< Johana 7 >
1 Thuutha ũcio, Jesũ nĩaceerangire Galili, nĩ ũndũ ndendaga gũthiĩ Judea tondũ Ayahudi akuo nĩmamũcaragia mamũũrage.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Jesu ń rìn ní Galili, nítorí tí kò fẹ́ rìn ní Judea, nítorí àwọn Júù ń wá a láti pa.
2 No hĩndĩ ĩrĩa Gĩathĩ gĩa Ithũnũ kĩa Ayahudi gĩakuhĩrĩirie-rĩ,
Àjọ àwọn Júù tí í ṣe àjọ àgọ́ súnmọ́ etílé tan.
3 ariũ a nyina na Jesũ makĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩwagĩrĩirwo uume gũkũ ũthiĩ Judea, nĩguo arutwo aku mone ciama iria ũringaga.
Nítorí náà, àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Lọ kúrò níhìn-ín yìí, kí o sì lọ sí Judea, kí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ pẹ̀lú lè fi iṣẹ́ rẹ hàn fún aráyé.
4 Gũtirĩ mũndũ wendaga kũmenyeka nĩ andũ ũhithaga ũrĩa areeka. Na tondũ nĩũreeka maũndũ maya-rĩ, wĩonanie kũrĩ kĩrĩndĩ.”
Nítorí pé kò sí ẹnikẹ́ni tí í ṣe ohunkóhun níkọ̀kọ̀, tí òun tìkára rẹ̀ sì ń fẹ́ kí a mọ òun ní gbangba. Bí ìwọ bá ń ṣe nǹkan wọ̀nyí, fi ara rẹ hàn fún aráyé.”
5 Nĩgũkorwo o na ariũ a nyina matiamwĩtĩkĩtie.
Nítorí pé àwọn arákùnrin rẹ̀ pàápàá kò tilẹ̀ gbà á gbọ́.
6 Nĩ ũndũ ũcio, Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Ihinda rĩakwa rĩrĩa rĩagĩrĩire rĩtirĩ rĩrakinya; no harĩ inyuĩ ihinda o rĩothe nĩrĩagĩrĩire.
Nítorí náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Àkókò gan an fún mi kò tí ì dé; fún ẹ̀yin, gbogbo àkókò ni ó dára fún yín.
7 Andũ a gũkũ thĩ matingĩmũthũũra, no niĩ nĩmathũire tondũ nĩnyumbũraga atĩ ũrĩa mekaga nĩ ũũru.
Ayé kò lè kórìíra yín; ṣùgbọ́n èmi ni ó kórìíra, nítorí tí mo jẹ́rìí gbé é pé, iṣẹ́ rẹ̀ burú.
8 Inyuĩ thiĩi Gĩathĩ-inĩ. Niĩ ndikwamba kwambata Gĩathĩ-inĩ kĩu, nĩgũkorwo ihinda rĩakwa rĩrĩa rĩagĩrĩru rĩtirĩ rĩrakinya.”
Ẹ̀yin ẹ gòkè lọ sí àjọ yìí, èmi kì yóò tí ì gòkè lọ sí àjọ yìí; nítorí tí àkókò mi kò ì tí ì dé.”
9 Na aarĩkia kuuga ũguo, agĩikara kũu Galili.
Nígbà tí ó ti sọ nǹkan wọ̀nyí fún wọn tan, ó dúró ní Galili síbẹ̀.
10 No rĩrĩ, thuutha wa ariũ a nyina gũthiĩ Gĩathĩ-inĩ kĩu, o nake agĩcooka agĩthiĩ, no ndaathiire akĩmenyekaga, no aathiire na hitho.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ gòkè lọ tan, nígbà náà ni òun sì gòkè lọ sí àjọ náà pẹ̀lú, kì í ṣe ní gbangba, ṣùgbọ́n bí ẹni pé níkọ̀kọ̀.
11 Na rĩrĩ, kũu Gĩathĩ-inĩ-rĩ, Ayahudi nĩmamũcaragia, makĩũranagia atĩrĩ, “Mũndũ ũcio arĩ ha?”
Nígbà náà ni àwọn Júù sì ń wá a kiri nígbà àjọ wí pé, “Níbo ni ó wà?”
12 Kũu mũingĩ-inĩ guothe andũ nĩmaragia na mĩheehũ ũhoro wake. Amwe makoiga atĩrĩ, “Mũndũ ũcio nĩ mũndũ mwega.” Nao arĩa angĩ makoiga atĩrĩ, “Aca, mũndũ ũcio nĩaheenagia andũ.”
Ìkùnsínú púpọ̀ sì wà láàrín àwọn ìjọ ènìyàn nítorí rẹ̀, nítorí àwọn kan wí pé, “Ènìyàn rere ní í ṣe.” Àwọn mìíràn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n òun ń tan ènìyàn jẹ ni.”
13 No gũtirĩ mũndũ ũngĩaririe ũhoro wake akĩiguagwo nĩ ũndũ wa gwĩtigĩra Ayahudi.
Ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó sọ̀rọ̀ rẹ̀ ní gbangba nítorí ìbẹ̀rù àwọn Júù.
14 Gĩathĩ gĩakinya gatagatĩ-rĩ, Jesũ akĩambata agĩthiĩ nja-inĩ cia hekarũ, akĩambĩrĩria kũrutana.
Nígbà tí àjọ dé àárín; Jesu gòkè lọ sí tẹmpili ó sì ń kọ́ni.
15 Nao Ayahudi makĩgega, makĩũrania atĩrĩ, “Mũndũ ũyũ aamenyeire maũndũ maya kũ, na ndathomete?”
Ẹnu sì ya àwọn Júù, wọ́n wí pé, “Ọkùnrin yìí ti ṣe mọ ìwé, nígbà tí kò kọ́ ẹ̀kọ́?”
16 Nake Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Ũrutani ũrĩa ndutanaga ti wakwa niĩ mwene. Uumaga kũrĩ ũrĩa wandũmire.
Jesu dáhùn, ó sì wí pé, “Ẹ̀kọ́ mi kì í ṣe tèmi, bí kò ṣe ti ẹni tí ó rán mi.
17 Mũndũ o wothe angĩenda gwĩka wendi wa Ngai, ũcio nĩarĩĩmenyaga kana ũrutani wakwa uumaga kũrĩ Ngai, kana njaragia ũhoro wakwa mwene.
Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀ yóò mọ̀ ní ti ẹ̀kọ́ náà, bí ìbá ṣe ti Ọlọ́run, tàbí bí èmi bá sọ ti ara mi.
18 Mũndũ ũrĩa waragia ũhoro wake we mwene eekaga ũguo nĩgeetha egoocithie we mwene, no ũrĩa ũrutaga wĩra nĩgeetha agoocithie ũrĩa ũmũtũmĩte nĩ mũndũ wa ma; gũtirĩ ũndũ wa maheeni ũmũkoniĩ.
Ẹni tí ń sọ ti ara rẹ̀ ń wá ògo ara rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹni tí ń wá ògo ẹni tí ó rán an, òun ni olóòtítọ́, kò sì sí àìṣòdodo nínú rẹ̀.
19 Githĩ Musa ndaamũheire watho? No gũtirĩ o na ũmwe wanyu ũmenyagĩrĩra watho. Mũrageria kũnjũraga nĩkĩ?”
Mose kò ha fi òfin fún yín, kò sí ẹnikẹ́ni nínú yín tí ó pa òfin náà mọ́? Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá ọ̀nà láti pa mí?”
20 Naguo mũingĩ wa andũ ũkĩmũcookeria atĩrĩ, “Wee ũrĩ na ndaimono. Nũũ ũrageria gũkũũraga?”
Ìjọ ènìyàn dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Ìwọ ní ẹ̀mí èṣù, ta ni ń wá ọ̀nà láti pa ọ́?”
21 Nake Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Ndaaringire kĩama kĩmwe, na inyuĩ inyuothe mũkĩgega.
Jesu dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Kìkì iṣẹ́ àmì kan ni mo ṣe, ẹnu sì ya gbogbo yín.
22 No rĩrĩ, tondũ Musa nĩamũheire ũhoro wa kũrua (o na gũtuĩka ũhoro ũcio ndwoimire kũrĩ Musa, no woimĩte kũrĩ maithe manyu ma tene-rĩ), inyuĩ nĩ mũruithagia mwana mũthenya wa Thabatũ.
Síbẹ̀, nítorí pé Mose fi ìkọlà fún yín (kò tilẹ̀ kúkú wá láti ọ̀dọ̀ Mose bí kò ṣe láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá yín); nítorí náà ẹ sì ń kọ ènìyàn ní ilà ní ọjọ́ ìsinmi.
23 Rĩu angĩkorwo mwana no aruithio mũthenya wa Thabatũ nĩgeetha watho wa Musa ndũgathaahio-rĩ, mũrakĩndakarĩra nĩkĩ nĩkũhonia mũndũ mũthenya wa Thabatũ?
Bí ènìyàn bá ń gba ìkọlà ní ọjọ́ ìsinmi, kí a má ba à rú òfin Mose, ẹ ha ti ṣe ń bínú sí mi, nítorí mo mú ènìyàn kan láradá ní ọjọ́ ìsinmi?
24 Tigai gũtuanagĩra ciira na ũrĩa mũndũ atariĩ, tuanagĩrai ciira na kĩhooto.”
Ẹ má ṣe ìdájọ́ nípa ti ara, ṣùgbọ́n ẹ máa ṣe ìdájọ́ òdodo.”
25 Tondũ ũcio andũ amwe a kũu Jerusalemu makĩambĩrĩria kũũrania atĩrĩ, “Githĩ ũyũ tiwe mũndũ ũrĩa marageria kũũraga?
Nígbà náà ni àwọn kan nínú àwọn ará Jerusalẹmu wí pé, “Ẹni tí wọ́n ń wá ọ̀nà láti pa kọ́ yìí?
26 Na rĩu araaria atekwĩhitha, na matirĩ ũndũ maramwĩra. Kaĩ anene mamenyete kũna atĩ ũyũ nĩwe Kristũ?
Sì wò ó, ó ń sọ̀rọ̀ ní gbangba, wọn kò sì wí nǹkan kan sí i. Àwọn olórí ha mọ̀ nítòótọ́ pé, èyí ni Kristi náà?
27 No ithuĩ nĩtũũĩ kũrĩa mũndũ ũyũ oimĩte; rĩrĩa Kristũ agooka, gũtirĩ mũndũ ũkaamenya kũrĩa agaakorwo oimĩte.”
Ṣùgbọ́n àwa mọ ibi tí ọkùnrin yí gbé ti wá, ṣùgbọ́n nígbà tí Kristi bá dé, kò sí ẹni tí yóò mọ ibi tí ó gbé ti wá.”
28 Tondũ ũcio Jesũ, o akĩrutanaga kũu hekarũ-inĩ, akĩanĩrĩra, akiuga atĩrĩ; “Ĩĩ nĩguo, nĩmũnjũũĩ, na mũkamenya kũrĩa nyumĩte. Ndiũkĩte gũkũ nĩ ũndũ wakwa niĩ mwene, no ũrĩa wandũmire nĩ wa ma. Inyuĩ mũtimũũĩ,
Nígbà náà ni Jesu kígbe ní tẹmpili bí ó ti ń kọ́ni, wí pé, “Ẹ̀yin mọ̀ mí, ẹ sì mọ ibi tí mo ti wá, èmi kò sì wá fún ara mi, ṣùgbọ́n olóòtítọ́ ni ẹni tí ó rán mi, ẹni tí ẹ̀yin kò mọ̀.
29 no niĩ nĩndĩmũũĩ, tondũ nyumĩte kũrĩ we, na nĩwe wandũmire.”
Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ̀ ni mo ti wá, òun ni ó rán mi.”
30 Maigua ũguo makĩgeria kũmũnyiita, no gũtirĩ o na ũmwe wamũhutirie, tondũ ihinda rĩake rĩtiarĩ ikinyu.
Nítorí náà wọ́n ń wá ọ̀nà à ti mú un, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbé ọwọ́ lé e, nítorí tí wákàtí rẹ̀ kò tí ì dé.
31 O na kũrĩ o ũguo, andũ aingĩ makĩmwĩtĩkia. Makiuga atĩrĩ, “Hĩndĩ ĩrĩa Kristũ agooka-rĩ, nĩakaringa ciama nyingĩ gũkĩra mũndũ ũyũ?”
Ọ̀pọ̀ nínú ìjọ ènìyàn sì gbà á gbọ́, wọ́n sì wí pé, “Nígbà tí Kristi náà bá dé, yóò ha ṣe iṣẹ́ àmì jù wọ̀nyí, tí ọkùnrin yìí ti ṣe lọ?”
32 Afarisai makĩigua andũ makĩheehana maũndũ ta macio mamũkoniĩ. Nao athĩnjĩri-Ngai arĩa anene na Afarisai magĩtũma thigari cia hekarũ ikamũnyiite.
Àwọn Farisi gbọ́ pé, ìjọ ènìyàn ń sọ nǹkan wọ̀nyí lábẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀; àwọn Farisi àti àwọn olórí àlùfáà sì rán àwọn oníṣẹ́ lọ láti mú un.
33 Nake Jesũ akiuga atĩrĩ, “Niĩ ngũkorwo na inyuĩ o ihinda inini, njooke thiĩ kũrĩ ũrĩa wandũmire.
Nítorí náà Jesu wí fún wọn pé, “Níwọ́n ìgbà díẹ̀ ni èmi yóò wà pẹ̀lú yín, èmi yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó rán mi.
34 Inyuĩ mũkaanjaria, no mũtikanyona; na kũrĩa ngaakorwo, mũtikahota gũkinya.”
Ẹ̀yin yóò wá mi, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi, àti ibi tí èmi bá wà, ẹ̀yin kì yóò le wà.”
35 Ayahudi makĩĩrana atĩrĩ, “Mũndũ ũyũ nĩ kũ arenda gũthiĩ, kũu tũtangĩhota kũmuona? Hihi egũthiĩ kũrĩa andũ aitũ matũũraga mahurunjũkĩte gatagatĩ ka Ayunani, akarute Ayunani ũhoro?
Nítorí náà ni àwọn Júù ń bá ara wọn sọ pé, “Níbo ni ọkùnrin yìí yóò gbé lọ tí àwa kì yóò fi rí i? Yóò ha lọ sí àárín àwọn Helleni tí wọ́n fọ́n káàkiri, kí ó sì máa kọ́ àwọn Helleni bí.
36 Nĩ atĩa ekwendaga kuuga, rĩrĩa oigire atĩ, ‘Mũkaanjaria no mũtikanyona’ na ‘kũrĩa ngaakorwo mũtikahota gũkinya’?”
Ọ̀rọ̀ kín ni èyí tí ó sọ yìí, ‘Ẹ̀yin yóò wá mi, ẹ kì yóò sì rí mi,’ àti ‘Ibi tí èmi bá wà ẹ̀yin kì yóò le wà’?”
37 Mũthenya wa mũthia, na ũrĩa warĩ mũnene wa Gĩathĩ kĩu-rĩ, Jesũ akĩrũgama, akĩanĩrĩra na mũgambo mũnene, akiuga atĩrĩ, “Mũndũ ũrĩa ũnyootiĩ-rĩ, nĩoke harĩ niĩ anyue.
Lọ́jọ́ tó kẹ́yìn, tí í ṣe ọjọ́ ńlá àjọ, Jesu dúró, ó sì kígbe wí pé, “Bí òǹgbẹ bá ń gbẹ ẹnikẹ́ni, kí ó tọ̀ mí wá, kí ó sì mu.
38 Ũrĩa wothe ũnjĩtĩkĩtie, thĩinĩ wake nĩkũriumaga njũũĩ cia maaĩ marĩ muoyo, o ta ũrĩa Maandĩko moigĩte.”
Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà mí gbọ́ gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́ ti wí, láti inú rẹ̀ ni odò omi ìyè yóò ti máa sàn jáde wá.”
39 Akĩaria ũguo aaragia ũhoro wa Roho, ũrĩa arĩa maamwĩtĩkĩtie makaheo thuutha-inĩ. Amu hĩndĩ ĩyo Roho ndaaheanĩtwo, nĩgũkorwo Jesũ ndaagoocithĩtio.
Ṣùgbọ́n ó sọ èyí ní ti ẹ̀mí, tí àwọn tí ó gbà á gbọ́ ń bọ̀ wá gbà, nítorí a kò tí ì fi Èmí Mímọ́ fún ni; nítorí tí a kò tí ì ṣe Jesu lógo.
40 Hĩndĩ ĩrĩa andũ maiguire ciugo ciake, amwe makiuga atĩrĩ, “Ti-itherũ mũndũ ũyũ nĩ we Mũnabii ũrĩa.”
Nítorí náà, nígbà tí ọ̀pọ̀ nínú ìjọ ènìyàn gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, wọ́n wí pé, “Lóòótọ́ èyí ni wòlíì náà.”
41 Arĩa angĩ makiuga atĩrĩ, “Ũyũ nĩwe Kristũ.” Nao angĩ makĩũria atĩrĩ, “Kwahoteka atĩa Kristũ oime Galili?
Àwọn mìíràn wí pé, “Èyí ni Kristi náà.” Ṣùgbọ́n àwọn kan wí pé kínla, “Kristi yóò ha ti Galili wá bí?
42 Githĩ Maandĩko matiugĩte atĩ Kristũ akoima rũciaro-inĩ rwa Daudi, na oime Bethilehemu itũũra rĩrĩa Daudi aatũũraga?”
Ìwé mímọ́ kò ha wí pé, Kristi yóò ti inú irú-ọmọ Dafidi wá, àti Bẹtilẹhẹmu, ìlú tí Dafidi ti wá?”
43 Nĩ ũndũ ũcio gũkĩgĩa na nyamũkano gatagatĩ-inĩ ka andũ acio nĩ ũndũ wa Jesũ.
Bẹ́ẹ̀ ni ìyapa wà láàrín ìjọ ènìyàn nítorí rẹ̀.
44 Amwe nĩmendaga kũmũnyiita, no gũtirĩ o na ũmwe wamũhutirie.
Àwọn mìíràn nínú wọn sì fẹ́ láti mú un; ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbé ọwọ́ lé e.
45 Marigĩrĩrio-inĩ arangĩri a hekarũ magĩcooka kũrĩ athĩnjĩri-Ngai arĩa anene na Afarisai, nao makĩmooria atĩrĩ, “Mwaga kũmũrehe nĩkĩ?”
Ní ìparí, àwọn ẹ̀ṣọ́ tẹmpili padà tọ àwọn olórí àlùfáà àti àwọn Farisi lọ, wọ́n sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi mú un wá?”
46 Arangĩri acio magĩcookia atĩrĩ, “Gũtirĩ mũndũ o na ũmwe ũrĩ waria ta ũrĩa mũndũ ũcio aragia.”
Àwọn ẹ̀ṣọ́ dáhùn wí pé, “Kò sí ẹni tí ó tí ì sọ̀rọ̀ bí ọkùnrin yìí rí!”
47 Nao Afarisai makĩmooria atĩrĩ, “Mũroiga atĩ o na inyuĩ nĩamũheenetie?
Nítorí náà àwọn Farisi dá wọn lóhùn pé, “A ha tan ẹ̀yin jẹ pẹ̀lú bí?
48 Nĩ kũrĩ mũnene o na ũmwe kana Mũfarisai ũmwĩtĩkĩtie?
Ǹjẹ́ nínú àwọn ìjòyè, tàbí àwọn Farisi ti gbà á gbọ́ bí?
49 Aca! No gĩkundi gĩkĩ kĩa andũ matooĩ watho-rĩ, nĩkĩnyiite nĩ kĩrumi.”
Ṣùgbọ́n ìjọ ènìyàn yìí, tí ko mọ òfin di ẹni ìfibú.”
50 Nikodemo, ũrĩa wathiĩte kũrĩ Jesũ mbere ĩyo na aarĩ ũmwe wa gĩkundi kĩao, akĩũria atĩrĩ,
Nikodemu ẹni tí ó tọ Jesu wá lóru rí, tí ó sì jẹ́ ọ̀kan nínú wọn sì sọ fún wọn pé,
51 “Watho witũ nĩũtuagĩra mũndũ ciira ataambĩte gũthikĩrĩrio nĩguo akamenyeka ũrĩa ekĩte?”
“Òfin wa ha ń ṣe ìdájọ́ ènìyàn kí ó tó gbọ́ ti ẹnu rẹ̀ àti kí ó tó mọ ohun tí ó ṣe bí?”
52 Nao makĩmũũria atĩrĩ, “O nawe kaĩ uumĩte Galili? Tuĩria ũhoro, na nĩũkũmenya atĩ mũnabii ndangiuma Galili.”
Wọ́n dáhùn wọ́n sì wí fún un pé, “Ìwọ pẹ̀lú wá láti Galili bí? Wá kiri, kí o sì wò nítorí kò sí wòlíì kan tí ó ti Galili dìde.”
53 (O mũndũ akĩinũka gwake mũciĩ.
Wọ́n sì lọ olúkúlùkù sí ilé rẹ̀.