< Jeremia 14 >
1 Ĩno nĩyo ndũmĩrĩri ya Jehova ĩrĩa yakinyĩrĩire Jeremia ĩkoniĩ ihinda rĩrĩa kwagĩte mbura:
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa sí Jeremiah nípa ti àjàkálẹ̀-ààrùn:
2 “Bũrũri wa Juda nĩũracakaya, namo matũũra makuo makoorwo nĩ hinya; nĩmararĩrĩra bũrũri, nakĩo kĩrĩro nĩkĩambatĩte na igũrũ kiumĩte Jerusalemu.
“Juda káàánú, àwọn ìlú rẹ̀ kérora wọ́n pohùnréré ẹkún fún ilẹ̀ wọn, igbe wọn sì gòkè lọ láti Jerusalẹmu.
3 Andũ arĩa marĩ igweta maratũma ndungata ciao igatahe maaĩ; irathiĩ marima-inĩ ikaaga maaĩ. Iracooka na ndigithũ itarĩ kĩndũ; ikehumbĩra mĩtwe iconokete na ikuĩte ngoro.
Àwọn ọlọ́lá ènìyàn rán àwọn ìránṣẹ́ wọn lọ bu omi, wọ́n lọ sí ìdí àmù ṣùgbọ́n wọn kò rí omi. Wọ́n padà pẹ̀lú ìkòkò òfìfo; ìrẹ̀wẹ̀sì àti àìnírètí bá wọn, wọ́n sì bo orí wọn.
4 Thĩ nĩyatũkangĩte, nĩ ũndũ gũtirĩ mbura yurĩte bũrũri-inĩ, arĩmi nao magakua ngoro, makehumbĩra mĩtwe.
Ilẹ̀ náà sán nítorí pé kò sí òjò ní ilẹ̀ náà; ìrètí àwọn àgbẹ̀ di òfo, wọ́n sì bo orí wọn.
5 O nayo thwariga nĩĩteete gacaũ kayo gaaciarwo o ro ũguo kũu werũ-inĩ, nĩ ũndũ gũtirĩ nyeki.
Kódà, abo àgbọ̀nrín tí ó wà lórí pápá fi ọmọ rẹ̀ tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ bí sílẹ̀, torí pé kò sí koríko.
6 Njagĩ nacio irũgamĩte tũrĩma-igũrũ kũrĩa gũtakũraga kĩndũ, ikĩhũmahũmaga ta mbwe; nĩciũrĩte maitho nĩ kwaga mahuti ma kũrĩa.”
Àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó dúró lórí òkè òfìfo wọ́n sì ń mí ẹ̀fúùfù bí ìkookò ojú wọn kò ríran nítorí pé kò sí koríko jíjẹ.”
7 O na gũtuĩka mehia maitũ nĩmaroimbũra ũũru ũrĩa twĩkĩte, Wee Jehova-rĩ, ĩka ũndũ nĩ tondũ wa rĩĩtwa rĩaku. Nĩgũkorwo gũcooka na thuutha gwitũ nĩ kũnene; nĩtũkwĩhĩirie.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀ṣẹ̀ wa jẹ́rìí lòdì sí wa, wá nǹkan kan ṣe sí i Olúwa, nítorí orúkọ rẹ. Nítorí ìpadàsẹ́yìn wa ti pọ̀jù, a ti ṣẹ̀ sí ọ.
8 Wee Kĩĩrĩgĩrĩro gĩa Isiraeli, o wee Mũhonokia wao hĩndĩ ĩrĩa marĩ na mĩnyamaro, nĩ kĩĩ gĩtũmĩte ũtuĩke ta mũgeni bũrũri-inĩ, kana ta mũgendi ũraarĩrĩire ũtukũ o ũmwe?
Ìrètí Israẹli; ìgbàlà rẹ lásìkò ìpọ́njú, èéṣe tí ìwọ dàbí àlejò ní ilẹ̀ náà bí arìnrìn-àjò tí ó dúró fún bí òru ọjọ́ kan péré?
9 Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte ũikare ta mũndũ mũmaku, ũgaikara ta njamba ĩrĩ hinya ĩtangĩhota kũhonokania? Wee Jehova-rĩ, ũrĩ gatagatĩ gaitũ, na ithuĩ tũgeetanio na rĩĩtwa rĩaku; ndũkanatũtirike!
Èéṣe tí ìwọ dàbí ẹni tí a dààmú, bí jagunjagun tí kò le ran ni lọ́wọ́? Ìwọ wà láàrín wa, Olúwa, orúkọ rẹ ni a sì ń pè mọ́ wa; má ṣe fi wá sílẹ̀.
10 Jehova ekuuga atĩrĩ ũhoro ũkoniĩ andũ aya: “Nĩmendete kũũrũũra mũno; nĩmaregete kũgirĩrĩria magũrũ mao. Nĩ ũndũ ũcio nake Jehova ndangĩmetĩkĩra; rĩu nĩekũririkana waganu wao, na amaherithie nĩ ũndũ wa mehia mao.”
Báyìí ni Olúwa sọ nípa àwọn ènìyàn wọ̀nyí: “Wọ́n fẹ́ràn láti máa rìn kiri; wọn kò kó ọkàn wọn ní ìjánu. Nítorí náà Olúwa kò gbà wọ́n; yóò wá rántí ìwà búburú wọn báyìí, yóò sì fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn jẹ wọ́n.”
11 Ningĩ Jehova akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Tiga kũhoera andũ aya atĩ nĩguo mone wega.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe gbàdúrà fún àlàáfíà àwọn ènìyàn wọ̀nyí.
12 O na mangĩĩhinga kũrĩa irio, ndigathikĩrĩria kĩrĩro kĩao; o na mangĩndutĩra maruta ma njino na maruta ma mũtu-rĩ, ndikametĩkĩra. Nĩ kũniina ngaamaniina na rũhiũ rwa njora, na ngʼaragu, o na mũthiro.”
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n gbààwẹ̀, èmi kò ní tẹ́tí sí igbe wọn. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ìyẹ̀fun, èmi ò nígbà wọ́n. Dípò bẹ́ẹ̀, èmi ó fi idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn pa wọ́n run.”
13 No ngiuga atĩrĩ, “Wũi, Mwathani Jehova, anabii mameeraga atĩrĩ, ‘Mũtikoona rũhiũ rwa njora kana mũhatĩrĩrio nĩ ngʼaragu. Ti-itherũ, nĩngamũhe thayũ wa gũtũũra kũndũ gũkũ.’”
Ṣùgbọ́n mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè. Àwọn wòlíì ń sọ fún wọn pé, ‘Ẹ kò ni rí idà tàbí ìyàn. Dájúdájú èmi ó fún yín ní àlàáfíà tí yóò tọ́jọ́ níbí yìí?’”
14 Hĩndĩ ĩyo Jehova akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Anabii acio mararatha ũhoro wa maheeni makĩgwetaga rĩĩtwa rĩakwa. Niĩ ndimatũmĩte, kana ngamathuura, o na kana ngamaarĩria. Maramũrathĩra mohoro ma cioneki cia maheeni, na ũragũri wa tũhũ, na kũhooya mĩhianano, na maũndũ ma maheeni marĩa methugundĩire na meciiria mao.
Nígbà náà Olúwa sọ fún mi pé, “Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Èmi kò rán wọn, tàbí yàn wọ́n tàbí bá wọn sọ̀rọ̀. Ìran èké ni wọ́n ń rí sí i yín. Àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín nípa ìran ìrírí, àfọ̀ṣẹ, ìbọ̀rìṣà àti ìtànjẹ ọkàn wọn.
15 Nĩ ũndũ ũcio, ũũ nĩguo Jehova ekuuga ũhoro ũkoniĩ anabii arĩa mararatha maũndũ makĩgwetaga rĩĩtwa rĩakwa: Niĩ ndiamatũmĩte, no-o moigaga atĩrĩ, ‘Gũtirĩ rũhiũ rwa njora kana ngʼaragu ikaahutia bũrũri ũyũ.’ Anabii o acio makaaniinwo na rũhiũ rwa njora, na ngʼaragu.
Nítorí náà, èyí ni Olúwa sọ nípa àwọn wòlíì tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ mi. Èmi kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n sì ń sọ pé, ‘Idà kan tàbí ìyàn, kì yóò dé ilẹ̀ yìí.’ Àwọn wòlíì kan náà yóò parẹ́ nípa idà àti ìyàn.
16 Nao andũ acio marathagĩrwo mohoro nĩo, magaikanio na kũu njĩra-inĩ cia itũũra rĩa Jerusalemu tondũ wa ngʼaragu na rũhiũ rwa njora. Gũtikoneka mũndũ wa kũmathika, kana wa gũthika atumia ao, o na kana wa gũthika ariũ ao na airĩtu ao. Nĩngamaitĩrĩria mũtino ũrĩa ũmagĩrĩire.
Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ènìyàn tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún ni a ó lé sí òpópónà Jerusalẹmu torí idà àti ìyàn. Wọn kò ní i rí ẹni tí yóò sìn wọ́n tàbí ìyàwó wọn, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn. Èmi yóò mú ìdààmú tí ó yẹ bá ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
17 “Maarĩrie ũhoro ũyũ, ũmeere atĩrĩ: “‘Rekei maitho makwa maite maithori ũtukũ na mũthenya mategũtigithĩria; nĩgũkorwo mũirĩtu wakwa gathirange, o acio andũ akwa, nĩmũgurarie ũũru, akagũthwo igũtha rĩa kũmũhehenja.
“Kí ìwọ kí ó sì sọ ọ̀rọ̀ yìí fún wọn pé: “‘Jẹ́ kí ojú mi kí ó sun omijé ní ọ̀sán àti ní òru láìdá; nítorí tí a ti ṣá wúńdíá, ọmọ ènìyàn mi ní ọgbẹ́ ńlá pẹ̀lú lílù bolẹ̀.
18 Ingĩtoonya bũrũri-inĩ, nyonaga arĩa moragĩtwo na rũhiũ rwa njora; ingĩtoonya itũũra inene, nyonaga arĩa manyariirĩtwo nĩ ngʼaragu. Mũnabii na mũthĩnjĩri-Ngai, eerĩ nĩmathiĩte bũrũri matooĩ.’”
Bí mo bá lọ sí orílẹ̀-èdè náà, Èmi yóò rí àwọn tí wọ́n fi idà pa. Bí mo bá lọ sí ìlú ńlá, èmi rí àwọn tí ìyàn ti sọ di aláàrùn. Wòlíì àti Àlùfáà ti lọ sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.’”
19 Rĩu-rĩ, kaĩ ũregete Juda biũ? Anga nĩũnyararĩte Zayuni? Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte ũtũhũũre, nginya tũkaaga kĩhonia? Twerĩgĩrĩire thayũ, no gũtirĩ wega tuonete, tũgeterera ihinda rĩa kũhonanio, no rĩrĩ, no maũndũ ma kũmakania tuonete.
Ṣé o ti kọ Juda sílẹ̀ pátápátá ni? Ṣé o ti ṣá Sioni tì? Èéṣe tí o fi pọ́n wa lójú tí a kò fi le wò wá sàn? A ń retí àlàáfíà ṣùgbọ́n ohun rere kan kò tí ì wá, ní àsìkò ìwòsàn ìpayà là ń rí.
20 Nĩtũkumbũra waganu witũ, Wee Jehova, o na wĩhia wa maithe maitũ; nĩ ũndũ ti-itherũ nĩtũkwĩhĩirie.
Olúwa, a jẹ́wọ́ ìwà ibi wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa; lóòótọ́ ni a ti ṣẹ̀ sí ọ.
21 Twagũthaitha ũtige gũtũthũũra, nĩ ũndũ wa rĩĩtwa rĩaku; ndũgaaconorithie gĩtĩ gĩaku kĩa ũnene kĩrĩa kĩrĩ riiri. Ririkana kĩrĩkanĩro kĩrĩa warĩkanĩire na ithuĩ, na ndũgagĩthũkie.
Nítorí orúkọ rẹ má ṣe kórìíra wa; má ṣe sọ ìtẹ́ ògo rẹ di àìlọ́wọ̀. Rántí májẹ̀mú tí o bá wa dá kí o má ṣe dà á.
22 Nĩ kũrĩ mũhianano o na ũmwe wa ĩyo ĩtarĩ kĩene ya ndũrĩrĩ ũngiuria mbura? Matu mo mene nĩmoiragia mbura? Aca, nĩwe, Wee Jehova Ngai witũ, uuragia mbura. Nĩ ũndũ ũcio, kĩĩrĩgĩrĩro giitũ kĩrĩ harĩwe, nĩgũkorwo wee nĩwe wĩkaga maũndũ macio mothe.
Ǹjẹ́ èyíkéyìí àwọn òrìṣà yẹ̀yẹ́ tí àwọn orílẹ̀-èdè le ṣe kí òjò rọ̀? Ǹjẹ́ àwọsánmọ̀ fúnra rẹ̀ rọ òjò bí? Rárá, ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run wa. Torí náà, ìrètí wa wà lọ́dọ̀ rẹ, nítorí pé ìwọ lo ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí.