< Joshua 2 >

1 Nake Joshua mũrũ wa Nuni agĩtũma athigaani eerĩ kuuma Shitimu na hitho; akĩmeera atĩrĩ, “Thiĩi mũbaare bũrũri ũcio, na makĩria Jeriko.” Nĩ ũndũ ũcio magĩthiĩ, magĩtoonya nyũmba ya mũmaraya wetagwo Rahabu, magĩikara kuo.
Nígbà náà ni Joṣua ọmọ Nuni rán àwọn ayọ́lẹ̀wò méjì jáde ní àṣírí láti Ṣittimu. Ó sì wí pé, “Ẹ lọ wo ilẹ̀ náà, pàápàá Jeriko.” Wọ́n sì lọ, wọ́n wọ ilé panṣágà kan, tí à ń pè ní Rahabu wọ́n sì dúró síbẹ̀.
2 Nake mũthamaki wa Jeriko akĩĩrwo atĩrĩ, “Nĩ kũrĩ andũ amwe a Isiraeli mokire gũkũ ũtukũ ũyũ gũthigaana bũrũri ũyũ ũrĩa ũhaana.”
A sì sọ fún ọba Jeriko, “Wò ó! Àwọn ará Israẹli kan wá ibí ní alẹ́ yìí láti wá yọ́ ilẹ̀ yí wò.”
3 Nĩ ũndũ ũcio mũthamaki wa Jeriko agĩtũmana kũrĩ Rahabu, akĩmwĩra atĩrĩ, “Andũ acio mokire gwaku nyũmba marutũrũre na nja, tondũ mokĩte gũthigaana bũrũri ũyũ wothe.”
Ọba Jeriko sì ránṣẹ́ sí Rahabu pé, “Mú àwọn ọkùnrin nì tí ó tọ̀ ọ́ wá, tí ó wọ inú ilé rẹ jáde wá, nítorí wọ́n wá láti yọ́ gbogbo ilẹ̀ yìí wò ni.”
4 No rĩrĩ, mũndũ-wa-nja ũcio nĩarĩkĩtie kuoya andũ acio eerĩ na akamahitha. Nake akiuga atĩrĩ, “Ĩĩ nĩguo, andũ acio nĩmegũkĩte gwakwa, no ndinamenya kũrĩa mekuumĩte.
Ṣùgbọ́n obìnrin náà ti mú àwọn ọkùnrin méjì náà o sì fi wọ́n pamọ́. Ó sì wí pé, “Lóòtítọ́ ní àwọn ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ibi tí wọ́n ti wá.
5 Hwaĩ-inĩ rĩrĩa kĩhingo gĩa itũũra inene kĩhingagwo-rĩ, andũ acio nĩmathiire. Ndinamenya na kũrĩa mathiire. Marũmĩrĩrei na ihenya. Mwahota kũmakinyĩra.”
Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, nígbà tí ó tó àkókò láti ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè, àwọn ọkùnrin náà sì jáde lọ. Èmi kò sì mọ ọ̀nà tí wọ́n gbà lọ. Ẹ lépa wọn kíákíá. Ẹ̀yin yóò bá wọn.”
6 (No rĩrĩ, nĩamatwarĩte nyũmba igũrũ, na akamahitha rungu rwa ũguta ũrĩa aarĩte kũu nyũmba igũrũ).
(Ṣùgbọ́n ó ti mú wọn gòkè àjà ó sì fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ pòròpòrò ọkà tó tò jọ sí orí àjà.)
7 Nĩ ũndũ ũcio andũ acio maatũmĩtwo nĩ mũthamaki makiumagara, makĩmarũmĩrĩra na njĩra ĩrĩa ĩthiiaga mariũko-inĩ ma Rũũĩ rwa Jorodani, na rĩrĩa andũ acio mamarũmĩrĩire moimire na nja o ũguo-rĩ, kĩhingo gĩkĩhingwo.
Àwọn ọkùnrin náà jáde lọ láti lépa àwọn ayọ́lẹ̀wò náà ní ọ̀nà tí ó lọ sí ìwọdò Jordani, bí àwọn tí ń lépa wọn sì ti jáde, wọ́n ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè.
8 Athigaani acio eerĩ matanakoma, mũndũ-wa-nja ũcio akĩambata kũu nyũmba igũrũ,
Kí àwọn ayọ́lẹ̀wò náà tó sùn ní alẹ́, ó gòkè tọ̀ wọ́n lọ lókè àjà.
9 na akĩmeera atĩrĩ, “Nĩnjũũĩ atĩ Jehova nĩamũheete bũrũri ũyũ, na atĩ nĩtũnyiitĩtwo nĩ guoya mũnene nĩ ũndũ wanyu, o nginya ithuothe andũ arĩa tũtũũraga bũrũri ũyũ tũkaiyũrwo nĩ maaĩ nda nĩ ũndũ wanyu.
Ó sì sọ fún wọn, “Èmi mọ̀ pé Olúwa ti fún un yín ní ilẹ̀ yìí àti pé ẹ̀rù u yín ti sọ wá di ojo dé ibi pé ìdí gbogbo àwọn tí ó n gbé ilẹ̀ yìí ti di omi nítorí i yín.
10 Nĩtũiguĩte ũrĩa Jehova aahũithirie maaĩ ma Iria Itune nĩ ũndũ wanyu rĩrĩa mwoimire bũrũri wa Misiri, na ũrĩa mwekire Sihoni na Ogu, athamaki arĩa eerĩ a Aamori o kũu mwena wa irathĩro wa Rũũĩ rwa Jorodani, arĩa mwaninire biũ.
Àwa ti gbọ́ bí Olúwa ti mú omi Òkun Pupa gbẹ níwájú u yín nígbà tí ẹ̀yin jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ohun tí ẹ̀yin ṣe sí Sihoni àti Ogu, àwọn ọba méjèèjì ti Amori ti ìlà-oòrùn Jordani, tí ẹ̀yin parun pátápátá.
11 Rĩrĩa twaiguire ũhoro ũcio, ngoro ciitũ nĩciaringĩkire na ũmĩrĩru wa mũndũ o mũndũ akĩũrwo nĩ hinya nĩ ũndũ wanyu, nĩgũkorwo Jehova Ngai wanyu nĩwe Ngai wa kũu igũrũ o na wa gũkũ thĩ.
Bí a ti gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ọkàn wa pami kò sì sí okun kankan fún wa mọ́ nítorí i yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni Ọlọ́run ní òkè ọ̀run àti ní ayé.
12 Na rĩrĩ, ndamũthaitha mwĩhĩte na mwĩhĩtwa mũkĩgwetaga rĩĩtwa rĩa Jehova atĩ nĩmũkaiguĩra andũ a nyũmba iitũ tha, na mũmĩĩke wega, tondũ o na niĩ nĩndamũiguĩra tha na ndamwĩka wega. Na mũnyonie ũndũ ũcio na kĩmenyithia kĩa ma
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ jọ̀wọ́ ẹ búra fún mi ní ti Olúwa pé ẹ̀yin yóò ṣe àánú fún ìdílé mi, nítorí pé mo ti ṣe yín ní oore. Ẹ̀yin yóò fún mi ní àmì tó dájú:
13 kĩa atĩ nĩmũkahonokia baba na maitũ, na ariũ a baba o na aarĩ a baba, na andũ ao othe ciana ciao ciothe, na atĩ nĩmũgatũhonokia kuuma harĩ gĩkuũ.”
pé ẹ̀yin yóò dá ẹ̀mí baba àti ìyá mi sí; arákùnrin mi àti arábìnrin mi, àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, àti pé ẹ̀yin yóò gbà wá là lọ́wọ́ ikú.”
14 Nao andũ acio makĩmũmĩrĩria, makĩmwĩra atĩrĩ, “Ithuĩ tũrokua tũngĩkaaga kũhonokia mĩoyo yanyu! Waga kuuga ũrĩa tũreeka, nĩtũkaamwĩka maũndũ ma ũtugi na ma kĩhooto rĩrĩa Jehova agaatũhe bũrũri ũyũ.”
“Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”
15 Nĩ ũndũ ũcio akĩmaikũrũkia na mũkanda, akĩmoimĩria ndirica tondũ nyũmba ĩrĩa aikaraga yaakĩtwo rũthingo-inĩ rwa itũũra rĩu inene.
Nígbà náà ní ó fi okùn sọ̀ wọ́n kalẹ̀ ní ojú u fèrèsé, nítorí ilé tí ó ń gbé wà ní ara odi ìlú.
16 Na rĩrĩ, nĩameerĩte atĩrĩ, “Thiĩi kũrĩa irĩma-inĩ nĩgeetha andũ acio mamũrũmĩrĩire matikamuone. Mwĩhithei kũu mĩthenya ĩtatũ o nginya makorwo macookete, mũcooke mwĩthiĩre.”
Ó sì ti sọ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí orí òkè, kí ẹ sì fi ara pamọ́ níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta kí àwọn tí ń lépa yín má ba à rí i yín títí tí wọn yóò fi darí. Lẹ́yìn náà kí ẹ máa bá ọ̀nà yín lọ.”
17 Nao andũ acio makĩĩra mũndũ-wa-nja ũcio atĩrĩ, “Mwĩhĩtwa ũyũ watwĩhĩtithia ndũgatũcookerera kana ũtwĩke ũũru,
Àwọn arákùnrin náà sì sọ fún un pé, “Kí ọrùn un wa ba à lè mọ́ kúrò nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú yìí.
18 o tiga wĩkire ũũ: rĩrĩa tũgaatoonya bũrũri ũyũ-rĩ, ũgaakorwo wohereire rũrigi rũrũ rũtune ndirica-inĩ o ĩno watũharũrũkĩria, nawe ũkorwo ũrehete thoguo na nyũkwa, na ariũ a thoguo, na andũ anyu othe gũkũ gwaku nyũmba.
Nígbà tí àwa bá wọ ilé è rẹ, ìwọ yóò so okùn aláwọ̀ aró yìí sí ojú fèrèsé èyí tí ìwọ fi sọ̀ wá kalẹ̀, kí ìwọ kí ó mú baba rẹ, ìyá rẹ, àwọn arákùnrin in rẹ àti gbogbo ìdílé è rẹ kí wọ́n wá sí inú ilé è rẹ.
19 Mũndũ o wothe ũkoima nja ya nyũmba yaku athiĩ na kũu barabara-inĩ-rĩ, thakame yake ĩkamũcookerera we mwene; no ithuĩ tũtigacookererwo nĩ ũũru nĩ ũndũ wake. No ũhoro wa mũndũ o wothe ũgaakorwo nyũmba hamwe nawe, thakame yake nĩĩgatũcookerera angĩgeekwo ũũru nĩ guoko kwa mũndũ o na ũrĩkũ.
Bí ẹnikẹ́ni bá jáde sí ìta láti inú ilé è rẹ sí inú ìgboro ìlú, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò sì wà ní orí ara rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí i rẹ̀. Fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wà nínú ilé pẹ̀lú rẹ, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí i wa bí ẹnikẹ́ni bá fi ọwọ́ kàn án.
20 No rĩrĩ ũngĩaria ũhoro ũyũ witũ twĩ naguo, tũtigacookererwo nĩ ũũru ũkoniĩ mwĩhĩtwa ũrĩa watwĩhĩtithia.”
Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò bọ́ nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú.”
21 Nake agĩcookia, akĩmeera atĩrĩ, “Nĩndetĩkĩra; nĩgũtuĩke o ta ũguo mwoiga.” Nĩ ũndũ ũcio agĩkĩmoigĩra ũhoro, nao magĩthiĩ. Na akĩoherera rũrigi rũu rũtune hau ndirica-inĩ.
Ó dáhùn pé, “Ó dára bẹ́ẹ̀. Ẹ jẹ́ kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí sọ.” Ó sì rán wọn lọ wọ́n sì lọ. Ó sì so okùn òdòdó náà sí ojú fèrèsé.
22 Maarĩkia kuumagara-rĩ, magĩthiĩ irĩma-inĩ na magĩikara kuo mĩthenya ĩtatũ, nginya rĩrĩa andũ arĩa maamarũmĩrĩire maahũndũkire. Andũ acio maamacarĩtie kũu njĩra-inĩ ĩyo yothe kũrĩa maathiĩrĩire, no matiigana kũmona.
Nígbà tí wọ́n kúrò, wọ́n sì lọ sí orí òkè wọ́n sì dúró ní ibẹ̀ ní ọjọ́ mẹ́ta, títí àwọn alépa fi wá wọn ní gbogbo ọ̀nà wọ́n sì padà láìrí wọn.
23 Thuutha wa ũguo Hĩndĩ ĩyo nao andũ acio eerĩ makĩambĩrĩria gũcooka. Magĩikũrũka moimĩte na irĩma-inĩ, makĩringa Rũũĩ rwa Jorodani, magĩkinya harĩ Joshua mũrũ wa Nuni, na makĩmũhe ũhoro wa maũndũ marĩa mothe maamakorete.
Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin méjì náà padà. Wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, wọ odò, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ọmọ Nuni wọ́n sì sọ fún un gbogbo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wọn.
24 Makĩĩra Joshua atĩrĩ, “Ti-itherũ Jehova nĩatũheete bũrũri ũcio wothe, akaũneana moko-inĩ maitũ; andũ othe a kũu nĩmaiyũrĩtwo nĩ guoya mũnene nĩ ũndũ witũ.”
Wọ́n sì sọ fún Joṣua, “Nítòótọ́ ni Olúwa tí fi gbogbo ilẹ̀ náà lé wa lọ́wọ́; gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà ni ìbẹ̀rùbojo ti mú nítorí i wa.”

< Joshua 2 >