< Isaia 45 >

1 Atĩrĩrĩ, ũyũ nĩguo ũhoro ũrĩa Jehova areera Kurusu, ũrĩa wake mũitĩrĩrie maguta, o ũcio niĩ nyitĩte guoko gwake kwa ũrĩo nĩguo ndoorie ndũrĩrĩ iria irĩ mbere yake, na njaũre athamaki indo ciao cia mbaara, nĩgeetha ndĩmũhingũrĩre mĩrango mbere yake, na nĩguo ndakanakore ihingo ihingĩtwo:
“Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ẹni òróró rẹ̀, sí Kirusi, ọwọ́ ọ̀tún ẹni tí mo dì mú láti dojú àwọn orílẹ̀-èdè bolẹ̀ níwájú rẹ̀ àti láti gba ohun ìjà àwọn ọba lọ́wọ́ wọn, láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé a kì yóò ti àwọn ẹnu-ọ̀nà.
2 Nĩngagũtongoria na nĩngaragania irĩma; nĩngoinanga ihingo cia gĩcango, na ndinangie mĩgĩĩko ya kĩgera.
Èmi yóò lọ síwájú rẹ, Èmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹsẹ Èmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹ èmi ó sì gé ọ̀pá irin.
3 Nĩngakũhe igĩĩna iria ihithĩtwo nduma-inĩ, ngũhe ũtonga ũrĩa mũhithe, nĩguo ũmenye atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova, o we Ngai wa Isiraeli, ũrĩa ũgwĩtĩte na rĩĩtwa rĩaku.
Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn, ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó fi ara sin, tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.
4 Nĩngwĩtĩte na rĩĩtwa rĩaku, nĩ ũndũ wa ndungata yakwa Jakubu, o na nĩ ũndũ wa Isiraeli ũcio niĩ ndĩthuurĩire, na ngakũhe rĩĩtwa rĩa gĩtĩĩo, o na gũtuĩka wee ndũnjũũĩ.
Nítorí Jakọbu ìránṣẹ́ mi àti Israẹli ẹni tí mo yàn, Mo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ, mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lórí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.
5 Niĩ nĩ niĩ Jehova, na gũtirĩ ũngĩ; tiga niĩ gũtirĩ Ngai ũngĩ. Nĩndĩrĩkuongagĩrĩra hinya, o na gũtuĩka wee ndũnjũũĩ,
Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmíràn; yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan, Èmi yóò fún ọ ní okun, bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,
6 nĩgeetha kuuma irathĩro rĩa riũa nginya ithũĩro rĩarĩo, andũ mamenye atĩ gũtirĩ ũngĩ tiga niĩ. Niĩ nĩ niĩ Jehova, na gũtirĩ ũngĩ.
tí o fi jẹ́ pé láti ìlà-oòrùn títí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀ kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi. Èmi ni Olúwa, lẹ́yìn mi kò sí ẹlòmíràn mọ́.
7 Nĩ niĩ ndũmaga kũgĩe ũtheri, o na ngatũma kũgĩe nduma, nĩ niĩ ndehaga ũgaacĩru na ngatũma kũgĩe mwanangĩko; Nĩ niĩ, Jehova, ũrĩa wĩkaga maũndũ macio mothe.
Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùn, Mo mú àlàáfíà wá, Mo sì dá àjálù; Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.
8 “Atĩrĩrĩ inyuĩ matu ma igũrũ, urĩriai thĩ ũthingu; o na inyuĩ matu ma mbura itĩrĩriai thĩ ũthingu. Thĩ nayo nĩyathamie kanua, naguo ũhonokio nĩũkunũke, ũmere, ũkũranĩre na ũthingu. Niĩ Jehova-rĩ, nĩ niĩ ndũmĩte igĩe kuo.
“Ìwọ ọ̀run lókè rọ òjò òdodo sílẹ̀; jẹ́ kí àwọsánmọ̀ kí ó rọ̀ ọ́ sílẹ̀. Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó yanu gbagada, jẹ́ kí ìgbàlà kí ó dìde sókè, jẹ́ kí òdodo kí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀; Èmi Olúwa ni ó ti dá a.
9 “Ũrĩa ũgianaga na Mũmũũmbi, kaĩ arĩ na haaro-ĩ! Ũcio ahaana o ta rũgĩo thĩinĩ wa ngĩĩo iria irĩ thĩ. Rĩũmba rĩahota kũũria ũrĩa ũmbaga indo narĩo atĩrĩ, ‘Nĩ kĩĩ kĩu ũromba?’ O na kana wĩra waku no uuge atĩrĩ, ‘Ndarĩ na moko’?
“Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà, ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrín àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀. Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé: ‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’ Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé, ‘Òun kò ní ọwọ́?’ (questioned)
10 Hĩ, kaĩ ũrĩa ũragia ithe atĩrĩ, ‘Nĩ kĩĩ kĩu wagĩire?’ kana akooria nyina atĩrĩ, ‘Nĩ kĩĩ kĩu waciara?’ Kaĩ arĩ na haaro-ĩ!
Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé, ‘Kí ni o bí?’ tàbí sí ìyá rẹ̀, ‘Kí ni ìwọ ti bí?’
11 “Jehova, Ũrĩa Mũtheru wa Isiraeli, na Mũũmbi wake, ekuuga atĩrĩ: Ha ũhoro ũkoniĩ maũndũ marĩa magooka-rĩ, anga no mũkĩnjũũrie ũhoro wa ciana ciakwa, kana mũnjathĩre wĩra wa moko makwa?
“Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ẹni Mímọ́ Israẹli, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀. Nípa ohun tí ó ń bọ̀, ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi, tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?
12 Nĩ niĩ ndombire thĩ, na ngĩũmba andũ arĩa marĩ kuo. Moko makwa nĩmo maatambũrũkirie kũu igũrũ, na ngĩatha mbũtũ cia igũrũ igĩe ho.
Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayé tí ó sì da ọmọ ènìyàn sórí i rẹ̀. Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀run; mo sì kó àwọn àgbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta.
13 Nĩngarahũra Kurusu nĩ ũndũ wa ũthingu wakwa: Nĩngatũma mĩthiĩre yake ĩrũngĩrĩre. We nĩagaaka itũũra rĩakwa rĩrĩa inene rĩngĩ, na ohorithie andũ akwa arĩa matahĩtwo, no rĩrĩ, matikarutĩrwo kĩndũ gĩa kũmakũũra kana marutĩrwo kĩheo, ũguo nĩguo Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekuuga.”
Èmi yóò gbé Kirusi sókè nínú òdodo mi. Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́. Òun yóò tún ìlú mi kọ́ yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
14 Jehova ekuuga atĩrĩ: “Maciaro ma bũrũri wa Misiri, na indo cia wonjorithia cia Kushi, o na andũ acio araihu a Sabea, nĩmagooka kũrĩ we matuĩke aku; nĩmagakuuma thuutha, na moke kũrĩ we mohetwo na mĩnyororo. Nĩmagakũinamĩrĩra, magũthaithe, makwĩre atĩrĩ, ‘Ti-itherũ Mũrungu arĩ hamwe nawe, na gũtirĩ ũngĩ tiga we; ti-itherũ gũtirĩ ngai ĩngĩ.’”
Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Àwọn èròjà ilẹ̀ Ejibiti àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kuṣi, àti àwọn Sabeani— wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ wọn yóò sì jẹ́ tìrẹ; wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn, wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́. Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀, wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé, ‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì ṣí ẹlòmíràn; kò sí ọlọ́run mìíràn.’”
15 Ti-itherũ wee ũrĩ Mũrungu ũrĩa ũikaraga ehithĩte, Wee Ngai na Mũhonokia wa Isiraeli.
Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́, Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Israẹli,
16 Arĩa othe mathondekaga mĩhianano ya kũhooywo nĩmagaconorithio na manyararithio; makoimagara mathiĩ manyararithio othe hamwe.
Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tì wọn yóò sì kan àbùkù; gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.
17 No rĩrĩ, Isiraeli nĩakahonokio nĩ Jehova na ũhonokio wake ũrĩa ũtũũraga tene na tene; wee ndũgaconorithio kana ũnyararithio nginya tene na tene.
Ṣùgbọ́n Israẹli ni a ó gbàlà láti ọwọ́ Olúwa pẹ̀lú ìgbàlà ayérayé; a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójútì yín, títí ayé àìnípẹ̀kun.
18 Nĩgũkorwo Jehova ekuuga atĩrĩ, ũcio wombire igũrũ, o we Ngai, o ũcio wombire thĩ na akĩmĩthondeka, agĩcooka akĩmĩrũmia wega; na ndaamĩũmbire ĩtũũre ĩrĩ ũtheri, no aamĩũmbire ĩtũũragwo nĩ andũ; we ekuuga atĩrĩ: “Niĩ nĩ niĩ Jehova, na gũtirĩ ũngĩ.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run, Òun ni Ọlọ́run; ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé, Òun ló ṣe é; Òun kò dá a láti wà lófo, ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀, Òun wí pé: “Èmi ni Olúwa, kò sì ṣí ẹlòmíràn.
19 Ndirĩ ndaaria na hitho, ndĩ handũ bũrũri-inĩ ũrĩ nduma; ndirĩ ndeera njiaro cia Jakubu atĩrĩ, ‘Nongoriai o ũguo tũhũ.’ Niĩ Jehova, njaragia ũhoro wa ma; nyumbũraga maũndũ marĩa magĩrĩire.
Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó fi ara sin, láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn, Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jakọbu pé, ‘Ẹ wá mi lórí asán.’ Èmi Olúwa sọ òtítọ́, Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.
20 “Cookanĩrĩrai hamwe, mũũke; ũnganai, inyuĩ arĩa mũũrĩte kuuma kũrĩ ndũrĩrĩ. Kwaga ũmenyi-rĩ, nĩ andũ arĩa makuuaga mĩhianano ya kũhooywo ya mĩtĩ, na makahooya ngai itangĩhota kũmahonokia.
“Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá; ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìsáǹsá láti àwọn orílẹ̀-èdè wá. Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri, tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.
21 Umbũrai ũhoro wa ũrĩa gũgaikara, na mũũheane, na andũ marekwo maciire marĩ hamwe. Nũũ waheanire ũhoro ũyũ kuuma o tene? Ningĩ nũũ waumbũrĩte matukũ-inĩ macio ma tene mũno? Githĩ ti niĩ, niĩ Jehova? Gũtirĩ Ngai ũngĩ tiga niĩ, Mũrungu mũthingu na Mũhonokia; ti-itherũ gũtirĩ ũngĩ tiga niĩ.
Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wá, jẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀. Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́, ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe? Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa? Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi, Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà; kò sí ẹlòmíràn àfi èmi.
22 “Atĩrĩrĩ, inyuĩ ituri ciothe cia thĩ, njookererai mũhonokio, nĩgũkorwo niĩ nĩ niĩ Mũrungu, na gũtirĩ ũngĩ tiga niĩ.
“Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là, ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé; nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì ṣí ẹlòmíràn.
23 Nĩndĩhĩtĩte ngĩĩgwetaga rĩĩtwa rĩakwa niĩ mwene, naguo ũhoro ũkoima kanua gakwa na kĩhooto, naguo ndũkagarũrũka o na atĩa: Maru mothe nĩmagaturio mbere yakwa; nacio nĩmĩ ciothe nĩcikeehĩta na rĩĩtwa rĩakwa.
Nípa èmi tìkára mi ni mo ti búra, ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lú gbogbo ipá mi, ọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́. Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀; nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.
24 Nĩmakaaria ũhoro wakwa, moige atĩrĩ, ‘Ũthingu na hinya cionekaga harĩ Jehova o we wiki.’” Andũ arĩa othe maarakarire makĩmũũkĩrĩra, nĩmagooka harĩ we maconorithio.
Wọn yóò sọ ní ti èmi, ‘Nínú Olúwa nìkan ni òdodo àti agbára wà.’” Gbogbo àwọn tí ó ti bínú sí; yóò wá sọ́dọ̀ rẹ̀ a ó sì dójútì wọn.
25 No njiaro ciothe cia Isiraeli nĩikoonekaga irĩ na ũthingu nĩ ũndũ wa Jehova, na nĩigakena mũno.
Ṣùgbọ́n nínú Olúwa gbogbo àwọn ìran Israẹli ni a ó rí ní òdodo, a o sì gbé wọn ga.

< Isaia 45 >