< Ayubu 6 >
1 Ningĩ Ayubu agĩcookia atĩrĩ:
Jobu sì dáhùn ó si wí pé,
2 “Naarĩ korwo ruo rũrũ ndĩ naruo rwathimwo, nayo mĩnyamaro ĩno ndĩ nayo yothe ĩigĩrĩrwo ratiri igũrũ!
“Háà! À bá lè wọ́n ìbìnújẹ́ mi nínú òsùwọ̀n, kí a sì le gbé ọ̀fọ̀ mi lé orí òsùwọ̀n ṣọ̀kan pọ̀!
3 Ti-itherũ yakorwo ĩrĩ mĩritũ gũkĩra mũthanga ũrĩa ũrĩ maria-inĩ marĩa manene; na nĩkĩo ndĩrahiũhire kwaria.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ìbá wúwo jú iyanrìn òkun lọ, nítorí náà ni ọ̀rọ̀ mi ṣe ń tàsé.
4 Mĩguĩ ya Mwene-Hinya-Wothe nĩĩndoonyete, naguo roho wakwa nĩũranyua ũrũrũ wayo; maũndũ ma kũmakania mũno ma Ngai nĩmerekeirio harĩ niĩ.
Nítorí pé ọfà Olódùmarè wọ̀ mi nínú, oró èyí tí ọkàn mi mú; ìpayà-ẹ̀rù Ọlọ́run dúró tì mí.
5 Njagĩ ya werũ-inĩ-rĩ, nĩyaanagia rĩrĩa ĩrĩ na nyeki ya kũrĩa, kana ndegwa ĩkaania rĩrĩa ĩtuĩrĩirwo?
Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó á máa dún nígbà tí ó bá ní koríko, tàbí ọ̀dá màlúù a máa dún lórí ìjẹ rẹ̀?
6 Irio itarĩ mũcamo nĩ irĩĩkaga itekĩrĩtwo cumbĩ? Mũruru wa itumbĩ ũrĩa mwerũ-rĩ, nĩ urĩ mũrĩo?
A ha lè jẹ ohun tí kò ní adùn ní àìní iyọ̀, tàbí adùn ha wà nínú funfun ẹyin?
7 Niĩ ndingĩcihutia; irio ta icio no itũme njire ngoro.
Ohun ti ọ̀kan mi kọ̀ láti tọ́wò, òun ni ó dàbí oúnjẹ tí ó mú mi ṣàárẹ̀.
8 “Naarĩ korwo ndaheo ũndũ ũrĩa ndĩrahooya, korwo Ngai aahe ũndũ ũrĩa ndĩrerirĩria,
“Háà! èmi ìbá lè rí ìbéèrè mi gbà; àti pé, kí Ọlọ́run lè fi ohun tí èmi ṣàfẹ́rí fún mi.
9 naguo nĩ atĩ Ngai eetĩkĩre kũũmemenda, arekererie guoko gwake kũũniine!
Àní Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa mí run, tí òun ìbá jẹ́ ṣíwọ́ rẹ̀ kì ó sì ké mi kúrò.
10 Hĩndĩ ĩyo no ngĩe na ũndũ wa kũũhooreria, ũndũ wa gĩkeno ruo-inĩ rũrũ rũtarathira, atĩ niĩ ndikaanĩte ciugo cia Ũrĩa Mũtheru.
Nígbà náà ní èmi ìbá ní ìtùnú síbẹ̀, àní, èmi ìbá mú ọkàn mi le nínú ìbànújẹ́ mi ti kò dá ni sí: nítorí èmi kò fi ọ̀rọ̀ ẹni mímọ́ ni sin rí.
11 “Ndĩ na hinya ũrĩkũ atĩ nĩguo njikare ndĩ na mwĩhoko? Ndĩ na kĩĩrĩgĩrĩro kĩrĩkũ atĩ nĩguo ngirĩrĩrie?
“Kí ní agbára mi tí èmi ó fi retí? Kí sì ní òpin mi tí èmi ó fi ní sùúrù?
12 Niĩ ndĩ hinya ta ihiga? Mwĩrĩ wakwa nĩ wa gĩcango?
Agbára mi ha ṣe agbára òkúta bí? Ẹran-ara mi í ṣe idẹ?
13 Niĩ ndĩ na hinya wa gwĩteithia, kuona atĩ rĩu nĩndunyĩtwo ũhootani?
Ìrànlọ́wọ́ mi kò ha wà nínú mi: ọgbọ́n kò ha ti sálọ kúrò lọ́dọ̀ mi bí?
14 “Mũndũ ũtarĩ na kĩĩrĩgĩrĩro aagĩrĩire gũteithio nĩ arata ake, o na angĩkorwo nĩatiganĩirie ũhoro wa gwĩtigĩra Ũrĩa Mwene-Hinya-Wothe.
“Ẹni tí àyà rẹ̀ yọ́ dànù, ta ni a bá máa ṣàánú fún láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ wá, kí ó má ba à kọ ìbẹ̀rù Olódùmarè sílẹ̀?
15 No ariũ a baba maagĩte kwĩhokeka o ta tũrũũĩ tũrĩa tũhũaga, ningĩ o ta tũrũũĩ tũrĩa tũiyũraga tũkoina,
Àwọn ará mi dàbí odò tí kò ṣe gbẹ́kẹ̀lé bí ìṣàn omi odò, wọ́n sàn kọjá lọ.
16 rĩrĩa tũirĩtio nĩ mbarabu ĩgĩtweka, na tũkaiyũrwo nĩ tharunji ĩrĩa ĩratweka,
Tí ó dúdú nítorí omi dídì, àti níbi tí yìnyín dídì gbé di yíyọ́.
17 no rĩrĩ, tũtithereraga rĩrĩa kwara, na hĩndĩ ya ũrugarĩ tũkahũa mĩtaro-inĩ yatuo.
Nígbàkígbà tí wọ́n bá gbóná wọn a sì yọ́ sàn lọ, nígbà tí oòrùn bá mú, wọn a sì gbẹ kúrò ni ipò wọn.
18 Ikundi cia agendi nĩithaamaga njĩra ciacio, ikambata werũ-inĩ, igathirĩra kuo.
Àwọn oníṣòwò yà kúrò ní ọ̀nà wọn, wọ́n gòkè sí ibi asán, wọ́n sì run.
19 Ikundi cia agendi cia Tema icaragia maaĩ, agendi a wonjoria a Sheba makamacaria marĩ na mwĩhoko.
Ẹgbẹ́ oníṣòwò Tema ń wá omi, àwọn oníṣòwò Ṣeba ń dúró dè wọ́n ní ìrètí.
20 Magathĩĩnĩka, tondũ makoretwo marĩ na kĩĩrĩgĩrĩro; no maakinya ho magakora hatirĩ kĩndũ.
Wọ́n káàárẹ̀, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e; wọ́n dé bẹ̀, wọ́n sì dààmú.
21 O na inyuĩ-rĩ, mũtuĩkĩte andũ matangĩheana ũteithio; muonaga ũndũ wa kũmakania mũgetigĩra.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin dàbí wọn; ẹ̀yin rí ìrẹ̀sílẹ̀ mi àyà sì fò mí.
22 Niĩ-rĩ, nĩ ndĩ ndoiga atĩrĩ: ‘Heanai kĩndũ nĩ ũndũ wakwa, ngũũrai na indo cianyu,
Èmi ó ha wí pé, ‘Ẹ mú ohun fún mi wá, tàbí pé ẹ fún mi ní ẹ̀bùn nínú ohun ìní yín?
23 honokiai guoko-inĩ gwa thũ, ngũũrai kuuma moko-inĩ ma arĩa matarĩ tha’?
Tàbí, ẹ gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá ni, tàbí, ẹ rà mí padà kúrò lọ́wọ́ alágbára nì’?
24 “Atĩrĩrĩ, ndutaai ũhoro na nĩngũkira; nyonereriai harĩa hĩtĩtie.
“Ẹ kọ́ mi, èmi ó sì pa ẹnu mi mọ́ kí ẹ sì mú mi wòye níbi tí mo gbé ti ṣìnà.
25 Kaĩ ciugo cia ma irĩ ruo-ĩ! No rĩrĩ, ngarari cianyu nĩ kĩhooto kĩrĩkũ irarehe?
Wò ó! Bí ọ̀rọ̀ òtítọ́ ti lágbára tó ṣùgbọ́n kí ni àròyé ìbáwí yín jásí?
26 Anga mũrenda kũruta mahĩtia ũrĩa njugĩte, mũgatua ciugo cia mũndũ ũũmĩirwo tha taarĩ rũhuho?
Ẹ̀yin ṣè bí ẹ tún ọ̀rọ̀ mi ṣe àti ohùn ẹnu tí ó dàbí afẹ́fẹ́ ṣe àárẹ̀.
27 Inyuĩ o na no mũcuukĩre mwana wa ngoriai mĩtĩ, na mwendie mũrata wanyu.
Àní ẹ̀yin ṣe gẹ́gẹ́ bí aláìní baba, ẹ̀yin sì da iye lé ọ̀rẹ́ yín.
28 “No rĩu-rĩ, ndamũthaitha mwĩtĩkĩre kũndora. Anga no ngĩheenanie o maitho-inĩ manyu?
“Nítorí náà, kí èyí kí ó tó fún yín. Ẹ má wò mi! Nítorí pé ó hàn gbangba pé, ní ojú yín ni èmi kì yóò ṣèké.
29 Mwĩcũraniei nĩguo mũtikogomie kĩhooto; njookererai, nĩgũkorwo wĩhokeku wakwa nĩguo ũraarũithio.
Èmi ń bẹ̀ yín, ẹ padà, kí ó má sì ṣe jásí ẹ̀ṣẹ̀; àní, ẹ sì tún padà, àre mi ń bẹ nínú ọ̀rọ̀ yìí.
30 Nĩ kũrĩ wĩhia ũrĩ mĩromo-inĩ yakwa? Anga kanua gakwa gatingĩhota gũkũũrana maũndũ ma rũmena?
Àìṣedéédéé ha wà ní ahọ́n mi? Ǹjẹ́ ìtọ́wò ẹnu mi kò kúkú le mọ ohun ti ó burú jù?