< Ayubu 30 >

1 “No rĩu-rĩ, andũ ethĩ kũngĩra nĩmaanyũrũragia, arĩa o na itangĩendire gũturanĩra maithe mao na ngui ciakwa cia rũũru.
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn tí mo gbà ní àbúrò ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà baba ẹni tí èmi kẹ́gàn láti tò pẹ̀lú àwọn ajá nínú agbo ẹran mi.
2 Hinya wa moko mao ũngĩangʼunire nakĩ, kuona atĩ hinya wao nĩwamehereire?
Kí ni ìwúlò agbára ọwọ́ wọn sí mi, níwọ̀n ìgbà tí agbára wọn ti fi wọ́n sílẹ̀?
3 Nĩmathĩnĩkĩte nĩ ũndũ wa wagi na ngʼaragu, ũtukũ-rĩ, moorũũraga bũrũri mũngʼaru, bũrũri mwanangĩku ũkirĩte ihooru.
Wọ́n rù nítorí àìní àti ìyàn wọ́n ń rìn káàkiri ní ilẹ̀ gbígbẹ ní ibi ìkọ̀sílẹ̀ ní òru.
4 Maahaaraga nyeni cia mahuti ma cumbĩ kuuma ihinga-inĩ, na irio ciao ciarĩ mĩri ya mũtĩ wa kĩhaato.
Àwọn ẹni tí ń já ewé iyọ̀ ní ẹ̀bá igbó; gbogbo igikígi ni oúnjẹ jíjẹ wọn.
5 Nĩmaingatirwo kuuma kũrĩ mũingĩ, makiugĩrĩrio ta maarĩ aici.
A lé wọn kúrò láàrín ènìyàn, àwọn ènìyàn sì pariwo lé wọn lórí bí ẹní pariwo lé olè lórí.
6 Nĩmahatĩrĩirio maikarage mĩkuru-inĩ ya tũrũũĩ tũhũu, kũu ndwaro-inĩ cia mahiga na marima-inĩ marĩa marĩ thĩ.
A mú wọn gbe inú pàlàpálá òkúta àfonífojì, nínú ihò ilẹ̀ àti ti òkúta.
7 Maanagia ta nyamũ kũu ihinga-inĩ, makahatĩkanagĩra kũu mahuti-inĩ.
Wọ́n ń dún ní àárín igbó wọ́n kó ara wọn jọ pọ̀ ní abẹ́ ẹ̀gún neteli.
8 Rũciaro rũtarĩ kĩene na rũtarĩ rĩĩtwa, nĩ rwarutũrũrirwo ruume kũu bũrũri-inĩ.
Àwọn ọmọ ẹni tí òye kò yé, àní àwọn ọmọ lásán, a sì lé wọn jáde kúrò ní orí ilẹ̀.
9 “Na rĩu ariũ ao maraanyũrũria na rwĩmbo; ngagĩtuĩka wa kuunagwo thimo nĩo.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, àwọn ọmọ wọn ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà nínú orin; àní èmi di ẹni ìṣọ̀rọ̀ sí láàrín wọn.
10 Nĩmathũire na magaikaraga haraihu na niĩ; matiĩtigagĩra kũnduĩra mata ũthiũ.
Wọ́n kórìíra mi; wọ́n sá kúrò jìnnà sí mi, wọn kò sì bìkítà láti tutọ́ sí mi lójú.
11 Nĩ ũndũ rĩu Ngai nĩaregeretie ũta wakwa, na akandeehera mathĩĩna-rĩ, matirĩ ũndũ merigagĩrĩria gwĩka marĩ harĩa ndĩ.
Nítorí Ọlọ́run ti tú okùn ìyè mi, ó sì pọ́n mi lójú; àwọn pẹ̀lú sì dẹ ìdẹ̀kùn níwájú mi.
12 Mwena wakwa wa ũrĩo kũrĩ rũrĩrĩ rũratharĩkĩra; maigagĩra magũrũ makwa mĩtego, na magaaka ihumbu ciao cia gũũtharĩkĩra.
Àwọn ènìyàn lásán dìde ní apá ọ̀tún mi; wọ́n tì ẹsẹ̀ mi kúrò, wọ́n sì la ipa ọ̀nà ìparun sílẹ̀ dè mí.
13 Maharaganagia njĩra yakwa; mahotaga kũnyũnũha o na gũtarĩ na mũndũ ũramateithia.
Wọ́n da ipa ọ̀nà mi rú; wọ́n sì sọ ìparun mi di púpọ̀, àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.
14 Mokĩte ta matoonyeire mwanya-inĩ mwariĩ; mokĩire gatagatĩ ga kũu kwanangĩku, makaamomokera.
Wọ́n ya sí mi bí i omi tí ó ya gbuuru; ní ariwo ńlá ni wọ́n rọ́ wá.
15 Imakania nĩcihootete; gĩtĩĩo gĩakwa kĩũmbũrĩtwo ta kĩhurutĩtwo nĩ rũhuho, naguo ũgitĩri wakwa ũkabuĩria ta itu.
Ẹ̀rù ńlá bà mí; wọ́n lépa ọkàn mi bí ẹ̀fúùfù, àlàáfíà mi sì kọjá lọ bí àwọ̀ sánmọ̀.
16 “Na rĩu muoyo wakwa nĩũrathirĩrĩkĩra; matukũ ma thĩĩna nĩmanyiitĩte.
“Àti nísinsin yìí, ayé mi n yòrò lọ díẹ̀díẹ̀; ọjọ́ ìpọ́njú mi dì mímú.
17 Ũtukũ ũtheecangaga mahĩndĩ makwa; ruo rwa gũthegenya rũtindigithagĩria.
Òru gún mi nínú egungun mi, èyí tí ó bù mí jẹ kò sì sinmi.
18 Ngai angũnjakũnjaga ta nguo na ũndũ wa ũhoti wake mũnene; aanyiitaga ta kanjũ yakwa ngingo-inĩ.
Nípa agbára ńlá rẹ̀ Ọlọ́run wà bí aṣọ ìbora fún mi, ó sì lẹ̀ mọ́ mi ní ara yíká bí aṣọ ìlekè mi.
19 Anjikĩtie ndoro-inĩ, ngatuĩka ta rũkũngũ na ta mũhu.
Ọlọ́run ti mú mi lọ sínú ẹrẹ̀, èmi sì dàbí eruku àti eérú.
20 “Nĩwe ndĩrakaĩra, o Wee Ngai, no ndũranjĩtĩka; ndĩrarũgama, no wee no kũndora ũrandora.
“Èmi ké pè ọ́ ìwọ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi lóhùn; èmi dìde dúró ìwọ sì wò mí lásán.
21 Wee nĩũngarũrũkĩte ũtarĩ na tha; ũtharĩkĩire na hinya wa guoko gwaku.
Ìwọ padà di ẹni ìkà sí mi; ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ fi dè mí ní ọ̀nà.
22 Nĩũũhurĩtie, ũkaandindĩka mbere ya rũhuho; ũũnyugutanĩtie kĩhuhũkanio-inĩ.
Ìwọ gbé mi sókè sí inú ẹ̀fúùfù, ìwọ mú mi fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì sọ mí di asán pátápátá.
23 Nĩnjũũĩ nĩũkanginyia o gĩkuũ-inĩ, ũndware kũrĩa gwathĩrĩirwo arĩa othe marĩ muoyo.
Èmi sá à mọ̀ pé ìwọ yóò mú mi lọ sínú ikú, sí ilé ìpéjọ tí a yàn fún gbogbo alààyè.
24 “Ti-itherũ gũtirĩ mũndũ ũũkagĩrĩra mũndũ ũthuthĩkĩte ngoro, hĩndĩ ĩrĩa egũkaya ateithio arĩ mĩnyamaro-inĩ.
“Bí ó ti wù kí ó rí, ẹnìkan kí yóò ha nawọ́ rẹ̀ nígbà ìṣubú rẹ̀, tàbí kì yóò ké nínú ìparun rẹ̀.
25 Niĩ-rĩ, githĩ ndianarĩrio nĩ arĩa marĩ na thĩĩna? Githĩ ngoro yakwa ndĩanaiguĩra arĩa athĩĩni kĩeha?
Èmi kò ha sọkún bí fún ẹni tí ó wà nínú ìṣòro? Ọkàn mi kò ha bàjẹ́ fún tálákà bí?
26 No rĩrĩ, rĩrĩa ndeerĩgagĩrĩra wega, ũũru ũgĩũka; rĩrĩa ndaacaragia ũtheri-rĩ, hĩndĩ ĩyo nduma ĩgĩũka.
Nígbà tí mo fojú ṣọ́nà fún àlàáfíà, ibi sì dé; nígbà tí mo dúró de ìmọ́lẹ̀, òkùnkùn sì dé.
27 Nda yakwa ndĩtigaga kũruruma; matukũ ma thĩĩna nĩmanginyĩire.
Ikùn mí n ru kò sì sinmi, ọjọ́ ìpọ́njú ti dé bá mi.
28 Thiiaga njirĩte biũ, no ti ũndũ wa kũhĩa nĩ riũa; ngarũgama kĩũngano-inĩ ngakaya ndeithio.
Èmí ń rìn kiri nínú ọ̀fọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú oòrùn; èmi dìde dúró ní àwùjọ mo sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́.
29 Nduĩkĩte mũrũ wa nyina na mbwe, ngatuĩka mũthiritũ wa ndundu.
Èmi ti di arákùnrin ìkookò, èmi di ẹgbẹ́ àwọn ògòǹgò.
30 Gĩkonde gĩakwa nĩkĩgarũrũkĩte, gĩgathita na gĩkoonũka; mwĩrĩ wakwa ũhiũhĩte nĩ ũrugarĩ.
Àwọ̀ mi di dúdú ní ara mi; egungun mi sì jórun fún ooru.
31 Kĩnanda gĩakwa kĩa mũgeeto kĩrutaga o mũgambo wa gũcakaya, naguo mũtũrirũ wakwa ũkaruta o mũgambo wa kĩrĩro.
Ohun èlò orin mi pẹ̀lú sì di ti ọ̀fọ̀, àti ìpè orin mi sì di ohùn àwọn tí ń sọkún.

< Ayubu 30 >