< Jeremia 27 >

1 O kĩambĩrĩria-inĩ kĩa wathani wa Zedekia mũrũ wa Josia, mũthamaki wa Juda, ndũmĩrĩri ĩno nĩyakinyĩrĩire Jeremia yumĩte kũrĩ Jehova:
Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìṣèjọba Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé.
2 Nake Jehova akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Wĩthondekere icooki rĩa mĩkwa na mĩtĩ mĩkĩranie, ũcooke ũmĩĩkĩre ngingo.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Ṣe àjàgà àti ọ̀pá irin fún ara rẹ, kí o sì fiwé ọrùn rẹ.
3 Ũcooke ũtũme ndũmĩrĩri kũrĩ athamaki a Edomu, na Moabi, na Amoni, na Turo na Sidoni ũmĩnengerete abarũthi ao arĩa mokĩte Jerusalemu kũrĩ Zedekia mũthamaki wa Juda.
Kí o rán ọ̀rọ̀ sí ọba ti Edomu, Moabu, Ammoni, Tire àti Sidoni láti ọwọ́ àwọn ikọ̀ tí ó wá sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ Sedekiah ọba Juda.
4 Mahe ndũmĩrĩri matwarĩre anene ao, ũmeere atĩrĩ, ‘Ũũ nĩguo Jehova Mwene-Hinya-Wothe, Ngai wa Isiraeli, ekuuga: “Ĩrai anene anyu atĩrĩ:
Kí o sì pàṣẹ fún wọn láti wí fún àwọn olúwa wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: “Sọ èyí fún àwọn olúwa rẹ.
5 Niĩ nĩ niĩ ndombire thĩ na andũ arĩa marĩ kuo o na nyamũ iria irĩ kuo na hinya wakwa mũnene na ndambũrũkĩtie guoko gwakwa, na ndĩmĩheaga o mũndũ ũrĩa ingĩenda kũhe.
Pẹ̀lú agbára ńlá mi àti ọwọ́ nínà mi ni Èmi dá ayé, ènìyàn àti ẹranko tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, mo sì fún ẹni tí ó wu ọkàn mi.
6 Na rĩu nĩngũneana mabũrũri manyu mothe kũrĩ ndungata yakwa Nebukadinezaru, mũthamaki wa Babuloni; nĩngũtũma o na nyamũ cia gĩthaka imũtungatagĩre.
Nísinsin yìí, Èmi yóò fa gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ fún Nebukadnessari ọba Babeli ìránṣẹ́ mi; Èmi yóò sì mú àwọn ẹranko búburú wọ̀n-ọn-nì jẹ́ tirẹ̀.
7 Ndũrĩrĩ ciothe nĩikamũtungatĩra we, na mũriũ, o na mwana wa mũriũ, nginya rĩrĩa ihinda rĩa bũrũri wake rĩgaakinya; hĩndĩ ĩyo ndũrĩrĩ nyingĩ na athamaki anene nĩmakamũtua wa kũmatungatagĩra arĩ o.
Gbogbo orílẹ̀-èdè ni yóò máa sìn ín àti àwọn ọmọdọ́mọ rẹ̀ títí ilẹ̀ rẹ yóò fi dé; ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè àti àwọn ọba ńlá ni yóò tẹríba fún.
8 “‘“No rĩrĩ, rũrĩrĩ o ruothe kana ũthamaki o wothe arĩa makaaga gũtungatĩra Nebukadinezaru mũthamaki wa Babuloni, kana marege kũinamia ngingo mekĩrwo icooki rĩake, nĩngaherithia rũrĩrĩ rũu na rũhiũ rwa njora, na ngʼaragu, na mũthiro, nginya rĩrĩa ngarũniinithia na guoko gwake, ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
“‘“Ṣùgbọ́n tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan kò bá ní sin Nebukadnessari ọba Babeli, tàbí kí ó tẹ orí rẹ̀ ba ní abẹ́ àjàgà rẹ̀, Èmi yóò fi ìyà jẹ orílẹ̀-èdè náà nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, ni Olúwa wí títí Èmi yóò fi run wọ́n nípa ọwọ́ rẹ̀.
9 Nĩ ũndũ ũcio-rĩ, tigai gũthikĩrĩria anabii anyu, na arathi anyu, na ataũri-a-irooto, na aragũri, kana andũ-ago, o acio mamwĩraga atĩrĩ: ‘Inyuĩ mũtirĩ hĩndĩ mũgaatungatĩra mũthamaki wa Babuloni.’
Nítorí náà, ẹ má ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí àwọn wòlíì yín, àwọn aláfọ̀ṣẹ yín, àwọn tí ń rọ́ àlá fún un yín, àwọn oṣó yín, tàbí àwọn àjẹ́ yín tí wọ́n ń sọ fún un yín pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli.’
10 Nĩ ũndũ ũcio nĩ ũhoro wa maheeni mamũrathagĩra, marĩa magaatũma mũtahwo, mũtwarwo kũndũ kũraya na bũrũri wanyu; ngamũingata, mũniinwo biũ.
Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún un yín èyí tí yóò mú u yín jìnnà réré kúrò ní ilẹ̀ yín; kí Èmi kí ó lè lé yín jáde, kí ẹ̀yin ó sì ṣègbé.
11 No rũrĩrĩ rũrĩa ruothe rũkainamia ngingo rwĩkĩrwo icooki rĩa mũthamaki wa Babuloni na rũmũtungatĩre-rĩ, nĩngetĩkĩria rũrĩrĩ rũu rũtũũre bũrũri-inĩ wao kĩũmbe, marĩmage na maikarage kuo, ũguo nĩguo Jehova ekuuga.”’”
Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kankan bá tẹ orí rẹ̀ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, tí ó sì sìn ín, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè náà wà lórí ilẹ̀ rẹ̀ láti máa ro ó, àti láti máa gbé ibẹ̀ ni Olúwa wí.”’”
12 Nĩndaheanire ndũmĩrĩri o ro ĩyo kũrĩ Zedekia mũthamaki wa Juda. Ngĩmwĩra atĩrĩ, “Inamia ngingo yaku, wĩkĩrwo icooki rĩa mũthamaki wa Babuloni; mũtungatĩre we mwene na andũ ake, na nĩũgũtũũra muoyo.
Èmi sì sọ ọ̀rọ̀ náà fún Sedekiah ọba Juda wí pé: “Tẹ orí rẹ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, sìn ín ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ yóò sì yè.
13 Wee mwene mũrĩ na andũ aku-rĩ, mũgũkĩĩninithia nĩkĩ na rũhiũ rwa njora, na ngʼaragu, o na mũthiro, o icio Jehova atuĩrĩire rũrĩrĩ o ruothe rũrĩa rũtagatungatĩra mũthamaki wa Babuloni?
Kí ló dé tí ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ yóò ṣe kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, èyí tí Olúwa fi ń halẹ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè tí kò bá sin ọba Babeli?
14 Tiga gũthikĩrĩria ũhoro wa anabii acio makwĩraga atĩrĩ, ‘Wee ndũrĩ hĩndĩ ũgaatungatĩra mũthamaki wa Babuloni,’ tondũ makũrathagĩra ũhoro wa maheeni.
Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì tí ó ń sọ wí pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli,’ nítorí pé àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín.
15 ‘Niĩ ndimatũmĩte,’ nĩguo Jehova ekuuga. ‘Mararatha ũhoro wa maheeni, makĩgwetaga rĩĩtwa rĩakwa. Nĩ ũndũ ũcio nĩngamũingata, na inyuĩ mũniinwo biũ, wee hamwe na anabii acio makũrathagĩra mohoro.’”
‘Èmi kò rán wọn ni Olúwa wí. Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Nítorí náà, Èmi yóò lé wọn, wọn yóò sì ṣègbé, ẹ̀yin pẹ̀lú àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín.’”
16 Ngĩcooka ngĩĩra athĩnjĩri-Ngai na andũ acio angĩ othe atĩrĩ: “Ũũ nĩguo Jehova ekuuga: Tigai gũthikĩrĩria anabii acio mamwĩraga atĩrĩ, ‘Hatigairie o kahinda kanini, nacio indo iria ciarutirwo nyũmba ya Jehova icookio kuuma Babuloni.’ Maramũrathĩra ũhoro wa maheeni.
Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹ má ṣe fetí sí nǹkan tí àwọn wòlíì ń sọ pé, ‘Láìpẹ́ ohun èlò ilé Olúwa ni a ó kó padà láti Babeli,’ àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ. Ẹ má tẹ́tí sí wọn.
17 Tigai kũmathikĩrĩria. Tungatĩrai mũthamaki wa Babuloni, na nĩmũgũtũũra muoyo. Kaĩ itũũra rĩĩrĩ rĩngĩkĩanangwo nĩkĩ?
Má ṣe tẹ́tí sí wọn, ẹ máa sin ọba Babeli, ẹ̀yin yóò sì yè. Èéṣe tí ìlú yóò fi di ahoro?
18 Angĩkorwo acio nĩ anabii marĩ na ndũmĩrĩri kuuma kũrĩ Jehova-rĩ, nĩmagĩthaithe Jehova Mwene-Hinya-Wothe nĩguo indo iria itigarĩte gũkũ thĩinĩ wa nyũmba ya Jehova, o na thĩinĩ wa nyũmba ya mũthamaki wa Juda, o na kũu Jerusalemu itigatwarwo Babuloni.
Tí wọ́n bá jẹ́ wòlíì, tí wọ́n sì ní ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ kí wọ́n bẹ Olúwa àwọn ọmọ-ogun kí a má ṣe kó ohun èlò tí ó kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
19 Nĩ ũndũ ũũ nĩguo Jehova Mwene-Hinya-Wothe oigĩte ũhoro ũkoniĩ itugĩ cia hekarũ, na karia ka maaĩ, indo cia kũigĩrĩra iria ingĩ, na indo ciothe cia nyũmba ingĩkorwo itigaire gũkũ itũũra-inĩ rĩĩrĩ inene,
Nítorí pé, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ nípa àwọn opó, omi Òkun ní ti ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti ní ti ohun èlò ìyókù tí ó kù ní ìlú náà.
20 iria Nebukadinezaru mũthamaki wa Babuloni ataakuuire hĩndĩ ĩrĩa aatahire Jekonia mũrũ wa Jehoiakimu mũthamaki wa Juda agĩthaamio arutĩtwo Jerusalemu na agĩtwarwo Babuloni, we mwene hamwe na andũ othe a Juda na a Jerusalemu arĩa maarĩ igweta:
Èyí tí Nebukadnessari ọba Babeli kò kó lọ nígbà tí ó mú Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn ọlọ́lá Juda àti Jerusalẹmu.
21 ĩĩ, ti-itherũ Jehova Mwene-Hinya-Wothe, Ngai wa Isiraeli oigĩte atĩrĩ ũhoro ũkoniĩ indo icio itigaire thĩinĩ wa nyũmba ya Jehova, o na thĩinĩ wa gĩikaro kĩa mũthamaki wa Juda, o na kũu Jerusalemu:
Lóòótọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí nípa àwọn ohun ìṣúra tí ó ṣẹ́kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti ní Jerusalẹmu:
22 ‘Nĩigatwarwo Babuloni, na igaikara kũu nginya mũthenya ũrĩa ngooka gũcigĩĩra,’ ũguo nĩguo Jehova ekuuga. ‘Hĩndĩ ĩyo nĩngacirehe ndĩcicookie gũkũ.’”
‘A ó mú wọn lọ sí ilẹ̀ Babeli, ní ibẹ̀ ni wọn ó sì wà títí di ìgbà tí mo bá padà,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa. ‘Lẹ́yìn èyí, Èmi yóò mú wọn padà, Èmi yóò sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ ní ibí yìí.’”

< Jeremia 27 >