< Isaia 29 >

1 Arieli, o wee Arieli, wee itũũra inene kũrĩa Daudi aatũũraga, kaĩ ũrĩ na haaro-ĩ! Ongerera mwaka kũrĩ mwaka ũngĩ, na mũreke ciathĩ cianyu ithiĩ o na mbere.
Ègbé ni fún ọ, Arieli, Arieli, ìlú níbi tí Dafidi tẹ̀dó sí! Fi ọdún kún ọdún sì jẹ́ kí àwọn àkọlùkọgbà àjọ̀dún un rẹ tẹ̀síwájú.
2 No nĩngarigiicĩria itũũra rĩa Arieli; nĩrĩkarĩra na rĩcakaye, na rĩgaatuĩka ta riiko rĩa kĩgongona harĩ niĩ.
Síbẹ̀síbẹ̀ èmi yóò dó ti Arieli òun yóò ṣọ̀fọ̀ yóò sì sọkún, òun yóò sì dàbí pẹpẹ ọkàn sí mi.
3 Nĩngamba hema ciakwa ngũrigiicĩrie; nĩngagũthiũrũrũkĩria na mĩthiringo mĩraihu na igũrũ, ngũrigiicĩrie na ihumbu cia tĩĩri, ngũtharĩkĩre.
Èmi yóò sì wà ní bùba yí ọ ká níbi gbogbo, Èmi yóò sì fi ilé ìṣọ́ yí ọ ká, Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìdó ti ni mi dojúkọ ọ́.
4 Nawe ũgaatungumanio thĩ, waragie ũrĩ thĩ; ũtuĩke wa kũngʼungʼua ũrĩ hau tĩĩri-inĩ. Mũgambo waku ũgaatuĩka ta wa roho wa ũragũri ũroima na thĩ; naguo mũgambo waku ũkaaiguagwo ũrĩ wa mĩheehũ ũkiuma tĩĩri-inĩ.
Ní ìrẹ̀sílẹ̀, ìwọ ó sì máa sọ̀rọ̀ láti ilẹ̀ wá; ọ̀rọ̀ rẹ yóò sì máa kùn jáde láti inú erùpẹ̀. Ohun rẹ yóò máa jáde bí i ti ẹnìkan tó ní ẹ̀mí àfọ̀ṣẹ láti ilẹ̀ jáde wá, láti inú erùpẹ̀ ni ohùn rẹ yóò máa wá wúyẹ́wúyẹ́.
5 No rĩrĩ, thũ ciaku nyingĩ ĩgaatuĩka ta rũkũngũ rũhinyu, na kĩrĩndĩ kĩa andũ arĩa matarĩ tha matuĩke ta mũũngũ ũrĩa ũmbũragwo. Ũndũ ũcio ũkooneka na ihenya, o rĩmwe,
Ṣùgbọ́n àwọn ọ̀tá rẹ, yóò dàbí yanrìn kíkúnná, agbo àwọn aláìláàánú bí ìyàngbò tí a fẹ́ dànù. Lójijì, ní ìṣẹ́jú kan,
6 amu Jehova Mwene-Hinya-Wothe nĩagooka na marurumĩ, na gĩthingithia, na mũrurumo mũnene, hamwe na rũhuho rũnene, na kĩhuhũkanio kĩnene, na nĩnĩmbĩ cia mwaki ũkũniinana.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò wá pẹ̀lú àrá àti ilẹ̀-rírì àti ariwo ńlá, àti ẹ̀fúùfù líle àti iná ajónirun.
7 Nakĩo kĩrĩndĩ kĩa ndũrĩrĩ ciothe kĩrĩa kĩrũaga na Arieli, kĩrĩa gĩtharĩkagĩra itũũra rĩu na ciĩhitho ciarĩo iria nũmu, na gĩkarĩthiũrũrũkĩria-rĩ, gĩkaabuĩria o ta kĩroto, o ta kĩoneki kĩa ũtukũ:
Lẹ́yìn náà, ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ ènìyàn tí gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó bá Arieli jà, tí ó dojú ìjà kọ òun àti ilé olódi rẹ̀ tí ó sì dó tì í, yóò dàbí ẹni pé nínú àlá, bí ìran ní òru
8 o ta ũrĩa mũndũ mũhũtu arootaga, akeyona akĩrĩa irio, no rĩrĩa okĩra, agakora no mũhũtu; ningĩ gũgaatuĩka o ta ũrĩa mũndũ mũnyootu arootaga, akeyona akĩnyua maaĩ, no agokĩra arĩ mũringĩku, na arĩ o mũnyootu. Ũguo noguo gũgaikara harĩ kĩrĩndĩ kĩa ndũrĩrĩ ciothe iria irũaga na Kĩrĩma gĩa Zayuni.
àti bí ìgbà tí ẹni tí ebi ń pa ń lá àlá pé òun ń jẹun, ṣùgbọ́n ó jí, ebi rẹ̀ sì wà pẹ̀lú rẹ̀; tàbí bí ìgbà tí ẹni tí òǹgbẹ ń gbẹ lá àlá pé òun ń mu omi, ṣùgbọ́n nígbà tí ó jí, sì wò ó, ó dákú, òǹgbẹ sì ń gbẹ ọkàn rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè tí ń bá òkè Sioni jà.
9 Gegearai na mũmake, mwĩtuei atumumu na mwage kuona; mũnyue mũrĩĩo, no mũtikarĩĩo nĩ ndibei, ningĩ mũtũgũũge, no mũtigatũgũũgio nĩ njoohi.
Ẹ bẹ̀rù kí ẹnu kí ó yà yín, ẹ fọ́ ara yín lójú kí ẹ má sì ríran; ẹ mutí yó kì í ṣe ọtí wáìnì, ẹ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n, ṣùgbọ́n kì í ṣe ti ọtí líle.
10 Jehova nĩamũreheire toro mũnene: nĩahingĩte maitho manyu (inyuĩ anabii); nĩahumbĩrĩte mĩtwe yanyu (inyuĩ ooni-maũndũ).
Olúwa ti mú oorun ìjìká wá sórí i yín: ó ti dì yín lójú ẹ̀yin wòlíì; ó ti bo orí yín ẹ̀yin aríran.
11 Naguo ũhoro wa kĩoneki gĩkĩ gĩothe harĩ inyuĩ ũtuĩkĩte kĩndũ gĩa tũhũ, ũgatuĩka ta ciugo irĩ ibuku-inĩ rĩa gĩkũnjo, rĩtumĩtwo na rĩkahũũrwo mũhũũri. Na mũngĩnengera mũndũ ũngĩhota gũthoma ibuku rĩu rĩa gĩkũnjo na mũmwĩre atĩrĩ, “Twagũthaitha, tũthomere ibuku rĩĩrĩ,” nake akaamũcookeria atĩrĩ, “Ndingĩhota gũthoma tondũ nĩitume na rĩkahũũrwo mũhũũri.”
Fún un yín gbogbo ìran yìí kò yàtọ̀ sí àwọn ọ̀rọ̀ tí a fi èdìdì dì sínú ìwé kíká. Bí ẹ bá sì fún ẹni tí ó lè ka ìwé kíká náà, tí ẹ sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò lè kà á; a ti dì í ní èdìdì.”
12 Kana mũngĩnengera mũndũ ũtangĩhota gũthoma ibuku rĩu rĩa gĩkũnjo, mũmwĩre atĩrĩ, “Twagũthaitha, tũthomere ibuku rĩĩrĩ,” nake akaamũcookeria atĩrĩ, “Niĩ ndiũĩ gũthoma.”
Tàbí bí ẹ bá fún ẹni tí kò lè ka ìwé kíká náà tí ẹ sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò mọ̀ ọ́n kà.”
13 Mwathani ekuuga atĩrĩ: “Andũ aya manguhagĩrĩria na tũnua twao, na makaahe gĩtĩĩo na mĩromo yao, no ngoro ciao irĩ kũraya na niĩ. Namo mahooya marĩa mahooyaga nĩ kũringana na mawatho marĩa marutĩtwo nĩ andũ.
Olúwa wí pé: “Àwọn ènìyàn yìí súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹnu wọn, wọ́n sì bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ètè wọn, ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnnà sí mi. Ìsìn wọn si mi ni a gbé ka orí òfin tí àwọn ọkùnrin kọ́ ni.
14 Nĩ ũndũ ũcio, o rĩngĩ nĩngagegia andũ aya, njĩke maũndũ ma kũgegania, o ma kũgegania biũ; ũũgĩ wa andũ arĩa oogĩ nĩũgaathira, naguo ũmenyo wa andũ arĩa moĩ gũkũũrana maũndũ nĩũkabuĩria.”
Nítorí náà lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò ya àwọn ènìyàn yìí lẹ́nu pẹ̀lú ìyanu lórí ìyanu; ọgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ni yóò ṣègbé, ìmọ̀ àwọn onímọ̀ ni yóò pòórá.”
15 Kaĩ andũ acio mekagĩra kĩyo kĩnene nĩguo mahithe Jehova mĩbango yao marĩ na haaro-ĩ! O acio marutagĩra mawĩra mao nduma-inĩ, mageciiria atĩrĩ, “Nũũ ũratuona?” ningĩ-rĩ, “Nũũ ũngĩmenya ũrĩa tũreka?”
Ègbé ni fún àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun láti fi ètò wọn pamọ́ kúrò lójú Olúwa, tí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ẹ wọn nínú òkùnkùn tí wọ́n sì rò pé, “Ta ló rí wa? Ta ni yóò mọ̀?”
16 Inyuĩ mũinamanagia maũndũ, mũũmbi ageciirĩrio nĩwe rĩũmba! Kĩrĩa kĩombirwo no kĩĩre mũkĩũmbi atĩrĩ, “Wee tiwe wanyũũmbire”? Nyũngũ no ĩĩre mũmĩũmbi atĩrĩ, “Wee ndũrĩ ũndũ ũũĩ”?
Ẹ̀yin dojú nǹkan délẹ̀, bí ẹni pé wọ́n rò pé amọ̀kòkò dàbí amọ̀! Ǹjẹ́ ohun tí a ṣe le sọ fún olùṣe pé, “Òun kọ́ ló ṣe mí”? Ǹjẹ́ ìkòkò lè sọ nípa amọ̀kòkò pé, “Kò mọ nǹkan”?
17 Githĩ ti kahinda kanini gatigaire Lebanoni kũgarũrwo gũtuĩke mũgũnda mũnoru, naguo mũgũnda ũcio mũnoru ũtuĩke ta mũtitũ?
Ní àìpẹ́ jọjọ, ǹjẹ́ a kò ní sọ Lebanoni di pápá ẹlẹ́tù lójú àti pápá ẹlẹ́tù lójú yóò dàbí aginjù?
18 Mũthenya ũcio, andũ arĩa mataiguaga nĩmakaigua ciugo cia ibuku rĩu rĩa gĩkũnjo, namo maitho ma atumumu arĩa matũũraga moonaga mairia na nduma nĩmakona.
Ní ọjọ́ náà adití yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ìwé kíká náà, láti inú fìrífìrí àti òkùnkùn ni àwọn ojú afọ́jú yóò ríran.
19 Na o rĩngĩ andũ arĩa ahooreri nĩmagakenera Jehova; nao andũ arĩa athĩĩni nĩmagakenera Ũrĩa Mũtheru wa Isiraeli.
Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn onírẹ̀lẹ̀ yóò yọ̀ nínú Olúwa: àwọn aláìní yóò yọ̀ nínú Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
20 Andũ arĩa matarĩ tha nĩmakabuĩria, nao arĩa anyũrũrania nĩmagathira, na arĩa meriragĩria gwĩka ũũru nĩmakaniinwo:
Aláìláàánú yóò pòórá, àwọn tí ń ṣẹlẹ́yà yóò di àwátì, gbogbo àwọn tí ó ní ojú ibi ni a ó ké lulẹ̀—
21 o acio mahũthagĩra kiugo kĩmwe magatua mũndũ mũhĩtia, na makaigĩra mũciiranĩrĩri mũtego iciirĩro-inĩ, na makahũthĩra ũira wa maheeni nĩguo mũndũ ũtekĩte ũũru aage gũtuĩrwo ciira na kĩhooto.
àwọn tí wọ́n fi ọ̀rọ̀ kan mú ẹnìkan di ẹlẹ́bi, ẹni tí ń dẹkùn mú olùgbèjà ní ilé ẹjọ́ tí ẹ fi ẹ̀rí èké dun aláìṣẹ̀ ní ìdájọ́.
22 Nĩ ũndũ ũcio Jehova ũrĩa wahonokirie Iburahĩmu ekwĩra nyũmba ya Jakubu atĩrĩ: “Jakubu ndagaaconorithio rĩngĩ; na matigacooka gũtukia ithiithi ciao rĩngĩ.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa, ẹni tí ó ra Abrahamu padà sọ sí ilé Jakọbu: “Ojú kì yóò ti Jakọbu mọ́; ojú wọn kì yóò sì rẹ̀wẹ̀sì mọ́.
23 Rĩrĩa makoona ciana ciao iria ndombire na moko makwa irĩ hamwe nao, nĩmakaiga rĩĩtwa rĩakwa rĩrĩ itheru; nĩmakoimbũra ũtheru wa Ũrĩa Mũtheru wa Jakubu, na maikarage metigĩrĩte Ngai wa Isiraeli.
Nígbà tí wọ́n bá rí i láàrín àwọn ọmọ wọn, àwọn iṣẹ́ ọwọ́ mi, wọn yóò ya orúkọ mi sí mímọ́, wọn yóò tẹ́wọ́gbà mímọ́ Ẹni Mímọ́ Jakọbu wọn yóò dìde dúró ní ìbọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run Israẹli.
24 Andũ arĩa ngoro ciao imahĩtithagia nĩmakaagĩa na ũmenyo, nao arĩa matetaga nĩmagathikĩrĩria mataaro.”
Gbogbo àwọn tí ń rìn ségesège ní yóò jèrè ìmọ̀; gbogbo àwọn tí ń ṣe àròyé yóò gba ìtọ́sọ́nà.”

< Isaia 29 >