< Johana 8 >
1 No rĩrĩ, Jesũ agĩthiĩ Kĩrĩma-inĩ kĩa Mĩtamaiyũ.
Jesu sì lọ sí orí òkè olifi.
2 Na rũciinĩ tene akĩroka o rĩngĩ kũu nja cia hekarũ, kũrĩa andũ othe maamũrigiicĩirie. Nake agĩikara thĩ kũmaruta.
Ó sì tún padà wá sí tẹmpili ní kùtùkùtù òwúrọ̀, gbogbo ènìyàn sì wá sọ́dọ̀ rẹ̀; ó sì jókòó, ó ń kọ́ wọn.
3 Arutani a watho hamwe na Afarisai makĩrehe mũtumia wanyiitĩtwo agĩtharia. Makĩmũrũgamia hau mbere ya gĩkundi,
Àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi sì mú obìnrin kan wá sọ́dọ̀ rẹ̀, tí a mú nínú ṣíṣe panṣágà; wọ́n sì mú un dúró láàrín.
4 na makĩĩra Jesũ atĩrĩ, “Mũrutani, mũtumia ũyũ aanyiitwo agĩtharia.
Wọ́n sì wí fún un pé, “Olùkọ́, a mú obìnrin yìí nínú ìṣe panṣágà.
5 Thĩinĩ wa watho-rĩ, Musa aatwathire tũhũũrage atumia ta aya na mahiga nyuguto. Rĩu we ũkuuga atĩa?”
Ǹjẹ́ nínú òfin, Mose pàṣẹ fún wa láti sọ irú àwọn obìnrin bẹ́ẹ̀ ní òkúta, ṣùgbọ́n ìwọ ha ti wí?”
6 Maahũthagĩra kĩũria gĩkĩ kĩrĩ ta mũtego, nĩgeetha magĩe na ũndũ wa kũmũthitangĩra. No Jesũ akĩinamĩrĩra, na akĩambĩrĩria kwandĩka thĩ na kĩara gĩake.
Èyí ni wọ́n wí, láti dán án wò, kí wọn ba à lè rí ẹ̀sùn kan kà sí i lọ́rùn. Ṣùgbọ́n Jesu bẹ̀rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ń fi ìka rẹ̀ kọ̀wé ní ilẹ̀.
7 Na rĩrĩa maathiire na mbere kũmũũria ũhoro ũcio, akĩinamũka, akĩmeera atĩrĩ, “Angĩkorwo harĩ na ũmwe wanyu ũtarĩ ehia-rĩ, nĩatuĩke wa mbere kũmũikĩria ihiga.”
Nígbà tí wọ́n ń bi í léèrè lemọ́lemọ́, ó gbe orí rẹ sókè, ó sì wí fún wọn pé, “Jẹ́ kí ẹni tí ó wà láìní ẹ̀ṣẹ̀ nínú yín kọ́kọ́ sọ òkúta lù ú.”
8 Agĩcooka akĩinamĩrĩra rĩngĩ, akĩandĩka thĩ na kĩara.
Ó sì tún bẹ̀rẹ̀ sílẹ̀, ó ń kọ̀wé ní ilẹ̀.
9 Rĩrĩa maiguire ũguo, makĩambĩrĩria kwehera hau ũmwe kwa ũmwe, maambĩrĩirie na arĩa akũrũ, nginya hagĩtigara o Jesũ na mũtumia ũcio arũngiĩ o hau.
Nígbà tí wọ́n gbọ́ èyí, wọ́n sì jáde lọ lọ́kọ̀ọ̀kan, bẹ̀rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn àgbà títí dé àwọn tí ó kẹ́yìn; a sì fi Jesu nìkan sílẹ̀, àti obìnrin náà láàrín, níbi tí ó wà.
10 Jesũ akĩinamũka, akĩmũũria atĩrĩ, “Mũtumia ũyũ, agũthitangi marĩ ha? Hatirĩ o na ũmwe wao wagũtuĩra?”
Jesu sì dìde, ó sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, àwọn olùfisùn rẹ dà? Kò sí ẹnìkan tí ó dá ọ lẹ́bi?”
11 Nake akĩmũcookeria atĩrĩ, “Mũthuuri ũyũ, gũtirĩ o na ũmwe.” Nake Jesũ akiuga atĩrĩ, “O na niĩ ndigũgũtuĩra. Thiĩ, na ndũkanacooke kwĩhia.”)
Ó wí pé, “Kò sí ẹnìkan, Olúwa.” Jesu wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ ni èmi náà kò dá ọ lẹ́bi, máa lọ, láti ìgbà yìí lọ, má dẹ́ṣẹ̀ mọ́.”
12 Rĩrĩa Jesũ aarĩirie andũ rĩngĩ, akiuga atĩrĩ, “Niĩ nĩ niĩ ũtheri wa thĩ. Ũrĩa wothe ũnũmagĩrĩra ndarĩ hĩndĩ arĩthiiaga na nduma, no arĩgĩaga na ũtheri wa muoyo.”
Jesu sì tún sọ fún wọn pé, “Èmi ni ìmọ́lẹ̀ ayé, ẹni tí ó bá tọ̀ mí lẹ́yìn kì yóò rìn nínú òkùnkùn, ṣùgbọ́n yóò ní ìmọ́lẹ̀ ìyè.”
13 Nao Afarisai makĩmũkararia, makĩmwĩra atĩrĩ, “We ũraheana ũira waku wee mwene; ũira waku ti wa ma.”
Nítorí náà àwọn Farisi wí fún un pé, “Ìwọ ń jẹ́rìí ara rẹ; ẹ̀rí rẹ kì í ṣe òtítọ́.”
14 Nake Jesũ agĩcookia atĩrĩ, “O na ingĩruta ũira wakwa niĩ mwene-rĩ, ũira wakwa nĩ wa ma, nĩgũkorwo nĩnjũũĩ kũrĩa ndoimire o na kũrĩa ndĩrathiĩ. No inyuĩ mũtiũĩ kũrĩa nyumĩte kana kũrĩa ndĩrathiĩ.
Jesu dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Bí mo tilẹ̀ ń jẹ́rìí fún ara mi, òtítọ́ ni ẹ̀rí mi: nítorí tí mo mọ ibi tí mo ti wá, mo sì mọ ibi tí mo ń lọ; ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò lè mọ ibi tí mo ti wá, àti ibi tí mo ń lọ.
15 Inyuĩ mũtuanagĩra ciira na ũmũndũ; niĩ ndirĩ mũndũ nduagĩra ciira.
Ẹ̀yin ń ṣe ìdájọ́ nípa ti ara; èmi kò ṣe ìdájọ́ ẹnikẹ́ni.
16 No o na ingĩtuanĩra ciira-rĩ, itua rĩakwa nĩrĩagĩrĩire, nĩgũkorwo ndituanagĩra ndĩ nyiki. No niĩ ndĩ na Baba, ũrĩa wandũmire.
Ṣùgbọ́n bí èmi bá sì ṣe ìdájọ́, òtítọ́ ni, nítorí èmi nìkan kọ́, ṣùgbọ́n èmi àti Baba tí ó rán mi.
17 Thĩinĩ wa watho wanyu nĩ kwandĩkĩtwo atĩ ũira wa andũ eerĩ nĩ wa ma.
A sì kọ ọ́ pẹ̀lú nínú òfin pé, òtítọ́ ni ẹ̀rí ènìyàn méjì.
18 Niĩ ndĩraruta ũira wakwa mwene; nake mũira wakwa ũcio ũngĩ nĩ Baba ũrĩa wandũmire.”
Èmi ni ẹni tí ń jẹ́rìí ara mi, Baba tí ó rán mi sì ń jẹ́rìí mi.”
19 Ningĩ makĩmũũria atĩrĩ, “Thoguo arĩ kũ?” Nake Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Inyuĩ mũtinjũũĩ, o na Baba mũtimũũĩ. Korwo nĩmũnjũũĩ, o na Baba nĩmũngĩmũũĩ.”
Nítorí náà wọ́n wí fún un pé, “Níbo ni Baba rẹ wà?” Jesu dáhùn pé, “Ẹ̀yin kò mọ̀ mí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò mọ Baba mi, ìbá ṣe pé ẹ̀yin mọ̀ mí, ẹ̀yin ìbá sì ti mọ Baba mi pẹ̀lú.”
20 Nake aaragia ciugo icio akĩrutana hekarũ-inĩ hakuhĩ na harĩa mũhothi warutagĩrwo. No gũtirĩ mũndũ wamũnyiitire nĩ tondũ ihinda rĩake rĩtiarĩ ikinyu.
Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni Jesu sọ níbi ìṣúra, bí ó ti ń kọ́ni ní tẹmpili, ẹnikẹ́ni kò sì mú un; nítorí wákàtí rẹ̀ kò tí ì dé.
21 O rĩngĩ Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Nĩngwĩthiĩra, na inyuĩ nĩmũkanjaria no mũgaakua mũrĩ o mehia-inĩ manyu. Kũrĩa ngũthiĩ inyuĩ mũtingĩhota gũũka.”
Nítorí náà ó tún wí fún wọn pé, “Èmi ń lọ, ẹ̀yin yóò sì wá mi, ẹ ó sì kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, ibi tí èmi gbé ń lọ, ẹ̀yin kì yóò lè wá.”
22 Ũhoro ũcio ũgĩtũma Ayahudi morie atĩrĩ, “Kaĩ ekwĩyũraga? Hihi nĩkĩo aroiga atĩ, ‘Kũrĩa ngũthiĩ mũtingĩhota gũũka’?”
Nítorí náà àwọn Júù wí pé, “Òun ó ha pa ara rẹ̀ bí? Nítorí tí ó wí pé, ‘Ibi tí èmi gbé ń lọ, ẹ̀yin kì yóò lè wá’?”
23 Nowe akĩmeera atĩrĩ, “Inyuĩ mũrĩ a gũkũ thĩ, niĩ nyumĩte Igũrũ.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ìsàlẹ̀ wá; èmi ti òkè wá; ẹ̀yin jẹ́ ti ayé yìí; èmi kì í ṣe ti ayé yìí.
24 Inyuĩ mũrĩ a thĩ-ĩno; no niĩ ndirĩ wa thĩ-ĩno. Ndamwĩrire atĩ mũgaakua mũrĩ o mehia-inĩ manyu; mũngĩrega gwĩtĩkia ũrĩa njugaga atĩ niĩ nĩ niĩ we, ti-itherũ mũgaakua mũrĩ o mehia-inĩ manyu.”
Nítorí náà ni mo ṣe wí fún yín pé, ẹ ó kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, nítorí bí kò ṣe pé ẹ bá gbàgbọ́ pé èmi ni, ẹ ó kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín.”
25 Nao makĩmũũria atĩrĩ, “Wee nĩwe ũ.” Nake Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Niĩ nĩ niĩ o ũrĩa ndũũrĩte ndĩmwĩraga kuuma o kĩambĩrĩria.
Nítorí náà wọ́n wí fún un pé, “Ta ni ìwọ jẹ́?” Jesu sì wí fún un pé, “Èmi ni èyí tí mo ti wí fún yín ní àtètèkọ́ṣe.
26 Ndĩ na maũndũ maingĩ ingiuga ma kũmũciirithia namo. No ũrĩa wandũmire nĩ mwĩhokeku, naguo ũrĩa njiguĩte kuuma kũrĩ we nĩguo njĩĩraga kĩrĩndĩ.”
Mo ní ohun púpọ̀ láti sọ, àti láti ṣe ìdájọ́ nípa yín, ṣùgbọ́n olóòtítọ́ ni ẹni tí ó rán mi, ohun tí èmi sì ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá, wọ̀nyí ni èmi ń sọ fún aráyé.”
27 Nao matiigana kũmenya atĩ aameeraga ũhoro wa Ithe.
Kò yé wọn pé ti Baba ni ó ń sọ fún wọn.
28 Nĩ ũndũ ũcio Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Mwarĩkia kwambararia Mũrũ wa Mũndũ-rĩ, nĩguo mũkamenya ũrĩa njugaga atĩ niĩ nĩ niĩ we, na atĩ gũtirĩ ũndũ njĩkaga ndĩĩrĩte, no njaragia o ũrĩa Baba andutĩte.
Lẹ́yìn náà Jesu wí fún wọn pé, “Nígbà tí ẹ mọ̀ pé, nígbà tí ẹ bá gbé Ọmọ Ènìyàn sókè, nígbà náà ni ẹ ó mọ̀ pé èmi ni àti pé èmi kò dá ohunkóhun ṣe fún ara mi, ṣùgbọ́n bí Baba ti kọ́ mi, èmí ń sọ nǹkan wọ̀nyí.
29 Nake ũrĩa wandũmire arĩ hamwe na niĩ; ndandigĩte ndĩ nyiki, nĩgũkorwo hĩndĩ ciothe njĩkaga maũndũ o marĩa mamũkenagia.”
Ẹni tí ó rán mí sì ń bẹ pẹ̀lú mi, kò fi mí sílẹ̀ ní èmi nìkan; nítorí tí èmi ń ṣe ohun tí ó wù ú nígbà gbogbo.”
30 O akĩaragia-rĩ, andũ aingĩ makĩmwĩtĩkia.
Bí ó ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí, ọ̀pọ̀ ènìyàn gbà á gbọ́.
31 Nake Jesũ akĩĩra Ayahudi arĩa maamwĩtĩkĩtie atĩrĩ, “Mũngĩrũmia ũrutani wakwa-rĩ, mũrĩ arutwo akwa kũna.
Nítorí náà Jesu wí fún àwọn Júù tí ó gbà á gbọ́, pé, “Bí ẹ bá tẹ̀síwájú nínú ọ̀rọ̀ mi ẹ ó jẹ́ ọmọ-ẹ̀yìn mi nítòótọ́.
32 Nĩ mũkaamenya ũhoro wa ma, naguo ũhoro ũcio wa ma nĩ ũkaamũkũũra.”
Ẹ ó sì mọ òtítọ́, òtítọ́ yóò sì sọ yín di òmìnira.”
33 Nao makĩmũcookeria makĩmwĩra atĩrĩ, “Ithuĩ tũrĩ a rũciaro rwa Iburahĩmu, na tũtirĩ twatuĩka ngombo cia mũndũ o na ũ. Ũngĩkiuga atĩa atĩ nĩtũgakũũrwo?”
Wọ́n dá a lóhùn pé, “Irú-ọmọ Abrahamu ni àwa jẹ́, àwa kò sì ṣe ẹrú fún ẹnikẹ́ni rí láé; ìwọ ha ṣe wí pé, ‘Ẹ ó di òmìnira’?”
34 Nake Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Ngũmwĩra atĩrĩ o ma, mũndũ o wothe wĩhagia nĩ ngombo ya mehia.
Jesu dá wọn lóhùn pé, “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá ń dẹ́ṣẹ̀, ẹrú ẹ̀ṣẹ̀ ni.
35 No rĩrĩ, ngombo ti ya gũtũũra mũciĩ nginya tene no mũriũ wa mwene mũciĩ nĩ wa gũtũũra mũciĩ nginya tene. (aiōn )
Ẹrú kì í sì í gbé ilé títí láé, ọmọ ní ń gbé ilé títí láé. (aiōn )
36 Nĩ ũndũ ũcio Mũrũ wa Ngai angĩkamũkũũra-rĩ, nĩmũgakũũrwo kũna.
Nítorí náà, bí Ọmọ bá sọ yín di òmìnira ẹ ó di òmìnira nítòótọ́.
37 Nĩnjũũĩ mũrĩ a rũciaro rwa Iburahĩmu, no nĩmwĩharĩirie kũnjũraga, tondũ ũhoro wakwa ndũrĩ na ũikaro thĩinĩ wanyu.
Mo mọ̀ pé irú-ọmọ Abrahamu ni ẹ̀yin jẹ́; ṣùgbọ́n ẹ ń wá ọ̀nà láti pa mí nítorí ọ̀rọ̀ mi kò rí ààyè nínú yín. Jesu sọ ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ nípa ara rẹ̀.
38 Niĩ ndĩramwĩra maũndũ marĩa nyonete harĩ Baba, na inyuĩ mwĩkaga maũndũ marĩa mũiguĩte kuuma kũrĩ ithe wanyu.”
Ohun tí èmi ti rí lọ́dọ̀ Baba ni mo sọ, ẹ̀yin pẹ̀lú sì ń ṣe èyí tí ẹ̀yin ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ baba yín.”
39 Nao makĩmũcookeria atĩrĩ, “Iburahĩmu nĩwe ithe witũ.” Nake Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Mũngĩrĩ ciana cia Iburahĩmu-rĩ, nĩ mũngĩĩkaga maũndũ marĩa Iburahĩmu eekaga.
Wọ́n dáhùn, wọ́n sì wí fún un pé, “Abrahamu ni baba wa!” Jesu wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ìbá ṣe iṣẹ́ Abrahamu.
40 Ũrĩa kũrĩ nĩ atĩ, inyuĩ nĩmũtuĩte itua rĩa kũnjũraga, o niĩ mũndũ ũrĩa ũmũheete ũhoro ũrĩa wa ma, o ũrĩa ndaiguire kuuma kũrĩ Ngai. Ũguo tiguo Iburahĩmu eekaga.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ̀yin ń wá ọ̀nà láti pa mí, ẹni tí ó sọ òtítọ́ fún yín, èyí tí mo ti gbọ́ lọ́dọ̀ Ọlọ́run, Abrahamu kò ṣe èyí.
41 Inyuĩ mũreka maũndũ marĩa ithe wanyu ekaga.” Nao makĩmũkararia makĩmwĩra atĩrĩ, “Ithuĩ tũtirĩ ciana ciumanĩte na ũtharia. Ithuĩ tũrĩ na Baba ũmwe tu, na nĩwe Ngai.”
Ẹ̀yin ń ṣe iṣẹ́ baba yín.” Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “a kò bí wa nípa panṣágà, a ní Baba kan, èyí sì ni Ọlọ́run.”
42 Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Ngai angĩrĩ Ithe wanyu-rĩ, no mũnyende, nĩgũkorwo ndoimire kũrĩ Ngai, na rĩu ndĩ gũkũ. Ti niĩ mwene ndĩĩtũmĩte, no nĩwe wandũmire.
Jesu wí fún wọn pé, “Ìbá ṣe pé Ọlọ́run ni Baba yín, ẹ̀yin ìbá fẹ́ràn mi, nítorí tí èmi ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run jáde, mo sì wá; bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì wá fún ara mi, ṣùgbọ́n òun ni ó rán mi.
43 Mũraga gũtaũkĩrwo nĩ ũrĩa ndĩroiga nĩkĩ? Tondũ mũtirahota kũmenya ũhoro ũrĩa ndĩraria.
Èéṣe tí èdè mi kò fi yé yín? Nítorí ẹ kò lè gbọ́ ọ̀rọ̀ mi.
44 Inyuĩ mũrĩ ciana cia ithe wanyu, Mũcukani, na mwendaga kũhingia merirĩria ma ithe wanyu. We aarĩ mũũragani kuuma o kĩambĩrĩria. Ndathingataga ũhoro wa ma, nĩgũkorwo gũtirĩ ũhoro wa ma thĩinĩ wake. Rĩrĩa ekũheenania, aaragia rũthiomi rwake, tondũ we nĩ mũheenania, na nĩwe ithe wa maheeni.
Ti èṣù baba yin ni ẹ̀yin jẹ́, ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ baba yín ni ẹ sì ń fẹ́ ṣe. Apànìyàn ni òun jẹ́ láti àtètèkọ́ṣe, kò sì dúró nínú òtítọ́; nítorí tí kò sí òtítọ́ nínú rẹ̀. Nígbà tí ó bá ń ṣèké, nínú ohun tirẹ̀ ni ó ń sọ nítorí èké ni, àti baba èké.
45 No tondũ njaragia ũhoro wa ma-rĩ, mũtinjĩtĩkagia.
Ṣùgbọ́n nítorí tí èmi ń sọ òtítọ́ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbà mí gbọ́.
46 Nĩ kũrĩ mũndũ ũmwe wanyu ũngĩonania atĩ ndĩ mwĩhia? Angĩkorwo ndĩraria ũhoro wa ma-rĩ, mũregaga kũnjĩtĩkia nĩkĩ?
Ta ni nínú yín tí ó ti dá mi lẹ́bi ẹ̀ṣẹ̀? Bí mo bá ń ṣọ òtítọ́, èéṣe tí ẹ̀yin kò fi gbà mí gbọ́?
47 Ũrĩa ũrĩ wa Ngai nĩaiguaga ũrĩa Ngai oigaga. Kĩrĩa kĩgiragia mũmũigue nĩ tondũ mũtirĩ a Ngai.”
Ẹni tí ń ṣe ti Ọlọ́run, a máa gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, nítorí èyí ni ẹ̀yin kò ṣe gbọ́, nítorí ẹ̀yin kì í ṣe ti Ọlọ́run.”
48 Nao Ayahudi makĩmũcookeria atĩrĩ, “Githĩ tũtirĩ na kĩhooto gĩa kuuga atĩ wee ũrĩ Mũsamaria na ũrĩ na ndaimono?”
Àwọn Júù dáhùn wọ́n sì wí fún un pé, “Àwa kò wí nítòótọ́ pé, ará Samaria ni ìwọ jẹ́, àti pé ìwọ ní ẹ̀mí èṣù?”
49 Nake Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Niĩ ndirĩ na ndaimono, no nĩndĩĩte Baba, no inyuĩ mũtindĩĩte.
Jesu sì dáhùn pé, “Èmi kò ní ẹ̀mí èṣù, ṣùgbọ́n èmi ń bu ọlá fún Baba mi, ẹ̀yin kò sì bu ọlá fún mi.
50 Ndirecarĩria ũgooci wakwa niĩ mwene, no nĩ harĩ na ũmwe ũrĩa ũũcaragia, na nĩwe mũtuanĩri ciira.
Èmi kò wá ògo ara mi, ẹnìkan ń bẹ tí ó ń wá a tí yóò sì ṣe ìdájọ́.
51 Ngũmwĩra atĩrĩ na ma, mũndũ o wothe angĩrũmia kiugo gĩakwa, ndarĩ hĩndĩ akona gĩkuũ.” (aiōn )
Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, bí ẹnìkan bá pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, kì yóò rí ikú láéláé.” (aiōn )
52 Ayahudi maigua ũguo, makĩgũthũka makĩmwĩra atĩrĩ, “Rĩu nĩtwamenya atĩ ũrĩ na ndaimono. Iburahĩmu nĩakuire o na anabii magĩkua, no wee ũroiga atĩ mũndũ o wothe angĩrũmia kiugo gĩaku, ndagacama gĩkuũ. (aiōn )
Àwọn Júù wí fún un pé, “Nígbà yìí ni àwa mọ̀ pé ìwọ ní ẹ̀mí èṣù. Abrahamu kú, àti àwọn wòlíì; ìwọ sì wí pé, ‘Bí ẹnìkan bá pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, kì yóò tọ́ ikú wò láéláé.’ (aiōn )
53 Wee ũkĩrĩ mũnene gũkĩra ithe witũ Iburahĩmu? We nĩakuire o na anabii magĩkua. Kaĩ ũreciiria we ũrĩ ũ?”
Ìwọ ha pọ̀ ju Abrahamu Baba wa lọ, ẹni tí ó kú? Àwọn wòlíì sì kú, ta ni ìwọ ń fi ara rẹ pè?”
54 Nake Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Ingĩĩgooca-rĩ, kwĩgooca gwakwa nĩ gwa tũhũ. Baba, ũrĩa muugaga atĩ nĩwe Ngai wanyu nĩwe ũngoocithagia.
Jesu dáhùn wí pé, “Bí mo bá yin ara mi lógo, ògo mi kò jẹ́ nǹkan, Baba mi ni ẹni tí ń yìn mí lógo, ẹni tí ẹ̀yin wí pé, Ọlọ́run yín ní i ṣe.
55 O na gũtuĩka mũtimũũĩ, niĩ nĩndĩmũũĩ. Ingiuga atĩ ndimũũĩ, ingĩtuĩka wa maheeni ta inyuĩ, no nĩndĩmũũĩ na nĩnũmĩtie kiugo gĩake.
Ẹ kò sì mọ̀ ọ́n, ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, bí mo bá sì wí pé, èmi kò mọ̀ ọ́n, èmi yóò di èké gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin, ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, mo sì pa ọ̀rọ̀ rẹ̀ mọ́.
56 Ithe wanyu Iburahĩmu nĩakenaga atĩ nĩakona mũthenya wakwa; na nĩawonire na agĩcanjamũka.”
Abrahamu baba yín yọ̀ láti rí ọjọ́ mi, ó sì rí i, ó sì yọ̀.”
57 Nao Ayahudi makĩmwĩra atĩrĩ, “Wee o na ndũkinyĩtie mĩaka mĩrongo ĩtano, na ũkoiga atĩ nĩwonete Iburahĩmu!”
Nítorí náà, àwọn Júù wí fún un pé, “Ọdún rẹ kò ì tó àádọ́ta, ìwọ sì ti rí Abrahamu?”
58 Nake Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Ngũmwĩra atĩrĩ na ma, Iburahĩmu atanaciarwo, Niĩ ndũire!”
Jesu sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kí Abrahamu tó wà, èmi ti wa.”
59 Maigua ũguo makĩoya mahiga mamũhũũre namo nyuguto, no Jesũ akĩĩhitha, akiuma kũu hekarũ-inĩ.
Nítorí náà wọ́n gbé òkúta láti sọ lù ú, ṣùgbọ́n Jesu fi ara rẹ̀ pamọ́, ó sì jáde kúrò ní tẹmpili.