< Isaia 9 >

1 No rĩrĩ, andũ a bũrũri ũyũ arĩa makoretwo marĩ na mĩnyamaro matigacooka kũgĩa na kĩeha. Mbere ĩyo nĩanyararithirie bũrũri wa Zebuluni na bũrũri wa Nafitali, no mahinda ma thuutha-inĩ nĩagatĩĩithia bũrũri ũrĩa ũgereire iria-inĩ, ũikũrũkanĩtie na Rũũĩ rwa Jorodani, nĩkuo gwĩtagwo Galili-kwa-Ndũrĩrĩ:
Síbẹ̀síbẹ̀, kò ní sí ìpòrúru kankan mọ́ fún àwọn tí ó wà nínú ìbànújẹ́. Nígbà kan rí ó rẹ ilẹ̀ Sebuluni sílẹ̀ àti ilẹ̀ Naftali pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ iwájú, yóò bu ọ̀wọ̀ fún Galili ti àwọn aláìkọlà, ní ọ̀nà Òkun, ní ẹ̀gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ Jordani.
2 Andũ arĩa matũũraga nduma-inĩ nĩmonete ũtheri mũnene; nao arĩa matũũraga bũrũri ũrĩ nduma ta ya gĩkuũ-rĩ, nĩmarĩirwo nĩ ũtheri.
Àwọn ènìyàn tí ń rìn nínú òkùnkùn ti rí ìmọ́lẹ̀ ńlá; lórí àwọn tí ń gbé nínú ilẹ̀ òjìji ikú, ní ara wọn ni ìmọ́lẹ̀ mọ́ sí.
3 Wee nĩũingĩhĩtie rũrĩrĩ rũu, na ũkongerera gĩkeno kĩaruo; andũ aruo makenaga marĩ mbere yaku, o ta ũrĩa andũ makenagĩra magetha, magakena o ta ũrĩa andũ makenaga makĩgayana indo cia ndaho.
Ìwọ ti sọ orílẹ̀-èdè di ńlá; wọ́n sì yọ̀ níwájú rẹ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn ti í yọ ayọ̀ ìkórè, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ti í yọ̀ nígbà tí à ń pín ìkógun.
4 Nĩgũkorwo o ta ũrĩa kwarĩ mũthenya ũrĩa Amidiani maahootirwo, ũguo noguo unangĩte icooki rĩrĩa rĩmaritũhagĩra, na ũkoinanga mũtĩ wa kũmoohania ciande, na rũthanju rwa arĩa mamahinyagĩrĩria.
Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí a ṣẹ́gun Midiani, ìwọ ti fọ́ ọ túútúú àjàgà ti ń pa wọ́n lẹ́rù, ọ̀pá tí ó dábùú èjìká wọn, ọ̀gọ aninilára wọn.
5 Iraatũ ciothe cia njamba cia ita iria ihũthagĩrwo mbaara-inĩ, na nguo ciothe ĩtoboketio thakame-inĩ, igaatuĩka cia gũcinwo ta irĩ ngũ cia mwaki.
Gbogbo bàtà jagunjagun tí a ti lò lójú ogun àti gbogbo ẹ̀wù tí a yí nínú ẹ̀jẹ̀, ni yóò wà fún ìjóná, àti ohun èlò iná dídá.
6 Nĩgũkorwo nĩtũciarĩirwo kaana, tũkaheo kahĩĩ, naguo wathani ũgaakorwo ciande-inĩ ciako. Nako gageetagwo Mũheani-Kĩrĩra-wa-Kũgegania, Mũrungu Mwene-Hinya, Ithe-wa-Andũ-wa-Tene-na-Tene, Mũnene-wa-Thayũ.
Nítorí a bí ọmọ kan fún wa, a fi ọmọkùnrin kan fún wa, ìjọba yóò sì wà ní èjìká rẹ̀. A ó sì máa pè é ní Ìyanu Olùdámọ̀ràn, Ọlọ́run Alágbára, Baba ayérayé, Ọmọ ọba aládé Àlàáfíà.
7 Naguo ũhoro wa gũtheerema kwa ũthamaki wake na thayũ gũtirĩ hĩndĩ igaathira. Agaathamakagĩra ũthamaki wake aikarĩire gĩtĩ kĩa ũnene kĩa Daudi, aũhaande na aũtiirĩrĩre na ciira wa kĩhooto na ũthingu, kuuma rĩu nginya tene. Kĩyo kĩa Jehova Mwene-Hinya-Wothe nĩkĩo gĩgaatũma maũndũ macio mekĩke.
Ní ti gbígbòòrò Ìjọba rẹ̀ àti àlàáfíà rẹ̀ ni kì yóò ní ìpẹ̀kun. Yóò jẹ ọba lórí ìtẹ́ Dafidi àti lórí ẹ̀kún un rẹ̀ gbogbo, nípa ìfìdímúlẹ̀ àti ìgbéró rẹ̀, pẹ̀lú òtítọ́ àti òdodo láti ìgbà náà lọ àti títí láéláé. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.
8 Mwathani nĩatũmĩte ndũmĩrĩri ya gũũkĩrĩra Jakubu; nayo nĩĩgakinyĩra Isiraeli.
Olúwa ti dojú iṣẹ́ kan kọ Jakọbu; yóò sì wá sórí Israẹli.
9 Nao andũ othe nĩmakamenya ũhoro wayo, andũ acio a Efiraimu, na arĩa matũũraga Samaria, o acio moigaga na mwĩtĩĩo na nguthi ngoro-inĩ atĩrĩ,
Gbogbo ènìyàn ni yóò sì mọ̀ ọ́n— Efraimu àti gbogbo olùgbé Samaria— tí ó sọ pẹ̀lú ìgbéraga àti gààrù àyà pé.
10 “Maturubarĩ nĩmagwĩte thĩ, no ithuĩ tũgwaka rĩngĩ na mahiga maicũhie; mĩtĩ ya mĩkũyũ nĩmĩteme, no ithenya rĩayo tũgwaka na mĩtarakwa.”
Àwọn bíríkì ti wó lulẹ̀ ṣùgbọ́n a ó tún un kọ́ pẹ̀lú òkúta dídán, a ti gé àwọn igi sikamore lulẹ̀ ṣùgbọ́n igi kedari ní a ó fi dípò wọn.
11 No rĩrĩ, Jehova nĩaheete andũ arĩa marĩ muku na Rezini hinya mamookĩrĩre, na akaarahũra thũ ciao.
Ṣùgbọ́n Olúwa fún àwọn ọ̀tá Resini ní agbára láti dojúkọ wọ́n ó sì ti rú àwọn ọ̀tá wọn sókè.
12 Andũ a Suriata kuuma mwena wa irathĩro, na Afilisti kuuma mwena wa ithũĩro nĩmathamĩtie kanua, magatambuura Isiraeli. No o na kũrĩ ũguo-rĩ, marakara make matirĩ maraahũahũa, guoko gwake no gũtambũrũkĩtio o na rĩu.
Àwọn ará Aramu láti ìlà-oòrùn àti Filistini láti ìwọ̀-oòrùn. Wọ́n sì fi gbogbo ẹnu jẹ Israẹli run. Ní gbogbo èyí ìbínú rẹ̀ kò yí kúrò ṣùgbọ́n ọwọ́ rẹ̀ nà jáde síbẹ̀.
13 No rĩrĩ, andũ acio maticookereire ũcio wamahũũrire, kana makarongooria Jehova Mwene-Hinya-Wothe.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò tí ì yípadà sí ẹni náà tí ó lù wọ́n bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kò wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
14 Nĩ ũndũ ũcio Jehova nĩagatinia mũtwe na mũtingʼoe wa Isiraeli, na arenge rũhonge rwa mũkĩndũ na rwa ithanjĩ o mũthenya ũmwe.
Nítorí náà ni Olúwa yóò ṣe ké àti orí àti ìrù kúrò ní Israẹli, àti ọ̀wá ọ̀pẹ àti koríko odò ní ọjọ́ kan ṣoṣo,
15 Athuuri na andũ arĩa marĩ igweta nĩo mũtwe, nao anabii arĩa marutanaga ũhoro wa maheeni nĩo mũtingʼoe.
àwọn àgbàgbà, àti àwọn gbajúmọ̀ ní orí, àwọn wòlíì tí ń kọ́ni ní irọ́ ni ìrù.
16 Nĩgũkorwo atongoria a andũ aya nĩo mamahĩtithagia, nao arĩa matongoragio makahĩtithio njĩra.
Àwọn tí ó ń tọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣì wọ́n lọ́nà, àwọn tí a sì tọ́ ni a ń sin sí ìparun.
17 Nĩ ũndũ ũcio Mwathani ndagakenio nĩ aanake, kana aiguĩre ciana cia ngoriai na atumia a ndigwa tha, nĩgũkorwo andũ othe matiĩtigĩrĩte Ngai na nĩ aaganu, natuo tũnua twao tuothe twaragia maũndũ mooru. No o na kũrĩ ũguo-rĩ, marakara make matirĩ maraahũahũa, guoko gwake no gũtambũrũkĩtio o na rĩu.
Nítorí náà, Olúwa kì yóò dunnú sí àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tàbí kí ó káàánú àwọn aláìní baba àti opó, nítorí pé gbogbo wọn jẹ́ ìkà àti aláìmọ Ọlọ́run, ibi ni ó ti ẹnu wọn jáde. Síbẹ̀, fún gbogbo èyí, ìbínú rẹ̀ kò yí kúrò ọwọ́ rẹ̀ sì wà ní gbígbéró.
18 Ti-itherũ waganu ũrĩrĩmbũkĩte ta mwaki, ũgacina congʼe na mĩigua, na ũgaakana ihinga-inĩ cia mũtitũ, nayo ndogo yaguo ĩgeekonja yambatĩte na igũrũ ta itu ithimbu.
Nítòótọ́ ìwà búburú ń jóni bí iná, yóò jó ẹ̀wọ̀n àti ẹ̀gún run, yóò sì rán nínú pàǹtí igbó, tó bẹ́ẹ̀ tí yóò fi gòkè lọ bí ọ̀wọ́n èéfín ti í gòkè.
19 Nĩ ũndũ wa mangʼũrĩ ma Jehova Mwene-Hinya-Wothe bũrũri nĩũgaacinwo biũ, nao andũ magaatuĩka ta ngũ cia mwaki; gũtirĩ mũndũ o na ũmwe ũgacaaĩra mũrũ wa nyina.
Nípasẹ̀ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogun ilẹ̀ náà yóò di gbígbẹ àwọn ènìyàn yóò sì di ohun ìdáná, ẹnìkan kì yóò sì dá arákùnrin rẹ̀ sí.
20 Magaathara irio cia mwena wao wa ũrĩo, na makorwo marĩ o ahũtu; makaarĩa cia mwena wao wa ũmotho, no matihũũne. O mũndũ akaarĩa nyama cia ciana ciake mwene;
Ní apá ọ̀tún wọn yóò jẹrun, síbẹ̀ ebi yóò sì máa pa wọ́n, ní apá òsì, wọn yóò jẹ, ṣùgbọ́n, kò ní tẹ́ wọn lọ́rùn. Ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò sì máa jẹ ẹran-ara apá rẹ̀.
21 Manase akaarĩa Efiraimu, nake Efiraimu arĩe Manase: nao marĩ hamwe nĩmagookĩrĩra Juda. No o na kũrĩ ũguo-rĩ, marakara make matirĩ maraahũahũa, guoko gwake no gũtambũrũkĩtio o na rĩu.
Manase yóò máa jẹ Efraimu, nígbà tí Efraimu yóò jẹ Manase wọn yóò parapọ̀ dojúkọ Juda. Síbẹ̀síbẹ̀, ìbínú un rẹ̀ kò yí kúrò Ọwọ́ọ rẹ̀ sì wà ní gbígbéró.

< Isaia 9 >