< Isaia 8 >
1 Ningĩ Jehova akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Oya kĩbaũ kĩnene, na ũkĩandĩke na karamu ka ndũire ũũ: Maheri-Shalali-Hashi-Bazu.
Olúwa sọ fún mi pé, mú ìwé ńlá kan, kí o sì fi kálàmù ìkọ̀wé lásán kọ Maha-Ṣalali-Haṣi-Basi.
2 Na niĩ nĩngwĩta Uria ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai, na Zekaria mũrũ wa Jeberekia matuĩke aira akwa ehokeku.”
Èmi yóò sì mú Uriah àlùfáà àti Sekariah ọmọ Jeberekiah gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́rìí òtítọ́ wá sí ọ̀dọ̀ mi.
3 Hĩndĩ ĩyo ngĩthiĩ, ngĩkoma na mũtumia wakwa, nake akĩgĩa nda, agĩciara kahĩĩ. Nake Jehova akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Gatue Maheri-Shalali-Hashi-Bazu.
Lẹ́yìn náà, mo lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin náà, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Olúwa sì wí fún mi pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Maha-Ṣalali-Haṣi-Basi.
4 Kahĩĩ kau gataanamenya gwĩtana koige ‘Baba’ kana ‘Maitũ’, ũtonga wa Dameski na indo iria itahĩtwo nĩ Samaria nĩigakuuo nĩ mũthamaki wa Ashuri.”
Kí ọmọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń sọ pé, ‘Baba mi’ tàbí ‘Ìyá mi,’ gbogbo ọrọ̀ Damasku àti ìkógun ti Samaria ni ọba àwọn Asiria yóò ti kó lọ.”
5 O rĩngĩ Jehova akĩnjarĩria, akĩnjĩĩra atĩrĩ:
Olúwa sì tún sọ fún mi pé,
6 “Kuona atĩ andũ aya nĩmaregete maaĩ marĩa mathereraga mahooreire ma Siloamu, na magakenera Rezini o na mũrũ wa Remalia-rĩ,
“Nítorí pé àwọn ènìyàn yìí ti kọ omi Ṣiloa tí ń sàn jẹ́ẹ́jẹ́ sílẹ̀ tí wọ́n sì ń yọ̀ nínú Resini àti ọmọ Remaliah,
7 nĩ ũndũ ũcio Mwathani akiriĩ kũmarehithĩria mũiyũro mũnene wa Rũũĩ rwa Farati, naruo nĩruo mũthamaki wa Ashuri arĩ na riiri wake wothe. Rũkaaiyũrĩrĩra mĩkaro yaruo yothe, na ruune hũgũrũrũ ciaruo,
ǹjẹ́ nítorí náà kíyèsi i, Olúwa ń fa omi odò tí ó le, tí ó sì pọ̀ wá sórí wọn, àní, ọba Asiria àti gbogbo ògo rẹ̀, yóò sì wá sórí gbogbo ọ̀nà odò rẹ̀, yóò sì gun orí gbogbo bèbè rẹ̀,
8 ningĩ rũgaathiĩ rũhaatĩte Juda rũiyũre guothe, rũhĩtũkĩire kuo na rũkinye nginya ngingo. Mathagu maaruo matambũrũkĩtio makaahumbĩra wariĩ wa bũrũri waku, wee Imanueli!”
yóò sì gbá àárín Juda kọjá, yóò sì ṣàn bò ó mọ́lẹ̀, yóò sì mú un dọ́rùn. Nínà ìyẹ́ apá rẹ̀ yóò sì bo gbogbo ìbú ilẹ̀ rẹ̀, ìwọ Emmanueli.”
9 Atĩrĩrĩ inyuĩ andũ a ndũrĩrĩ, ugĩrĩriai mbugĩrĩrio ya mbaara, na no mũgũthetherwo! Ta thikĩrĩriai inyuĩ mabũrũri ma kũraya. Haarĩriai mbaara, na no mũgũthetherwo! Haarĩriai mbaara, na no mũgũthetherwo!
Ké ariwo ogun, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, kí a sì fọ́ ọ yín túútúú, fetísílẹ̀, ẹ̀yin ilẹ̀ jíjìn réré. Ẹ palẹ̀mọ́ fún ogun, kí a sì fọ́ ọ túútúú!
10 Thugundai mĩbango yanyu, no ĩgaatuĩka ya tũhũ; ariai ũhoro wa matanya manyu, no matikahinga, nĩgũkorwo Mũrungu arĩ hamwe na ithuĩ.
Ẹ gbìmọ̀ pọ̀, yóò sì di asán, ẹ gbèrò ọ̀rọ̀ náà, ṣùgbọ́n kì yóò dúró, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa.
11 Jehova nĩanjarĩirie ũhoro ũcio agwatĩirie mũno, na akĩngaania ndikarũmĩrĩre njĩra cia andũ acio. Akĩnjĩĩra atĩrĩ:
Olúwa bá mi sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀ o ìkìlọ̀ fún mi pé, èmi kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Ó wí pé,
12 “Maũndũ marĩa mothe andũ aya metaga ndundu ya gwĩka ũũru, wee ndũkamete ndundu ya gwĩka ũũru; na ndũgetigĩre kĩrĩa metigagĩra, na ndũkamakio nĩkĩo.
“Má ṣe pe èyí ní ọ̀tẹ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn yìí pè ní ọ̀tẹ̀, má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n bá bẹ̀rù, má sì ṣe fòyà rẹ̀.
13 Jehova Mwene-Hinya-Wothe nĩwe mũrĩtuaga mũtheru, we nĩwe mwagĩrĩirwo nĩ gwĩtigĩra, o we nĩwe ũngĩtũma mũmake,
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ẹni tí ìwọ yóò kà sí mímọ́, Òun ni kí o bẹ̀rù Òun ni kí àyà rẹ̀ fò ọ́,
14 na nĩwe ũgaatuĩka handũ hanyu harĩa haamũre; no kũrĩ nyũmba cierĩ cia Isiraeli agaatuĩka ihiga rĩrĩa rĩtũmaga andũ mahĩngwo, na rwaro rwa ihiga rũrĩa rũtũmaga magũe. Na kũrĩ andũ arĩa matũũraga Jerusalemu agaatuĩka mũtego na gĩkerenge gĩa kũmanyiita.
Òun yóò sì jẹ́ ibi mímọ́ ṣùgbọ́n fún ilé Israẹli méjèèjì ni yóò jẹ́, òkúta tí í mú ni kọsẹ̀ àti àpáta tí ó mú wọn ṣubú àti fún àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ni yóò jẹ́ tàkúté àti ìdẹ̀kùn.
15 Aingĩ ao nĩmakahĩngwo; nao magũe na moinĩke, magwatio na manyiitwo.”
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn ni yóò kọsẹ̀, wọn yóò ṣubú wọn yóò sì fọ́ yángá, okùn yóò mú wọn, ọwọ́ yóò sì tẹ̀ wọ́n.”
16 Oha ũira ũcio na watho ũcio, ũũhũũre mũhũũri ũtuĩke kĩrĩra harĩ arutwo akwa.
Di májẹ̀mú náà kí o sì fi èdìdì di òfin náà láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mi.
17 Niĩ ngweterera Jehova, ũrĩa ũhithĩte nyũmba ya Jakubu ũthiũ wake. Ndĩrĩikaraga ndĩmwĩhokete.
Èmi yóò dúró de Olúwa, ẹni tí ó ń fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún ilé Jakọbu. Mo fi ìgbẹ́kẹ̀lé mi sínú rẹ.
18 Niĩ hamwe na ciana iria Jehova aheete-rĩ, nĩ ithuĩ marũũri na imenyithia thĩinĩ wa Isiraeli kuuma kũrĩ Jehova Mwene-Hinya-Wothe ũrĩa ũtũũraga Kĩrĩma-inĩ gĩa Zayuni.
Èmi nìyí, àti àwọn ọmọ tí Olúwa fi fún mi. Àwa jẹ́ àmì àti àpẹẹrẹ ní Israẹli láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ẹni tí ó ń gbé ní òkè Sioni.
19 Andũ mangĩkwĩra ũgatuĩrie kĩrĩra kuuma kũrĩ aragũri na ago arĩa mahehanaga na makangʼungʼura-rĩ, ũkaamoria atĩrĩ, “Githĩ andũ matiagĩrĩirwo nĩgũtuĩria ũhoro harĩ Ngai wao?” Nĩ kĩĩ gĩgũtũma mũtuĩrie ũhoro wa andũ arĩa marĩ muoyo kuuma kũrĩ arĩa akuũ?
Nígbà tí àwọn ènìyàn bá sọ fún un yín pé kí ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn oṣó, ti máa ń kún tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, ǹjẹ́ kò ha yẹ kí àwọn ènìyàn béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run wọn bí? Èéṣe tí ẹ fi ń bá òkú sọ̀rọ̀ ní orúkọ alààyè?
20 Nĩ kaba mũũtuĩrie watho-inĩ wa Ngai o na ũira-inĩ wake! Angĩkorwo ũhoro wao ndũkũringana na ciugo ici, o nao matirĩ na ũtheri.
Sí òfin àti májẹ̀mú! Bí wọn kò bá sọ̀rọ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ yìí, wọn kò rí ìmọ́lẹ̀ ọjọ́.
21 Andũ magaatuĩkanagĩria bũrũri-inĩ marĩ anyamaarĩku na marĩ ahũtu; na rĩrĩ, rĩrĩa makahũũta mũno, nĩmakarakara mũno na matiire maitho na igũrũ, nao marume mũthamaki wao na Ngai wao.
Nínú ìnilára àti ebi, ni wọn yóò máa kọjá lọ láàrín ilẹ̀ náà, nígbà tí ebi bá pa wọ́n, nígbà yìí ni wọn yóò máa kanra, wọn yóò wòkè, wọn yóò sì fi ọba àti Ọlọ́run wọn ré.
22 Hĩndĩ ĩyo makaarora thĩ mone o mĩnyamaro, na nduma, na kĩeha gĩa kũmakania, nao nĩmagaikio nduma-inĩ ndumanu.
Nígbà náà ni wọn yóò sì wolẹ̀, wọn yóò sì rí ìpọ́njú, òkùnkùn àti ìpòrúru tí ó ba ni lẹ́rù, a ó sì sọ wọ́n sínú òkùnkùn biribiri.