< Jeremia 25 >
1 Ndũmĩrĩri nĩyakinyĩrĩire Jeremia ĩkoniĩ andũ othe a Juda, mwaka-inĩ wa kana wa gũthamaka kwa Jehoiakimu mũrũ wa Josia mũthamaki wa Juda, naguo nĩguo warĩ mwaka wa mbere wa gũthamaka kwa Nebukadinezaru mũthamaki wa Babuloni.
Ọ̀rọ̀ sì tọ Jeremiah wá nípa àwọn ènìyàn Juda ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kìn-ín-ní Nebukadnessari ọba Babeli.
2 Nĩ ũndũ ũcio Jeremia ũcio mũnabii akĩĩra andũ othe a Juda na arĩa othe maatũũraga Jerusalemu atĩrĩ:
Nítorí náà, Jeremiah wòlíì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti sí àwọn olùgbé Jerusalẹmu.
3 Ihinda rĩa mĩaka mĩrongo ĩĩrĩ na ĩtatũ, kuuma mwaka-inĩ wa ikũmi na ĩtatũ wa ũthamaki wa Josia mũrũ wa Amoni mũthamaki wa Juda, nginya ũmũthĩ, ndũmĩrĩri cia Jehova itũire inginyagĩrĩra, na niĩ ngamũhe ũhoro wacio kaingĩ kaingĩ, no mũtithikĩrĩirie.
Fún odidi ọdún mẹ́tàlélógún, bẹ̀rẹ̀ láti ọdún kẹtàlá Josiah, ọmọ Amoni ọba Juda, títí di ọjọ́ yìí, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, mo sì ti sọ ọ́ fún un yín láti ìgbà dé ìgbà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
4 Na rĩrĩ, o na gũtuĩka Jehova nĩamũtũmĩire ndungata ciake ciothe cia anabii kaingĩ, kaingĩ, mũtiigana gũthikĩrĩria kana gũtega matũ manyu nĩguo mũmaigue.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn wòlíì sí i yín láti ìgbà dé ìgbà, ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
5 Maamwĩrĩte atĩrĩ, “Garũrũkai rĩu o ũmwe wanyu, mũtigane na mĩthiĩre yanyu mĩũru na ciĩko cianyu njũru, nĩguo mũtũũre bũrũri-inĩ ũrĩa Jehova aamũheire inyuĩ o na maithe manyu nginya tene.
Wọ́n sì wí pé, “Ẹ yípadà olúkúlùkù yín kúrò ní inú ibi rẹ̀ àti ní ọ̀nà ibi rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì lè dúró ní ilẹ̀ tí Olúwa fún un yín àti àwọn baba yín títí láéláé.
6 Mũtikanarũmĩrĩre ngai ingĩ mũcitungatĩre kana mũcihooe; mũtikandakarie na ũndũ wa kĩrĩa mwĩthondekeire na moko manyu. Mwathĩka ũguo, hĩndĩ ĩyo ndikamũgera ngero.”
Má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn láti sìn wọ́n tàbí bọ wọ́n; ẹ má ṣe mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ ti fi ọwọ́ yín ṣe. Nígbà náà ni Èmi kò ní ṣe yín ní ibi.”
7 Jehova ekuuga atĩrĩ, “No inyuĩ mũtiathikĩrĩirie, no mũgĩĩthirĩkia nĩguo ndaakare na ũndũ wa kĩrĩa mwethondekeire na moko manyu, na inyuĩ nĩmũkĩĩgerithĩtie ngero.”
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni ẹ sì ti mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ fi ọwọ́ yín ṣe, ẹ sì ti mú ibi wá sórí ara yín.”
8 Nĩ ũndũ ũcio Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekuuga atĩrĩ: “Tondũ nĩmũregete gũthikĩrĩria ndũmĩrĩri yakwa,
Nítorí náà, Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ èyí: “Nítorí wí pé ẹ̀yin kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi,
9 nĩngwĩta andũ othe a mwena wa gathigathini hamwe na ndungata yakwa Nebukadinezaru, mũthamaki wa Babuloni,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga. “Nĩngũmarehe mookĩrĩre bũrũri ũyũ na arĩa matũũraga kuo o na mookĩrĩre ndũrĩrĩ ciothe iria iũrigiicĩirie. Nĩngamaniina biũ na ndũme matuĩke ta kĩndũ kĩa ihooru na gĩa kũmeneka, na manangĩke nginya tene.
Èmi yóò pe gbogbo àwọn ènìyàn àríwá, àti ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò sì mú wọn dìde lòdì sí ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé rẹ̀ àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè àyíká rẹ̀. Èmi yóò pa wọ́n run pátápátá, Èmi yóò sọ wọ́n di nǹkan ẹ̀rù àti yẹ̀yẹ́ àti ìparun ayérayé.
10 Nĩngũmehereria mĩgambo ya gĩkeno na ya kũrũũhia, o na mĩgambo ya mũhiki na mũhikania, na mũrurumo wa ithĩi, o na ũtheri wa tawa.
Èmi yóò sì mú ìró ayọ̀ àti inú dídùn kúrò lọ́dọ̀ wọn; ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó, ìró ọlọ òkúta àti ìmọ́lẹ̀ fìtílà.
11 Bũrũri ũyũ wothe ũgaatuĩka bũrũri ũtarĩ kĩndũ o na ũkirĩte ihooru, nacio ndũrĩrĩ icio nĩigatungatĩra mũthamaki wa Babuloni mĩaka mĩrongo mũgwanja.
Gbogbo orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì sìn ọba Babeli ní àádọ́rin ọdún.
12 “No rĩrĩ, mĩaka mĩrongo mũgwanja yathira, nĩngaherithia mũthamaki wa Babuloni na rũrĩrĩ rwake, herithie bũrũri ũcio wa andũ a Babuloni nĩ ũndũ wa mahĩtia mao, na ningĩ nĩngatũma bũrũri ũcio ũtũũre ũkirĩte ihooru nginya tene,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
“Ṣùgbọ́n, nígbà tí àádọ́rin ọdún náà bá pé, Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Babeli àti orílẹ̀-èdè rẹ, ilẹ̀ àwọn ará Babeli nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò sọ ọ́ di ahoro títí láé.
13 “Nĩngarehithĩria bũrũri ũcio maũndũ mothe marĩa ndanoiga atĩ nĩmakaũkora, marĩa mothe mandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩĩrĩ, o macio maarathĩirwo ndũrĩrĩ ciothe nĩ Jeremia.
Èmi yóò sì mú gbogbo ohun tí mo ti sọ wọ̀nyí wá sórí ilẹ̀ náà, gbogbo ohun tí a ti sọ àní gbogbo èyí tí a ti kọ sínú ìwé yìí, èyí tí Jeremiah ti sọtẹ́lẹ̀ sí gbogbo orílẹ̀-èdè.
14 Nĩgũkorwo o ene nĩmagatuĩka ngombo cia ndũrĩrĩ nyingĩ na athamaki anene; na niĩ nĩngerĩhĩria harĩo kũringana na ciĩko ciao, o na kũringana na maũndũ marĩa maneeka na moko mao.”
Àwọn fúnra wọn yóò sì sin orílẹ̀-èdè púpọ̀ àti àwọn ọba ńlá. Èmi yóò sì sán fún oníkálùkù gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”
15 Atĩrĩrĩ, Jehova Ngai wa Isiraeli, aanjĩĩrire atĩrĩ: “Oya gĩkombe gĩkĩ kĩiyũrĩte ndibei ya mangʼũrĩ makwa kuuma guoko-inĩ gwakwa, na ũkĩnyuithie ndũrĩrĩ iria ciothe ngũgũtũma kũrĩ cio.
Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí fún mi: “Gba ago yìí ní ọwọ́ mí tí ó kún fún ọtí wáìnì ìbínú mi, kí o sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè ti mo rán ọ sí mu ún.
16 Rĩrĩa ikaanyua-rĩ, nĩigatũgũũga na igũrũke nĩ ũndũ wa rũhiũ rwa njora rũrĩa ngaarehithia gatagatĩ-inĩ kao.”
Nígbà tí wọ́n bá mu ún, wọn yóò ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n: bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n di aṣiwèrè nítorí idà tí yóò ránṣẹ́ sí àárín wọn.”
17 Nĩ ũndũ ũcio ngĩoya gĩkombe kĩu kuuma guoko-inĩ kwa Jehova, na ngĩtũma ndũrĩrĩ iria ciothe aandũmĩte kũrĩ cio ikĩnyuĩre:
Mo sì gba ago náà lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó rán mi sí mu ún.
18 itũũra rĩa Jerusalemu na matũũra ma Juda, na athamaki akuo na anene akuo, nĩguo manangĩke, na matuĩke ta kĩndũ kĩrĩ magigi na gĩa kũmeneka, o na kĩndũ kĩgwatĩtwo nĩ kĩrumi, ta ũrĩa matariĩ ũmũthĩ;
Jerusalẹmu àti àwọn ìlú Juda, àwọn ọba wọn pẹ̀lú àwọn aláṣẹ wọn, láti sọ wọ́n di ohun ìparun, ohun ẹ̀rù, ẹ̀sìn àti ègún, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti rí lónìí yìí.
19 ningĩ Firaũni mũthamaki wa Misiri, na arĩa mamũtungataga, na anene ake na andũ ake othe,
Farao ọba Ejibiti, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn aláṣẹ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
20 na ageni arĩa othe matũũraga kuo; na ningĩ athamaki othe a Uzu; na ningĩ athamaki othe a Afilisti (aya nĩ andũ a Ashikeloni, na Gaza, na Ekironi, o na andũ arĩa maatigaire Ashidodi);
Àti gbogbo àwọn ènìyàn àjèjì tí ó wà níbẹ̀; gbogbo àwọn ọba Usi, gbogbo àwọn ọba Filistini, gbogbo àwọn ti Aṣkeloni, Gasa, Ekroni àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kù sí Aṣdodu.
21 ningĩ andũ a Edomu, na Moabi na Amoni;
Edomu, Moabu àti Ammoni;
22 ningĩ athamaki othe a Turo na Sidoni; o na athamaki a icigĩrĩra iria irĩ mũrĩmo wa iria;
gbogbo àwọn ọba Tire àti Sidoni; gbogbo àwọn ọba erékùṣù wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ìkọjá Òkun.
23 ningĩ andũ a Dedani, na Tema, na Buzu, na arĩa othe marĩ kũraya;
Dedani, Tema, Busi àti gbogbo àwọn tí ń gbé lọ́nà jíjìn réré.
24 ningĩ athamaki othe a Arabia, na athamaki othe a ndũrĩrĩ ngʼeni arĩa matũũraga werũ-inĩ;
Gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn ọba àwọn àjèjì ènìyàn tí ń gbé inú aginjù.
25 ningĩ athamaki othe a Zimuri, na Elamu na Media;
Gbogbo àwọn ọba Simri, Elamu àti Media.
26 o na athamaki othe a mwena wa gathigathini, a gũkuhĩ na a kũraya, marũmanĩrĩre mũndũ na ũrĩa ũngĩ: moimĩte mothamaki-inĩ mothe ma thĩ. Na thuutha wao othe, mũthamaki wa Sheshaki nĩagakĩnyuĩra o nake.
Àti gbogbo àwọn ọba àríwá ní tòsí àti lọ́nà jíjìn, ẹnìkínní lẹ́yìn ẹnìkejì; gbogbo àwọn ìjọba lórí orílẹ̀ ayé. Àti gbogbo wọn, ọba Ṣeṣaki náà yóò sì mu.
27 “Ũcooke ũmeere atĩrĩ, ‘Ũũ nĩguo Jehova Mwene-Hinya-Wothe, Ngai wa Isiraeli, ekuuga: Nyuai, mũrĩĩo na mũtahĩke, mũcooke mũgũe na mũtikanacooke gũũkĩra, nĩ ũndũ wa rũhiũ rwa njora rũrĩa ngaarehithia gatagatĩ-inĩ kanyu.’
“Nígbà náà, sọ fún wọn, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí. Mu, kí o sì mú àmuyó kí o sì bì, bẹ́ẹ̀ ni kí o sì ṣubú láì dìde mọ́ nítorí idà tí n ó rán sí àárín yín.
28 No rĩrĩ, mangĩkaarega kuoya gĩkombe kĩu kuuma guoko-inĩ gwaku manyue-rĩ, ũkameera atĩrĩ, ‘Ũũ nĩguo Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekuuga: No nginya mũnyue!
Ṣùgbọ́n bí wọ́n ba kọ̀ láti gba ago náà ní ọwọ́ rẹ kí wọ́n sì mu ún, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹyin gbọdọ̀ mu ún!
29 Atĩrĩrĩ, nĩnyambĩrĩirie kũrehe mwanangĩko itũũra-inĩ rĩĩrĩ inene rĩĩtanĩtio na Rĩĩtwa rĩakwa; anga inyuĩ no mwage kũherithio? Mũtikaaga kũherithio, nĩ ũndũ nĩndĩrarehithĩria andũ arĩa othe matũũraga gũkũ thĩ rũhiũ rwa njora, ũguo nĩguo Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekuuga.’
Wò ó, èmi ń mú ibi bọ̀ sí orí orílẹ̀-èdè tí ó ń jẹ́ orúkọ mi; ǹjẹ́ yóò ha a lè lọ láìjìyà? Ẹ̀yin ń pe idà sọ̀kalẹ̀ sórí gbogbo àwọn olùgbé ayé, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ.’
30 “Rĩu marathĩre mohoro maya mothe, ũmeere atĩrĩ: “‘Jehova akaararama arĩ o kũu igũrũ; akaagamba ta ngwa arĩ gĩikaro-inĩ gĩake gĩtheru, na ararame na hinya, okĩrĩre bũrũri wake. Akaanĩrĩra na mũgambo mũnene mũno ta wa andũ arĩa marangagĩrĩria thabibũ, agũthũkĩre andũ othe arĩa matũũraga gũkũ thĩ.
“Nísinsin yìí, sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí nípa wọn: “‘Kí o sì sọ pé, Olúwa yóò bú láti òkè wá, yóò sì bú kíkankíkan sí ilẹ̀ náà. Yóò parí gbogbo olùgbé ayé, bí àwọn tí ń tẹ ìfúntí.
31 Inegene rĩu nĩrĩkaiguĩka nginya ituri-inĩ ciothe cia thĩ, nĩ ũndũ Jehova nĩagaciirithia ndũrĩrĩ; nĩagatuĩra andũ othe ciira na oorage arĩa aaganu na rũhiũ rwa njora,’” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
Ìrọ́kẹ̀kẹ̀ yóò wà títí dé òpin ilẹ̀ ayé, nítorí pé Olúwa yóò mú ìdààmú wá sí orí àwọn orílẹ̀-èdè náà, yóò mú ìdájọ́ wá sórí gbogbo ènìyàn, yóò sì fi àwọn olùṣe búburú fún idà,’” ni Olúwa wí.
32 Ũũ nĩguo Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekuuga: “Atĩrĩrĩ! Mwanangĩko nĩũrahunja kuuma rũrĩrĩ rũmwe nginya rũrĩa rũngĩ; kĩhuhũkanio nĩkĩrahuhũkana kuuma ituri-inĩ cia thĩ.”
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Wò ó! Ibi ń tànkálẹ̀ láti orílẹ̀-èdè kan sí òmíràn; ìjì ńlá yóò sì ru sókè láti òpin ayé.”
33 Ihinda-inĩ rĩu andũ arĩa mooragithĩtio nĩ Jehova magaakorwo maaraganĩte kũndũ guothe, kuuma gĩturi kĩmwe gĩa thĩ nginya kĩrĩa kĩngĩ. Matikarĩrĩrwo, kana monganio, kana mathikwo, no magaaikara ta rũrua, mahurunjũkĩte thĩ.
Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò ṣọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.
34 Rĩrai na mũgirĩke, inyuĩ arĩithi aya; mwĩgaragariei rũkũngũ-inĩ, inyuĩ atongoria a rũũru rwa mbũri. Nĩgũkorwo ihinda rĩanyu rĩa gũthĩnjwo nĩ ikinyu; mũkaagũa mũthuthĩke o ta rĩũmba rĩrĩa rĩega mũno.
Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, ẹ yí nínú eruku, ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran. Nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé, ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.
35 Arĩithi acio matikoona kũndũ gwa kũũrĩra, na atongoria a rũũru rwa mbũri matikoona gwa gwĩtharĩra.
Àwọn olùṣọ́-àgùntàn kì yóò rí ibi sálọ kì yóò sì ṣí àsálà fún olórí agbo ẹran.
36 Thikĩrĩriai mũigue kĩrĩro kĩa arĩithi, o na kĩgirĩko kĩa atongoria a rũũru rwa mbũri, nĩ ũndũ Jehova nĩaranangithia ũrĩithio wao.
Gbọ́ igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn, àti ìpohùnréré ẹkún àwọn olórí agbo ẹran; nítorí pé Olúwa ń pa pápá oko tútù wọn run.
37 Ũrĩithio ũcio wa cianda-inĩ ũtarĩ ũgwati nĩũkanangwo tondũ wa marakara mahiũ ma Jehova.
Ibùgbé àlàáfíà yóò di ahoro, nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
38 Akoimagara ta mũrũũthi ũkiuma kĩmamo-inĩ kĩaguo, na bũrũri wao nĩũgaakira ihooru nĩ tondũ wa rũhiũ rwa njora rwa mũhinyanĩrĩria, na nĩ ũndũ wa marakara mahiũ ma Jehova.
Gẹ́gẹ́ bí kìnnìún yóò fi ibùba rẹ̀ sílẹ̀, ilẹ̀ wọn yóò sì di ahoro, nítorí idà àwọn aninilára, àti nítorí ìbínú ńlá Olúwa.