< Hosea 2 >
1 “Ha ũhoro wa ariũ a thoguo, meere atĩrĩ, ‘Inyuĩ mũrĩ andũ akwa’, na ha ũhoro wa aarĩ a thoguo, ũmeere atĩrĩ, ‘Inyuĩ mũrĩ endwa akwa’.
“Sọ fún àwọn arákùnrin rẹ, ‘Ènìyàn mi,’ kí o sì wí fún àwọn arábìnrin rẹ ‘Àyànfẹ́ mi.’
2 “Thaithai nyina wanyu, mũthaithei, nĩgũkorwo we ti mũtumia wakwa, na niĩ ndirĩ mũthuuriwe. Nĩeherie maũndũ ma ũtharia ũthiũ-inĩ wake, na athengie ũmaraya gatagatĩ-inĩ ka nyondo ciake.
“Ẹ bá ìyá yín wí, ẹ bá a wí, nítorí pé kì í ṣe ìyàwó mi, Èmi náà kì í sì í ṣe ọkọ rẹ̀. Jẹ́ kí ó yọ àgbèrè rẹ̀ kúrò lójú rẹ̀ àti àìṣòótọ́ kúrò ní àyà rẹ̀.
3 Akorwo ti ũguo ndĩmũrute nguo aikare arĩ njaga, na ndũme aikare njaga o ta mũthenya ũrĩa aaciarirwo; ngaamũtua ta werũ, na ndĩmũgarũre atuĩke bũrũri mũngʼaru, na ndĩmũũrage na nyoota.
Àìṣe bẹ́ẹ̀ èmi yóò tú u sí ìhòhò, Èmi yóò sì gbé e kalẹ̀ bí ọjọ́ tí a bí i. Èmi yóò ṣe ọ́ bí i aṣálẹ̀ ilẹ̀, Èmi yóò sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀ Èmi yóò sì fi òǹgbẹ gbẹ ẹ́.
4 Ndikaiguĩra ciana ciake tha, tondũ nĩ ciana cia ũtharia.
Èmi kò ní fi àánú mi hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀ nítorí ọmọ àgbèrè ni wọ́n jẹ́.
5 Nyina wao akoretwo akĩhũũra ũmaraya, na aagĩire nda ciao na njĩra cia ũũra-thoni. Nĩ ũndũ oigĩte atĩrĩ, ‘Nĩngũrũmĩrĩra endwa akwa, arĩa maaheaga irio ciakwa na maaĩ makwa, na guoya wakwa wa ngʼondu o na gatani yakwa, maguta makwa o na kĩrĩa nyuuaga.’
Nítorí ìyá wọn ti hùwà àgbèrè, ó sì lóyún wọn nínú ìtìjú. Ó wí pé, ‘Èmi ó tún tọ́ àwọn àyànfẹ́ mi lẹ́yìn, tó ń fún mi ní oúnjẹ àti omi, ní irun àgùntàn mi àti ọ̀gbọ̀ mi, òróró mi àti ohun mímu mi.’
6 Nĩ ũndũ wa ũguo nĩngũhinga njĩra yake na mĩigua, ndĩmũirigĩre thĩinĩ, aage njĩra ya kuumĩra.
Nítorí náà, èmi ó fi ẹ̀gún dì í lọ́nà, Èmi ó mọ odi yí i ká kí ó má ba à rọ́nà lọ.
7 Nĩagatengʼeria endwa ake na ndakamakinyĩra. Akaamacaria na ndakamona. Hĩndĩ ĩyo nĩagacooka oige atĩrĩ, ‘Nĩngũcooka kũrĩ mũthuuri wakwa wa mbere, nĩgũkorwo hĩndĩ ĩyo nĩndaikarĩte wega gũkĩra rĩu.’
Yóò sáré lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n kò ní bá wọn; yóò wá wọn ṣùgbọ́n kò ní rí wọn. Nígbà náà ni yóò sọ pé, ‘Èmi ó padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ mi àkọ́kọ́ nítorí pé ó dára fún mi nígbà náà ju ìsinsin yìí lọ.’
8 Mũtumia ũcio nĩagire kũmenya atĩ nĩ niĩ ndaamũheaga ngano, na ndibei ya mũhihano, o na maguta, na ngamũingĩhĩria betha na thahabu, iria maahũthagĩra gũthondeka ngai ĩrĩa ĩĩtagwo Baali.
Nítorí pé kò tí ì mọ̀ pé èmi ni àti ẹni tó fún un ní ọkà, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ẹni tí ó fún un ní fàdákà àti wúrà lọ́pọ̀lọ́pọ̀, èyí tí wọ́n lò fún Baali.
9 “Tondũ ũcio nĩngoya ngano yakwa yakũra, na ndibei yakwa ya mũhihano yagĩrĩra, na ndĩmũtunye guoya wakwa wa ngʼondu na gatani yakwa, o iria ciarĩ cia kũmũhumbĩra njaga yake.
“Nítorí náà, èmi yóò mú ọkà mi kúrò nígbà tó bá pọ́n, èmi yóò sì mú wáìnì mi kúrò ní àsìkò rẹ̀. Èmi yóò sì gba irun àgùntàn àti ọ̀gbọ̀ mi padà ti mo ti fi fún un láti bo ìhòhò rẹ̀.
10 Nĩ ũndũ ũcio, nĩngaguũria maũndũ make ma waganu endwa ake mamwĩroreire; gũtirĩ mũndũ ũkaamũteithũra moko-inĩ makwa.
Èmi yóò sì fi ìwà ìtìjú rẹ̀ hàn lójú àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ẹni tí yóò gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ mi,
11 Nĩnganiina ikeno ciake ciothe, arĩ cio: ciathĩ ciake cia mwaka o mwaka, na Tũrũgamo twake twa mweri, na mĩthenya yake ya Thabatũ, na ciathĩ ciake ciothe iria nyamũre.
Èmi yóò mú gbogbo ayọ̀ rẹ̀ wá sí òpin: àjọ̀dún ọdọọdún rẹ̀, oṣù tuntun rẹ̀, ọjọ́ ìsinmi, àti gbogbo àwọn àjọ̀dún tí a yàn.
12 Nĩngathũkangia mĩthabibũ yake na mĩkũyũ yake, ĩrĩa oigire nĩ irĩhi rĩake kuuma kũrĩ endwa ake; nĩngamĩtua ihinga, na nyamũ cia gĩthaka nĩikamĩrĩa.”
Èmi yóò pa àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ run, èyí tí ó pè ní èrè rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, Èmi yóò sọ wọ́n di igbó, àwọn ẹranko búburú yóò sì jẹ́ wọn run.
13 Jehova ekuuga atĩrĩ, “Nĩngamũherithia nĩ ũndũ wa mĩthenya ĩrĩa acinĩire Baali ũbumba; rĩrĩa eegemagia na icũhĩ, na mathaga ma goro, na akĩrũmĩrĩra endwa ake, no akĩriganĩrwo nĩ niĩ.
Èmi yóò bẹ̀ ọjọ́ Baalimu wò ní ara rẹ̀ nínú èyí tó ń fi tùràrí jóná fún Baali; tí ó fi òrùka etí àti ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́, tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ. Ṣùgbọ́n èmi ni òun gbàgbé,” ni Olúwa wí.
14 “Nĩ ũndũ wa ũguo nĩngũmũguucĩrĩria na waara; ngũmũtongoria nginya werũ-inĩ, na ndĩmwarĩrie na ciugo cia wendo.
“Nítorí náà, èmi yóò tàn án, Èmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀, Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀
15 Kũu nĩkuo ngaamũcookeria mĩgũnda yake ya mĩthabibũ, na ndue Kĩanda kĩa Akori mũrango wa mwĩhoko. Kũu nĩkuo akaina o ta ũrĩa ainaga matukũ-inĩ ma ũnini wake, aine ta ũrĩa ainire mũthenya ũrĩa aambatire kuuma bũrũri wa Misiri.”
Níbẹ̀ ni èmi yóò ti dá ọgbà àjàrà rẹ̀ padà fún un, Èmi yóò fi àfonífojì Akori ṣe ìlẹ̀kùn ìrètí fún un. Yóò sì kọrin níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tó kúrò ní Ejibiti.
16 Jehova ekuuga atĩrĩ, “Mũthenya ũcio-rĩ, nĩũkanjĩta ‘Mũthuuri wakwa’; ndũkanjĩta rĩngĩ ‘Mwathi wakwa’.
“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò pè mí ní ‘ọkọ mi’; ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’ ni Olúwa wí.
17 Nĩngeheria marĩĩtwa ma Baali kuuma mĩromo-inĩ yake; marĩĩtwa macio matikagwetwo rĩngĩ.
Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Baali kúrò lẹ́nu rẹ̀; ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Baali pè mọ́.
18 Mũthenya ũcio nĩngathondeka kĩrĩkanĩro na nyamũ cia gĩthaka, o na nyoni cia rĩera-inĩ, na ciũmbe iria ithiiagĩra gũkũ thĩ nĩ ũndũ wao. Ũta, na rũhiũ rwa njora, na mbaara nĩngaciniina bũrũri-inĩ, nĩgeetha othe makomage marĩ na thayũ.
Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀mú fún wọn àti àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀. Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́. Ọfà, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náà kí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.
19 Nĩngakũũria ũtuĩke mũtumia wakwa nginya tene; ngaakũũria ũtuĩke wakwa ũhoro-inĩ wa ũthingu na wa kĩhooto, ngũũrie ndĩ na wendo na tha.
Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé; Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àti òtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.
20 Nĩngakũũria ũtuĩke wakwa na wĩhokeku, nawe nĩũgetĩkĩra Jehova.”
Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní òtítọ́ ìwọ yóò sì mọ Olúwa.
21 Jehova ekuuga atĩrĩ, “Mũthenya ũcio-rĩ, nĩngacookia ũhoro; nĩngacookeria matu ũhoro, namo matu macookerie thĩ ũhoro;
“Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí; “Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùn àwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;
22 nayo thĩ ĩcookerie ngano, na ndibei ya mũhihano, na maguta ũhoro, nacio nĩigacookeria Jezireeli ũhoro.
ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró lóhùn Gbogbo wọn ó sì dá Jesreeli lóhùn.
23 Nĩngamũhaanda bũrũri-inĩ nĩ ũndũ wakwa mwene; nĩngonania wendo wakwa harĩ ũrĩa nderĩte atĩrĩ, ‘Niĩ ndikwendete’. Arĩa nderĩte atĩrĩ, ‘Inyuĩ mũtirĩ andũ akwa’, nĩngameera atĩrĩ, ‘Inyuĩ mũrĩ andũ akwa’; na mũndũ o mũndũ oige atĩrĩ, ‘Wee nĩwe Ngai wakwa.’”
Èmi ó sì gbìn ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náà, Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘Àánú gbà.’ Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’ ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’”