< Hosea 7 >

1 o rĩrĩa ndenda kũhonia Isiraeli-rĩ, mehia ma Efiraimu makonanio, nacio ngero cia Samaria ikaguũrio. Maaragia maũndũ ma maheeni, na aici magatua nyũmba, magatoonya, nacio njangiri igatunyana indo njĩra-inĩ;
nígbà tí èmi ìbá mú Israẹli láradá. Ẹ̀ṣẹ̀ Efraimu ń farahàn ìwà búburú Samaria sì ń hàn síta. Wọ́n ń ṣe ẹ̀tàn, àwọn olè ń fọ́ ilé; àwọn ọlọ́ṣà ń jalè ní òpópónà;
2 no rĩrĩ, matimenyaga atĩ nĩndirikanaga ciĩko icio ciao njũru ciothe. Mehia mao nĩmamarigiicĩirie; makoragwo mbere yakwa hĩndĩ ciothe.
ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀ pé mo rántí gbogbo ìwà búburú wọn. Ẹ̀ṣẹ̀ wọn gbé wọn mì pátápátá; wọ́n wà níwájú mi nígbà gbogbo.
3 “Makenagia mũthamaki na waganu wao, magakenia anene na maheeni mao.
“Wọ́n ń mú inú ọba dùn pẹ̀lú ìwà búburú wọn, àti inú ọmọ-aládé dùn pẹ̀lú irọ́ wọn.
4 Othe nĩ itharia, maakanaga ta riiko rĩa kũrugĩra mĩgate, rĩrĩa mũrugi wa mĩgate atabataragio nĩ gwakĩrĩria kuuma gũkanda mũtu nginya ũimbe.
Alágbèrè ni gbogbo wọn wọ́n gbóná bí ààrò àkàrà tí a dáwọ́ kíkoná dúró, lẹ́yìn ìgbà tí o ti pò ìyẹ̀fun tán, títí ìgbà tí yóò wú.
5 Mũthenya wa gĩathĩ kĩa mũthamaki witũ-rĩ, we na anene ake manyuuaga ndibei makarĩĩo, nake akanyiitana moko na arĩa manyũrũranagia.
Ní ọjọ́ àjọ̀dún ọba wa wáìnì mú ara ọmọ-aládé gbóná ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn oníyẹ̀yẹ́.
6 Ngoro ciao nĩ ta riiko rĩa kũrugĩra mĩgate; mathiiaga harĩ we marĩ na waara. Thuti ciao ciakanaga kahora ũtukũ wothe; nakuo gwakĩa rũciinĩ igaakana ta mwaki wa rũrĩrĩmbĩ.
Ọkàn wọn ń gbóná bí i ààrò wọ́n sì tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú rìkíṣí, ìbínú wọn pa lọ́lọ́ ní gbogbo òru ó sì bú jáde bí ọ̀wọ́-iná ní òwúrọ̀.
7 Othe mahiũhĩte ta riiko rĩa kũrugĩra mĩgate; moragaga aathani ao. Athamaki ao othe maniinagwo, na gũtirĩ o na ũmwe wao ũngayagĩra.
Gbogbo wọn gbóná bí ààrò wọ́n pa gbogbo olórí wọn run, gbogbo ọba wọn si ṣubú kò sì ṣí ẹnìkan nínú wọn tí ó ké pè mí.
8 “Efiraimu nĩetukanĩtie na ndũrĩrĩ; Efiraimu nĩ mũgate ũtarĩ mũgarũre.
“Efraimu ti darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn náà; Efraimu jẹ́ àkàrà tí a kò yípadà.
9 Andũ a kũngĩ marĩĩaga hinya wake, nowe ndamenyaga ũguo. Njuĩrĩ ciake irĩ na mbuĩ, nowe ndoonaga ũguo.
Àwọn àlejò ti jẹ agbára rẹ̀ run ṣùgbọ́n kò sì mọ̀. Ewú ti wà ní orí rẹ̀ káàkiri bẹ́ẹ̀ ni kò kíyèsi i.
10 Mwĩtĩĩo wa Isiraeli nĩũrutaga ũira wa kũmũũkĩrĩra, no o na kũrĩ ũguo-rĩ, we ndacookagĩrĩra Jehova Ngai wake, kana akamũrongooria.
Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí sí i ṣùgbọ́n pẹ̀lú gbogbo èyí kò padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run, tàbí kí ó wá a.
11 “Efiraimu ahaana ta ndutura, ĩrĩa ĩheenekaga narua, ĩtarĩ ũmenyo; rĩmwe akayagĩra bũrũri wa Misiri na rĩrĩa rĩngĩ agathiĩ Ashuri.
“Efraimu dàbí àdàbà tó rọrùn láti tànjẹ àti aláìgbọ́n tó wá ń pé Ejibiti nísinsin yìí tó sì tún ń padà lọ si Asiria.
12 Rĩrĩa magaathiĩ-rĩ, nĩngaikia wabu yakwa igũrũ rĩao; nĩngamaharũrũkia ta nyoni cia rĩera-inĩ. Rĩrĩa ngaigua nĩmaracookanĩrĩra-rĩ, nĩngamanyiita.
Nígbà tí wọ́n bá lọ, èmi ó ta àwọ̀n mi sórí wọn, Èmi ó fà wọ́n lulẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ ojú ọ̀run. Nígbà tí mo bá gbọ́ pé wọ́n rìn pọ̀, Èmi ó nà wọ́n fún iṣẹ́ búburú ọwọ́ wọn.
13 Kaĩ marĩ na haaro-ĩ, tondũ nĩmandiganĩirie! Maroniinwo, tondũ nĩmanemeire! Niĩ nĩnyendaga kũmahonokia, no-o no igenyo manjigagĩrĩra.
Ègbé ní fún wọn, nítorí pé wọ́n ti yà kúrò lọ́dọ̀ mi! Ìparun wà lórí wọn, nítorí pé wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi! Èmi fẹ́ láti rà wọ́n padà. Ṣùgbọ́n wọ́n ń parọ́ mọ́ mi.
14 Matingayagĩra kuuma ngoro-inĩ ciao, no kũgirĩka magirĩkaga marĩ marĩrĩ-inĩ mao. Monganaga hamwe nĩ ũndũ wa ngano, na ndibei ya mũhihano, no niĩ makaahutatĩra.
Wọn kò kégbe pè mí láti ọkàn wọn, ṣùgbọ́n wọ́n ń pohùnréré ẹkún lórí ibùsùn wọn. Wọ́n kó ara wọn jọ, nítorí ọkà àti wáìnì ṣùgbọ́n wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.
15 Ndaamathomithirie na ngĩmekĩra hinya, no-o mathugundaga kũnjĩka ũũru.
Mo kọ́ wọn, mo sì fún wọn ní agbára, síbẹ̀ wọ́n tún ń dìtẹ̀ mọ́ mi.
16 Maticookagĩrĩra Ũrĩa-ũrĩ-Igũrũ-Mũno; mahaana ta ũta ũrĩa ũhĩtagia wathi. Atongoria ao makooragwo na rũhiũ rwa njora, nĩ ũndũ wa ciugo ciao cia rũtũrĩko. Nĩ ũndũ wa ũguo nĩmakanyũrũrio kũu bũrũri wa Misiri.
Wọn kò padà sí ọ̀dọ̀ Ọ̀gá-ògo; wọ́n dàbí ọfà tí ó ti bàjẹ́. Àwọn aṣíwájú wọn yóò ti ipa idà ṣubú nítorí ìrunú ahọ́n wọn. Torí èyí, wọn ó fi wọ́n ṣe ẹlẹ́yà ní ilẹ̀ Ejibiti.

< Hosea 7 >