< Ayubu 21 >
1 Ningĩ Ayubu agĩcookia atĩrĩ:
Jobu wá dáhùn, ó sì wí pé,
2 “Thikĩrĩriai wega ciugo ciakwa; rekei ũndũ ũyũ ũtuĩke nĩguo mũkũũhooreria naguo.
“Ẹ tẹ́tí sílẹ̀ dáradára sì àwọn ọ̀rọ̀ mi, kí èyí kí ó jásí ìtùnú fún mi.
3 Ngirĩrĩriai na niĩ njarie, na ndaarĩkia kwaria-rĩ, mũgĩcooke mũũnyũrũrie.
Ẹ jọ̀wọ́ mi ki èmi sọ̀rọ̀; lẹ́yìn ìgbà ìwọ le máa fi mi ṣẹ̀sín ń ṣo.
4 “Niĩ-rĩ, kaĩ mateta makwa meerekeirio mũndũ? Ngũkĩaga kũremwo nĩ gũkirĩrĩria nĩkĩ?
“Àròyé mi ha ṣe sí ènìyàn bí? Èétise tí ọkàn mi kì yóò fi ṣe àìbalẹ̀?
5 Ta ndorai mũgege; mwĩnyiite tũnua twanyu na moko nĩ kũmaka.
Ẹ wò mí fín, kí ẹnu kí ó sì yà yín, kí ẹ sì fi ọwọ́ lé ẹnu yín.
6 Ndĩciiragia ũhoro ũyũ ngamaka mũno; ngethithimũkwo nĩ mwĩrĩ, ngambĩrĩria kũinaina.
Àní nígbà tí mo rántí, ẹ̀rù bà mí, ìwárìrì sì mú mi lára.
7 Atĩrĩ, andũ arĩa aaganu marekagwo matũũre muoyo nĩkĩ, magakũra o na magakĩrĩrĩria kũgĩa na ũhoti?
Nítorí kí ní ènìyàn búburú fi wà ní ayé, tí wọ́n gbó, àní tí wọ́n di alágbára ní ipa?
8 Nĩmeonagĩra ciana ciao ikĩgaacĩra kũu marĩ, makoona rũciaro rwao rũkĩĩhaanda mbere ya maitho mao.
Irú-ọmọ wọn fi ìdí kalẹ̀ ní ojú wọn pẹ̀lú wọn, àti ọmọ ọmọ wọn ní ojú wọn.
9 Mĩciĩ yao ĩikaraga ĩgitĩirwo na ĩtarĩ na guoya; naruo rũthanju rwa Ngai rũtimahũũraga.
Ilé wọn wà láìní ewu àti ẹ̀rù, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá ìbínú Ọlọ́run kò sí lára wọn.
10 Ndegwa ciao itiagaga kũgwatia; ngʼombe ciao iciaraga, na itihunaga.
Akọ màlúù wọn a máa gùn, kì í sì tàsé; abo màlúù wọn a máa bí, kì í sì í ṣẹ́yun.
11 Moimagaragia twana twao tũingĩ o ta rũũru; ciana icio ciao ikaina igĩtũrũhaga.
Wọn a máa rán àwọn ọmọ wọn wẹ́wẹ́ jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa jo kiri.
12 Nao o ene mainaga makĩhũũraga tũhembe na inanda cia mũgeeto; mekenagia na mũgambo wa mũtũrirũ.
Wọ́n mú ohun ọ̀nà orin, ìlù àti haapu; wọ́n sì ń yọ̀ sí ohùn fèrè.
13 Matũũraga mĩaka yao magaacĩire, na magathiĩ mbĩrĩra-inĩ marĩ na thayũ. (Sheol )
Wọ́n n lo ọjọ́ wọn nínú ọrọ̀; wọn sì lọ sí ipò òkú ní àlàáfíà. (Sheol )
14 Na no-o meeraga Mũrungu atĩrĩ, ‘Thiĩ! Tigana na ithuĩ! Tũtikwenda kũmenya njĩra ciaku.
Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa!’ Nítorí pé wọn kò fẹ́ ìmọ̀ ipa ọ̀nà rẹ.
15 Mwene-Hinya-Wothe nĩwe ũ, atĩ nĩguo tũmũtungatagĩre? Tũkũgunĩka nakĩ tũngĩmũhooya?’
Kí ni Olódùmarè tí àwa ó fi máa sìn in? Èrè kí ni a ó sì jẹ bí àwa ba gbàdúrà sí i?
16 No rĩrĩ, kũgaacĩra kwao gũtirĩ moko-inĩ mao ene, nĩ ũndũ ũcio niĩ njikaraga haraaya na kĩrĩra kĩa andũ arĩa aaganu.
Kíyèsi i, àlàáfíà wọn kò sí nípa ọwọ́ wọn; ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi réré.
17 “Na rĩrĩ, nĩ maita maigana tawa wa arĩa aaganu ũhoragio? Nĩ maita maigana makoragwo nĩ mũtino, na nĩ maita maigana Ngai amagayagĩra ruo nĩ kũmarakarĩra?
“Ìgbà mélòó mélòó ní a ń pa fìtílà ènìyàn búburú kú? Ìgbà mélòó mélòó ní ìparun wọn dé bá wọn, tí Ọlọ́run sì í máa pín ìbìnújẹ́ nínú ìbínú rẹ̀?
18 Nĩ maita maigana matuĩkaga ta nyeki nyũmũ ĩkũhurutwo nĩ rũhuho, o na kana ta maragara marĩa mombũragwo nĩ kĩhuhũkanio?
Wọ́n dàbí àgékù koríko níwájú afẹ́fẹ́, àti bí ìyàngbò, tí ẹ̀fúùfù ńlá fẹ́ lọ.
19 Kuugagwo atĩrĩ, ‘Ngai aigagĩra ciana iherithia rĩa ithe wao.’ No rĩrĩ, nĩ kaba Ngai aherithie mũndũ ũcio we mwene, nĩguo amenye nĩehĩtie!
Ẹ̀yin wí pé, ‘Ọlọ́run to ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jọ fún àwọn ọmọ rẹ̀.’ Jẹ́ kí ó san án fún un, yóò sì mọ̀ ọ́n.
20 Maitho make nĩmeyonere mwanangĩko wake mwene; nĩarekwo akunde mangʼũrĩ ma Mwene-Hinya-Wothe.
Ojú rẹ̀ yóò rí ìparun ara rẹ̀, yóò sì máa mu nínú ríru ìbínú Olódùmarè.
21 Nĩ ũndũ-rĩ, anga no eetangaga ha ũhoro wa andũ ake arĩa agaatiga na thuutha, matukũ make maathira?
Nítorí pé àlàáfíà kí ni ó ní nínú ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí a bá ké iye oṣù rẹ̀ kúrò ní agbede-méjì?
22 “Nĩ kũrĩ mũndũ o na ũmwe ũngĩhota kũruta Mũrungu atĩ nĩguo agĩe na ũmenyo, kuona atĩ Mũrungu nĩwe ũtuanagĩra ciira, o na agatuĩra arĩa atũũgĩirie mũno?
“Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni le kọ Ọlọ́run ní ìmọ̀? Òun ní í sá à ń ṣe ìdájọ́ ẹni ibi gíga.
23 Nĩ kũrĩ mũndũ ũkuuaga arĩ na hinya wake wothe, arĩ mũgitĩre wega biũ, na arĩ na thayũ,
Ẹnìkan a kú nínú pípé agbára rẹ̀, ó wà nínú ìrora àti ìdákẹ́ pátápátá.
24 mwĩrĩ wake ũheetwo irio wega, na mahĩndĩ ma mĩthiimo yake marĩ o maigũ.
Ọpọ́n rẹ̀ kún fún omi ọmú, egungun rẹ̀ sì tutù fún ọ̀rá.
25 Mũndũ ũngĩ agakua arĩ na marũrũ ma ngoro, atarĩ aakenera kĩndũ kĩega o na kĩ.
Ẹlòmíràn a sì kú nínú kíkorò ọkàn rẹ̀, tí kò sì fi inú dídùn jẹun.
26 Makomaga o ro ũndũ ũmwe tĩĩri-inĩ, na eerĩ-rĩ, igunyũ ikamahumbĩra.
Wọ́n o dùbúlẹ̀ bákan náà nínú erùpẹ̀, kòkòrò yóò sì ṣùbò wọ́n.
27 “Niĩ nĩnjũũĩ wega ũrĩa mũreciiria, ngamenya mathugunda manyu maakũhĩtĩria namo.
“Kíyèsi i, èmi mọ̀ èrò inú yín àti àrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.
28 Mũrooria atĩrĩ, ‘Rĩu nyũmba ya mũndũ ũrĩa mũnene ĩkĩrĩ ha, na hema ĩrĩa andũ aaganu maratũũraga-rĩ, ĩkĩrĩ ha?’
Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní ilé ọmọ-aládé, àti níbo ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’
29 Kaĩ mũtarĩ muoria andũ arĩa mathiiaga ngʼendo? Kaĩ mũtarũmbũyagia ũrĩa mamwĩraga:
Ẹ̀yin kò béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ń kọjá lọ ní ọ̀nà? Ẹ̀yin kò mọ̀ àmì wọn,
30 atĩ mũndũ ũrĩa mwaganu nĩ aiguagĩrwo tha mũthenya wa mũtino, atĩ nĩahonokagio mũthenya wa mangʼũrĩ?
pé ènìyàn búburú ní a fi pamọ́ fún ọjọ́ ìparun. A ó sì mú wọn jáde ní ọjọ́ ríru ìbínú.
31 Nũũ ũreganaga na mĩtugo ya mũndũ mwaganu maitho-inĩ make? Nũũ ũmũrĩhagia kũringana na maũndũ marĩa aaneka?
Ta ni yóò tako ipa ọ̀nà rẹ̀ lójúkojú, ta ni yóò sì san án padà fún un ní èyí tí ó ti ṣe?
32 Atwaragwo mbĩrĩra-inĩ, nayo mbĩrĩra yake ĩkarangagĩrwo.
Síbẹ̀ a ó sì sin ín ní ọ̀nà ipò òkú, a ó sì máa ṣọ́ ibojì òkú.
33 Tĩĩri wa gĩtuamba nĩũrĩ mũrĩo harĩ we; andũ othe nĩwe marũmagĩrĩra, na kĩrĩndĩ gĩtangĩtarĩka gĩgathiiaga mbere yake.
Ògúlùtu àfonífojì yóò dùn mọ́ ọn. Gbogbo ènìyàn yóò sì máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, bí ènìyàn àìníye ti lọ síwájú rẹ̀.
34 “Mwakĩhota atĩa kũũhooreria na ndeto cia tũhũ? Hatirĩ kĩndũ gĩtigaru harĩ macookio manyu tiga o maheeni!”
“Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin fi ń tù mí nínú lásán, bí ò ṣe pé ní ìdáhùn yín, àrékérekè wa níbẹ̀!”