< Ayubu 13 >
1 “Atĩrĩrĩ, maitho makwa nĩmonete maũndũ macio mothe, matũ makwa nĩmamaiguĩte na magataũkĩrwo nĩmo.
“Wò ó, ojú mi ti rí gbogbo èyí rí, etí mí sì gbọ́, ó sì ti yé mi.
2 Ũrĩa mũũĩ o na niĩ nĩnjũũĩ; mũtirĩ oogĩ kũngĩra.
Ohun tí ẹ̀yin mọ̀, èmi mọ̀ pẹ̀lú, èmi kò kéré sí i yin.
3 No niĩ ndĩrenda kwaria na Mwene-Hinya-Wothe, na ngerirĩria gũciira na Mũrungu.
Nítòótọ́ èmi ó bá Olódùmarè sọ̀rọ̀, èmi sì ń fẹ́ bá Ọlọ́run sọ àsọyé.
4 No inyuĩ-rĩ, mũranjigĩrĩra ndeto cia maheeni; inyuothe mũrĩ athondekani a tũhũ!
Ẹ̀yin fi irọ́ bá mi sọ̀rọ̀, oníṣègùn lásán ni gbogbo yín.
5 Naarĩ korwo mwakira ki! Ũndũ ũcio ũngĩtuĩka ũũgĩ harĩ inyuĩ.
Háà! ẹ̀yin kì bá kúkú dákẹ́! Èyí ni kì bá sì ṣe ọgbọ́n yín.
6 Na rĩrĩ, thikĩrĩriai kĩhooto gĩakwa; iguai gũthaithana kwa mĩromo yakwa.
Ẹ gbọ́ àwíyé mi nísinsin yìí; ẹ sì fetísílẹ̀ sí àròyé ẹnu mi.
7 Kaĩ mũngĩaria ũũru mũkĩarĩrĩria Mũrungu? Kaĩ mũngĩaria maheeni igũrũ rĩake?
Ẹ̀yin fẹ́ sọ ìsọkúsọ fún Ọlọ́run? Ki ẹ sì fi ẹ̀tàn sọ̀rọ̀ gbè é?
8 Kaĩ mũngĩmuonia kĩmenyano? Kaĩ mũgũciirĩrĩra Mũrungu?
Ẹ̀yin fẹ́ ṣe ojúsàájú rẹ̀? Ẹ̀yin fẹ́ gbèjà fún Ọlọ́run?
9 Angĩmũtuĩria inyuĩ-rĩ, ũndũ ũcio no ũtuĩke mwega? No mũmũheenie ta ũrĩa mũngĩheenia mũndũ?
Ó ha dára to tí yóò hú àṣírí yín síta, tàbí kí ẹ̀yin tàn án bí ẹnìkan ti í tan ẹnìkejì?
10 Ti-itherũ no amũrũithie mũngĩtuĩka a kuonania kĩmenyano na hitho.
Yóò máa bá yín wí nítòótọ́, bí ẹ̀yin bá ṣe ojúsàájú ènìyàn níkọ̀kọ̀.
11 Hĩ, riiri wake ndũngĩmũmakia? Mũtingĩnyiitwo nĩ guoya nĩ ũndũ wake?
Ìwà ọlá rẹ̀ kì yóò bà yín lẹ́rù bí? Ìpayà rẹ̀ kì yóò pá yín láyà?
12 Mĩario yanyu ya ũũgĩ nĩ thimo hũthũ o ta mũhu; ihooto cianyu no ta kwĩgitĩra na rĩũmba.
Àwọn òwe yín dàbí eérú, bẹ́ẹ̀ ni àwọn odi ìlú yin dàbí amọ̀.
13 “Kirai ki, mũreke njarie; o ũrĩa ndĩrĩona-rĩ, rekei nyone.
“Ẹ pa ẹnu yín mọ́ kúrò lára mi, kí èmi kí ó lè sọ̀rọ̀, ki ohun tí ń bọ̀ wá í bá mi, le è máa bọ̀.
14 Nĩ kĩĩ gĩgũtũma ndĩtoonyie ũgwati-inĩ na ngaiga muoyo wakwa moko-inĩ makwa?
Ǹjẹ́ nítorí kí ni èmi ṣe ń fi eyín mi bu ẹran-ara mi jẹ, tí mo sì gbé ẹ̀mí mi lé ara mi lọ́wọ́?
15 O na angĩnjũraga-rĩ, niĩ nowe ndĩrĩĩhokaga; na ti-itherũ nĩ ngatetera mĩthiĩre yakwa hau mbere yake.
Bí ó tilẹ̀ pa mí, síbẹ̀ èmi ó máa gbẹ́kẹ̀lé e, èmi ó máa tẹnumọ́ ọ̀nà mi níwájú rẹ̀.
16 Ti-itherũ, ũndũ ũyũ noguo ũgaatuĩka wa kũũhonokia, nĩgũkorwo mũndũ ũtooĩ Ngai ndangĩũmĩrĩria gũũka mbere yake!
Èyí ni yóò sì ṣe ìgbàlà mi, àgàbàgebè kì yóò wá síwájú rẹ̀.
17 Thikĩrĩriai wega ũhoro wakwa; matũ manyu nĩmakĩigue ũrĩa nguuga.
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi ní ìfarabalẹ̀, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ mí dún ni etí yín.
18 Ti-itherũ nĩhaarĩirie ciira wakwa, na nĩnjũũĩ nĩ nguoneka ndĩ wa kĩhooto.
Wò ó nísinsin yìí, èmi ti mura ọ̀ràn mi sílẹ̀; èmi mọ̀ pé a ó dá mi láre.
19 Nĩ kũrĩ mũndũ ũngĩhota gũũthitanga? Angĩkorwo nĩ kũrĩ-rĩ, no gũkira ngũkira ngue.
Ta ni òun ti yóò bá mi ṣàròyé? Ǹjẹ́ nísinsin yìí, èmi fẹ́ pa ẹnu mi mọ́, èmi ó sì jọ̀wọ́ ẹ̀mí mi lọ́wọ́.
20 “Wee Ngai, ta kĩĩhe o maũndũ maya meerĩ, na ndigũcooka gũkwĩhitha:
“Ṣùgbọ́n, má ṣe ṣe ohun méjì yìí sí mi, nígbà náà ni èmi kì yóò sì fi ara mi pamọ́ kúrò fún ọ.
21 Atĩrĩ, eheria guoko gwaku, gũikare kũraya na niĩ, na ũtige kũũmakia na imakania ciaku.
Fa ọwọ́ rẹ sẹ́yìn kúrò lára mi, má sì jẹ́ kí ẹ̀rù rẹ kí ó pá mi láyà.
22 Ningĩ ũnjĩte na nĩngwĩtĩka, kana ũkĩreke njarie, nawe ũnjookerie.
Nígbà náà ni kí ìwọ kí ó pè, èmi o sì dáhùn, tàbí jẹ́ kí ń máa sọ̀rọ̀, ki ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
23 Nĩ mahĩtia na mehia maigana niĩ njĩkĩte? Nyonia ihĩtia na rĩĩhia rĩakwa.
Mélòó ní àìṣedéédéé àti ẹ̀ṣẹ̀ mi? Mú mi mọ̀ ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ mi.
24 Ũraahitha ũthiũ waku nĩkĩ, na ũkandua thũ yaku?
Nítorí kí ni ìwọ ṣe pa ojú rẹ mọ́, tí o sì yàn mí ní ọ̀tá rẹ?
25 Nĩũngĩnyamaria ithangũ rĩrahurutwo nĩ rũhuho? Nĩũgũtengʼerania na maragara momũ?
Ìwọ ó fa ewé ti afẹ́fẹ́ ń fẹ́ síyìn-ín sọ́hùn-ún ya bi? Ìwọ a sì máa lépa ìyàngbò?
26 Nĩgũkorwo nĩ wandĩkĩte maũndũ marũrũ ma kũnjũkĩrĩra, na ũkaangaĩra igai rĩa mehia ma ũnini wakwa.
Nítorí pé ìwọ kọ̀wé ohun kíkorò sí mi, o sì mú mi jogún àìṣedéédéé èwe mi.
27 Wohaga magũrũ makwa na mĩnyororo; ũrangagĩra njĩra ciakwa ciothe na ũndũ wa gũcora njoro makinya ma magũrũ makwa.
Ìwọ kàn àbà mọ́ mi lẹ́sẹ̀ pẹ̀lú, ìwọ sì ń wò ipa ọ̀nà ìrìn mi ní àwòfín; nípa fífi ìlà yí gígísẹ̀ mi ká.
28 “Nĩ ũndũ ũcio mũndũ amocaga ta kĩndũ kĩbuthĩte, agathira ta nguo ĩrĩĩtwo nĩ memenyi.
“Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn ń ṣègbé bí ohun ìdíbàjẹ́, bi aṣọ tí kòkòrò jẹ.