< Ayubu 9 >

1 Ningĩ Ayubu agĩcookia, akiuga atĩrĩ:
Jobu sì dáhùn ó sì wí pé,
2 “Ti-itherũ nĩnjũũĩ ũhoro ũcio nĩ wa ma. No rĩrĩ, mũndũ angĩhota atĩa gũkorwo arĩ mũthingu mbere ya Mũrungu?
“Èmi mọ̀ pe bẹ́ẹ̀ ni ní òtítọ́. Báwo ní ènìyàn yóò ha ti ṣe jẹ́ aláre níwájú Ọlọ́run?
3 O na korwo mũndũ enda gũkararania na Ngai-rĩ, ndangĩhota kũmũcookeria kĩũria o na kĩmwe harĩ ciũria ngiri.
Bí ó bá ṣe pé yóò bá a jà, òun kì yóò lè dalóhùn kan nínú ẹgbẹ̀rún ọ̀rọ̀.
4 Ũũgĩ wake nĩ mũingĩ mũno, na ũhoti wake nĩ mũnene. Nũũ wanaregana nake akĩgaacĩra?
Ọlọ́gbọ́n nínú àwọn alágbára ní ipa ní Òun. Ta ni ó ṣe agídí sí i tí ó sì gbé fún rí?
5 Eeheragia irĩma itekũmenya, na agacingʼaũrania nĩ kũrakara.
Ẹni tí ó sí òkè nídìí tí wọn kò sì mọ́: tí ó taari wọn ṣubú ní ìbínú rẹ̀.
6 Athingithagia thĩ ĩkoima handũ hayo, na akainainia itugĩ ciayo.
Tí ó mi ilẹ̀ ayé tìtì kúrò ní ipò rẹ̀, ọwọ̀n rẹ̀ sì mì tìtì.
7 Aathaga riũa rĩkaaga kũratha; nake agiragĩrĩria ũtheri wa njata.
Ó pàṣẹ fún oòrùn kò sì le è ràn, kí ó sì dí ìmọ́lẹ̀ ìràwọ̀ mọ́.
8 Nĩwe watambũrũkirie igũrũ arĩ o wiki, na athiiaga agĩkinyangaga makũmbĩ ma iria.
Òun nìkan ṣoṣo ni ó ta ojú ọ̀run, ti ó sì ń rìn lórí ìgbì Òkun.
9 Nĩwe Mũũmbi wa njata iria ciĩtagwo Nduba, na Karaũ, na Kĩrĩmĩra, o na ikundi cia njata cia mwena wa gũthini.
Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Beari àti Orioni, Pleiadesi àti ìràwọ̀ púpọ̀ ti gúúsù.
10 Nĩekaga magegania matangĩmenyeka, na akaringa ciama itangĩtarĩka.
Ẹni tí ń ṣe ohun tí ó tóbi jù àwárí lọ, àní ohun ìyanu láìní iye.
11 Rĩrĩa aahĩtũkĩra harĩa ndĩ, ndingĩmuona; o na rĩrĩa aathiĩra harĩa ndĩ ndimenyaga.
Kíyèsi i, ó ń kọjá lọ ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ mi, èmi kò sì rí i, ó sì kọjá síwájú, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò rí ojú rẹ̀.
12 Angĩgutha kĩndũ-rĩ, nũũ ũngĩhota kũmũgiria? Nũũ ũngĩmũũria atĩrĩ, ‘Nĩ atĩa ũreka?’
Kíyèsi i, ó já a gbà lọ, ta ni ó lè fà á padà? Ta ni yóò bi í pé kí ni ìwọ ń ṣe nì?
13 Ngai ndahingagĩrĩria marakara make; o na arĩa maateithagĩrĩria Rahabu nĩmamũinamagĩrĩra.
Ọlọ́run kò ní fa ìbínú rẹ̀ sẹ́yìn, àwọn onírànlọ́wọ́ ti Rahabu a sì tẹríba lábẹ́ rẹ̀.
14 “Niĩ-rĩ, ndaakĩhota atĩa kũmũkararia? Ingĩruta kũ ciugo cia kũmũcookeria?
“Kí ní ṣe tí èmi ti n o fi ba ṣàròyé? Tí èmi yóò fi ma ṣe àwáwí?
15 O na korwo ndihĩtĩtie-rĩ, ndingĩhota kũmũcookeria ũndũ; ũrĩa ingĩĩka no gũthaitha ingĩthaitha Mũnjiirithia anjiguĩre tha.
Bí ó tilẹ̀ ṣe pé mo ṣe aláìlẹ́bi, èmi kò gbọdọ̀ dá a lóhùn; ṣùgbọ́n èmi ó gbàdúrà fún àánú.
16 O na ingĩamwĩtire nake anjĩtĩke-rĩ, ndingĩĩtĩkia nĩangĩathikĩrĩirie.
Bí èmi bá sì ké pè é, tí Òun sì dá mi lóhùn, èmi kì yóò sì gbàgbọ́ pé, Òun ti fetí sí ohùn mi.
17 We angĩamemendire na kĩhuhũkanio, na aingĩhie ironda ciakwa hatarĩ gĩtũmi.
Nítorí pé òun yóò lọ̀ mí lúúlúú pẹ̀lú ìjì ńlá, ó sọ ọgbẹ́ mi di púpọ̀ láìnídìí.
18 Ndarekaga njookererwo nĩ mĩhũmũ, no nĩahatagĩrĩria na mathĩĩna.
Òun kì yóò jẹ́ kí èmi kí ó rí ẹ̀mí mi, ṣùgbọ́n ó mú ohun kíkorò kún un fún mi.
19 Korwo no ũhoro wa hinya-rĩ, we arĩ hinya mũno! Na korwo no ũhoro wa ciira wa kĩhooto-rĩ, nũũ ũngĩmwĩta?
Bí mo bá sọ ti agbára, wò ó! Alágbára ni, tàbí ní ti ìdájọ́, ta ni yóò dá àkókò fún mi láti rò?
20 O na korwo ndiahĩtĩtie-rĩ, kanua gakwa no kandue mũhĩtia; korwo ndiarĩ na ũcuuke-rĩ, nĩkangĩanduire mũhĩtia.
Bí mo tilẹ̀ dá ara mi láre, ẹnu ara mi yóò dá mi lẹ́bi; bí mo wí pé olódodo ni èmi yóò sì fi mí hàn ní ẹni ẹ̀bi.
21 “O na gũtuĩka ndirĩ na ũcuuke-rĩ, ndikwĩrĩrĩra; muoyo wakwa nĩndĩwagĩire kĩene.
“Olóòótọ́ ni mo ṣe, síbẹ̀ èmi kò kíyèsi ara mi, ayé mi ní èmi ìbá máa gàn.
22 Ũhoro no ũrĩa ũmwe; nĩkĩo ndĩroiga atĩrĩ, ‘Aniinaga arĩa matarĩ ũcuuke o na akaniina arĩa aaganu.’
Ohùn kan náà ni, nítorí náà ni èmi ṣe sọ: ‘Òun a pa ẹni òtítọ́ àti ènìyàn búburú pẹ̀lú.’
23 Hĩndĩ ĩrĩa ihũũra rĩarehe gĩkuũ kĩa narua, nĩathekagĩrĩra kũũrwo nĩ hinya kwa arĩa matarĩ na mahĩtia.
Bí ìjàǹbá bá pa ni lójijì, yóò rẹ́rìn-ín nínú ìdààmú aláìṣẹ̀.
24 Hĩndĩ ĩrĩa bũrũri wagĩa moko-inĩ ma andũ aaganu, nĩahingaga aciirithania maitho. Akorwo ti we-rĩ, nũũ wĩkaga ũguo?
Nígbà tí a bá fi ayé lé ọwọ́ ènìyàn búburú; ó sì bo àwọn onídàájọ́ rẹ̀ lójú; bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ ǹjẹ́ ta ni?
25 “Matukũ makwa marahanyũka gũkĩra mũkinyia-ũhoro; mombũkaga matarĩ na gĩkeno o na kĩnini.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí ọjọ́ mi yára ju oníṣẹ́ lọ, wọ́n fò lọ, wọn kò rí ayọ̀.
26 Mahĩtũkaga na ihenya mũno ta tũtarũ twa irura, kana ta nderi igũcuuhũkĩra kĩndũ gĩa kũrĩa.
Wọ́n kọjá lọ bí ọkọ̀ eèsún papirusi tí ń sáré lọ; bí idì tí ń yára si ohùn ọdẹ.
27 Ingiuga atĩrĩ, ‘Nĩngũriganĩrwo nĩ mateta makwa, nĩngũtiga gũtukia gĩthiithi, ngene,’
Bí èmi bá wí pé, ‘Èmi ó gbàgbé arò ìbìnújẹ́ mi, èmi ó fi ọkàn lélẹ̀, èmi ó sì rẹ ara mi lẹ́kún.’
28 no ngeetigĩra mĩnyamaro yakwa yothe, nĩgũkorwo nĩnjũũĩ ndũkandua atĩ ndiĩhĩtie.
Ẹ̀rù ìbànújẹ́ mi gbogbo bà mí, èmi mọ̀ pé ìwọ kì yóò mú mi bí aláìṣẹ̀.
29 Kuona atĩ nĩndĩkĩtie gũtuuo mũhĩtia-rĩ, nĩ kĩĩ gĩgũtũma ndĩĩnogie tũhũ?
Bí ó bá ṣe pé ènìyàn búburú ni èmi, ǹjẹ́ kí ni èmi ń ṣe làálàá lásán sí?
30 O na ingĩĩthamba na thabuni, na ndĩĩthambe moko na igata-rĩ,
Bí mo tilẹ̀ fi ọṣẹ dídì wẹ ara mi, tí mo fi omi aró wẹ ọwọ́ mi mọ́,
31 no ũndikirie irima rĩa gĩcoro nĩgeetha o na nguo ciakwa iithũũre.
síbẹ̀ ìwọ ó gbé mi wọ inú ihò ọ̀gọ̀dọ̀ aṣọ ara mi yóò sọ mi di ìríra.
32 “We ti mũndũ ta niĩ atĩ nĩguo ndĩmũcookerie, nĩguo tũngʼethanĩre igooti-inĩ.
“Nítorí Òun kì í ṣe ènìyàn bí èmi, tí èmi ó fi dá a lóhùn tí àwa o fi pàdé ní ìdájọ́.
33 Naarĩ korwo nĩ harĩ mũndũ ũngĩtũiguithania, atũigĩrĩre guoko gwake ithuĩ eerĩ,
Bẹ́ẹ̀ ni kò sí alátúnṣe kan ní agbede-méjì wa tí ìbá fi ọwọ́ rẹ̀ lé àwa méjèèjì lára.
34 mũndũ wa kũnjehereria rũthanju rwa Ngai, nĩgeetha ndigacooke kũmakio nĩ itebeebania rĩake.
Kí ẹnìkan sá à mú ọ̀pá Ọlọ́run kúrò lára mi, kí ìbẹ̀rù rẹ̀ kí ó má sì ṣe dáyà fò mí.
35 Hĩndĩ ĩyo nĩingĩacooka kwaragia itekũmwĩtigĩra, no ũrĩa ndariĩ rĩu-rĩ, ndingĩhota.
Nígbà náà ni èmi ìbá sọ̀rọ̀, èmi kì bá sì bẹ̀rù rẹ̀; ṣùgbọ́n bí ó tí dúró tì mí, kò ri bẹ́ẹ̀ fún mi.

< Ayubu 9 >