< Kĩambĩrĩria 48 >

1 Thuutha-inĩ ũcio Jusufu akĩĩrwo atĩrĩ, “Thoguo nĩ mũrũaru.” Nĩ ũndũ ũcio akĩoya ariũ ake eerĩ, Manase na Efiraimu, agĩthiĩ kũmũrora.
Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀ si, a wí fún Josẹfu pé, “Baba rẹ ń ṣàìsàn,” nítorí náà, ó mú àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì, Manase àti Efraimu lọ́wọ́ lọ pẹ̀lú rẹ̀.
2 Na rĩrĩa Jakubu eerirwo atĩrĩ, “Mũrũguo Jusufu nĩoka gũkuona,” Isiraeli akĩĩyũmĩrĩria, agĩikara thĩ ũrĩrĩ-inĩ.
Nígbà tí a sọ fún Jakọbu pé, “Josẹfu ọmọ rẹ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,” Israẹli rọ́jú dìde jókòó lórí ibùsùn rẹ̀.
3 Jakubu akĩĩra Jusufu atĩrĩ, “Ngai Mwene-Hinya-Wothe nĩanyumĩrĩire ndĩ Luzu bũrũri-inĩ wa Kaanani, na akĩndathima,
Jakọbu wí fún Josẹfu pé, “El-Ṣaddai, fi ara hàn mí ní Lusi ní ilẹ̀ Kenaani, níbẹ̀ ni ó sì ti súre fún mi.
4 akĩnjĩĩra atĩrĩ, ‘Nĩngatũma ũciarane na ũingĩhe. Nĩngagũtua kĩrĩndĩ kĩa andũ, na nĩngaheana bũrũri ũyũ kũrĩ njiaro ciaku iria igooka thuutha waku ũtuĩke wacio tene na tene.’
Ó sì wí fún mi pé, ‘Èmi yóò mú kí o bí sí i, ìwọ yóò sì pọ̀ sí i, èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, èmi yóò sì fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ ní ilẹ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí ohun ìní ayérayé.’
5 “Rĩu-rĩ, ariũ aku eerĩ arĩa maaciarĩirwo gũkũ Misiri itanooka kũrĩ we-rĩ, megũtuuo ta marĩ akwa; Efiraimu na Manase meegũtuĩka akwa, o ta ũrĩa Rubeni na Simeoni marĩ akwa.
“Nítorí náà báyìí, àwọn ọmọ rẹ méjèèjì tí a bí fún ọ ní ilẹ̀ Ejibiti, kí èmi kí ó tó tọ̀ ọ́ wá ní ìhín, ni mo sọ di ọmọ mi fúnra mi. Manase àti Efraimu yóò jẹ́ tèmi gẹ́gẹ́ bí Reubeni àti Simeoni ti jẹ́ tèmi.
6 Ciana iria ingĩ ũngĩciarĩrwo thuutha wao nĩ ciaku; kũrĩa makagaya mageetanagio na marĩĩtwa ma ariũ a ithe wao.
Àwọn ọmọ mìíràn tí ìwọ bá bí lẹ́yìn wọn yóò jẹ́ ọmọ rẹ. Ní ilẹ̀ tí wọn yóò jogún, orúkọ arákùnrin wọn ni a ó máa fi pè wọ́n.
7 Na rĩrĩa ndacookaga kuuma Padani, ngĩnyiitwo nĩ kĩeha gĩa gũkuĩrwo nĩ Rakeli kũu bũrũri-inĩ wa Kaanani tũrĩ o rũgendo-inĩ, hakuhĩ na Efiratha. Nĩ ũndũ ũcio ngĩmũthika hau mũkĩra-inĩ wa njĩra ya gũthiĩ Efiratha” (na nokuo Bethilehemu).
Bí mo ti ń padà láti Padani, Rakeli kú ní ọ̀nà nígbà tí ó ṣì wà ní ilẹ̀ Kenaani, èyí tó mú ìbànújẹ́ bá mi, níbi tí kò jìnnà sí Efrata. Nítorí náà èmí sì sin ín sí ẹ̀bá ọ̀nà tí ó lọ sí Efrata” (tí ṣe Bẹtilẹhẹmu).
8 Na rĩrĩa Isiraeli onire ariũ a Jusufu, akĩũria atĩrĩ, “Aya nĩ a?”
Nígbà tí Israẹli rí àwọn ọmọ Josẹfu, ó béèrè wí pé, “Àwọn wo nìyí?”
9 Jusufu akĩĩra ithe atĩrĩ, “Nĩ ariũ akwa arĩa Ngai aaheete ndĩ gũkũ”. Nake Isiraeli akiuga atĩrĩ, “Mareharehe harĩ niĩ ndĩmarathime.”
Josẹfu fún baba rẹ̀ lésì pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi fún mi ní ìhín.” Nígbà náà ni Israẹli wí pé, “Kó wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi kí èmi kí ó ba à le súre fún wọn.”
10 Na rĩrĩ, maitho ma Isiraeli nĩmoorĩte nĩ gũkũra, na ndoonaga wega. Jusufu agĩkĩrehe ariũ ake hakuhĩ na Isiraeli, nake Jakubu akĩmamumunya na akĩmahĩmbĩria.
Báyìí, ojú Israẹli ti ń di bàìbàì nítorí ogbó, agbára káká sì ni ó fi ń ríran. Josẹfu sì kó àwọn ọmọ rẹ̀ súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, baba rẹ̀ fẹnukò wọ́n ni ẹnu, ó sì dì mọ́ wọn.
11 Isiraeli akĩĩra Jusufu atĩrĩ, “Ndieciragia nĩngona ũthiũ waku rĩngĩ, na rĩu Ngai nĩanjĩtĩkĩrĩtie nyone o na ciana ciaku.”
Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Èmi kò lérò rárá pé, mo tún le rí ojú rẹ mọ́ láéláé, ṣùgbọ́n Ọlọ́run tún fún mi ní àǹfààní, mo sì tún rí àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú.”
12 Nake Jusufu akĩmaruta maru-inĩ ma Isiraeli, akĩinamĩrĩria ũthiũ akĩũturumithia thĩ.
Nígbà náà ni Josẹfu kó àwọn ọmọ náà kúrò ní orí eékún baba rẹ̀, ó wólẹ̀, ó sì tẹríba.
13 Jusufu akĩoya ariũ ake eerĩ, Efiraimu arĩ mwena wake wa ũrĩo aamwerekeirie guoko-inĩ kwa ũmotho gwa Isiraeli, na Manase arĩ mwena wake wa ũmotho aamwerekeirie guoko-inĩ kwa ũrĩo gwa Isiraeli, akĩmarehe hakuhĩ nake.
Josẹfu sì mú àwọn méjèèjì, Efraimu ni o fi sí ọwọ́ ọ̀tún òun tìkára rẹ̀, èyí tí í ṣe ọwọ́ òsì fún Israẹli, ó sì fi Manase sí ọwọ́ òsì ara rẹ̀, èyí tí ó bọ́ sí ọwọ́ ọ̀tún Israẹli.
14 No Isiraeli agĩtambũrũkia guoko gwake kwa ũrĩo agĩkũigĩrĩra mũtwe wa Efiraimu, o na gũtuĩka nĩwe warĩ mũnini, na akĩhĩtũkania moko make, akĩigĩrĩra guoko gwake kwa ũmotho mũtwe-inĩ wa Manase, o na gũtuĩka Manase nĩwe warĩ irigithathi.
Israẹli sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ jáde, ó sì gbe lé Efraimu lórí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun ni àbúrò, ó sì fi ọwọ́ rẹ̀ tàsé ara wọn, ó sì na ọwọ́ òsì lé Manase lórí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Manase ni àkọ́bí.
15 Ningĩ akĩrathima Jusufu, akiuga atĩrĩ, “Ngai ũrĩa maithe makwa Iburahĩmu na Isaaka maatungatagĩra, Ngai ũrĩa ũkoretwo arĩ mũrĩithi wakwa mũtũũrĩre-inĩ wakwa wothe nginya ũmũthĩ,
Nígbà náà ni ó súre fún Josẹfu wí pé, “Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run, ẹni tí baba mi Abrahamu àti Isaaki rìn níwájú rẹ̀, Ọlọ́run tí ó ti jẹ́ olùtọ́jú àti aláàbò mi ní gbogbo ọjọ́ ayé mi títí di òní,
16 na Mũraika ũrĩa ũũhonoketie kuuma mĩtino-inĩ yothe, arorathima imwana ici. Iroetanagio na rĩĩtwa rĩakwa, na ciĩtanagio na marĩĩtwa ma maithe makwa, Iburahĩmu na Isaaka, na maroingĩha mũno gũkũ thĩ.”
Angẹli tí ó dá mi ní ìdè kúrò lọ́wọ́ gbogbo ewu, kí ó súre fún àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí. Kí a máa fi orúkọ mi pè wọ́n àti orúkọ àwọn baba mi Abrahamu àti Isaaki, kí wọn kí ó sì pọ̀ sí i lọ́pọ̀lọ́pọ̀ lórí ilẹ̀ ayé.”
17 Na rĩrĩa Jusufu onire atĩ ithe aigĩrĩire guoko gwake kwa ũrĩo mũtwe-inĩ wa Efiraimu-rĩ, ndaakenire; akĩnyiita guoko gwa ithe akweherie kuuma mũtwe-inĩ wa Efiraimu, akũigĩrĩre mũtwe-inĩ wa Manase.
Nígbà tí Josẹfu rí i pé baba òun gbé ọwọ́ ọ̀tún lé Efraimu lórí, inú rẹ̀ bàjẹ́, ó sì gbá ọwọ́ baba rẹ̀ mú láti gbé ọwọ́ rẹ̀ kúrò lórí Efraimu lọ sí orí Manase.
18 Jusufu akĩmwĩra atĩrĩ, “Aca, baba ũyũ nĩwe irigithathi; mũigĩrĩre guoko gwaku kwa ũrĩo mũtwe.”
Josẹfu wí fun pé, “Rárá, baba mi, èyí ni àkọ́bí, orí rẹ̀ ni kí ìwọ kí o gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ lé.”
19 No ithe akĩrega, akiuga atĩrĩ, “Nĩnjũũĩ ũguo mũrũ wakwa, nĩnjũũĩ. O nake nĩagatuĩka rũrĩrĩ, na nĩakaneneha. No rĩrĩ, mũrũ wa nyina ũrĩa mũnini nĩakaneneha kũmũkĩra, nacio njiaro ciake ituĩke gĩkundi kĩa ndũrĩrĩ.”
Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ kò gbà, ó wí pé, “Mo mọ̀, ọmọ mi, mo mọ̀. Òun náà yóò di orílẹ̀-èdè, òun náà yóò sì di ńlá. Ṣùgbọ́n àbúrò rẹ̀ yóò di ẹni ńlá jù ú lọ, irú-ọmọ rẹ yóò sì di ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè.”
20 Akĩmarathima mũthenya ũcio, akiuga atĩrĩ, “Isiraeli akaarathimanaga akĩgwetaga rĩĩtwa rĩaku akoiga atĩrĩ: ‘Ngai arotũma ũtuĩke o ta Efiraimu na Manase.’” Nĩ ũndũ ũcio akĩgweta Efiraimu mbere ya Manase.
Ó súre fún wọn lọ́jọ́ náà pé, “Ní orúkọ yín ni Israẹli yóò máa súre yìí pé, ‘Kí Ọlọ́run ṣe ọ́ bí i ti Efraimu àti Manase.’” Ó sì gbé Efraimu gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ́n sí Manase.
21 Ningĩ Isiraeli akĩĩra Jusufu atĩrĩ, “Ndĩ hakuhĩ gũkua, no Ngai nĩegũkorwo hamwe na inyuĩ, na nĩakamũcookia bũrũri-inĩ wa maithe manyu.
Nígbà náà ni Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Ọjọ́ ikú mi súnmọ́ etílé, ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò wà pẹ̀lú yín, yóò sì mú un yín padà sí ilẹ̀ àwọn baba yín.
22 Nawe, ũrĩ ta mwathi wa ariũ a thoguo-rĩ, nĩndakũhe rũgongo rwa bũrũri ũrĩa ndaatunyire Aamori na rũhiũ rwakwa rwa njora na ũta wakwa.”
Pẹ̀lúpẹ̀lú èmi yóò fún ọ ní ìpín kan ju ti àwọn arákùnrin rẹ lọ. Ilẹ̀ tí mo fi idà àti ọ̀kọ̀ mi gbà lọ́wọ́ àwọn ará Amori.”

< Kĩambĩrĩria 48 >