< Jeremia 40 >

1 Ĩno nĩyo ndũmĩrĩri ĩrĩa yakinyĩrĩire Jeremia yumĩte kũrĩ Jehova thuutha wa Nebuzaradani ũcio mũnene wa arangĩri a mũthamaki kũmũrekereria oime kũu Rama. Nĩakorete Jeremia arĩ muohe na mĩnyororo arĩ gatagatĩ-inĩ ka andũ arĩa othe maatahĩtwo kuuma Jerusalemu na Juda rĩrĩa maatwaragwo Babuloni marĩ ohe.
Ọ̀rọ̀ náà sì tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa lẹ́yìn tí Nebusaradani balógun àwọn ẹ̀ṣọ́ ti tú u sílẹ̀ ní Rama. Ó rí Jeremiah tí a fi ẹ̀wọ̀n dè láàrín gbogbo àwọn tí wọ́n mú ní Jerusalẹmu àti Juda. Wọ́n kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì Babeli.
2 Nake mũnene ũcio wa arangĩri a mũthamaki oona Jeremia, akĩmwĩra atĩrĩ, “Jehova Ngai waku nĩwe watuĩrĩire kũndũ gũkũ mwanangĩko ũyũ.
Nígbà tí balógun ẹ̀ṣọ́ rí Jeremiah, ó sọ fún un wí pé, “Olúwa Ọlọ́run rẹ ni ó pàṣẹ ibí yìí fún mi.
3 Na rĩu-rĩ, Jehova nĩatũmĩte gwĩkĩke ũguo; ekĩte o ta ũrĩa oigire. Maũndũ maya mothe meekĩkĩte nĩ ũndũ inyuĩ andũ aya nĩmwehĩirie Jehova na mũkĩaga kũmwathĩkĩra.
Nísinsin yìí, Olúwa ti mú un jáde; ó ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ pé òun yóò ṣe. Gbogbo èyí ṣẹlẹ̀ nítorí wí pé ẹ̀yin ènìyàn ṣẹ̀ sí Olúwa, àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀.
4 No rĩrĩ, ũmũthĩ nĩngũkuohora mĩnyororo ĩno ũrĩ nayo moko. Ũka tũthiĩ nawe Babuloni, akorwo nĩũkwenda, na niĩ nĩndĩkũmenyagĩrĩra; no ũngĩkorwo ndũkwenda tũthiĩ nawe, tiga gũũka. Atĩrĩrĩ, bũrũri ũyũ wothe ũrĩ mbere yaku; thiĩ o harĩa hothe ũngĩenda.”
Ṣùgbọ́n, ní òní yìí mò ń tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọwọ́ rẹ. Bí o bá fẹ́, tẹ̀lé mi ká lọ sí Babeli, èmi yóò sì bojútó ọ; ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá fẹ́, dúró síbí. Wò ó, gbogbo orílẹ̀-èdè wà níwájú rẹ, lọ sí ibikíbi tí ó bá tẹ́ ọ lọ́rùn.”
5 No rĩrĩ, Jeremia atanagarũrũka acooke-rĩ, Nebuzaradani akĩmwarĩria rĩngĩ, akĩmwĩra atĩrĩ, “Cooka kũrĩ Gedalia mũrũ wa Ahikamu, mũrũ wa Shafani, ũrĩa mũthamaki wa Babuloni atuĩte mũrũgamĩrĩri wa matũũra ma Juda, mũgatũũre nake kũu hamwe na andũ arĩa angĩ, kana ũgĩthiĩ o harĩa hangĩ hothe ũngĩenda.” Ningĩ mũnene ũcio wa arangĩri akĩmũhe irio, o na akĩmũhe kĩheo, akĩreka ethiĩre.
Ẹ̀wẹ̀, kí ó tó di pé Jeremiah pẹ̀yìndà láti máa lọ, Nebusaradani fi kún un wí pé, “Padà tọ Gedaliah ọmọ Ahikamu lọ, ọmọ Ṣafani, ẹni tí ọba Babeli ti fi jẹ baálẹ̀ lórí ìlú Juda, kí o sì máa gbé ní àárín àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o máa lọ ibikíbi tí ó bá tọ́ ní ojú rẹ.” Nígbà náà ni balógun náà fún un ní oúnjẹ àti ẹ̀bùn, ó sì jẹ́ kí ó lọ.
6 Nĩ ũndũ ũcio Jeremia agĩthiĩ kũrĩ Gedalia, mũrũ wa Ahikamu kũu Mizipa, magĩtũũra nake gatagatĩ-inĩ ka andũ acio angĩ maatigĩtwo bũrũri-inĩ ũcio.
Báyìí ni Jeremiah lọ sí ọ̀dọ̀ Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu ní Mispa, ó sì dúró tì í láàrín àwọn ènìyàn tí ó ṣẹ́kù ní ilẹ̀ náà.
7 Rĩrĩa anene othe a mbũtũ cia ita na andũ ao arĩa maarĩ kũu bũrũri-inĩ ũcio mwaraganu maiguire atĩ mũthamaki wa Babuloni nĩatuĩte Gedalia mũrũ wa Ahikamu barũthi wa bũrũri ũcio, na atĩ nĩamũtuĩte mũrũgamĩrĩri wa arũme, na andũ-a-nja, na ciana, o acio maarĩ athĩĩni mũno kũu bũrũri ũcio, arĩa mataatahirwo matwarwo Babuloni-rĩ,
Nígbà tí gbogbo àwọn olórí ogun àti àwọn ènìyàn tí wọ́n kù lórí orílẹ̀-èdè náà gbọ́ pé ọba Babeli ti yan Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu gẹ́gẹ́ bí baálẹ̀ ní ilẹ̀ náà; àti pé ó ti fi àwọn ọkùnrin, obìnrin àti ọmọdé tí wọ́n jẹ́ tálákà ní ilẹ̀ náà tí wọn kò kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì sí ìkáwọ́ rẹ̀,
8 magĩthiĩ kũrĩ Gedalia kũu Mizipa: nao maarĩ Ishumaeli mũrũ wa Nethania, na Johanani na Jonathani ariũ a Karea, na Seraia mũrũ wa Tanihumethu, na ariũ a Efai ũrĩa Mũnetofathi, na Jaazania mũrũ wa Mũmaakathi, marĩ na andũ ao.
wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Gedaliah ní Mispa; Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah, Johanani àti Jonatani ọmọkùnrin ti Karea, Seraiah ọmọkùnrin Tanhumeti tí í ṣe ọmọkùnrin Efai ará Netofa àti Jesaniah ọmọkùnrin Maakati àti àwọn ènìyàn wọn.
9 Gedalia mũrũ wa Ahikamu, mũrũ wa Shafani akĩĩhĩta nĩguo amatĩtĩrithie marĩ hamwe na andũ ao, akĩmeera atĩrĩ, “Tigai gwĩtigĩra gũtungatĩra andũ aya a Babuloni. Tũũrai bũrũri ũyũ na mũtungatage mũthamaki wa Babuloni, na nĩmũrĩonaga maũndũ mega.
Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu, ọmọkùnrin ti Ṣafani ṣe ìbúra láti tún fi dá àwọn ènìyàn lójú pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù láti sin àwọn Babeli.” Ó sọ wí pé, “Gbé ilẹ̀ náà kí ẹ sì máa sin ọba Babeli, yóò sì dára fún un yín.
10 Niĩ mwene nĩngũtũũra gũkũ Mizipa nĩgeetha ndĩmwaragĩrĩrie kũrĩ andũ a Babuloni arĩa marĩũkaga kũrĩ ithuĩ, no inyuĩ-rĩ, thondekai ndibei, na mũgethage matunda ma hĩndĩ ya riũa, o na maguta, mwĩigĩre ndigithũ-inĩ cianyu cia mũthiithũ, na mũtũũre matũũra-inĩ marĩa mwĩnyiitĩire.”
Èmi fúnra mi yóò dúró ní Mispa láti ṣojú yín níwájú Babeli tí wọ́n tọ̀ wá wá. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni yóò máa kórè ọtí wáìnì, èso igi àti òróró; kí ẹ sì kó wọn sí inú àpò àpamọ́wọ́ yín; kí ẹ̀yin sì máa gbé ní ìlú tí ẹ ti gbà.”
11 Hĩndĩ ĩrĩa Ayahudi arĩa othe maarĩ Moabi, na Amoni, na arĩa maarĩ Edomu, o na arĩa maarĩ mabũrũri marĩa mangĩ mothe maiguire atĩ mũthamaki wa Babuloni nĩatigĩtie matigari kũu Juda, na atĩ nĩatuĩte Gedalia mũrũ wa Ahikamu, mũrũ wa Shafani, barũthi wao-rĩ,
Nígbà tí gbogbo àwọn Juda ní Moabu, Ammoni, Edomu àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè gbọ́ pé ọba Babeli ti fi ohun tókù sílẹ̀ ní Juda, àti pé ó ti yan Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu ọmọkùnrin Ṣafani gẹ́gẹ́ bí gómìnà lórí wọn.
12 othe magĩcooka bũrũri wa Juda kũrĩ Gedalia kũu Mizipa, moimĩte mabũrũri-inĩ mothe marĩa maahurunjũkĩire. Nao magĩĩthondekera ndibei nyingĩ, o na makĩgetha matunda maingĩ ma hĩndĩ ya riũa.
Gbogbo wọn padà wá sí ilẹ̀ Juda sọ́dọ̀ Gedaliah ní Mispa láti orílẹ̀-èdè gbogbo tí a ti lé wọn sí. Wọ́n sì kórè ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọtí wáìnì àti èso igi.
13 Johanani mũrũ wa Karea, marĩ na anene othe a mbũtũ cia ita arĩa maarĩ o kũu bũrũri ũcio mwaraganu, magĩũka kũrĩ Gedalia kũu Mizipa,
Johanani ọmọkùnrin ti Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí ó kù ní orílẹ̀-èdè sì tọ Gedaliah wá ní Mispa.
14 nao makĩmwĩra atĩrĩ, “Kaĩ ũtamenyete atĩ Balisi mũthamaki wa andũ a Amoni nĩatũmĩte Ishumaeli mũrũ wa Nethania oke akũrute muoyo?” No Gedalia mũrũ wa Ahikamu ndaametĩkirie.
Wọ́n sì sọ fún un wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ha mọ̀ pé Baalisi ọba àwọn Ammoni ti rán Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah láti lọ mú ẹ̀mí rẹ?” Ṣùgbọ́n Gedaliah ọmọkùnrin ti Ahikamu kò gbà wọ́n gbọ́.
15 Hĩndĩ ĩyo Johanani mũrũ wa Karea akĩarĩria Gedalia na hitho marĩ kũu Mizipa, akĩmwĩra atĩrĩ: “Njĩtĩkĩria thiĩ ngoorage Ishumaeli mũrũ wa Nethania, na gũtirĩ mũndũ ũkũmenya ũhoro ũcio. Nĩ kĩĩ gĩgũtũma ende gũkũruta muoyo, nĩguo atũme Ayahudi aya othe mecookanĩrĩirie harĩwe mahurunjũke, namo matigari ma Juda mathire biũ?”
Nígbà náà ni Johanani ọmọkùnrin Karea sọ ní ìkọ̀kọ̀ fún Gedaliah ní Mispa pé, “Jẹ́ kí èmi lọ pa Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah, ẹnikẹ́ni kò sì ní mọ èyí. Kí ni ìdí rẹ̀ tí yóò ṣe mú ẹ̀mí rẹ, tí o sì ṣe fẹ́ mú àwọn Júù tí ó yí ọ ká túká, kí ìyókù Juda sì parun?”
16 Nowe Gedalia mũrũ wa Ahikamu akĩĩra Johanani mũrũ wa Karea atĩrĩ, “Ndũkae gwĩka ũndũ ta ũcio! Ũhoro ũcio ũraaria ũkoniĩ Ishumaeli ti wa ma.”
Ṣùgbọ́n Gedaliah ọmọ Ahikamu sọ fún Johanani ọmọ Karea pé, “Má ṣe ṣe nǹkan yìí! Nítorí nǹkan tí ò ń sọ nípa Iṣmaeli kì í ṣe òtítọ́.”

< Jeremia 40 >