< Ayubu 3 >
1 Thuutha wa matukũ macio, Ayubu agĩtumũra kanua, akĩruma mũthenya ũrĩa aaciarirwo.
Ẹ̀yìn èyí ní Jobu yanu, ó sì fi ọjọ́ ìbí rẹ̀ ré
3 “Mũthenya ũrĩa niĩ ndaciarirwo ũroora, o na ũtukũ ũcio kwerirwo atĩrĩ, ‘Mũtumia nĩaciara mwana wa kahĩĩ!’
“Kí ọjọ́ tí a bí mi kí ó di ìgbàgbé, àti òru ni, nínú èyí tí a wí pé, ‘A lóyún ọmọkùnrin kan!’
4 Mũthenya ũcio-rĩ, ũrotuĩka o nduma; Ngai arĩ igũrũ aroaga kũũrũmbũiya; mũthenya ũcio ũroaga gũthererwo nĩ ũtheri.
Kí ọjọ́ náà kí ó já si òkùnkùn, kí Ọlọ́run kí ó má ṣe kà á sí láti ọ̀run wá; bẹ́ẹ̀ ni kí ìmọ́lẹ̀ kí ó má ṣe mọ́ sí i.
5 Mũthenya ũcio ũrokĩĩnyiitĩrwo nĩ nduma nene na kĩĩruru gĩa gĩkuũ; ũrohumbĩrwo nĩ itu; nduma ĩrotooria ũtheri waguo.
Kí òkùnkùn àti òjìji ikú fi ṣe ti ara wọn; kí àwọsánmọ̀ kí ó bà lé e; kí ìṣúdudu ọjọ́ kí ó pa láyà.
6 Ũtukũ ũcio-rĩ, ũronyiitwo nĩ nduma ndumanu; ũroaga gũtaranĩrio na mĩthenya ĩrĩa ĩngĩ ya mwaka, o na kana ũtarwo harĩ mweri o na ũrĩkũ.
Kí òkùnkùn kí ó ṣú bo òru náà biribiri, kí ó má ṣe yọ pẹ̀lú ọjọ́ ọdún náà: kí a má ṣe kà a mọ́ iye ọjọ́ oṣù.
7 Ũtukũ ũcio ũrothaata; o na gũtikanoigwo ngemi ũtukũ ũcio.
Kí òru náà kí ó yàgàn; kí ohun ayọ̀ kan kí ó má ṣe wọ inú rẹ̀ lọ.
8 Arĩa marumaga mĩthenya maroruma mũthenya ũcio, o acio moĩ kwarahũra nyamũ ĩrĩa ĩĩtagwo Leviathani.
Kí àwọn tí í fi ọjọ́ gégùn ún kí o fi gégùn ún, tí wọ́n mura tán láti ru Lefitani sókè.
9 Njata ciaguo cia rũciinĩ irotuĩka nduma; ũroeterera ũtheri na wage kũwona, o na ũroaga kuona ruoro rũgĩtema,
Kí ìràwọ̀ òwúrọ̀ ọjọ́ rẹ̀ kí ó ṣókùnkùn; kí ó má wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó máa mọ́ sí i, bẹ́ẹ̀ ni kí ó má ṣe rí àfẹ̀mọ́júmọ́
10 nĩ ũndũ ndũigana kũhinga mĩrango ya nda ya maitũ, na ndũigana kũgirĩrĩria maitho makwa kuona thĩĩna.
nítorí tí kò sé ìlẹ̀kùn inú ìyá mi, láti pa ìbànújẹ́ rẹ́ ní ojú mi.
11 “Ndaagire gũkua ngĩciarwo nĩkĩ? Ndaagire gũkua ngiuma nda nĩkĩ?
“Èéṣe tí èmi kò fi kú láti inú wá, tàbí tí èmi kò kú ní ìgbà tí mo ti inú jáde wá?
12 Ndaamũkĩrirwo maru-inĩ nĩkĩ? Ndaamũkĩrirwo nyondo-inĩ atĩ nĩguo nyongithio nĩkĩ?
Èéṣe tí orúnkún wá pàdé mi, tàbí ọmú tí èmi yóò mu?
13 Nĩgũkorwo rĩu ingĩkomete ndĩ na thayũ; rĩu ingĩrĩ toro hurũkĩte
Ǹjẹ́ nísinsin yìí èmi ìbá ti dùbúlẹ̀ jẹ́ẹ́; èmi ìbá ti sùn, èmi ìbá ti sinmi
14 hamwe na athamaki na aheani kĩrĩra a gũkũ thĩ arĩa meeyakĩire kũndũ kũrĩa kwanangĩku rĩngĩ,
pẹ̀lú àwọn ọba àti ìgbìmọ̀ ayé tí wọ́n mọ ilé fún ara wọn wá dùbúlẹ̀ nínú ìsọdahoro.
15 o hamwe na aathani arĩa maarĩ na thahabu, o arĩa maiyũrĩtie nyũmba ciao betha.
Tàbí pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé tí ó ní wúrà, tí wọ́n sì fi fàdákà kun ilé wọn.
16 Ningĩ-rĩ, nĩ kĩĩ kĩagiririe thikwo tĩĩri-inĩ ta kĩhuno o na kana ta gakenge karĩa gatoonire ũtheri wa riũa?
Tàbí bí ọlẹ̀ tí a sin, èmi kì bá ti sí: bí ọmọ ìṣunú tí kò rí ìmọ́lẹ̀?
17 Kũu andũ arĩa aaganu nĩmatigĩte kũnyamarĩka, na kũu arĩa anogu nĩmahurũkĩte.
Níbẹ̀ ni ẹni búburú ṣíwọ́ ìyọnilẹ́nu, níbẹ̀ ni ẹni àárẹ̀ wà nínú ìsinmi.
18 Kũu-rĩ, mĩgwate o nayo nĩĩkenagĩra kwaraha kwayo; nĩĩtigĩte kũigua kĩgũthũko kĩa nyabaara ya ngombo.
Níbẹ̀ ni àwọn ìgbèkùn sinmi pọ̀, wọn kò gbóhùn amúnisìn mọ́.
19 Andũ arĩa anini na arĩa anene othe marĩ kuo, nayo ngombo nĩĩrekereirio kuuma kũrĩ mũmĩathi.
Àti èwe àti àgbà wà níbẹ̀, ẹrú sì di òmìnira kúrò lọ́wọ́ olówó rẹ̀.
20 “Nĩ kĩĩ gĩtũmaga andũ arĩa marĩ na mĩnyamaro maheo ũtheri, naguo muoyo ũkaheo arĩa marĩ na ruo rwa ngoro,
“Nítorí kí ni a ṣe fi ìmọ́lẹ̀ fún òtòṣì, àti ìyè fún ọlọ́kàn kíkorò,
21 o acio meriragĩria gĩkuũ na gĩtingĩũka, o arĩa magĩcaragia gũkĩra kĩndũ kĩa goro kĩrĩa kĩhithe,
tí wọ́n dúró de ikú, ṣùgbọ́n òun kò wá, tí wọ́n wá a jù ìṣúra tí a bò mọ́lẹ̀ pamọ́ lọ.
22 acio maiyũragwo nĩ gĩkeno magakena maakinya mbĩrĩra?
Ẹni tí ó yọ̀ gidigidi, tí inú wọ́n sì dùn nígbà tí wọ́n wá ibojì òkú rí?
23 Nĩ kĩĩ gĩtũmaga muoyo ũheo mũndũ ũũrĩte njĩra, o ũcio mũhingĩrĩrie nĩ Ngai?
Kí ni a fi ìmọ́lẹ̀ fún ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ fi ara pamọ́ fún, tí Ọlọ́run sì ṣọgbà dí mọ́ ká?
24 Nĩ ũndũ handũ ha ndĩe irio, no kuumwo nyumagwo nĩ ngoro; nakuo gũcaaya gwakwa gũitĩkaga ta maaĩ.
Nítorí pé èémí-ẹ̀dùn wà ṣáájú oúnjẹ mi; ìkérora mi sì tú jáde bí omi.
25 Ũndũ ũrĩa ndeetigagĩra nĩũngorete; ũndũ ũrĩa wamakagia mũno nĩguo ũnginyĩrĩire.
Nítorí pé ohun náà tí mo bẹ̀rù gidigidi ni ó dé bá mi yìí, àti ohun tí mo fòyà rẹ̀ bá mi ó sì ṣubú lù mí.
26 Ndionaga thayũ, o na kana ngahoorera; ndionaga ũhurũko, no mĩnyamaro.”
Èmi wà láìní àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ní ìsinmi; bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ni ìfàyàbalẹ̀, bí kò ṣe ìdààmú.”