< Kĩambĩrĩria 44 >

1 Nake Jusufu agĩatha mũnene wa nyũmba yake, akĩmwĩra atĩrĩ, “Iyũria makũnia ma andũ aya irio nyingĩ o ta ũrĩa mangĩhota gũkuua, na wĩkĩre betha ya mũndũ o mũndũ mũromo-inĩ wa ikũnia rĩake.
Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Di oúnjẹ kún inú àpò àwọn ọkùnrin náà tó ìwọ̀n èyí tí wọ́n le rù, kí o sì mú owó olúkúlùkù àwọn ọkùnrin náà padà sí ẹnu àpò rẹ̀.
2 Ningĩ wĩkĩre gĩkombe gĩakwa kĩrĩa kĩa betha mũromo-inĩ wa ikũnia rĩa ũrĩa mũnini biũ wao, hamwe na betha cia ngano yake.” Nake mũnene ũcio agĩĩka o ũrĩa Jusufu aamwĩrire.
Nígbà náà ni kí o mú kọ́ọ̀bù idẹ mi sí ẹnu àpò èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn nínú wọn pẹ̀lú owó tí ó fi ra ọkà,” ó sì ṣe bí Josẹfu ti sọ.
3 Rũciinĩ gwakĩa-rĩ, andũ acio makiumagario hamwe na ndigiri ciao.
Bí ilẹ̀ ti ń mọ́, wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà lọ pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.
4 Matanathiĩ kũraya na itũũra rĩu inene-rĩ, Jusufu akĩĩra mũnene wa nyũmba yake atĩrĩ, “Rũmĩrĩra andũ acio o rĩu, na wamakinyĩra ũmoorie atĩrĩ, ‘Mwarĩha wega na ũũru nĩkĩ?
Wọn kò tí ì rìn jìnnà sí ìlú náà tí Josẹfu fi wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Lépa àwọn ọkùnrin náà, nígbà tí o bá sì bá wọn, kí o wí pé, ‘Èéṣe ti ẹ fi búburú san rere?
5 Githĩ gĩkombe gĩkĩ tikĩo mwathi wakwa anyuuaga nakĩo na akaragũra nakĩo? Ũndũ ũyũ mwĩkĩte nĩ ũndũ mũũru mũno.’”
Èyí ha kọ́ ni kọ́ọ̀bù tí olúwa mi ń lò fún ohun mímu tí ó sì tún ń fi í ṣe àyẹ̀wò? Ohun tí ẹ ṣe yìí burú púpọ̀.’”
6 Na rĩrĩa aamakinyĩrire-rĩ, agĩcookera ciugo icio kũrĩ o.
Nígbà tí ó sì bá wọn, o sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún wọn.
7 Nao makĩmũũria atĩrĩ, “Mwathi witũ ekwaria maũndũ ta macio nĩkĩ? Ithuĩ ndungata ciaku tũroaga gwĩka ũndũ ta ũcio!
Ṣùgbọ́n wọ́n dá a lóhùn pé, “Kí ló dé tí olúwa mi sọ irú nǹkan wọ̀nyí? Ká má rí i! Àwọn ìránṣẹ́ rẹ kò le ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀!
8 Ithuĩ o na nĩtũragũcookeirie betha iria twakorire mĩromo-inĩ ya makũnia maitũ kuuma bũrũri wa Kaanani; nĩ kĩĩ kĩngĩtũma tũiye betha kana thahabu kuuma nyũmba ya mwathi waku?
A tilẹ̀ mú owó tí a rí lẹ́nu àpò wa padà tọ̀ ọ́ wá láti ilẹ̀ Kenaani. Nítorí náà èéṣe tí àwa yóò fi jí wúrà tàbí idẹ ní ilé olúwa à rẹ?
9 Ndungata o na ĩmwe yaku yakorwo ĩrĩ nakĩo-rĩ, no ĩgũkua, na ithuĩ aya angĩ tũtuĩke ngombo cia mwathi witũ.”
Bí a bá rí i lọ́wọ́ èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ, kíkú ni yóò kú, àwọn tí ó kù yóò sì di ẹrú fún olúwa à rẹ.”
10 Nake akiuga atĩrĩ, “Nĩ wega, nĩgũtuĩke o ũguo mwoiga. Ũrĩa ũgũkorwo nakĩo nĩwe ũgũtuĩka ngombo yakwa; inyuĩ arĩa angĩ mũtirĩ na ũcuuke.”
Ó wí pé, “Ó dára, kí ó rí bí ẹ ti ṣe sọ. Ẹnikẹ́ni tí mo bá rí i lọ́wọ́ rẹ̀ yóò di ẹrú mi. Ẹ̀yin tí ó kù yóò sì wà láìlẹ́bi.”
11 O mũndũ o mũndũ agĩikũrũkia ikũnia rĩake thĩ na ihenya na akĩrĩtumũra.
Olúkúlùkù wọn yára sọ àpò rẹ̀ kalẹ̀, wọ́n sì tú u.
12 Nake mũnene ũcio wa nyũmba ya Jusufu akĩambĩrĩria gũcaria gĩkombe, ambĩrĩirie harĩ ũrĩa mũkũrũ wao na akĩrĩkĩrĩria harĩ ũrĩa mũnini biũ. Nakĩo gĩkombe kĩu gĩkĩoneka ikũnia-inĩ rĩa Benjamini.
Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà bẹ̀rẹ̀ sí ní í wá a, bẹ̀rẹ̀ láti orí ẹ̀gbọ́n títí lọ sórí àbúrò pátápátá. Ó sì rí kọ́ọ̀bù náà nínú àpò ti Benjamini.
13 Nao moona ũguo-rĩ, magĩtembũranga nguo ciao. Magĩcooka makĩhaicia mĩrigo yao ndigiri igũrũ magĩcooka na thuutha kũu itũũra-inĩ inene.
Nígbà tí wọ́n rí èyí, wọ́n fa aṣọ wọn ya, wọ́n sì banújẹ́ gidigidi, wọn tún ẹrù wọn dì sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọ́n sì padà sí inú ìlú.
14 Jusufu aarĩ o kũu nyũmba rĩrĩa Juda na ariũ a ithe maatoonyire kuo. Nao makĩĩgũithia thĩ mbere yake.
Josẹfu sì wà nínú ilé nígbà tí Juda àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wọlé wá. Gbogbo wọn sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
15 Jusufu akĩmooria atĩrĩ, “Nĩ ũndũ ũrĩkũ ũyũ mwĩkĩte? Kaĩ mũtooĩ atĩ mũndũ ta niĩ no ahote kũmenya maũndũ na njĩra ya ũragũri?”
Josẹfu wí fún wọn pé, “Èwo ni èyí tí ẹ ṣe yìí? Ṣe ẹ kò mọ pé, ènìyàn bí èmi le è rí ìdí nǹkan nípa ṣíṣe àyẹ̀wò?”
16 Juda akĩmũcookeria atĩrĩ, “Nĩ atĩa tũngĩĩra mwathi witũ? Tũngiuga atĩa? Tũngĩhota atĩa kuonania atĩ tũtiĩhĩtie? Ngai nĩwe ũguũrĩtie mahĩtia ma ndungata ciaku. Rĩu ithuĩ tũrĩ ngombo cia mwathi witũ, ithuothe ũndũ ũmwe na ũrĩa ũkorirwo na gĩkombe kĩu.”
Juda dáhùn pé, “Kí ni à bá sọ fún olúwa mi? Báwo ni a ṣe lè wẹ ara wa mọ́? Ọlọ́run ti tú àṣírí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, a ti di ẹrú olúwa à mi báyìí àwa fúnra wa àti ẹni náà tí a rí kọ́ọ̀bù lọ́wọ́ rẹ̀.”
17 No Jusufu akiuga atĩrĩ, “Ndĩroaga gwĩka ũndũ ta ũcio! Mũndũ ũrĩa ũkorirwo na gĩkombe kĩu nowe ũgũtuĩka ngombo yakwa. Inyuĩ aya angĩ, cookai kũrĩ ithe wanyu na thayũ.”
Ṣùgbọ́n Josẹfu dáhùn pé, “Ká má rí i pé mo ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀! Ẹni tí a bá kọ́ọ̀bù mi lọ́wọ́ rẹ̀ nìkan ni yóò di ẹrú mi, ẹ̀yin tí ó kù, ẹ máa lọ sọ́dọ̀ baba yín ní àlàáfíà.”
18 No Juda agĩthiĩ harĩ we, akiuga atĩrĩ, “Ndagũthaitha mwathi wakwa, ĩtĩkĩria ndungata yaku yarĩrie mwathi wakwa. Ndũkarakarĩre ndungata yaku o na gũtuĩka ũiganaine na Firaũni we mwene.
Nígbà náà ni Juda súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó sọ ọ̀rọ̀ kan fún olúwa mi, má ṣe bínú sí ìránṣẹ́ rẹ bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ pẹ̀lú láṣẹ bí i ti Farao.
19 Mwathi wakwa, wee woririe ndungata ciaku atĩrĩ, ‘Nĩ mũrĩ ithe wanyu kana mũrũ wa thoguo wanyu ũngĩ?’
Olúwa mi béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ǹjẹ́ ó ní baba tàbí arákùnrin?’
20 Na ithuĩ tũgĩgũcookeria atĩrĩ, ‘Tũrĩ na ithe witũ mũthuuri mũkũrũ mũno, na kũrĩ kamwana kanini aaciarĩirwo ũkũrũ-inĩ wake. Mũrũ-wa-nyina na kamwana kau nĩ mũkuũ, na nowe wiki wa ariũ a nyina ũtigarĩte, na ithe nĩamwendete mũno.’
Àwa sì wí fún olúwa mi pé, ‘A ni baba tí ó ti darúgbó, ọmọkùnrin kan sì wà pẹ̀lú tí a bí fún un ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀, baba rẹ̀ sì fẹ́ràn án rẹ̀.’
21 “Hĩndĩ ĩyo ũkĩĩra ndungata ciaku atĩrĩ, ‘Thiĩi mũmũikũrũkie mũmũrehe ndĩmwĩonere.’
“Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ mu un tọ̀ mí wá kí n le fojú ara mi rí i.’
22 Na ithuĩ tũkĩĩra mwathi witũ atĩrĩ, ‘Kamwana kau gatingiuma harĩ ithe; kangiuma harĩ we, ithe no gũkua angĩkua.’
A sì sọ fún olúwa à mi pé, ‘Ọmọkùnrin náà kò le è fi baba rẹ̀ sílẹ̀, bí ó bá dán an wò baba rẹ̀ yóò kú.’
23 No wee werire ndungata ciaku atĩrĩ, ‘Tiga mũũkire na mũrũ wa thoguo ũcio mũnini biũ, mũtikoona ũthiũ wakwa rĩngĩ.’
Ṣùgbọ́n ìwọ wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ má ṣe padà tọ̀ mí wá àyàfi bí àbíkẹ́yìn yín bá bá yín wá.’
24 Na twainũka kũrĩ ndungata yaku ũcio ithe witũ, tũkĩmwĩra ũrĩa wee mwathi witũ woigĩte.
Nígbà tí a padà lọ sọ́dọ̀ baba wa, tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ, a sọ ohun tí olúwa à mi wí fún un.
25 “Ningĩ ithe witũ agĩtwĩra atĩrĩ, ‘Cookai, mũthiĩ mũgũre irio ingĩ nini.’
“Nígbà náà ni baba wa wí pé, ‘Ẹ padà lọ láti lọ ra oúnjẹ díẹ̀ wá.’
26 No ithuĩ tũkĩmwĩra atĩrĩ, ‘Tũtingĩikũrũka kuo. No gũkorirwo nĩtũgũthiĩ na mũriũ waku ũyũ mũnini biũ. Tũtingĩona ũthiũ wa mũndũ ũcio tiga mũriũ waku ũyũ akorirwo na ithuĩ.’
Ṣùgbọ́n a wí pe, ‘Àwa kò le è padà lọ, àyàfi bí àbúrò wa pátápátá yóò bá bá wa lọ. A kò le è rí ojú ọkùnrin náà àyàfi tí àbúrò wa bá lọ pẹ̀lú wa.’
27 “Nayo ndungata yaku ũcio ithe witũ agĩtwĩra atĩrĩ, ‘Inyuĩ nĩmũũĩ atĩ mũtumia wakwa Rakeli aanjiarĩire ariũ eerĩ.
“Baba mi, ìránṣẹ́ rẹ wí fún wa pé, ‘Ẹ mọ̀ pé ìyàwó mi bí ọmọkùnrin méjì fún mi.
28 Ũmwe wacio nĩathiire na ndacooke, na niĩ ngiuga atĩrĩ, “Ti-itherũ nĩatambuurĩtwo nĩ nyamũ!” Na kuuma hĩndĩ ĩyo ndirĩ ndamuona rĩngĩ.
Ọ̀kan nínú wọn lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, mo sì wí pé, “Dájúdájú a ti fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.” N kò sì tí ì ri láti ọjọ́ náà.
29 Mũngĩoya ũyũ ũngĩ nake akoone mũtino-rĩ, mwatũma mbuĩ ici ciakwa ithiĩ mbĩrĩra na kĩeha.’ (Sheol h7585)
Tí ẹ bá tún mú èyí lọ, kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ohunkóhun bá ṣe é, ìbànújẹ́ ni ẹ ó fi mú ewú orí mi lọ sí ipò òkú.’ (Sheol h7585)
30 “Na rĩrĩ, kamwana gaka kangĩaga gũthiĩ na niĩ tũgacooka kũrĩ ndungata yaku ũcio baba, o baba ũcio muoyo wake wohanĩtio na muoyo wa kamwana gaka-rĩ,
“Nítorí náà, bí a bá padà tọ baba wa lọ láìsí ọmọ náà pẹ̀lú wa nígbà tí a mọ̀ pé, ọmọ náà ni ẹ̀mí baba wa.
31 oone atĩ kamwana gaka tũtirĩ nako, no gũkua agaakua. Ithuĩ ndungata ciaku tũgĩikũrũkie mbuĩ cia ithe witũ mbĩrĩra-inĩ na kĩeha. (Sheol h7585)
Tí ó bá ri pé ọmọkùnrin náà kò wá pẹ̀lú wa, yóò kùú. Àwọn ìránṣẹ́ rẹ yóò wá mú baba wa tòun ti ewú orí lọ sí ipò òkú ní ìbànújẹ́. (Sheol h7585)
32 Niĩ ndungata yaku-rĩ, nĩnderutĩire kũrĩ baba gũkamenyerera. Ngiuga atĩrĩ, ‘Ingĩkaaga gũgacookia kũrĩ we-rĩ, nĩngacookererwo nĩ ihĩtia rĩĩrĩ ndĩ mbere ya baba, matukũ mothe ma muoyo wakwa!’
Ìránṣẹ́ rẹ ló ṣe onídùúró fún ààbò ọmọ náà lọ́dọ̀ baba mi. Mo wí pé, ‘Bí n kò bá mú un padà tọ̀ ọ́ wá, baba mi, èmi ó ru ẹ̀bi rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé mi!’
33 “Na rĩu ndagũthaitha ũreke niĩ ndungata yaku ndigwo gũkũ nduĩke ngombo ya mwathi wakwa handũ ha kamwana gaka, na wĩtĩkĩrie kamwana gaka kainũke na ariũ a ithe.
“Nítorí náà, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó dúró ní ìhín lọ́dọ̀ olúwa à mi bí ẹrú dípò ọmọ náà. Kí ọmọ náà bá àwọn arákùnrin rẹ̀ padà.
34 Ingĩhota atĩa kũinũka kũrĩ baba itarĩ na kamwana gaka? Aca! Ndũkareke ngoone kĩeha kĩrĩa kĩngĩnyiita baba.”
Báwo ni mo ṣe lè padà tọ baba mi lọ láì bá ṣe pé ọmọ náà wà pẹ̀lú mi? Rárá, èmi kò fẹ́ kí n rí ìbànújẹ́ tí yóò dé bá baba mi.”

< Kĩambĩrĩria 44 >