọ́ta ṣékélì, mo ṣe ojúkòkòrò wọn mo sì mú wọn. Mo fi wọ́n pamọ́ ní abẹ́ àgọ́ mi àti fàdákà ní abẹ́ rẹ̀.”
22 Nĩ ũndũ ũcio Joshua agĩtũma andũ, nao makĩhanyũka magĩthiĩ nginya hema-inĩ yake, na magĩkora indo icio ihithĩtwo thĩinĩ wa hema ĩyo, nayo betha ĩyo yaigĩtwo rungu rwacio.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ran àwọn òjíṣẹ́, wọ́n sì sáré wọ inú àgọ́ náà, ó sì wà níbẹ̀, a sì fi pamọ́ nínú àgọ́ ọ rẹ̀, àti fàdákà ní abẹ́ ẹ rẹ̀.
23 Nao andũ acio makĩruta indo icio kuuma hema-inĩ ĩyo, magĩcitwarĩra Joshua o hamwe na andũ a Isiraeli othe, nao magĩciaragania thĩ mbere ya Jehova.
Wọ́n sì mú àwọn nǹkan náà jáde láti inú àgọ́ rẹ̀, wọ́n mú wọn wá fún Joṣua àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì fi wọ́n lélẹ̀ níwájú Olúwa.
24 Nake Joshua, hamwe na Isiraeli othe, makĩnyiita Akani mũrũ wa Zera, na makĩoya betha ĩyo, na kabuti, na gĩkama gĩa thahabu, na ariũ ake na airĩtu ake, na ngʼombe ciake, na ndigiri na ngʼondu ciake, na makĩoya hema yake o na indo ciothe iria arĩ nacio, magĩcitwara Gĩtuamba kĩa Akori.
Nígbà náà ni Joṣua pẹ̀lú gbogbo Israẹli, mú Akani ọmọ Sera, fàdákà, ẹ̀wù àti wúrà tí a dà, àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, màlúù rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti àgùntàn àgọ́ rẹ̀ àti gbogbo ohun tí ó ni, wọ́n sì kó wọn lọ sí ibi àfonífojì Akori.
25 Nake Joshua akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte ũtũrehere thĩĩna ũyũ? Wee nawe ũmũthĩ nĩũkuonio thĩĩna nĩ Jehova.” Nao andũ a Isiraeli othe makĩmũhũũra na mahiga nyuguto, na maarĩkia kũhũũra acio angĩ na mahiga, makĩmacina.
Joṣua sì wí pé, “Èéṣe tí ìwọ mú wàhálà yìí wá sí orí wa? Olúwa yóò mú ìpọ́njú wá sí orí ìwọ náà lónìí.” Nígbà náà ni gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sọ àwọn tókù ní òkúta pa tán, wọ́n sì jó wọn níná.
26 Magĩcooka makĩhũmbĩra Akani na hĩba nene mũno ya mahiga, namo mahiga macio marĩ o ho nginya ũmũthĩ. Nake Jehova agĩthirwo nĩ marakara marĩa maamũcinĩte. Nĩ ũndũ ũcio handũ hau hagĩcooka gwĩtwo Gĩtuamba kĩa Akori o nginya ũmũthĩ.
Wọ́n sì kó òkìtì òkúta ńlá lé Akani lórí títí di òní yìí. Nígbà náà ní Olúwa sì yí ìbínú gbígbóná rẹ̀ padà. Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ ibẹ̀ ní àfonífojì Akori láti ìgbà náà.

< Joshua 7 >