< Johana 4 >
1 Afarisai nĩmaiguire atĩ Jesũ nĩagĩĩaga na arutwo aingĩ gũkĩra Johana na akamabatithia,
Àwọn Farisi sì gbọ́ pé, Jesu ni, ó sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn púpọ̀ ju Johanu lọ.
2 o na gũtuĩka, ti Jesũ wabatithanagia, no nĩ arutwo ake.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Jesu tìkára rẹ̀ kò ṣe ìtẹ̀bọmi bí kò ṣe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀,
3 Hĩndĩ ĩrĩa Mwathani aamenyire ũhoro ũcio, akiuma Judea na agĩcooka Galili o rĩngĩ.
Ó fi Judea sílẹ̀, ó sì tún lọ sí Galili.
4 Na rĩrĩ, no nginya angĩatuĩkanĩirie bũrũri wa Samaria.
Òun sì ní láti kọjá láàrín Samaria.
5 Nĩ ũndũ ũcio, agĩkinya itũũra rĩarĩ Samaria rĩetagwo Sukaru, hakuhĩ na gĩthaka kĩrĩa Jakubu aaheete mũriũ Jusufu.
Nígbà náà ni ó dé ìlú Samaria kan, tí a ń pè ní Sikari, tí ó súnmọ́ etí ilẹ̀ oko tí Jakọbu ti fi fún Josẹfu, ọmọ rẹ̀.
6 Nakĩo gĩthima kĩa Jakubu nĩkuo kĩarĩ, nake Jesũ, tondũ wa kũnoga nĩ rũgendo, agĩikara thĩ hau gĩthima-inĩ. Na kwarĩ ta thaa thita.
Kànga Jakọbu sì wà níbẹ̀. Nítorí pé ó rẹ Jesu nítorí ìrìn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó jókòó létí kànga, ó sì jẹ́ ìwọ̀n wákàtí kẹfà ọjọ́.
7 Na rĩrĩa mũtumia ũmwe Mũsamaria okire gũtaha maaĩ-rĩ, Jesũ akĩmũũria atĩrĩ, “No ũũhe maaĩ ma kũnyua?”
Obìnrin kan, ará Samaria sì wá láti fà omi, Jesu wí fún un pé ṣe ìwọ yóò fún mi ni omi mu.
8 (Hĩndĩ ĩyo arutwo ake nĩmathiĩte kũgũra irio itũũra-inĩ.)
Nítorí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ti lọ sí ìlú láti lọ ra oúnjẹ.
9 Nake mũtumia ũcio Mũsamaria akĩmwĩra atĩrĩ, “Wee ũrĩ Mũyahudi na niĩ ndĩ mũtumia Mũsamaria. Ũngĩkĩĩhooya gĩa kũnyua atĩa?” (Nĩgũkorwo Ayahudi matirĩ ngwatanĩro na Asamaria.)
Obìnrin ará Samaria náà sọ fún un pé, “Júù ni ìwọ, obìnrin ará Samaria ni èmi. Èétirí tí ìwọ ń béèrè ohun mímu lọ́wọ́ mi?” (Nítorí tí àwọn Júù kì í bá àwọn ará Samaria ṣe pọ̀.)
10 Nake Jesũ akĩmũcookeria atĩrĩ, “Korwo nĩũũĩ kĩheo kĩa Ngai na ũkamenya nũũ ũrakũhooya maaĩ ma kũnyua, wee nĩwe ũngĩamũhooya nake nĩangĩakũhe maaĩ ma muoyo.”
Jesu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ìbá ṣe pé ìwọ mọ ẹ̀bùn Ọlọ́run, àti ẹni tí ó wí fún ọ pé, ‘Fún mi ni omi mu’, ìwọ ìbá sì ti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, òun ìbá ti fi omi ìyè fún ọ.”
11 Nake mũtumia ũcio akĩmwĩra atĩrĩ, “Mũthuuri ũyũ, ndũrĩ na kĩndũ gĩa gũtaha maaĩ nakĩo, na gĩthima gĩkĩ nĩ kĩriku. Ũngĩkĩruta kũ maaĩ macio ma muoyo?
Obìnrin náà wí fún un pé, “Alàgbà, ìwọ kò ní igbá-ìfami tí ìwọ ó fi fà omi, bẹ́ẹ̀ ni kànga náà jì, Níbo ni ìwọ ó ti rí omi ìyè náà?
12 Anga ũkĩrĩ mũnene gũkĩra ithe witũ Jakubu ũrĩa watũheire gĩthima gĩkĩ, na we mwene aatũũrĩte anyuuaga maaĩ kuuma kĩo o hamwe na ariũ ake na ndũũru ciake cia mbũri na cia ngʼombe?”
Ìwọ pọ̀ ju Jakọbu baba wa lọ bí, ẹni tí ó fún wa ní kànga náà, tí òun tìkára rẹ̀ si mu nínú rẹ̀, àti àwọn ọmọ rẹ̀, àti àwọn ẹran ọ̀sìn rẹ̀?”
13 Nake Jesũ akĩmũcookeria atĩrĩ, “Mũndũ o wothe ũnyuuaga maaĩ maya nĩanyootaga rĩngĩ,
Jesu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá mu nínú omi yìí, òǹgbẹ yóò sì tún gbẹ ẹ́.
14 no ũrĩa wothe ũkũnyua maaĩ marĩa ngaamũhe ndarĩ hĩndĩ akaanyoota. Ti-itherũ, maaĩ marĩa ngũmũhe megũtuĩka gĩthima kĩa maaĩ thĩinĩ wake, gĩtherũkage muoyo wa tene na tene.” (aiōn , aiōnios )
Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá mu nínú omi tí èmi ó fi fún un, òǹgbẹ kì yóò gbẹ ẹ́ mọ́ láé; ṣùgbọ́n omi tí èmi ó fi fún un yóò di kànga omi nínú rẹ̀, tí yóò máa sun si ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōn , aiōnios )
15 Nake mũtumia ũcio akĩmwĩra atĩrĩ, “Mũthuuri ũyũ, he maaĩ macio nĩguo ndikananyoote rĩngĩ, na ndige gũũkaga haha gũtaha maaĩ.”
Obìnrin náà sì wí fún u pé, “Alàgbà, fún mi ní omi yìí, kí òǹgbẹ kí ó má ṣe gbẹ mí, kí èmi kí ó má sì wá fa omi níbí mọ́.”
16 Nake akĩmwĩra atĩrĩ, “Thiĩ wĩte mũthuuriguo mũũke nake.”
Jesu wí fún un pé, “Lọ pe ọkọ rẹ, kí ó sì padà wá sí ìhín yìí.”
17 Nake mũtumia ũcio akĩmũcookeria atĩrĩ, “Niĩ ndirĩ na mũthuuri.” Nake Jesũ akĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩ waria ma rĩrĩa woiga atĩ ndũrĩ na mũthuuri.
Obìnrin náà dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Èmi kò ní ọkọ.” Jesu wí fún un pé, “Ìwọ́ dáhùn dáradára pé, èmi kò ní ọkọ:
18 Ũhoro wa ma nĩ atĩ ũkoretwo ũrĩ na athuuri atano, na mũndũ mũrũme ũrĩa ũrĩ nake rĩu ti mũthuuriguo. Ũguo woiga nĩ ũhoro wa ma.”
Nítorí tí ìwọ ti ní ọkọ márùn-ún rí, ọkùnrin tí ìwọ sì ní báyìí kì í ṣe ọkọ rẹ. Ohun tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ tán yìí, òtítọ́ ni.”
19 Nake mũtumia ũcio akĩmwĩra atĩrĩ, “Mũthuuri ũyũ, nĩndĩrona atĩ wee ũrĩ mũnabii.
Obìnrin náà wí fún un pé, “Alàgbà, mo wòye pé, wòlíì ni ìwọ ń ṣe.
20 Maithe maitũ maahooyagĩra Ngai kĩrĩma-inĩ gĩkĩ, no inyuĩ Ayahudi muugaga atĩ Jerusalemu nokuo kũndũ kũrĩa twagĩrĩirwo nĩkũhooyagĩra Ngai.”
Àwọn baba wa sìn lórí òkè yìí; ẹ̀yin sì wí pé, Jerusalẹmu ni ibi tí ó yẹ tí à bá ti máa sìn.”
21 Nake Jesũ akiuga atĩrĩ, “Mũtumia ũyũ, njĩtĩkia, kũrĩ ihinda rĩroka rĩrĩa mũtakaahooyagĩra Baba kĩrĩma-inĩ gĩkĩ o na kana Jerusalemu.
Jesu wí fún un pé, “Gbà mí gbọ́ obìnrin yìí, àkókò náà ń bọ̀, nígbà tí kì yóò ṣe lórí òkè yìí tàbí ní Jerusalẹmu ni ẹ̀yin ó máa sin Baba.
22 Inyuĩ Asamaria mũhooyaga kĩrĩa mũtooĩ; no ithuĩ tũhooyaga kĩrĩa tũũĩ, nĩgũkorwo ũhonokio uumĩte kũrĩ Ayahudi.
Ẹ̀yin ń sin ohun tí ẹ̀yin kò mọ̀, àwa ń sin ohun tí àwa mọ̀, nítorí ìgbàlà ti ọ̀dọ̀ àwọn Júù wá.
23 No ihinda nĩrĩroka na rĩu nĩrĩkinyu, rĩrĩa arĩa mahooyaga na ma makaahooyaga Baba na roho, na mamũhooyage na ma, nĩgũkorwo nĩ andũ ta acio Baba acaragia a kũmũhooyaga.
Ṣùgbọ́n àkókò ń bọ̀, ó sì dé tán nísinsin yìí, nígbà tí àwọn olùsìn tòótọ́ yóò máa sin Baba ní ẹ̀mí àti ní òtítọ́, nítorí irú wọn ni Baba ń wá kí ó máa sin òun.
24 Ngai nĩ roho, nao arĩa mamũhooyaga no nginya mamũhooyage na roho, na mamũhooyage na ma.”
Ẹ̀mí ni Ọlọ́run: àwọn ẹni tí ń sìn ín kò lè ṣe aláìsìn ín ní Ẹ̀mí àti ní òtítọ́.”
25 Nake mũtumia ũcio akĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩnjũũĩ atĩ Mesia” (ũrĩa wĩtagwo Kristũ) “nĩarooka. Hĩndĩ ĩrĩa agooka nĩagatũtaarĩria maũndũ mothe.”
Obìnrin náà wí fún un pé, mo mọ̀ pé, “Messia ń bọ̀ wá, tí a ń pè ní Kristi, nígbà tí Òun bá dé, yóò sọ ohun gbogbo fún wa.”
26 Nake Jesũ akiuga atĩrĩ, “Niĩ ndĩrakwarĩria nĩ niĩ we.”
Jesu sọ ọ́ di mí mọ̀ fún un pé, “Èmi ẹni tí ń bá ọ sọ̀rọ̀ yìí ni Òun.”
27 O ihinda-inĩ rĩu arutwo ake magĩũka, na makĩgega maakora akĩaranĩria na mũtumia. No gũtirĩ o na ũmwe woririe atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ ũrenda?” kana akĩũria, “Ũraaranĩria nake nĩkĩ?”
Lákokò yí ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ dé, ẹnu sì yà wọ́n pé ó ń bá obìnrin sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó wí pé, “Kí ni ìwọ ń wá?” tàbí “Èéṣe tí ìwọ fi ń bá a sọ̀rọ̀?”
28 O hĩndĩ ĩyo mũtumia ũcio agĩtiga ndigithũ yake ya maaĩ, agĩcooka itũũra-inĩ, akĩĩra andũ atĩrĩ,
Nígbà náà ni obìnrin náà fi ládugbó rẹ̀ sílẹ̀, ó sì mú ọ̀nà rẹ̀ pọ̀n lọ sí ìlú, ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé,
29 “Ũkai, mũkone mũndũ wanjĩĩra maũndũ marĩa mothe ndaaneka. Ũcio no akorwo nĩwe Kristũ?”
“Ẹ wá wò ọkùnrin kan, ẹni tí ó sọ ohun gbogbo tí mo ti ṣe rí fún mi, èyí ha lè jẹ́ Kristi náà?”
30 Nao makiuma kũu itũũra-inĩ, magĩthiĩ harĩa Jesũ aarĩ.
Nígbà náà ni wọ́n ti ìlú jáde, wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá.
31 Mũira wa makinye, arutwo ake makĩmũringĩrĩria makĩmwĩra atĩrĩ, “Rabii, rĩa irio.”
Láàrín èyí, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń rọ̀ ọ́ wí pé, “Rabbi, jẹun.”
32 Nowe akĩmeera atĩrĩ, “Ndĩ na irio cia kũrĩa, iria mũtarĩ ũndũ wacio mũũĩ.”
Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Èmi ní oúnjẹ láti jẹ, tí ẹ̀yin kò mọ̀.”
33 Nao arutwo ake makĩũrania atĩrĩ, “Kaĩ hihi harĩ mũndũ ũmũreheire irio?”
Nítorí náà ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń bi ara wọn lérè wí pé, “Ẹnìkan mú oúnjẹ fún un wá láti jẹ bí?”
34 Nake Jesũ akiuga atĩrĩ, “Irio ciakwa nĩ gwĩka wendi wa ũrĩa wandũmire na kũrĩĩkia wĩra wake.
Jesu wí fún wọn pé, “Oúnjẹ mi ni láti ṣe ìfẹ́ ẹni tí ó rán mi, àti láti parí iṣẹ́ rẹ̀.
35 Githĩ mũtiugaga atĩ, ‘Nĩ mĩeri ĩna ĩtigarĩte magetha makinye’? Ngũmwĩra atĩrĩ, hingũrai maitho manyu muone mĩgũnda! Magetha nĩmakinyu.
Ẹ̀yin kò ha wí pé, ‘Ó ku oṣù mẹ́rin, ìkórè yóò sì dé?’ wò ó, mo wí fún un yín, Ẹ ṣí ojú yín sókè, kí ẹ sì wo oko; nítorí tí wọn ti pọ́n fún ìkórè.
36 O na rĩu mũgethi nĩagĩĩaga na mũcaara wake, o na nĩagethaga magetha ma muoyo wa tene na tene, nĩgeetha mũhaandi na mũgethi makenanĩre hamwe. (aiōnios )
Kódà báyìí, ẹni tí ó ń kórè ń gba owó ọ̀yà rẹ̀, ó si ń kó èso jọ sí ìyè àìnípẹ̀kun, kí ẹni tí ó ń fúnrúgbìn àti ẹni tí ń kórè lè jọ máa yọ̀ pọ̀. (aiōnios )
37 Amu nĩ ũhoro wa ma ũrĩa uugaga atĩ, ‘Ũmwe ahaandaga, nake ũngĩ akagetha.’
Nítorí nínú èyí ni ọ̀rọ̀ náà fi jẹ́ òtítọ́, ‘Ẹnìkan ni ó fúnrúgbìn, ẹlòmíràn ni ó sì ń kórè jọ.’
38 Niĩ ndaamũtũmire mũkagethe kĩrĩa mũtarutĩire wĩra. Angĩ nĩo marutĩte wĩra mũritũ, na inyuĩ mũkagetha uumithio wa wĩra wao.”
Mo rán yín lọ kórè ohun tí ẹ kò ṣiṣẹ́ fún. Àwọn ẹlòmíràn ti ṣiṣẹ́, ẹ̀yin sì kórè èrè làálàá wọn.”
39 Nao Asamaria aingĩ kuuma itũũra rĩu makĩmwĩtĩkia nĩ ũndũ wa ũira wa mũtumia ũcio, tondũ nĩameerire atĩrĩ, “Nĩanjĩĩrire maũndũ marĩa mothe ndaneeka.”
Ọ̀pọ̀ àwọn ará Samaria láti ìlú náà wá sì gbà á gbọ́ nítorí ìjẹ́rìí obìnrin náà pé, “Ó sọ gbogbo ohun tí mo ti ṣe fún mi.”
40 Nĩ ũndũ ũcio, hĩndĩ ĩrĩa Asamaria mokire kũrĩ Jesũ, makĩmũringĩrĩria aikaranie nao, nake agĩikara mĩthenya ĩĩrĩ.
Nítorí náà, nígbà tí àwọn ará Samaria wá sọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n rọ̀ ọ́ pé, kí ó wà pẹ̀lú wọn, ó sì dúró fún ọjọ́ méjì.
41 Na tondũ wa ciugo ciake, andũ angĩ aingĩ magĩĩtĩkia.
Àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ sì gbàgbọ́ sí i nítorí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
42 Magĩkĩĩra mũtumia ũcio atĩrĩ, “Ithuĩ tũtiretĩkia no ũndũ wa ũrĩa ũratwĩrire; rĩu nĩtwĩiguĩrĩire ithuĩ ene na tũkamenya atĩ mũndũ ũyũ ti-itherũ nĩwe Mũhonokia wa kĩrĩndĩ.”
Wọ́n sì wí fún obìnrin náà pé, “Kì í ṣe nítorí ọ̀rọ̀ rẹ nìkan ni àwa ṣe gbàgbọ́, nítorí tí àwa tìkára wa ti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, àwa sì mọ̀ pé, nítòótọ́ èyí ni Kristi náà, Olùgbàlà aráyé.”
43 Thuutha wa mĩthenya ĩyo ĩĩrĩ, akiumagara agĩthiĩ Galili.
Lẹ́yìn ọjọ́ méjì ó sì ti ibẹ̀ kúrò, ó lọ sí Galili.
44 (Amu Jesũ we mwene nĩoigĩte atĩ mũnabii ndatĩĩagwo bũrũri-inĩ wake mwene.)
Nítorí Jesu tìkára rẹ̀ ti jẹ́rìí wí pé, Wòlíì kì í ní ọlá ní ilẹ̀ òun tìkára rẹ̀.
45 Rĩrĩa aakinyire Galili, andũ a Galili makĩmũnyiita ũgeni. Nĩmonete ũrĩa wothe ekĩte Jerusalemu hĩndĩ ya Gĩathĩ gĩa Bathaka, nĩgũkorwo o nao maarĩ kuo.
Nítorí náà nígbà tí ó dé Galili, àwọn ará Galili gbà á, nítorí ti wọ́n ti rí ohun gbogbo tí ó ṣe ní Jerusalẹmu nígbà àjọ ìrékọjá; nítorí àwọn tìkára wọn lọ sí àjọ pẹ̀lú.
46 O rĩngĩ agĩceera Kana ya Galili, kũrĩa aagarũrĩte maaĩ magatuĩka ndibei. Na kũu Kaperinaumu nĩ kwarĩ na mũndũ ũmwe mũnene warĩ na mũriũ mũrũaru.
Bẹ́ẹ̀ ni Jesu tún wá sí Kana ti Galili, níbi tí ó gbé sọ omi di wáìnì. Ọkùnrin ọlọ́lá kan sì wá, ẹni tí ara ọmọ rẹ̀ kò dá ní Kapernaumu.
47 Rĩrĩa mũndũ ũcio aaiguire atĩ Jesũ nĩoimĩte Judea agooka Galili, agĩthiĩ kũrĩ we, akĩmũthaitha athiĩ akahonie mũriũ, ũrĩa warĩ hakuhĩ gũkua.
Nígbà tí ó gbọ́ pé Jesu ti Judea wá sí Galili, ó tọ̀ ọ́ wá, ó sì ń bẹ̀ ẹ́, kí ó lè sọ̀kalẹ̀ wá kí ó mú ọmọ òun láradá: nítorí tí ó wà ní ojú ikú.
48 Jesũ akĩmwĩra atĩrĩ, “Inyuĩ mũtangĩona ciama na morirũ, mũtingĩtĩkia.”
Nígbà náà ni Jesu wí fún un pé, “Bí kò ṣe pé ẹ̀yin bá rí àmì àti iṣẹ́ ìyanu, ẹ̀yin kì yóò gbàgbọ́ láé.”
49 Nake mũnene ũcio akĩmwĩra atĩrĩ, “Mũthuuri ũyũ, nĩtũikũrũke mwana wakwa atanakua.”
Ọkùnrin ọlọ́lá náà wí fún un pé, “Olúwa, sọ̀kalẹ̀ wá kí ọmọ mi tó kú.”
50 Nake Jesũ akĩmũcookeria atĩrĩ, “Inũka. Mũrũguo nĩekũhona.” Mũndũ ũcio agĩĩtĩkia ũguo Jesũ aamwĩrire, na akĩinũka.
Jesu wí fún un pé, “Máa bá ọ̀nà rẹ lọ; ọmọ rẹ yóò yè.” Ọkùnrin náà sì gba ọ̀rọ̀ Jesu gbọ́, ó sì kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
51 Naarĩ njĩra akĩinũka, ndungata ciake ikĩmũtũnga na ndũmĩrĩri atĩ mũrũwe arĩ o muoyo.
Bí ó sì ti ń sọ̀kalẹ̀ lọ, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pàdé rẹ̀, wọ́n sì wí fún un pé, ọmọ rẹ ti yè.
52 Rĩrĩa aamooririe nĩ ta thaa ciigana mũriũ aambĩrĩirie kũigua wega, makĩmwĩra atĩrĩ, “Ira thaa mũgwanja nĩguo araahonire.”
Nígbà náà ni ó béèrè wákàtí tí ara rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í yá lọ́wọ́ wọn, wọ́n sì wí fún un pé, “Ní àná, ní wákàtí keje ni ibà náà fi í sílẹ̀.”
53 Nake ithe akĩmenya atĩ thaa icio nocio Jesũ aramwĩrĩte atĩrĩ, “Mũrũguo nĩekũhona.” Nĩ ũndũ ũcio we na nyũmba yake yothe magĩĩtĩkia.
Bẹ́ẹ̀ ni baba náà mọ̀ pé ní wákàtí kan náà ni, nínú èyí tí Jesu wí fún un pé “Ọmọ rẹ̀ yè.” Òun tìkára rẹ̀ sì gbàgbọ́, àti gbogbo ilé rẹ̀.
54 Gĩkĩ nĩkĩo kĩarĩ kĩama gĩa keerĩ kĩrĩa Jesũ aaringire kũu Galili, oimĩte Judea.
Èyí ni iṣẹ́ àmì kejì tí Jesu ṣe nígbà tí ó ti Judea jáde wá sí Galili.