< Johana 1 >

1 Kĩambĩrĩria-inĩ Ũhoro aarĩ o kuo, nake Ũhoro aatũũrĩte na Ngai, na Ũhoro aarĩ Ngai.
Ní àtètèkọ́ṣe ni Ọ̀rọ̀ wà, Ọ̀rọ̀ sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run, Ọlọ́run sì ni Ọ̀rọ̀ náà.
2 We aatũũrĩte na Ngai kuuma o kĩambĩrĩria.
Òun ni ó sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run ní àtètèkọ́ṣe.
3 Indo ciothe ciombirwo na ũndũ wake; gũtirĩ kĩndũ kĩa iria ciombirwo kĩagĩire atarĩ ho.
Nípasẹ̀ rẹ̀ ni a dá ohun gbogbo; lẹ́yìn rẹ̀ a kò sì dá ohun kan nínú ohun tí a ti dá.
4 Thĩinĩ wake kwarĩ muoyo, naguo muoyo ũcio nĩguo warĩ ũtheri wa andũ.
Nínú rẹ̀ ni ìyè wà, ìyè yìí náà sì ni ìmọ́lẹ̀ aráyé,
5 Ũtheri ũcio nĩũtheraga nduma-inĩ, nayo nduma ndĩigana kũũhoota.
ìmọ́lẹ̀ náà sì ń mọ́lẹ̀ nínú òkùnkùn, òkùnkùn kò sì borí rẹ̀.
6 Nĩguokire mũndũ watũmĩtwo nĩ Ngai; eetagwo Johana.
Ọkùnrin kan wà tí a rán láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá; orúkọ ẹni tí ń jẹ́ Johanu.
7 We okire arĩ mũira oimbũre ũhoro ũkoniĩ ũtheri ũcio, nĩgeetha andũ othe metĩkie nĩ ũndũ wake.
Òun ni a sì rán fún ẹ̀rí, kí ó lè ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà, kí gbogbo ènìyàn kí ó lè gbàgbọ́ nípasẹ̀ rẹ̀.
8 We mwene tiwe warĩ ũtheri ũcio, no okire arĩ o ta mũira tu nĩgeetha oimbũre ũhoro wa ũtheri ũcio.
Òun fúnra rẹ̀ kì í ṣe ìmọ́lẹ̀ náà, ṣùgbọ́n a rán an wá láti ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà.
9 Ũtheri ũcio wa ma, ũrĩa ũtheragĩra o mũndũ o wothe, nĩwokaga thĩ.
Ìmọ́lẹ̀ òtítọ́ ń bẹ tí ń tan ìmọ́lẹ̀ fún olúkúlùkù ènìyàn tí ó wá sí ayé.
10 We Ũhoro aarĩ gũkũ thĩ, no o na gũtuĩka thĩ yombirwo na ũndũ wake-rĩ, andũ a thĩ matiigana kũmũmenya.
Òun sì wà ní ayé, àti pé, nípasẹ̀ rẹ̀ ni a sì ti dá ayé, ṣùgbọ́n ayé kò sì mọ̀ ọ́n.
11 Okire gwake mwene, no andũ ake mwene matiigana kũmwĩtĩkĩra.
Ó tọ àwọn tirẹ̀ wá, àwọn tirẹ̀ kò sì gbà á.
12 No andũ arĩa othe maamwĩtĩkĩrire, o acio metĩkirie rĩĩtwa rĩake, nĩamahotithirie gũtuĩka ciana cia Ngai
Ṣùgbọ́n iye àwọn tí ó gbà á, àní àwọn náà tí ó gbà orúkọ rẹ̀ gbọ́, àwọn ni ó fi ẹ̀tọ́ fún láti di ọmọ Ọlọ́run.
13 ciana itaciarĩtwo nĩ thakame, kana igaciarwo nĩ kwenda kwa mwĩrĩ kana kwenda kwa mũndũ, no iciarĩtwo nĩ kwenda kwa Ngai.
Àwọn ọmọ tí kì í ṣe nípa ẹ̀jẹ̀, tàbí nípa ti ìfẹ́ ara, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe nípa ìfẹ́ ti ènìyàn, bí kò ṣe láti ọwọ́ Ọlọ́run.
14 We Kiugo agĩtuĩka mũndũ na agĩtũũrania na ithuĩ. Nĩtuonete riiri wake, riiri wa Mũrũ wake wa Mũmwe, ũrĩa woimire kũrĩ Ithe aiyũrĩtwo nĩ ũtugi na ũhoro wa ma.
Ọ̀rọ̀ náà sì di ara, òun sì ń bá wa gbé. Àwa sì ti rí ògo rẹ̀, àní ògo ọmọ rẹ kan ṣoṣo, tí ó ti ọ̀dọ̀ Baba wá, ó kún fún oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́.
15 Johana nĩoimbũraga ũhoro wake. Aanagĩrĩra akoiga atĩrĩ, “Ũyũ nĩwe ũrĩa ndaaragia ũhoro wake ngiuga atĩrĩ, ‘Ũrĩa ũgũũka thuutha wakwa nĩ mũnene kũngĩra, tondũ aarĩ mbere yakwa.’”
Johanu sì jẹ́rìí nípa rẹ̀, ó kígbe, ó sì wí pé, “Èyí ni ẹni tí mo sọ̀rọ̀ rẹ̀ pé, ‘Ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi pọ̀jù mí lọ, nítorí òun ti wà ṣáájú mi.’”
16 Na kuuma ũiyũrĩrĩru wa ũtugi wake-rĩ, ithuothe nĩtwamũkĩrĩte irathimo nyingĩ mũno.
Nítorí láti inú ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ ni gbogbo wa sì ti gba ìbùkún kún ìbùkún.
17 Tondũ watho wokire na Musa, no ũtugi na ũhoro ũrĩa wa ma ciokire na Jesũ Kristũ.
Nítorí pé nípasẹ̀ Mose ni a ti fi òfin fún ni ṣùgbọ́n òun; oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́ láti ipasẹ̀ Jesu Kristi wá.
18 Gũtirĩ mũndũ o na ũrĩkũ ũrĩ ona Ngai, o tiga Mũrũ wake wa Mũmwe ũrĩa ũikarĩte hamwe na Ithe, na nĩwe ũtũmĩte amenyeke.
Kò sí ẹni tí ó rí Ọlọ́run rí, bí kò ṣe òun nìkan, àní ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo, ẹni tí òun pàápàá jẹ́ Ọlọ́run, tí ó sì wà ní ìbáṣepọ̀ tí ó súnmọ́ jùlọ pẹ̀lú baba, òun náà ni ó sì fi í hàn.
19 Na rĩrĩ, ũyũ nĩguo ũira wa Johana hĩndĩ ĩrĩa Ayahudi a Jerusalemu maamũtũmĩire athĩnjĩri-Ngai na Alawii makamũũrie we aarĩ ũ.
Èyí sì ni ẹ̀rí Johanu, nígbà tí àwọn Júù rán àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi láti Jerusalẹmu wá láti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ ẹni tí òun ń ṣe.
20 We ndaagire kuumbũra, no oimbũrire atekũhitha, akiuga atĩrĩ, “Niĩ ti niĩ Kristũ.”
Òun kò sì kùnà láti jẹ́wọ́, ṣùgbọ́n òun jẹ́wọ́ wọ́ọ́rọ́wọ́ pé, “Èmi kì í ṣe Kristi náà.”
21 Nao makĩmũũria atĩrĩ, “Wee ũkĩrĩ ũ? Wee nĩwe Elija?” Nake akĩmacookeria atĩrĩ, “Aca, ti niĩ.” Ningĩ makĩmũũria atĩrĩ, “Nĩwe Mũnabii ũrĩa?” Nake agĩcookia atĩrĩ, “Aca.”
Wọ́n sì bi í léèrè pé, “Ta ha ni ìwọ? Elijah ni ìwọ bí?” Ó sì wí pé, “Èmi kọ́.” “Ìwọ ni wòlíì náà bí?” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”
22 Mũthia-inĩ makĩmũũria atĩrĩ, “Wee ũkĩrĩ ũ? Tũhe macookio nĩguo tũcookerie arĩa matũtũmire. Ũkuuga atĩa ha ũhoro waku mwene?”
Ní ìparí wọ́n wí fún un pé, “Ta ni ìwọ í ṣe? Fún wa ní ìdáhùn kí àwa kí ó lè mú èsì padà tọ àwọn tí ó rán wa wá lọ. Kí ni ìwọ wí nípa ti ara rẹ?”
23 Johana akĩmacookeria na ciugo iria ciarĩtio nĩ mũnabii Isaia, akĩmeera atĩrĩ, “Niĩ ndĩ mũgambo wa mũndũ ũranĩrĩra werũ-inĩ akoiga atĩrĩ, ‘Rũngariai njĩra ya Mwathani.’”
Johanu sì fi ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah fún wọn ní èsì pé, “Èmi ni ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ ṣe ọ̀nà Olúwa ní títọ́.’”
24 Na rĩrĩ, Afarisai amwe arĩa maatũmĩtwo
Ọ̀kan nínú àwọn Farisi tí a rán
25 makĩmũũria atĩrĩ, “Angĩkorwo we tiwe Kristũ, na tiwe Elija, o na kana Mũnabii ũrĩa-rĩ, ũkĩbatithanagia nĩkĩ?”
bi í léèrè pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń bamitiisi nígbà náà, bí ìwọ kì í bá ṣe Kristi, tàbí Elijah, tàbí wòlíì náà?”
26 Nake Johana akĩmacookeria atĩrĩ, “Niĩ ndĩmũbatithagia na maaĩ. No gatagatĩ-inĩ kanyu nĩ harĩ na ũmwe mũtooĩ.
Johanu dá wọn lóhùn, wí pé, “Èmi ń fi omi bamitiisi, ẹnìkan dúró láàrín yín, ẹni tí ẹ̀yin kò mọ̀,
27 Ũcio nĩwe ũgũũka thuutha wakwa, o we ũrĩa itaagĩrĩire kuohora ndigi cia iraatũ ciake.”
Òun náà ni ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi, okùn bàtà ẹni tí èmi kò tó láti tú.”
28 Maũndũ maya mothe mekĩkire itũũra-inĩ rĩa Bethania, mũrĩmo wa Rũũĩ rwa Jorodani, kũrĩa Johana aabatithanagĩria.
Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó ṣẹlẹ̀ ní Betani ní òdìkejì odò Jordani, níbi tí Johanu ti ń fi omi bamitiisi.
29 Mũthenya ũyũ ũngĩ, Johana akĩona Jesũ agĩũka na kũrĩ we, akiuga atĩrĩ, “Onei! Gatũrũme ka Ngai karĩa keheragia mehia ma kĩrĩndĩ!
Ní ọjọ́ kejì, Johanu rí Jesu tí ó ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run, ẹni tí ó kó ẹ̀ṣẹ̀ ayé lọ!
30 Ũyũ nĩwe ndaaragia ũhoro wake rĩrĩa ndoigire atĩrĩ, ‘Mũndũ ũrĩa ũgũũka thuutha wakwa nĩ mũnene kũrĩ niĩ tondũ we aarĩ kuo mbere yakwa.’
Èyí ni ẹni tí mo ń sọ nígbà tí mo wí pé, ‘Ọkùnrin kan tí ń bọ̀ wá lẹ́yìn mi, tí ó pọ̀jù mí lọ, nítorí tí ó ti wà ṣáájú mi.’
31 Niĩ mwene ndiamũũĩ, no ndokire ngĩbatithanagia na maaĩ nĩgeetha aguũrĩrio andũ a Isiraeli.”
Èmi gan an kò sì mọ̀ ọ́n, ṣùgbọ́n ìdí tí mo fi wá ń fi omi ṣe ìtẹ̀bọmi ni kí a lè fi í hàn fún Israẹli.”
32 Ningĩ Johana akĩheana ũira ũyũ: “Nĩndonire Roho agĩikũrũka kuuma igũrũ atariĩ ta ndutura, agĩikara igũrũ rĩake.
Nígbà náà ni Johanu jẹ́rìí sí i pé, “Mo rí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá bí àdàbà, tí ó sì bà lé e.
33 Niĩ ndingĩamũmenyire, tiga ũrĩa wandũmire mbatithanagie na maaĩ aanjĩĩrire atĩrĩ, ‘Mũndũ ũrĩa ũkoona Roho agĩikũrũkĩra na aikare igũrũ rĩake-rĩ, ũcio nĩwe ũkaabatithanagia na Roho Mũtheru.’
Èmi kì bá tí mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe pé ẹni tí ó rán mi láti fi omi bamitiisi sọ fún mi pé, ‘Ọkùnrin tí ìwọ rí tí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ tí ó bà lé lórí ni ẹni tí yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi.’
34 Niĩ nĩnyonete ũguo na ngoimbũra atĩ ũyũ nĩwe Mũrũ wa Ngai.”
Èmi ti rí i, mo sì jẹ́rìí pé, èyí ni Ọmọ Ọlọ́run.”
35 Ningĩ mũthenya ũyũ ũngĩ, Johana agĩkorwo arĩ kũu o rĩngĩ marĩ na arutwo ake eerĩ.
Ní ọjọ́ kejì, Johanu dúró pẹ̀lú méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
36 Na rĩrĩa onire Jesũ akĩhĩtũka, akiuga atĩrĩ, “Onei Gatũrũme ka Ngai!”
Nígbà tí ó sì rí Jesu bí ó ti ń kọjá lọ, ó wí pé, “Wò ó Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run!”
37 Hĩndĩ ĩrĩa arutwo acio eerĩ maiguire oiga ũguo, makĩrũmĩrĩra Jesũ.
Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn méjì náà sì gbọ́ ohun tí ó wí yìí, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sì í tọ Jesu lẹ́yìn.
38 Jesũ ehũgũra akĩmoona mamumĩte thuutha, akĩmooria atĩrĩ, “Nĩ atĩa mũrenda?” Nao makĩmwĩra atĩrĩ, “Rabii” (ũguo nĩ kuuga Mũrutani), “ũikaraga kũ?”
Nígbà náà ni Jesu yípadà, ó rí i pé wọ́n ń tọ òun lẹ́yìn, ó sì béèrè pé, “Kí ni ẹ̀yin ń wá?” Wọ́n wí fún un pé, “Rabbi” (ìtumọ̀ èyí tí í ṣe Olùkọ́ni), “Níbo ni ìwọ ń gbé?”
39 Nake akĩmacookeria atĩrĩ, “Ũkai na nĩmũkuona.” Nĩ ũndũ ũcio magĩthiĩ makĩona kũrĩa aikaraga, na magĩikara nake mũthenya ũcio. Na kwarĩ ta thaa ikũmi.
Ó wí fún wọn pé, “Ẹ wá wò ó, ẹ̀yin yóò sì rí i.” Wọ́n sì wá, wọ́n sì rí ibi tí ó ń gbé, wọ́n sì wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ náà. Ó jẹ́ ìwọ̀n wákàtí kẹwàá ọjọ́.
40 Na rĩrĩ, ũmwe wa arutwo acio eerĩ arĩa maiguĩte ũrĩa Johana oigĩte na makĩrũmĩrĩra Jesũ aarĩ Anderea, mũrũ wa nyina na Simoni Petero.
Anderu arákùnrin Simoni Peteru jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn méjì tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Johanu, tí ó sì tọ Jesu lẹ́yìn.
41 Ũndũ wa mbere ũrĩa Anderea eekire nĩgũcaria mũrũ wa nyina Simoni, na kũmwĩra atĩrĩ, “Nĩtuonete Mesia” (nĩwe Kristũ).
Ohun àkọ́kọ́ tí Anderu ṣe ni láti wá Simoni arákùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí Messia” (ẹni tí ṣe Kristi).
42 Nake akĩmũtwara kũrĩ Jesũ. Nake Jesũ akĩmũrora, akiuga atĩrĩ, “Wee nĩwe Simoni mũrũ wa Johana. Ũgũcooka gwĩtwo Kefa” (na rĩo rĩgĩtaũrwo nĩ kuuga Petero).
Ó sì mú un wá sọ́dọ̀ Jesu. Jesu sì wò ó, ó wí pé, “Ìwọ ni Simoni ọmọ Jona: Kefa ni a ó sì máa pè ọ” (ìtumọ̀ èyí tí ṣe Peteru).
43 Mũthenya ũyũ ũngĩ Jesũ agĩtua itua rĩa gũthiĩ Galili. Agĩkora Filipu, akĩmwĩra atĩrĩ, “Nũmĩrĩra.”
Ní ọjọ́ kejì Jesu ń fẹ́ jáde lọ sí Galili, ó sì rí Filipi, ó sì wí fún un pé, “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”
44 Filipu, o ta Petero na Anderea, aarĩ wa itũũra rĩa Bethisaida.
Filipi gẹ́gẹ́ bí i Anderu àti Peteru, jẹ́ ará ìlú Betisaida.
45 Filipu agĩkora Nathanieli, akĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩtuonete mũndũ ũrĩa Musa aandĩkire ũhoro wake Ibuku-inĩ rĩa Watho, na nowe anabii maandĩkire ũhoro wake, nake nĩwe Jesũ wa Nazarethi, mũrũ wa Jusufu.”
Filipi rí Natanaeli, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí ẹni náà tí Mose kọ nípa rẹ̀ nínú òfin àti ẹni tí àwọn wòlíì ti kọ̀wé rẹ̀, Jesu ti Nasareti, ọmọ Josẹfu.”
46 Nake Nathanieli akĩmũũria atĩrĩ, “Kũrĩ kĩndũ kĩega kĩngiuma Nazarethi?” Nake Filipu akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ũka ũkoone.”
Natanaeli béèrè pé, “Nasareti? Ohun rere kan ha lè ti ibẹ̀ jáde?” Filipi wí fún un pé, “Wá wò ó.”
47 Hĩndĩ ĩrĩa Jesũ onire Nathanieli agĩũka kũrĩ we, akĩaria ũhoro wake, akiuga atĩrĩ, “Onei Mũisiraeli kũna ũtarĩ ũhinga.”
Jesu rí Natanaeli ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí nípa rẹ̀ pé, “Èyí ni ọmọ Israẹli tòótọ́, nínú ẹni tí ẹ̀tàn kò sí.”
48 Nake Nathanieli akĩmũũria atĩrĩ, “Ũnjũũĩ atĩa?” Jesũ akĩmũcookeria atĩrĩ, “Nĩngũkuonete o na rĩrĩa uuma rungu rwa mũkũyũ, Filipu atanagwĩta.”
Natanaeli béèrè pé, “Báwo ni ìwọ ti ṣe mọ̀ mí?” Jesu sì dáhùn pé, “Èmi rí ọ nígbà tí ìwọ wà lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ kí Filipi tó pè ọ́.”
49 Hĩndĩ ĩyo Nathanieli akiuga atĩrĩ, “Rabii, wee nĩwe Mũrũ wa Ngai; wee nĩwe Mũthamaki wa Isiraeli.”
Nígbà náà ni Natanaeli sọ ọ́ gbangba pé, “Rabbi, ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run; Ìwọ ni ọba Israẹli.”
50 Nake Jesũ akiuga atĩrĩ, “Wetĩkia tondũ nĩndakwĩra atĩ nĩnguonire ũrĩ rungu rwa mũkũyũ. Nĩũkuona maũndũ manene kũrĩ macio.”
Jesu sì wí fún un pé, “Ìwọ gbàgbọ́ nítorí mo wí fún ọ pé mo rí ọ lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́. Ìwọ ó rí ohun tí ó pọ̀jù ìwọ̀nyí lọ.”
51 Ningĩ akĩmeera atĩrĩ, “Ngũmwĩra atĩrĩ na ma, nĩmũkona igũrũ rĩhingũkĩte na araika a Ngai makĩambata na magĩikũrũka, harĩ Mũrũ wa Mũndũ.”
Nígbà náà ni ó fi kún un pé, “Èmi wí fún yín nítòótọ́, ẹ̀yin yóò rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, àwọn angẹli Ọlọ́run yóò sì máa gòkè, wọ́n ó sì máa sọ̀kalẹ̀ sórí Ọmọ Ènìyàn.”

< Johana 1 >