< Joshua 23 >

1 Thuutha wa ihinda inene gũthira na Jehova agĩkorwo aheete andũ a Isiraeli ũhurũko kuuma kũrĩ thũ ciao ciothe iria ciamathiũrũrũkĩirie, na Joshua agĩkorwo aarĩ mũkũrũ mũno na akaingĩhia mĩaka-rĩ,
Lẹ́yìn ọjọ́ pípẹ́, nígbà tí Olúwa sì ti fún Israẹli ní ìsinmi kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn tí ó yí wọn ká, nígbà náà Joṣua sì ti di arúgbó.
2 agĩĩta andũ a Isiraeli othe, na athuuri ao, na atongoria, na atuithania a maciira, na anene, akĩmeera atĩrĩ: “Rĩu niĩ ndĩ mũkũrũ na ngaingĩhia mĩaka.
Ó sì pe gbogbo Israẹli jọ: àgbàgbà wọn, olórí wọn, adájọ́ àti àwọn ìjòyè, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti pọ̀ ní ọdún èmi ti di arúgbó.
3 Inyuĩ ene nĩmwĩoneire maũndũ marĩa mothe Jehova Ngai wanyu ekĩte ndũrĩrĩ ici ciothe Nĩ ũndũ wanyu, nĩgũkorwo nĩ Jehova Ngai wanyu wamũrũĩrĩire.
Ẹ̀yin tìkára yín sì ti rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀nyí nítorí yín, Olúwa Ọlọ́run yín ni ó jà fún yín.
4 Ririkanai ũrĩa ndamũgaĩire ndũrĩrĩ iria ciatigarĩte ituĩke igai rĩa mĩhĩrĩga yanyu, hamwe na mabũrũri ma ndũrĩrĩ iria niĩ mwene ndatooririe, kuuma Rũũĩ rwa Jorodani o nginya Iria rĩrĩa Inene rĩa mwena wa ithũĩro.
Ẹ rántí bí mo ṣe pín ogún ìní fún àwọn ẹ̀yà yín ní ilẹ̀ orílẹ̀-èdè gbogbo tí ó kù; àwọn orílẹ̀-èdè tí mo ti ṣẹ́gun ní àárín Jordani àti Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
5 Jehova Ngai wanyu we mwene nĩagaciingata imweherere. Nĩagacieheria mbere yanyu, na inyuĩ nĩmũkegwatĩra bũrũri wao ũtuĩke wanyu, o ta ũrĩa Jehova Ngai wanyu aamwĩrire.
Olúwa Ọlọ́run yín fúnra rẹ̀ yóò lé wọn jáde kúrò ní ọ̀nà yín, yóò sì tì wọ́n jáde ní iwájú yín, ẹ̀yin yóò sì gba ilẹ̀ ìní wọn, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún yín.
6 “Gĩai na hinya mũno; mũrũmie na mwathĩkagĩre watho wothe ũrĩa wandĩkĩtwo Ibuku-inĩ rĩa watho wa Musa, mũtekũgarũrũka na mwena wa ũrĩo kana wa ũmotho.
“Ẹ jẹ́ alágbára gidigidi, kí ẹ sì ṣọ́ra láti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun tí a kọ sí inú ìwé òfin Mose, láìyí padà sí ọ̀tún tàbí sí òsì.
7 Mũtikanagwatanĩre na ndũrĩrĩ ici itigaire thĩinĩ wanyu; mũtikanagwete marĩĩtwa ma ngai ciacio kana mwĩhĩte nacio. Mũtikanacitungatĩre kana mũciinamĩrĩre.
Ẹ má ṣe ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ṣẹ́kù láàrín yín; ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà wọn tàbí kí ẹ fi wọ́n búra. Ẹ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n tàbí ki ẹ tẹríba fún wọn.
8 No inyuĩ no nginya mũrũmie kwĩgwatania na Jehova Ngai wanyu, o ta ũrĩa mũkoretwo mũgĩĩka nginya ũmũthĩ.
Ṣùgbọ́n ẹ di Olúwa Ọlọ́run yín mú ṣinṣin gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ń ṣe tẹ́lẹ̀ títí di àkókò yìí.
9 “Jehova nĩamũingatĩire ndũrĩrĩ nene na irĩ hinya mũno ikamweherera; na nginya ũmũthĩ ũyũ gũtirĩ mũndũ o na ũmwe ũhotete kũmwĩtiiria.
“Olúwa ti lé àwọn orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára kúrò níwájú yín; títí di òní yìí kò sí ẹnìkan tí ó le dojúkọ yín.
10 Mũndũ ũmwe wanyu atooragia andũ ngiri, Nĩ ũndũ Jehova Ngai wanyu nĩwe ũmũrũagĩrĩra, o ta ũrĩa eeranĩire.
Ọ̀kan nínú yín lé ẹgbẹ̀rún ọ̀tá, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín jà fún yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí.
11 Nĩ ũndũ ũcio mwĩmenyererei mũno nĩguo mwendage Jehova Ngai wanyu.
Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ ṣọ́ra gidigidi láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín.
12 “No rĩrĩ, mũngĩgarũrũka na mũnyiitanagĩre na matigari ma ndũrĩrĩ ici itigaire thĩinĩ wanyu na mũhikanie nacio na mũgwatanĩre nacio,
“Ṣùgbọ́n bí ẹ bá yí padà, tí ẹ sì gba ìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú àwọn tó ṣẹ́kù lára àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù láàrín yín, tí ẹ sì ń fọmọ fún ara yín ní ìyàwó, tí ẹ sì bá wọn ní àjọṣepọ̀.
13 hĩndĩ ĩyo na inyuĩ mũmenye wega atĩ Jehova Ngai wanyu ndagacooka kũingata ndũrĩrĩ icio ciehere mbere yanyu. No rĩrĩ, igaatuĩka cia kũmũheenereria o na ituĩke ta mĩtego ya kũmũgwatia, na ituĩke iboko cia kũmũhũũra, na mĩigua ya kũmũtũra maitho, nginya mũthire bũrũri-inĩ ũyũ mwega, ũrĩa Jehova Ngai wanyu amũheete.
Nígbà náà ni ẹ ó mọ̀ dájú pé Olúwa Ọlọ́run yín kì yóò lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde mọ́ kúrò níwájú yín. Dípò èyí, wọn yóò jẹ́ ìkẹ́kùn àti tàkúté fún un yín, pàṣán ní ẹ̀yin yín àti ẹ̀gún ní ojú yín, títí ẹ ó fi ṣègbé kúrò ní ilẹ̀ dáradára yí, èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fi fún yín.
14 “Rĩu niĩ ngirie gwĩthiĩra na njĩra ĩrĩa andũ othe a thĩ mathiiaga. Nĩmũũĩ na ngoro cianyu ciothe, na maroho manyu atĩ gũtirĩ kĩĩranĩro o na kĩmwe kĩa maũndũ marĩa mothe mega Jehova Ngai wanyu aamwĩrĩire atahingĩtie. Irĩkanĩro ciothe nĩihingĩtio, na gũtirĩ o na kĩmwe gĩtahingĩte.
“Nísinsin yìí èmi ti fẹ́ máa lọ sí ibi tí àwọn àgbà ń rè. Ẹ mọ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti àyà yín pé, kò sí ohun kan tí ó kùnà nínú àwọn ìlérí rere gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín. Gbogbo ìlérí tó ti ṣe kò sí ọ̀kan tí ó kùnà.
15 No rĩrĩ, o ta ũrĩa ciĩranĩro ciothe njega iria Ngai eeranĩire ihingĩte-rĩ, ũguo noguo Jehova akaamũrehithĩria ũũru ũrĩa wothe oigĩte nĩakamũrehere, o nginya amũniine mwehere bũrũri-inĩ ũyũ mwega amũheete.
Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí ìlérí dáradára gbogbo ti Olúwa Ọlọ́run yín ti wá sí ìmúṣẹ, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò mú ibi gbogbo tí ó ti kìlọ̀ wá sí orí yín, títí yóò fi pa yín run kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.
16 Mũngĩthũkia kĩrĩkanĩro kĩa Jehova Ngai wanyu kĩrĩa aamwathire mũrũmagĩrĩre, na mũcooke gũtungatagĩra ngai ingĩ na mũgaciinamĩrĩra-rĩ, marakara ma Jehova nĩmakamũrĩrĩmbũkĩra, na inyuĩ nĩmũgakua narua mũthire bũrũri ũyũ mwega amũheete.”
Bí ẹ bá sẹ̀ sí májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín, èyí tí ó pàṣẹ fún un yín, tí ẹ bá sì lọ tí ẹ sì sin àwọn òrìṣà tí ẹ sì tẹ orí ba fún wọn, ìbínú gbígbóná Olúwa yóò wá sórí i yín, ẹ̀yin yóò sì ṣègbé kíákíá kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.”

< Joshua 23 >