< Johana 6 >

1 Thuutha wa maũndũ macio, Jesũ akĩringa mũrĩmo ũrĩa ũngĩ wa Iria rĩa Galili (na norĩo rĩĩtagwo Iria rĩa Tiberia),
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Jesu kọjá sí apá kejì Òkun Galili, tí í ṣe Òkun Tiberia.
2 nakĩo kĩrĩndĩ kĩnene kĩa andũ gĩkĩmũrũmĩrĩra tondũ nĩkĩoneete ciama iria aaringĩire andũ arĩa maarĩ arũaru.
Ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, nítorí tí wọ́n rí iṣẹ́ àmì rẹ̀ tí ó ń ṣe lára àwọn aláìsàn.
3 Nake Jesũ akĩambata kĩrĩma-inĩ, agĩikara thĩ marĩ hamwe na arutwo ake.
Jesu sì gun orí òkè lọ, níbẹ̀ ni ó sì gbé jókòó pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
4 Nakĩo Gĩathĩ gĩa Bathaka ya Ayahudi nĩgĩakuhĩrĩirie.
Àjọ ìrékọjá ọdún àwọn Júù sì súnmọ́ etílé.
5 Rĩrĩa Jesũ aarorire akĩona kĩrĩndĩ kĩnene gĩgĩũka kũrĩ we, akĩũria Filipu atĩrĩ, “Tũkũgũra mĩgate kũ andũ aya marĩe?”
Ǹjẹ́ bí Jesu ti gbé ojú rẹ̀ sókè, tí ó sì rí ọ̀pọ̀ ènìyàn wá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó wí fún Filipi pé, “Níbo ni a ó ti ra àkàrà, kí àwọn wọ̀nyí lè jẹ?”
6 Oririe ũguo nĩguo amũgerie, nĩgũkorwo we nĩooĩ ũrĩa egwĩka.
Ó sì sọ èyí láti dán an wò; nítorí tí òun fúnra rẹ̀ mọ ohun tí òun ó ṣe.
7 Nake Filipu akĩmũcookeria atĩrĩ, “Mũcara wa mĩeri ĩnana ndũngĩgũra mĩgate ya kũigana nĩguo o mũndũ arũme kenyũ!”
Filipi dá a lóhùn pé, “Àkàrà igba owó idẹ kò lè tó fún wọn, bí olúkúlùkù wọn kò tilẹ̀ ní í rí ju díẹ̀ bù jẹ.”
8 Nake mũrutwo ũngĩ wake wetagwo Anderea, mũrũ wa nyina na Simoni Petero, akiuga atĩrĩ,
Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Anderu, arákùnrin Simoni Peteru wí fún un pé,
9 “Haha harĩ kahĩĩ karĩ na mĩgate ĩtano ya mũtu wa cairi na thamaki igĩrĩ nini, no ingĩkĩigana atĩa andũ marĩ aingĩ ũũ?”
“Ọmọdékùnrin kan ń bẹ níhìn-ín yìí, tí ó ní ìṣù àkàrà barle márùn-ún àti ẹja wẹ́wẹ́ méjì, ṣùgbọ́n kín ni ìwọ̀nyí jẹ́ láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn wọ̀nyí?”
10 Nake Jesũ akiuga atĩrĩ, “Ĩraai andũ maikare thĩ.” Hau maarĩ haarĩ na nyeki nyingĩ, nao arũme magĩikara thĩ, na maarĩ ta arũme ngiri ithano.
Jesu sì wí pé, “Ẹ mú kí àwọn ènìyàn náà jókòó!” Koríko púpọ̀ sì wá níbẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin náà jókòó; ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún márùn-ún ènìyàn ní iye.
11 Jesũ agĩcooka akĩoya mĩgate ĩyo, agĩcookia ngaatho na akĩgaĩra arĩa maikarĩte thĩ kũringana na mũigana ũrĩa o mũndũ angĩendire. Agĩcooka agĩĩka o ũguo na thamaki.
Jesu sì mú ìṣù àkàrà náà. Nígbà tí ó sì ti dúpẹ́, ó pín wọn fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì pín wọn fún àwọn tí ó jókòó; bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ sì ni ẹja ní ìwọ̀n bí wọ́n ti ń fẹ́.
12 Rĩrĩa othe maarĩire na makĩhũũna, akĩĩra arutwo ake atĩrĩ, “Ũnganiai cienyũ iria ciatigara. Mũtikareke kĩndũ o na kĩrĩkũ kĩũrĩre.”
Nígbà tí wọ́n sì yó, ó wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ẹ kó àjẹkù tí ó kù jọ, kí ohunkóhun má ṣe ṣòfò.”
13 Nĩ ũndũ ũcio magĩciũngania, makĩiyũria ikabũ ikũmi na igĩrĩ na icunjĩ cia mĩgate ĩrĩa ĩtano ya cairi, iria ciatigirio nĩ andũ acio maarĩkia kũrĩa.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kó wọn jọ wọ́n sì fi àjẹkù ìṣù àkàrà barle márùn-ún náà kún agbọ̀n méjìlá, èyí tí àwọn tí ó jẹun jẹ kù.
14 Thuutha wa andũ kuona ciama iria Jesũ aaringĩte, makĩambĩrĩria kuuga atĩrĩ, “Ti-itherũ ũyũ nĩwe mũnabii ũrĩa ũgooka gũkũ thĩ.”
Nítorí náà nígbà tí àwọn ọkùnrin náà rí iṣẹ́ àmì tí Jesu ṣe, wọ́n wí pé, “Lóòótọ́ èyí ni wòlíì náà tí ń bọ̀ wá sí ayé.”
15 Nake Jesũ akĩmenya atĩ nĩmendaga mamũtue mũthamaki wao na hinya, nĩ ũndũ ũcio akĩmeherera o rĩngĩ, akĩambata kĩrĩma-inĩ arĩ wiki.
Nígbà tí Jesu sì wòye pé wọ́n ń fẹ́ wá fi agbára mú òun láti lọ fi jẹ ọba, ó tún padà lọ sórí òkè, òun nìkan.
16 Rĩrĩa gwakinyire hwaĩ-inĩ arutwo ake magĩikũrũka nginya iria-inĩ,
Nígbà tí alẹ́ sì lẹ́, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun.
17 magĩtoonya marikabu, makĩringa iria marorete Kaperinaumu. Hĩndĩ ĩyo kwarĩ nduma, na Jesũ ndaathiĩte kũrĩ o.
Wọ́n sì bọ́ sínú ọkọ̀ ojú omi, wọ́n sì rékọjá Òkun lọ sí Kapernaumu. Ilẹ̀ sì ti ṣú, Jesu kò sì tí ì dé ọ̀dọ̀ wọn.
18 Nĩ kwarĩ na makũmbĩ ma maaĩ tondũ wa rũhuho rũnene rũrĩa rwahurutanaga.
Òkun sì ń ru nítorí ẹ̀fúùfù líle tí ń fẹ́.
19 Na hĩndĩ ĩrĩa maatwarithĩtie marikabu ta kilomita ithano kana ithathatũ, makĩona Jesũ agĩũka kũrĩ marikabu-inĩ agereire maaĩ igũrũ; nao makĩmaka.
Nígbà tí wọ́n wa ọkọ̀ ojú omi tó bí ìwọ̀n ibùsọ̀ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n tàbí ọgbọ̀n, wọ́n rí Jesu ń rìn lórí Òkun, ó sì súnmọ́ ọkọ̀ ojú omi náà; ẹ̀rù sì bà wọ́n.
20 Nowe akĩmeera atĩrĩ, “Nĩ niĩ; tigai gwĩtigĩra.”
Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Èmi ni; ẹ má bẹ̀rù.”
21 Magĩtĩkĩra atoonye thĩinĩ wa marikabu, na kahinda o kau marikabu ĩgĩkinya hũgũrũrũ-inĩ cia kũrĩa maathiiaga.
Nítorí náà wọ́n fi ayọ̀ gbà á sínú ọkọ̀; lójúkan náà ọkọ̀ náà sì dé ilẹ̀ ibi tí wọ́n ń lọ.
22 Mũthenya ũcio ũngĩ, kĩrĩndĩ kĩrĩa kĩarĩ mũrĩmo ũũrĩa ũngĩ wa iria gĩkĩmenya atĩ no marikabu ĩmwe yarĩ ho, na atĩ Jesũ ndaamĩingĩrĩte hamwe na arutwo ake no maathiĩte marĩ oiki.
Ní ọjọ́ kejì nígbà tí àwọn ènìyàn tí ó dúró ní òdìkejì Òkun rí i pé, kò sí ọkọ̀ ojú omi mìíràn níbẹ̀, bí kò ṣe ọ̀kan náà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wọ̀, àti pé Jesu kò bá àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wọ inú ọkọ̀ ojú omi náà, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ nìkan ni ó lọ.
23 No ningĩ gũgĩũka marikabu ingĩ ciumĩte Tiberia ikĩrũgama hakuhĩ na harĩa andũ maarĩĩrĩire mĩgate thuutha wa Mwathani gũcookeria Ngai ngaatho.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkọ̀ ojú omi mìíràn ti Tiberia wá, létí ibi tí wọn gbé jẹ àkàrà, lẹ́yìn ìgbà tí Olúwa ti dúpẹ́.
24 Na rĩrĩa kĩrĩndĩ kĩamenyire atĩ Jesũ kana arutwo ake gũtirĩ warĩ ho, gĩkĩingĩra marikabu icio, gĩgĩthiĩ Kaperinaumu gũcaria Jesũ.
Nítorí náà nígbà tí àwọn ènìyàn rí i pé Jesu tàbí ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kò sí níbẹ̀, àwọn pẹ̀lú wọ ọkọ̀ ojú omi lọ sí Kapernaumu, wọ́n ń wá Jesu.
25 Rĩrĩa maamũkorire mũrĩmo ũũrĩa ũngĩ wa iria makĩmũũria atĩrĩ, “Rabii, ũkinyire gũkũ rĩ?”
Nígbà tí wọ́n sì rí i ní apá kejì Òkun, wọ́n wí fún un pé, “Rabbi, nígbà wo ni ìwọ wá síyìn-ín yìí?”
26 Nake Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Ngũmwĩra atĩrĩ na ma, inyuĩ mũtiranjaria nĩ ũndũ wa ciama iria mũronire, no nĩ ũndũ nĩmũrarĩire mĩgate mũrahũũna.
Jesu dá wọn lóhùn ó sì wí pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún yín. Ẹ̀yin ń wá mi, kì í ṣe nítorí tí ẹ̀yin rí iṣẹ́ àmì, ṣùgbọ́n nítorí ẹ̀yin jẹ àjẹyó ìṣù àkàrà.
27 Tigagai gũtangĩkĩra irio iria ithũkaga, no mwĩtangagei nĩ ũndũ wa irio iria cia gũtũũra nginya muoyo-inĩ wa tene na tene, iria Mũrũ wa Mũndũ akaamũhe. Ũcio nĩwe Ngai Ithe ahũũrĩte mũhũũri wa gwĩtĩkĩrĩka.” (aiōnios g166)
Ẹ má ṣe ṣiṣẹ́ fún oúnjẹ tí ń ṣègbé, ṣùgbọ́n fún oúnjẹ tí ó wà títí di ayé àìnípẹ̀kun, èyí tí Ọmọ Ènìyàn yóò fi fún yín. Nítorí pé òun ni, àní Ọlọ́run Baba ti fi èdìdì dì í.” (aiōnios g166)
28 Magĩcooka makĩmũũria atĩrĩ, “Twagĩrĩirwo nĩ gwĩka atĩa nĩgeetha tũrutage mawĩra marĩa Ngai endaga?”
Nígbà náà ni wọ́n wí fún wọn pé, “Kín ni àwa ó ha ṣe, kí a lè ṣe iṣẹ́ Ọlọ́run?”
29 Nake Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Wĩra wa Ngai nĩ ũyũ: nĩ mwĩtĩkie ũrĩa we atũmĩte.”
Jesu dáhùn, ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni iṣẹ́ Ọlọ́run pé, kí ẹ̀yin gba ẹni tí ó rán an gbọ́.”
30 Nĩ ũndũ ũcio makĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ ciama irĩkũ ũgũtũringĩra tuone nĩguo tũgwĩtĩkie? Ũgwĩka atĩa?
Nígbà náà ni wọ́n wí fún wọn pé, “Iṣẹ́ àmì kín ní ìwọ ń ṣe, tí àwa lè rí, kí a sì gbà ọ́ gbọ́? Iṣẹ́ kín ní ìwọ ṣe?
31 Maithe maitũ ma tene maarĩĩaga mana kũu werũ-inĩ; o ta ũrĩa kwandĩkĩtwo atĩrĩ: ‘Aamaheire mĩgate kuuma igũrũ marĩe.’”
Àwọn baba wa jẹ manna ní aginjù; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, ‘Ó fi oúnjẹ láti ọ̀run wá fún wọn jẹ.’”
32 Nake Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Ngũmwĩra atĩrĩ na ma, ti Musa wamũheire mũgate kuuma igũrũ, no nĩ Baba ũmũheaga mũgate ũrĩa wa ma kuuma igũrũ.
Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kì í ṣe Mose ni ó fi oúnjẹ fún yín láti ọ̀run wá, ṣùgbọ́n Baba mi ni ó fi oúnjẹ òtítọ́ náà fún yín láti ọ̀run wá.
33 Nĩgũkorwo mũgate wa Ngai nĩ ũrĩa ũikũrũkaga kuuma igũrũ akahe kĩrĩndĩ gĩa thĩ muoyo wa tene na tene.”
Nítorí pé oúnjẹ Ọlọ́run ni èyí tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, tí ó sì fi ìyè fún aráyé.”
34 Nao makĩmwĩra atĩrĩ, “Mũthuuri ũyũ, kuuma rĩu tũheage mũgate ũcio.”
Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “Olúwa, máa fún wa ní oúnjẹ yìí títí láé.”
35 Nake Jesũ akiuga atĩrĩ, “Niĩ nĩ niĩ mũgate wa muoyo. Mũndũ ũrĩa ũũkaga kũrĩ niĩ ndakahũũta o na rĩ, na ũrĩa ũnjĩtĩkĩtie ndakanyoota o na rĩ.
Jesu wí fún wọn pé, “Èmi ni oúnjẹ ìyè, ẹnikẹ́ni tí ó bá tọ̀ mí wá, ebi kì yóò pa á; ẹni tí ó bá sì gbà mí gbọ́, òǹgbẹ kì yóò gbẹ ẹ́ mọ́ láé.
36 No rĩrĩ, o ta ũrĩa ndĩmwĩrĩte, nĩmũnyonete, no mũtirĩ mũretĩkia.
Ṣùgbọ́n mo wí fún yín pé, Ẹ̀yin ti rí mi, ẹ kò sì gbàgbọ́.
37 Arĩa othe Baba ahee nĩmarĩũkaga kũrĩ niĩ, na ũrĩa wothe ũgooka kũrĩ niĩ ndikamũingata o na rĩ.
Gbogbo èyí tí Baba fi fún mi, yóò tọ̀ mí wá; ẹni tí ó bá sì tọ̀ mí wá, èmi kì yóò tà á nù, bí ó tí wù kó rí.
38 Nĩgũkorwo ndiikũrũkĩte kuuma igũrũ njũke gwĩka wendi wakwa niĩ mwene, no njũkĩte gwĩka wendi wa ũrĩa wandũmire.
Nítorí èmi sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá, kì í ṣe láti máa ṣe ìfẹ́ ti èmi fúnra mi, bí kò ṣe ìfẹ́ ti ẹni tí ó rán mi.
39 Naguo ũyũ nĩguo wendi wa ũrĩa wandũmire, atĩ ndigaate o na ũmwe wa arĩa othe aaheete, no ngaamariũkia mũthenya wa kũrigĩrĩria.
Èyí sì ni ìfẹ́ Baba tí ó rán mi pé ohun gbogbo tí o fi fún mi, kí èmi má ṣe sọ ọ̀kan nù nínú wọn, ṣùgbọ́n kí èmi lè jí wọn dìde níkẹyìn ọjọ́.
40 Nĩgũkorwo wendi wa Baba nĩ atĩ ũrĩa wothe wonete Mũriũ na akamwĩtĩkia nĩakagĩa na muoyo wa tene na tene, na nĩngamũriũkia mũthenya wa kũrigĩrĩria.” (aiōnios g166)
Èyí sì ni ìfẹ́ ẹni tí ó rán mi, pé ẹnikẹ́ni tí ó bá wo ọmọ, tí ó bá sì gbà á gbọ́, kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun, Èmi ó sì jí i dìde níkẹyìn ọjọ́.” (aiōnios g166)
41 Ayahudi maigua ũguo makĩambĩrĩria kũngʼongʼora nĩ ũndũ wake tondũ nĩoigĩte atĩrĩ, “Niĩ nĩ niĩ mũgate ũrĩa waikũrũkire kuuma igũrũ.”
Nígbà náà ni àwọn Júù ń kùn sí i, nítorí tí ó wí pé, “Èmi ni oúnjẹ tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá.”
42 Makiuga atĩrĩ, “Githĩ ũyũ ti Jesũ mũrũ wa Jusufu, ũrĩa ithe na nyina tũũĩ? Rĩu angĩhota atĩa kuuga atĩ, ‘Niĩ ndaikũrũkire kuuma igũrũ’?”
Wọ́n sì wí pé, “Jesu ha kọ́ èyí, ọmọ Josẹfu, baba àti ìyá ẹni tí àwa mọ̀? Báwo ni ó ṣe wí pé, ‘Èmi ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá’?”
43 Nake Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Tigai kũngʼongʼora gatagatĩ-inĩ kanyu.
Nítorí náà Jesu dáhùn, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe kùn láàrín yín!
44 Gũtirĩ mũndũ ũngĩũka kũrĩ niĩ ataguucĩrĩirio nĩ Baba ũrĩa wandũmire, na niĩ nĩngamũriũkia mũthenya wa kũrigĩrĩria.
Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè wá sọ́dọ̀ mi, bí kò ṣe pé Baba tí ó rán mi fà á, Èmi ó sì jí i dìde níkẹyìn ọjọ́.
45 Nĩ kwandĩkĩtwo maandĩko-inĩ ma Anabii atĩrĩ, ‘Nao othe makaarutwo ũhoro nĩ Ngai.’ Nake ũrĩa wothe ũthikagĩrĩria Baba na akeeruta ũhoro kuuma kũrĩ we, nĩokaga kũrĩ niĩ.
A sá à ti kọ ọ́ nínú ìwé àwọn wòlíì pé, ‘A ó sì kọ́ gbogbo wọn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá,’ nítorí náà ẹnikẹ́ni tí ó bá ti gbọ́, tí a sì ti ọ̀dọ̀ Baba kọ́, òun ni ó ń tọ̀ mí wá.
46 Gũtirĩ mũndũ ũrĩ ona Baba, tiga o ũrĩa uumĩte kũrĩ Ngai; we wiki nowe wonete Baba.
Kì í ṣe pé ẹnìkan ti rí Baba bí kò ṣe ẹni tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, òun ni ó ti rí Baba.
47 Ngũmwĩra atĩrĩ na ma, mũndũ ũrĩa wĩtĩkĩtie arĩ na muoyo wa tene na tene. (aiōnios g166)
Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹni tí ó bá gbà mí gbọ́, ó ní ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios g166)
48 Niĩ nĩ niĩ mũgate wa muoyo.
Èmi ni oúnjẹ ìyè.
49 Maithe manyu ma tene maarĩĩaga mana marĩ werũ-inĩ, na no maakuire.
Àwọn baba yín jẹ manna ní aginjù, wọ́n sì kú.
50 No ũyũ nĩguo mũgate ũrĩa ũikũrũkĩte kuuma igũrũ, ũrĩa mũndũ angĩrĩa na ndakue.
Èyí ni oúnjẹ tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, kí ènìyàn lè máa jẹ nínú rẹ̀ kí ó má sì kú.
51 Niĩ nĩ niĩ mũgate ũrĩa ũrĩ muoyo ũrĩa waikũrũkire kuuma igũrũ. Mũndũ o wothe ũngĩrĩa mũgate ũyũ, nĩagatũũra tene na tene. Mũgate ũyũ nĩ mwĩrĩ wakwa ũrĩa ngũheana nĩ ũndũ wa muoyo wa andũ a gũkũ thĩ.” (aiōn g165)
Èmi ni oúnjẹ ìyè náà tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, bí ẹnikẹ́ni bá jẹ nínú oúnjẹ yìí, yóò yè títí láéláé, oúnjẹ náà tí èmi ó sì fi fún ni fún ìyè aráyé ni ara mi.” (aiōn g165)
52 Hĩndĩ ĩyo nao Ayahudi makĩambĩrĩria gũkararania mũno o ene, makoorania atĩrĩ, “Mũndũ ũyũ angĩhota atĩa gũtũhe mwĩrĩ wake tũrĩe?”
Nítorí náà ni àwọn Júù ṣe ń bá ara wọn jiyàn, pé, “Ọkùnrin yìí yóò ti ṣe lè fi ara rẹ̀ fún wa láti jẹ?”
53 Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Ngũmwĩra atĩrĩ na ma, mũtangĩrĩa mwĩrĩ wa Mũrũ wa Mũndũ na mũnyue thakame yake, mũtirĩ na muoyo thĩinĩ wanyu.
Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin bá jẹ ara Ọmọ Ènìyàn, kí ẹ sì mu ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, ẹ̀yin kò ní ìyè nínú yin.
54 Ũrĩa wothe ũrĩĩaga mwĩrĩ wakwa na akanyua thakame yakwa arĩ na muoyo wa tene na tene, na nĩngamũriũkia mũthenya wa kũrigĩrĩria. (aiōnios g166)
Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ara mi, tí ó bá sì mu ẹ̀jẹ̀ mi, ó ní ìyè tí kò nípẹ̀kun. Èmi o sì jí i dìde níkẹyìn ọjọ́. (aiōnios g166)
55 Nĩgũkorwo mwĩrĩ wakwa nĩ irio kũna, nayo thakame yakwa nĩ kĩndũ gĩa kũnyua kũna.
Nítorí ara mi ni ohun jíjẹ nítòótọ́, àti ẹ̀jẹ̀ mi ni ohun mímu nítòótọ́.
56 Ũrĩa wothe ũrĩĩaga mwĩrĩ wakwa na akanyua thakame yakwa aikaraga thĩinĩ wakwa na niĩ ngaikara thĩinĩ wake.
Ẹni tí ó bá jẹ ara mi, tí ó bá sì mu ẹ̀jẹ̀ mi, ó ń gbé inú mi, èmi sì ń gbé inú rẹ̀.
57 O ta ũrĩa Baba mũtũũra muoyo aandũmire na o ta ũrĩa na niĩ ndũũraga muoyo nĩ ũndũ wa Baba, noguo mũndũ ũrĩa ũndĩĩaga agaatũũra muoyo nĩ ũndũ wakwa.
Gẹ́gẹ́ bí Baba alààyè ti rán mi, tí èmi sì yè nípa Baba gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó jẹ mí, òun pẹ̀lú yóò yè nípa mi.
58 Ũyũ nĩguo mũgate ũrĩa waikũrũkire kuuma igũrũ. Maithe manyu maarĩire mana na nĩmakuire, no ũrĩa ũrĩĩaga mũgate ũyũ egũtũũra tene na tene.” (aiōn g165)
Èyí sì ni oúnjẹ náà tí ó sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá, kì í ṣe bí àwọn baba yín ti jẹ manna, tí wọ́n sì kú, ẹni tí ó bá jẹ́ oúnjẹ yìí yóò yè láéláé.” (aiōn g165)
59 Maũndũ macio aamaaririe rĩrĩa aarutanaga thunagogi-inĩ kũu Kaperinaumu.
Nǹkan wọ̀nyí ni ó sọ nínú Sinagọgu, bí ó ti ń kọ́ni ní Kapernaumu.
60 Arutwo ake aingĩ maigua ũguo makiuga atĩrĩ, “Ũyũ nĩ ũrutani mũritũ mũno, nũũ ũngĩhota kũwĩtĩkĩra?”
Nítorí náà nígbà tí ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ gbọ́ èyí, wọ́n wí pé, “Ọ̀rọ̀ tí ó le ni èyí; ta ní lè gbọ́ ọ?”
61 Jesũ amenya atĩ arutwo ake nĩmangʼongʼoraga nĩ ũndũ wa ũhoro ũcio akĩmeera atĩrĩ, “Kaĩ ũhoro ũcio wamũrakaria?
Nígbà tí Jesu sì mọ̀ nínú ara rẹ̀ pé àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń kùn sí ọ̀rọ̀ náà, ó wí fún wọn pé, “Èyí jẹ́ ìkọ̀sẹ̀ fún yín bí?
62 Ĩ mũngĩkĩona Mũrũ wa Mũndũ akĩambata igũrũ kũrĩa aarĩ mbere!
Ǹjẹ́, bí ẹ̀yin bá sì rí i tí Ọmọ Ènìyàn ń gòkè lọ sí ibi tí ó gbé ti wà rí ń kọ́?
63 Roho aheanaga muoyo; mwĩrĩ ndũrĩ kĩene. Ciugo iria ndamwarĩria nĩ roho na nĩcio muoyo.
Ẹ̀mí ní ń sọ ni di ààyè; ara kò ní èrè kan; ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí mo sọ fún yín, ẹ̀mí ni, ìyè sì ni pẹ̀lú.
64 No nĩ kũrĩ amwe anyu matarĩ maretĩkia.” Nĩgũkorwo kuuma o kĩambĩrĩria Jesũ nĩooĩ arĩa matetĩkĩtie, na ũrĩa ũkaamũkunyanĩra.
Ṣùgbọ́n àwọn kan wà nínú yín tí kò gbàgbọ́.” Nítorí Jesu mọ̀ láti ìbẹ̀rẹ̀ wá ẹni tí wọ́n jẹ́ tí kò gbàgbọ́, àti ẹni tí yóò fi òun hàn.
65 Agĩthiĩ na mbere, akiuga atĩrĩ, “Nĩkĩo ndamwĩrire atĩ gũtirĩ mũndũ ũngĩhota gũũka kũrĩ niĩ atahotithĩtio nĩ Baba.”
Ó sì wí pé, “Nítorí náà ni mo ṣe wí fún yín pé, kò sí ẹni tí ó lè tọ̀ mí wá, bí kò ṣe pé a fi fún un láti ọ̀dọ̀ Baba mi wá.”
66 Kuuma hĩndĩ ĩyo, arutwo ake aingĩ makĩhũndũka, na matiacookire kũmũrũmĩrĩra.
Nítorí èyí ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ padà sẹ́yìn, wọn kò sì bá a rìn mọ́.
67 Jesũ akĩũria arĩa ikũmi na eerĩ atĩrĩ, “O na inyuĩ kaĩ mũrenda gũthiĩ?”
Nítorí náà Jesu wí fún àwọn méjìlá pé, “Ẹ̀yin pẹ̀lú ń fẹ́ lọ bí?”
68 Nake Simoni Petero akĩmũcookeria, atĩrĩ, “Mwathani, tũngĩthiĩ kũrĩ ũ? Wee nĩwe ũrĩ na ciugo cia muoyo wa tene na tene. (aiōnios g166)
Nígbà náà ni Simoni Peteru dá a lóhùn pé, “Olúwa, ọ̀dọ̀ ta ni àwa ó lọ? Ìwọ ni ó ni ọ̀rọ̀ ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios g166)
69 Nĩtwĩtĩkĩtie na tũkamenya atĩ wee nĩwe ũrĩa Mũtheru wa Ngai.”
Àwa sì ti gbàgbọ́, a sì mọ̀ pé ìwọ ni Kristi náà, Ọmọ Ọlọ́run alààyè.”
70 Hĩndĩ ĩyo Jesũ akĩmacookeria akĩmeera atĩrĩ, “Githĩ ti niĩ ndĩmũthuurĩte mũrĩ ikũmi na eerĩ? No ũmwe wanyu nĩ ndaimono!”
Jesu dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin méjìlá kọ́ ni mo yàn, ọ̀kan nínú yín kò ha sì ya èṣù?”
71 (Aaragia ũhoro wa Judasi mũrũ wa Simoni Isikariota, tondũ o na aakorwo aarĩ ũmwe wa acio ikũmi na eerĩ, nĩwe warĩ amũkunyanĩre thuutha ũcio.)
(Ó ń sọ ti Judasi Iskariotu ọmọ Simoni ọ̀kan nínú àwọn méjìlá, nítorí pé òun ni ẹni tí yóò fi í hàn.)

< Johana 6 >