< Johana 9 >

1 Na rĩrĩa aathiiaga na njĩra-rĩ, akĩona mũndũ waciarĩtwo arĩ mũtumumu.
Bí ó sì ti ń kọjá lọ, ó rí ọkùnrin kan tí ó fọ́jú láti ìgbà ìbí rẹ̀ wá.
2 Nao arutwo ake makĩmũũria atĩrĩ, “Rabii, nũũ wehirie, nĩ mũndũ ũyũ kana nĩ aciari ake, nĩgeetha aciarwo arĩ mũtumumu?”
Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì bi í léèrè, pé, “Rabbi, ta ní ó dẹ́ṣẹ̀, ọkùnrin yìí tàbí àwọn òbí rẹ̀, tí a fi bí i ní afọ́jú?”
3 Nake Jesũ akiuga atĩrĩ, “Ti mũndũ ũyũ kana aciari ake mehirie. No ũndũ ũyũ wekĩkire nĩgeetha wĩra wa Ngai wonanio mũtũũrĩre-inĩ wake.
Jesu dáhùn pé, “Kì í ṣe nítorí pé ọkùnrin yìí dẹ́ṣẹ̀, tàbí àwọn òbí rẹ̀: ṣùgbọ́n kí a ba à lè fi iṣẹ́ Ọlọ́run hàn lára rẹ̀.
4 Rĩrĩa rĩothe arĩ mũthenya-rĩ, no nginya tũrute wĩra wa ũrĩa wandũmire. Ũtukũ nĩũrooka rĩrĩa gũtarĩ mũndũ ũngĩhota kũruta wĩra.
Èmi ní láti ṣe iṣẹ́ ẹni tí ó rán mi, níwọ̀n ìgbà tí ó bá ti jẹ́ ọ̀sán, òru ń bọ̀ wá nígbà tí ẹnìkan kì yóò lè ṣe iṣẹ́.
5 Rĩrĩa ndĩ gũkũ thĩ, nĩ niĩ ũtheri wa thĩ.”
Níwọ́n ìgbà tí mo wà láààyè, èmi ni ìmọ́lẹ̀ ayé.”
6 Na aarĩkia kuuga ũguo, agĩtua mata thĩ, akĩringia ndoro na mata macio, na akĩmĩhaka mũndũ ũcio maitho.
Nígbà tí ó ti wí bẹ́ẹ̀ tan, ó tutọ́ sílẹ̀, ó sì fi itọ́ náà ṣe amọ̀, ó sì fi amọ̀ náà ra ojú afọ́jú náà.
7 Akĩmwĩra atĩrĩ, “Thiĩ ũgethambe Karia-inĩ ga Siloamu” (narĩo rĩĩtwa Siloamu nĩ kuuga Gũtũmwo.) Nĩ ũndũ ũcio mũndũ ũcio agĩthiĩ na agĩĩthamba, na agĩũka mũciĩ akĩonaga.
Ó sì wí fún un pé, “Lọ wẹ̀ nínú adágún Siloamu!” (Ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ yìí ni “rán”). Nítorí náà ó gba ọ̀nà rẹ̀ lọ, ó wẹ̀, ó sì dé, ó ń ríran.
8 Nao andũ a itũũra rĩake na arĩa maamuonete mbere ĩyo akĩhooya ũteithio makĩũrania atĩrĩ, “Githĩ mũndũ ũyũ ti ũrĩa ũraikaraga thĩ ahooyage ũteithio?”
Ǹjẹ́ àwọn aládùúgbò àti àwọn tí ó rí i nígbà àtijọ́ pé alágbe ni ó jẹ́, wí pé, “Ẹni tí ó ti ń jókòó ṣagbe kọ́ yìí?”
9 Andũ amwe makiuga atĩ aarĩ we. Nao arĩa angĩ makiuga atĩrĩ, “Aca, no kũhaana amũhaana.” Nowe agĩkĩrĩrĩria kuuga atĩrĩ, “Nĩ niĩ mũndũ ũcio.”
Àwọn kan wí pé òun ni. Àwọn ẹlòmíràn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ó jọ ọ́ ni.” Ṣùgbọ́n òun wí pé, “Èmi ni.”
10 Nao makĩmũũria atĩrĩ, “Maitho maku makĩhingũkire atĩa?”
Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “Bá wo ni ojú rẹ ṣe là?”
11 Nake akĩmacookeria atĩrĩ, “Mũndũ ũrĩa metaga Jesũ nĩwe ũringirie ndoro aahaka maitho, anjĩĩra thiĩ ngeethambe Karia-inĩ ga Siloamu. Nĩ ũndũ ũcio ndathiĩ na ndeethamba, na ndahota kuona.”
Ó dáhùn ó sì wí fún un pé, “Ọkùnrin kan tí a ń pè ní Jesu ni ó ṣe amọ̀, ó sì fi kun ojú mí, ó sì wí fún mi pé, Lọ sí adágún Siloamu, kí o sì wẹ̀, èmi sì lọ, mo wẹ̀, mo sì ríran.”
12 Nao makĩmũũria atĩrĩ, “Mũndũ ũcio arĩ ha?” Nake akĩmeera atĩrĩ, “Niĩ ndiũũĩ.”
Wọ́n sì wí fún un pé, “Òun náà ha dà?” Ó sì wí pé, “Èmi kò mọ̀.”
13 Nao magĩtwara mũndũ ũcio warĩ mũtumumu kũrĩ Afarisai.
Wọ́n mú ẹni tí ojú rẹ̀ ti fọ́ rí wá sọ́dọ̀ àwọn Farisi.
14 Na rĩrĩ, mũthenya ũcio Jesũ aaringirie ndoro na akĩhingũra maitho ma mũndũ ũcio warĩ wa Thabatũ.
Ọjọ́ ìsinmi ni ọjọ́ náà nígbà tí Jesu ṣe amọ̀, tí ó sì là á lójú.
15 Nĩ ũndũ ũcio Afarisai o nao makĩmũũria ũrĩa aahotete kuona. Nake mũndũ ũcio akĩmacookeria atĩrĩ, “Aahakire ndoro maitho, na niĩ ndeethamba na rĩu nĩndĩrona.”
Nítorí náà àwọn Farisi pẹ̀lú tún bi í léèrè, bí ó ti ṣe ríran. Ọkùnrin náà fèsì, “Ó fi amọ̀ lé ojú mi, mo sì wẹ̀, báyìí mo sì ríran.”
16 Nao Afarisai amwe makiuga atĩrĩ, “Mũndũ ũyũ ndoimĩte kũrĩ Ngai, nĩgũkorwo ndamenyagĩrĩra Thabatũ.” No arĩa angĩ makĩũria atĩrĩ, “Mũndũ mwĩhia ahota atĩa kũringa ciama ta ici?” Nĩ ũndũ ũcio makĩamũkana.
Nítorí náà àwọn kan nínú àwọn Farisi wí pé, “Ọkùnrin yìí kò ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, nítorí tí kò pa ọjọ́ ìsinmi mọ́.” Àwọn ẹlòmíràn wí pé, “Ọkùnrin tí í ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ yóò ha ti ṣe lè ṣe irú iṣẹ́ àmì wọ̀nyí?” Ìyapa sì wà láàrín wọn.
17 Mũthia-inĩ Afarisai acio makĩhũgũkĩra mũndũ ũcio warĩ mũtumumu, makĩmũũria atĩrĩ, “Wee ũkuuga atĩa ha ũhoro wake? Nĩwe araahingũrire maitho.” Nake mũndũ ũcio agĩcookia atĩrĩ, “Nĩ mũnabii.”
Nítorí náà, wọ́n sì tún wí fún afọ́jú náà pé, “Kí ni ìwọ ní wí nípa rẹ̀, nítorí tí ó là ọ́ lójú?” Ó sì wí pé, “Wòlíì ní í ṣe.”
18 O na kũrĩ ũguo Ayahudi matiigana gwĩtĩkia ũhoro wa mũndũ ũcio atĩ aarĩ mũtumumu na atĩ nĩacookete kuona, nginya rĩrĩa maatũmanĩire aciari ake.
Nítorí náà àwọn Júù kò gbàgbọ́ nípa rẹ̀ pé ojú rẹ̀ ti fọ́ rí, àti pé ó sì tún ríran, títí wọ́n fi pe àwọn òbí ẹni tí a ti là lójú.
19 Makĩmooria atĩrĩ, “Ũyũ nĩ mwana wanyu? Ũyũ nĩwe mũroiga aaciarirwo arĩ mũtumumu? Rĩu ahotete atĩa kuona?”
Wọ́n sì bi wọ́n léèrè wí pé, “Ǹjẹ́ èyí ni ọmọ yín, ẹni tí ẹ̀yin wí pé, a bí ní afọ́jú? Báwo ni ó ṣe ríran nísinsin yìí?”
20 Nao aciari ake magĩcookia atĩrĩ, “Ithuĩ tũũĩ nĩ mwana witũ na tũũĩ aaciarirwo arĩ mũtumumu.
Àwọn òbí rẹ̀ dá wọn lóhùn wí pé, “Àwa mọ̀ pé ọmọ wa ni èyí, àti pé a bí i ní afọ́jú,
21 No ũrĩa ahotete kuona, kana ũrĩa ũmũhingũrire maitho make, ithuĩ tũtiũĩ. Mũũriei nĩ mũgima, nĩekwĩyarĩrĩria.”
ṣùgbọ́n bí ó tí ṣe ń ríran nísinsin yìí àwa kò mọ̀, ẹni tí ó là á lójú, àwa kò mọ̀, ẹni tí ó ti dàgbà ni òun; ẹ bi í léèrè, yóò wí fúnra rẹ̀.”
22 Aciari ake moigire ũguo nĩ ũndũ wa gwĩtigĩra Ayahudi, nĩgũkorwo Ayahudi nĩmarĩkĩtie gũtua atĩ mũndũ o wothe ũngiuga atĩ Jesũ nĩwe Kristũ nĩegũikio nja ya thunagogi.
Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn òbí rẹ̀ sọ, nítorí tí wọ́n bẹ̀rù àwọn Júù: nítorí àwọn Júù ti fohùn ṣọ̀kan pé bí ẹnìkan bá jẹ́wọ́ pé Kristi ni, wọn ó yọ ọ́ kúrò nínú Sinagọgu.
23 Nĩkĩo aciari ake moigire atĩrĩ, “Nĩ mũgima; mũũriei.”
Nítorí èyí ni àwọn òbí rẹ̀ fi wí pé, “Ẹni tí ó dàgbà ni òun, ẹ bi í léèrè.”
24 Magĩĩta mũndũ ũcio warĩ mũtumumu hĩndĩ ya keerĩ. Makĩmwĩra atĩrĩ, “Goocithia Ngai. Nĩtũũĩ mũndũ ũyũ nĩ mwĩhia.”
Nítorí náà, wọ́n pe ọkùnrin afọ́jú náà lẹ́ẹ̀kejì, wọ́n sì wí fún un pé, “Fi ògo fún Ọlọ́run, àwa mọ̀ pé ẹlẹ́ṣẹ̀ ni ọkùnrin yìí jẹ́.”
25 Nake agĩcookia atĩrĩ, “Niĩ ndiũĩ kana nĩ mwĩhia kana ti mwĩhia. No njũũĩ ũndũ ũyũ ũmwe; ndĩraarĩ mũtumumu na rĩu nĩndĩrona!”
Nítorí náà, ó dáhùn ó sì wí pé, “Bí ẹlẹ́ṣẹ̀ ni, èmi kò mọ̀, Ohun kan ni mo mọ̀, pé mo tí fọ́jú rí, nísinsin yìí mo ríran.”
26 Ningĩ makĩmũũria atĩrĩ, “Agwĩkire atĩa? Akũhingũrire maitho atĩa?”
Nítorí náà, wọ́n wí fún un pé, “Kí ni ó ṣe ọ́? Báwo ni ó ṣe là ọ́ lójú.”
27 Nake akĩmacookeria atĩrĩ, “Nĩndamwĩra ũhoro o rĩu na inyuĩ mũtinathikĩrĩria. Mũrenda kũigua rĩngĩ nĩkĩ? O na inyuĩ nĩmũkwenda gũtuĩka arutwo ake?”
Ó dá wọn lóhùn wí pé, “Èmi ti sọ fún yín tẹ́lẹ̀, ẹ̀yin kò sì gbọ́, nítorí kín ni ẹ̀yin ṣe ń fẹ́ tún gbọ́? Ẹ̀yin pẹ̀lú ń fẹ́ ṣe ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ bí?”
28 Nao makĩmũruma, makĩmwĩra atĩrĩ, “Wee ũrĩ mũrutwo wa mũndũ ũyũ! Ithuĩ tũrĩ arutwo a Musa!
Wọ́n sì fi í ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n sì wí pé, “Ìwọ ni ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ṣùgbọ́n ọmọ-ẹ̀yìn Mose ni àwa.
29 Ithuĩ nĩtũũĩ atĩ Ngai nĩarĩirie Musa, no ha ũhoro wa mũndũ ũyũ-rĩ, tũtiũĩ o na kũrĩa oimĩte.”
Àwa mọ̀ pé Ọlọ́run bá Mose sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti eléyìí, àwa kò mọ ibi tí ó ti wá.”
30 Nake mũndũ ũcio akĩmacookeria atĩrĩ, “Kaĩ ũcio nĩ ũrirũ-ĩ! Inyuĩ mũtiũĩ kũrĩa oimĩte, na nĩwe ũũhingũrire maitho.
Ọkùnrin náà dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ohun ìyanu sá à ni èyí, pé ẹ̀yin kò mọ ibi tí ó tí wá, ṣùgbọ́n òun sá à ti là mí lójú.
31 Nĩtũũĩ atĩ Ngai ndathikagĩrĩria andũ ehia. Athikagĩrĩria mũndũ ũrĩa ũrĩ na ũngai na ũrĩa wĩkaga wendi wake.
Àwa mọ̀ pé Ọlọ́run kì í gbọ́ ti ẹlẹ́ṣẹ̀; ṣùgbọ́n bí ẹnìkan bá ṣe olùfọkànsìn sí Ọlọ́run, tí ó bá sì ń ṣe ìfẹ́ rẹ̀, Òun ni ó ń gbọ́ tirẹ̀.
32 Gũtirĩ mũndũ ũrĩ waigua ũhoro wa mũndũ ũhingũrĩtwo maitho aciarĩtwo arĩ mũtumumu. (aiōn g165)
Láti ìgbà tí ayé ti ṣẹ̀, a kò ì tí ì gbọ́ pé ẹnìkan la ojú ẹni tí a bí ní afọ́jú rí. (aiōn g165)
33 Korwo mũndũ ũyũ ndoimĩte kũrĩ Ngai ndarĩ ũndũ angĩhota gwĩka.”
Ìbá ṣe pé ọkùnrin yìí kò ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, kì bá tí lè ṣe ohunkóhun.”
34 Igũrũ rĩa ũhoro ũcio magĩcookia atĩrĩ, “Wee waciarirwo ũrĩ na mehia. Ũngĩkĩgeria atĩa gũtũruta!” Nao makĩmũikania na kũu nja.
Sí èyí, wọ́n fèsì pé, “Láti ìbí ni o tì jíngírí nínú ẹ̀ṣẹ̀, ìwọ ha fẹ́ kọ́ wa bí?” Wọ́n sì tì í sóde.
35 Jesũ nĩaiguire atĩ nĩmaikĩtie mũndũ ũcio nja, na rĩrĩa aamuonire akĩmũũria atĩrĩ, “Wee nĩwĩtĩkĩtie Mũrũ wa Mũndũ?”
Jesu gbọ́ pé, wọ́n ti tì í sóde; nígbà tí ó sì rí i, ó wí pe, “Ìwọ gba Ọmọ Ọlọ́run, gbọ́ bí?”
36 Nake mũndũ ũcio akĩmũũria atĩrĩ, “Mũthuuri ũyũ, ũcio nĩwe ũ? Njĩĩra, nĩgeetha ndĩmwĩtĩkie.”
Òun sì dáhùn wí pé, “Ta ni, Olúwa, kí èmi lè gbà á gbọ́?”
37 Nake Jesũ akiuga atĩrĩ, “Rĩu nĩũmuonete; nĩwe ũyũ ũraaria nawe.”
Jesu wí fún un pé, “Ìwọ ti rí i, Òun náà sì ni ẹni tí ń bá ọ sọ̀rọ̀ yìí.”
38 Nake mũndũ ũcio akiuga atĩrĩ, “Mwathani, nĩndetĩkia,” na akĩmũthathaiya.
Ó sì wí pé, “Olúwa, mo gbàgbọ́,” ó sì wólẹ̀ fún un.
39 Ningĩ Jesũ akiuga atĩrĩ, “Njũkĩte gũkũ thĩ nĩ ũndũ wa gũtuanĩra ciira, nĩgeetha arĩa atumumu mahote kuona, nao arĩa monaga matuĩke atumumu.”
Jesu sì wí pé, “Nítorí ìdájọ́ ni mo ṣe wá sí ayé yìí, kí àwọn tí kò ríran lè ríran; àti kí àwọn tí ó ríran lè di afọ́jú.”
40 Afarisai amwe arĩa maarĩ nake makĩigua akiuga ũguo, nao makĩmũũria atĩrĩ, “Atĩ atĩa? O na ithuĩ tũrĩ atumumu?”
Nínú àwọn Farisi tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, wọ́n sì wí fún un pé, “Àwa pẹ̀lú fọ́jú bí?”
41 Nake Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Mũngĩrĩ atumumu-rĩ, mũtingĩrĩ na mehia; no rĩu tondũ muugaga atĩ nĩmuonaga-rĩ, mũgũikara o na wĩhia wanyu.”
Jesu wí fún wọn pé, “Ìbá ṣe pé ẹ̀yin fọ́jú, ẹ̀yin kì bá tí lẹ́sẹ̀, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa ríran,’ nítorí náà ẹ̀ṣẹ̀ yín wà síbẹ̀.

< Johana 9 >