< Kĩambĩrĩria 41 >

1 Na rĩrĩ, mĩaka ĩĩrĩ mĩgima yathira-rĩ, Firaũni akĩroota kĩroto: Akĩona arũgamĩte rũteere-inĩ rwa Rũũĩ rwa Nili;
Nígbà tí odindi ọdún méjì sì ti kọjá, Farao lá àlá: ó rí ara rẹ̀ tó dúró ní etí odò Naili.
2 na rĩrĩ, gũkiumĩra ngʼombe mũgwanja njega na noru kuuma thĩinĩ wa rũũĩ rũu, na igĩitĩka kũrĩa nyeki ithanjĩ-inĩ.
Nígbà náà ni màlúù méje jáde láti inú odò, wọ́n dára láti wò, wọ́n sì sanra, wọ́n sì ń jẹ koríko.
3 Thuutha wacio rĩ, hakiumĩra ngʼombe ingĩ mũgwanja, njongʼi na hĩnju, kuuma rũũĩ rũu rwa Nili, na ikĩrũgama mwena-inĩ harĩa icio ingĩ ciarũgamĩte hũgũrũrũ-inĩ cia rũũĩ.
Lẹ́yìn àwọn wọ̀nyí, ni àwọn màlúù méje mìíràn tí kò lẹ́wà tí ó sì rù jáde wá láti inú odò Naili, wọ́n sì dúró ti àwọn méje tí ó sanra tí ó wà ní bèbè odò náà.
4 Na rĩrĩ, ngʼombe icio njongʼi na hĩnju ikĩrĩa ngʼombe iria mũgwanja njega na noru. Hĩndĩ ĩyo Firaũni akĩũrwo nĩ toro.
Àwọn màlúù tí ó rù, tí kò sì lẹ́wà sì gbé àwọn tí ó lẹ́wà tí ó sanra jẹ. Nígbà náà ni Farao jí.
5 Ningĩ Firaũni agĩkoma rĩngĩ na akĩroota kĩroto gĩa keerĩ: Magira mũgwanja mega ma ngano, maiyũrĩte ngano, maakũraga kamũtĩ-inĩ kamwe ka ngano.
Ó sì tún padà sùn, ó sì lá àlá mìíràn: ó rí síírí ọkà méje tí ó kún, ó yómọ, ó sì dára, ó sì jáde lára igi ọkà kan ṣoṣo.
6 Thuutha wamo gũgĩthethũka magira mangĩ mũgwanja ma ngano mahĩnju, mahaana ta macinĩtwo nĩ rũhuho rwa mwena wa irathĩro.
Lẹ́yìn wọn ni síírí ọkà méje mìíràn yọ, wọn kò yómọ, afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ti rẹ̀ ẹ́ dànù.
7 Magira macio mahĩnju ma ngano makĩmeria magira marĩa mũgwanja maarĩ mega na maiyũrĩte ngano. Hĩndĩ ĩyo Firaũni akĩũrwo nĩ toro, agĩũkĩra agĩkora nĩ kũroota ekũrootaga.
Àwọn síírí ọkà méje tí kò yómọ (ọmọ rẹ̀ kò tóbi) wọ̀nyí sì gbé àwọn tí ó yómọ (ọmọ rẹ̀ tóbi) mì. Nígbà náà ni Farao jí lójú oorun, ó sì rí i pé àlá ni.
8 Rũciinĩ agĩtangĩka meciiria, na nĩ ũndũ ũcio agĩtũmanĩra andũ-ago othe na andũ arĩa oogĩ a Misiri. Firaũni akĩmeera irooto ciake, no gũtirĩ wao o na ũmwe wahotire kũmũtaũrĩra.
Ní òwúrọ̀, ọkàn rẹ̀ dàrú, nítorí náà, ó ránṣẹ́ pe gbogbo àwọn onídán àti ọ̀mọ̀ran ilẹ̀ Ejibiti. Farao rọ́ àlá rẹ̀ fún wọn, ṣùgbọ́n kò rí ọ̀kan nínú wọn tí ó le sọ ìtumọ̀ àlá náà fún un.
9 Hĩndĩ ĩyo mũnene wa arĩa maamũtwaragĩra ndibei akĩĩra Firaũni atĩrĩ, “Ũmũthĩ nĩndaririkanio mahĩtia makwa.
Nígbà náà ni olórí agbọ́tí wí fún Farao pé, “Lónìí ni mo rántí ẹ̀ṣẹ̀ mi.
10 Hĩndĩ ĩmwe-rĩ, Firaũni nĩarakarĩtio nĩ ndungata ciake; na niĩ hamwe na mũnene wa arĩa athondeki mĩgate-rĩ, agĩtuohithia njeera nyũmba-inĩ ya mũnene wa arangĩri.
Nígbà kan tí Farao bínú sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, tí ó sì fi èmi àti olórí alásè sínú ẹ̀wọ̀n ní ilé olórí ẹ̀ṣọ́.
11 Ũtukũ ũmwe-rĩ, o ũmwe witũ akĩroota kĩroto, na o kĩroto kĩarĩ na ũtaũri wakĩo mwanya.
Ọ̀kọ̀ọ̀kan wa lá àlá, àlá kọ̀ọ̀kan sì ní ìtumọ̀ tirẹ̀.
12 Na rĩrĩ, kũu njeera twarĩ na mwanake Mũhibirania, ndungata ya mũnene wa arangĩri. Na ithuĩ tũkĩmwĩra irooto ciitũ, nake agĩtũtaũrĩra; akĩhe o mũndũ ũtaũri wa kĩroto gĩake.
Ọmọkùnrin ará Heberu kan tí ó jẹ́ ìránṣẹ́ olórí ẹ̀ṣọ́ wà níbẹ̀ pẹ̀lú wa. A rọ́ àwọn àlá wa fún un, ó sì túmọ̀ wọn fún wa, ó sọ ìtumọ̀ àlá ẹnìkọ̀ọ̀kan fún un.
13 Namo maũndũ magĩkĩka o ta ũrĩa aatũtaũrĩire. Niĩ ngĩcookio wĩra-inĩ wakwa, nake mũndũ ũcio ũngĩ agĩcuurio mũtĩ igũrũ.”
Bí ó sì ti túmọ̀ àlá wọ̀nyí náà ni ohun gbogbo rí. A dá mi padà sí ipò mi, a sì so ọkùnrin kejì kọ́ sórí ọ̀wọ̀n.”
14 Nĩ ũndũ ũcio Firaũni agĩtũmanĩra Jusufu, nake akĩrutwo kũu njeera narua. Na aarĩkia kwĩyenja na kũruta nguo iria arĩ nacio na gwĩkĩra ingĩ-rĩ, agĩthiĩ mbere ya Firaũni.
Nítorí náà Farao ránṣẹ́ pe Josẹfu, wọn sì mú un wá kíákíá láti inú ìhámọ́. Nígbà tí ó fá irun rẹ̀, tí ó sì pààrọ̀ aṣọ rẹ̀, ó wá síwájú Farao.
15 Nake Firaũni akĩĩra Jusufu atĩrĩ, “Ndĩrarootire kĩroto na gũtirĩ mũndũ ũrahota gũgĩtaũra. No nĩnjiguĩte gũkĩĩrwo atĩrĩ, wee ũngĩĩrwo kĩroto no ũhote gũgĩtaũra.”
Farao wí fún Josẹfu, “Mo lá àlá kan, kò sì sí ẹni tí o le è túmọ̀ rẹ̀. Ṣùgbọ́n mo ti gbọ́ nípa rẹ pé bí o bá ti gbọ́ àlá, o le è túmọ̀ rẹ̀.”
16 Jusufu agĩcookeria Firaũni atĩrĩ, “Niĩ mwene ndingĩhota, no Ngai nĩekũhe Firaũni macookio marĩa arenda.”
Josẹfu dá Farao ní ohùn pé, “Kì í ṣe agbára mi, ṣùgbọ́n, Ọlọ́run ni yóò fi ìdáhùn àlàáfíà fún Farao ní ìtumọ̀ àlá náà.”
17 Hĩndĩ ĩyo Firaũni akĩĩra Jusufu atĩrĩ, “Kĩroto-inĩ gĩakwa-rĩ, ndĩrarũgamĩte hũgũrũrũ-inĩ cia Rũũĩ rwa Nili,
Nígbà náà ni Farao wí fún Josẹfu pé, “Ní inú àlá mi, mo dúró ni etí bèbè odò Naili,
18 rĩrĩa haroimĩrire ngʼombe mũgwanja njega na noru kuuma rũũĩ, na iraitĩka kũrĩa kũu ithanjĩ-inĩ.
sì kíyèsi i, màlúù méje tí ó sanra tí o sì lẹ́wà jáde wá, wọ́n sì ń jẹ koríko ní tòsí ibẹ̀.
19 Thuutha wacio kũracooka kũroimĩra ngʼombe ingĩ mũgwanja hinyaru, njongʼi mũno na hĩnju. Ndirĩ ndona ngʼombe njongʼi ta icio bũrũri-inĩ wothe wa Misiri.
Lẹ́yìn wọn, màlúù méje mìíràn jáde wá, wọ́n rù hángógó, wọn kò sì lẹ́wà tó bẹ́ẹ̀ tí n kò tí ì rí irú màlúù tí ó ṣe àìlẹ́wà tó bẹ́ẹ̀ rí ní ilẹ̀ Ejibiti.
20 Nacio ngʼombe icio hĩnju na njongʼi irarĩa ngʼombe iria mũgwanja noru iria iroimĩrĩte mbere.
Àwọn màlúù tí ó rù tí kò sì lẹ́wà sì jẹ àwọn màlúù tí ó sanra tí ó kọ́ jáde nínú odò.
21 No rĩrĩ, o na ciarĩkia gũcirĩa-rĩ, gũtirĩ mũndũ ũngĩramenyire atĩ nĩirarĩĩte; tondũ ironekaga irĩ o njongʼi o ta mbere. Hĩndĩ ĩyo ndĩrokĩra.
Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jẹ́ wọ́n tan, kò sì ẹni tí ó le mọ̀ pé wọ́n jẹ ohunkóhun, nítorí wọn kò sanra sí i, wọn sì bùrẹ́wà síbẹ̀. Nígbà náà ni mo tají.
22 “Ningĩ irooto-inĩ ciakwa-rĩ, nĩndĩronire magira mũgwanja mega ma ngano na maiyũrĩte ngano, magĩkũũra kamũtĩ-inĩ ka ngano.
“Ní ojú àlá mi, mo tún rí síírí ọkà méje tí ó yó ọmọ tí ó sì dára, wọ́n jáde láti ara igi ọkà kan.
23 Thuutha wamo, magira mangĩ mũgwanja marathethũka, marĩ mahoohu na macinĩtwo nĩ rũhuho rwa mwena wa irathĩro.
Lẹ́yìn wọn, àwọn méje mìíràn yọ jáde, tí kò yó ọmọ bẹ́ẹ̀ ni afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ti rẹ̀ ẹ́ dànù tán.
24 Namo magira macio mahĩnju marameria magira marĩa mũgwanja mega. Ndĩraheire andũ-ago ũhoro ũcio, no gũtirĩ o na ũmwe ũrahotire kũndaũrĩra irooto icio.”
Àwọn síírí ọkà méje tí kò yómọ sì gbé àwọn méje tí ó dára wọ̀nyí mì. Mo sọ àlá yìí fún àwọn onídán mi, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó le túmọ̀ rẹ̀ fún mi.”
25 Nake Jusufu akĩĩra Firaũni atĩrĩ, “Irooto cia Firaũni cierĩ no kĩroto kĩmwe. Ngai nĩaguũrĩirie Firaũni ũrĩa akiriĩ gwĩka.
Nígbà náà ni Josẹfu wí fún Farao, “Ìtumọ̀ kan náà ni àwọn àlá méjèèjì ní. Ọlọ́run fi ohun tí ó fẹ́ ṣe hàn fún Farao.
26 Ngʼombe iria mũgwanja njega nĩ mĩaka mũgwanja, na magira marĩa mũgwanja mega ma ngano nĩ mĩaka mũgwanja; kĩroto kĩu no kĩmwe.
Àwọn màlúù méje ti ó dára jẹ́ ọdún méje, síírí ọkà méje tí ó dára náà sì jẹ́ ọdún méje: ọ̀kan ṣoṣo ni wọn, àlá kan náà ni.
27 Nacio ngʼombe icio mũgwanja hĩnju na njongʼi iria cioimĩrire thuutha nĩ mĩaka mũgwanja, na no taguo magira marĩa mũgwanja matarĩ ngano macinĩtwo nĩ rũhuho rwa mwena wa irathĩro: ĩyo nĩ mĩaka mũgwanja ya ngʼaragu.
Àwọn màlúù méje tí kò sanra, tí kò sì rẹwà tí ó jáde gbẹ̀yìn jẹ́ ọdún méje, bẹ́ẹ̀ náà ni síírí ọkà méje tí kò dára, tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ti rẹ̀ dànù tan, wọn jẹ́ ọdún méje tí ìyàn yóò fi mú.
28 “Na o ta ũrĩa ndeera Firaũni: Ngai nĩ oneetie Firaũni ũrĩa akiriĩ gwĩka.
“Bí mo ti wí fún Farao ní ìṣáájú náà ni: Ọlọ́run fi ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ han Farao.
29 Nĩgũgũkorwo na mĩaka mũgwanja ya bũthi mũnene bũrũri wothe wa Misiri,
Ọdún méje tí oúnjẹ yóò pọ̀ yanturu ń bọ̀ wà ní Ejibiti.
30 no nĩgũgũcooka kũrũmĩrĩrwo nĩ mĩaka mũgwanja ya ngʼaragu. Naguo bũthi ũcio wothe wa Misiri nĩũkariganĩra, nayo ngʼaragu nĩĩkananga bũrũri ũyũ.
Ṣùgbọ́n ọdún méje mìíràn tí ìyàn yóò mú ń bọ̀, nígbà náà ni a ó tilẹ̀ gbàgbé gbogbo ọ̀pọ̀ ní ilẹ̀ Ejibiti, ìyàn yóò sì run gbogbo ilẹ̀ náà.
31 Bũthi wa bũrũri ndũkaririkanwo, tondũ ngʼaragu ĩrĩa ĩgacooka kũgĩa nĩĩgakorwo ĩrĩ nene mũno.
A kò ní rántí àsìkò ọ̀pọ̀ oúnjẹ yanturu náà mọ́ nítorí pé ìyàn tí yóò tẹ̀lé e yóò pọ̀ púpọ̀.
32 Gĩtũmi kĩa Firaũni aheo kĩroto kĩu maita meerĩ, nĩ tondũ Ngai nĩatuĩte nĩegwĩka ũndũ ũcio, na ekũwĩka o narua.
Ìdí tí Ọlọ́run fi fi àlá náà han fún Farao ní ọ̀nà méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni pé, Ọlọ́run ti pinnu pé yóò ṣẹlẹ̀ bẹ́ẹ̀ dandan, àti pé kò ni pẹ́ tí Ọlọ́run yóò fi ṣe é.
33 “Rĩu Firaũni nĩacarie mũndũ ũũĩ gũkũũrana maũndũ na mũndũ mũũgĩ, amũtue mũrũgamĩrĩri wa bũrũri wa Misiri.
“Ìmọ̀ràn mi ni wí pé, jẹ́ kí Farao wá ọlọ́gbọ́n ènìyàn kan ní ilẹ̀ Ejibiti, kí ó sì fi ṣe alákòóso iṣẹ́ àgbẹ̀ ilẹ̀ Ejibiti.
34 O na ningĩ Firaũni nĩagĩthuure atabarĩri a bũrũri a kuoyaga gĩcunjĩ gĩa ithano kĩa magetha ma Misiri mĩaka-inĩ ĩyo mũgwanja ya bũthi.
Kí Farao sì yan àwọn alábojútó láti máa gba ìdámárùn-ún ìkórè oko ilẹ̀ Ejibiti ní àsìkò ọdún méje ọ̀pọ̀.
35 Nao nĩmacookanĩrĩrie irio icio ciothe cia mĩaka ĩyo mĩega ĩrooka, na ngano ĩyo ĩkorwo watho-inĩ wa Firaũni, ĩigwo matũũra-inĩ ĩrĩ irio.
Kí wọn kó gbogbo oúnjẹ ilẹ̀ náà ni àwọn ọdún méje ọ̀pọ̀ yìí, kí wọn sì kó àwọn ọkà tí wọn jẹ ṣẹ́kù pamọ́ lábẹ́ àṣẹ Farao. Kí a kó wọn pamọ́ ni àwọn ìlú fún jíjẹ.
36 Nacio irio icio ciagĩrĩire kũigwo irĩ mũthiithũ wa bũrũri, ikaahũthĩrwo hĩndĩ ĩrĩa ya mĩaka mũgwanja ya ngʼaragu ĩrĩa ĩkaagĩa Misiri, nĩgeetha bũrũri ndũkanathũkio nĩ ngʼaragu ĩyo.”
Kí wọn kó oúnjẹ náà pamọ́ fún orílẹ̀-èdè yìí, kí a ba à le lò ó ni ọdún méje tí ìyàn yóò fi jà ní ilẹ̀ Ejibiti, kí ìyàn náà má ba à pa orílẹ̀-èdè yìí run.”
37 Firaũni na anene ake makĩona mũbango ũcio ũrĩ mwega.
Èrò náà sì dára lójú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀.
38 Nĩ ũndũ ũcio Firaũni akĩmooria atĩrĩ, “No tuone mũndũ ũngĩ ta ũyũ, mũndũ ũrĩ na roho wa Ngai thĩinĩ wake?”
Farao sì bi wọ́n pé, “Ǹjẹ́ a le rí ẹnikẹ́ni bi ọkùnrin yìí, nínú ẹni tí ẹ̀mí Ọlọ́run ń gbé?”
39 Firaũni agĩkĩĩra Jusufu atĩrĩ, “Kuona atĩ Ngai nĩakũmenyithĩtie maũndũ maya mothe-rĩ, gũtirĩ mũndũ ũngĩ ũngĩkũũrana maũndũ na mũũgĩ ta we.
Nígbà náà ni Farao wí fún Josẹfu, “Níwọ́n bí Ọlọ́run ti fi gbogbo èyí hàn ọ́, kò sí ẹni náà tí ó gbọ́n tí ó sì mọ̀ràn bí i tìrẹ ní ilẹ̀ Ejibiti yìí,
40 Wee nĩwe ũkũrũgamĩrĩra nyũmba yakwa ya ũthamaki, na andũ akwa othe marĩathĩkagĩra watho waku. Ũndũ ngũgũkĩra naguo no atĩrĩ, niĩ nĩ niĩ Mũthamaki.”
ìwọ yóò ṣe àkóso ààfin mi gbogbo àwọn ènìyàn gbọdọ̀ tẹríba fún àṣẹ ẹ̀ rẹ. Ìtẹ́ mi nìkan ni èmi yóò fi jù ọ́ lọ.”
41 Nĩ ũndũ ũcio Firaũni akĩĩra Jusufu atĩrĩ, “Kuuma rĩu nĩndagũtua mũrũgamĩrĩri wa bũrũri wothe wa Misiri.”
Farao wí fún Josẹfu pé, “Mo fi ọ́ ṣe alábojútó gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.”
42 Ningĩ Firaũni akĩruta gĩcũhĩ gĩake kĩa mũhũũri kuuma kĩara gĩake agĩgĩĩkĩra kĩara-inĩ kĩa Jusufu. Agĩcooka akĩmũhumba nguo cia gatani njega, na kĩrengeeri gĩa thahabu ngingo.
Farao sì bọ́ òrùka èdìdì ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi wọ Josẹfu ó wọ̀ ọ́ ní aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára, ó sì fi ẹ̀gbà tí ó dára sí i lọ́rùn.
43 Ningĩ agĩtũma akuuo na ngaari yake ya ita, arĩ mũndũ wa keerĩ harĩ we wathani-inĩ, nao andũ magĩthiĩ makĩanagĩrĩra marĩ mbere yake atĩrĩ, “Eherai njĩra-inĩ!” Nĩ ũndũ ũcio Firaũni agĩtua Jusufu mũrũgamĩrĩri wa bũrũri wothe wa Misiri.
Ó sì mú un kí ó gun kẹ̀kẹ́-ẹṣin bí igbákejì ara rẹ̀, àwọn ènìyàn sì ń pariwo níwájú rẹ̀ pé, “Ẹ yàgò lọ́nà.” Báyìí ni ó sì fi ṣe alábojútó gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
44 Ningĩ Firaũni akĩĩra Jusufu atĩrĩ, “Nĩ niĩ Firaũni, no rĩrĩ, hatarĩ na rũtha rwaku, gũtirĩ mũndũ ũgeeka ũndũ atarĩ na rũtha rwaku gũkũ Misiri guothe.”
Nígbà náà ni Farao wí fún Josẹfu pé, “Èmi ni Farao. Ṣùgbọ́n láìsí àṣẹ rẹ, ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ ṣe ohunkóhun ní ilẹ̀ Ejibiti.”
45 Nake Firaũni agĩĩta Jusufu Zafenathu-Panea, na akĩmũhe Asenathu mwarĩ wa Potifera, mũthĩnjĩri-ngai wa Onu, atuĩke mũtumia wake. Nake Jusufu agĩtuĩkania bũrũri wothe wa Misiri.
Farao sì sọ Josẹfu ní orúkọ yìí Safenati-Panea (èyí tí ó túmọ̀ sí ẹni tí ó ni agbára ikú àti ìyè ní ìkáwọ́ bí òrìṣà). Ó sì fun un ní Asenati ọmọ Potifẹra, alábojútó òrìṣà Oni, gẹ́gẹ́ bí aya. Josẹfu sì rin gbogbo ilẹ̀ Ejibiti já.
46 Jusufu aarĩ na mĩaka mĩrongo ĩtatũ rĩrĩa atoonyire ũtungata-inĩ wa Firaũni mũthamaki wa Misiri. Nake Jusufu akĩehera mbere ya Firaũni, agĩtuĩkania bũrũri wothe wa Misiri.
Ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni Josẹfu nígbà tí ó wọ iṣẹ́ Farao ọba Ejibiti. Josẹfu sì jáde kúrò níwájú Farao, ó sì ṣe ìbẹ̀wò káàkiri gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
47 Na rĩrĩ, ihinda rĩa mĩaka ĩyo mũgwanja ya bũthi, bũrũri ũcio ũgĩciara maciaro maingĩ mũno.
Ní ọdún méje ọ̀pọ̀, ilẹ̀ náà so èso lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
48 Nake Jusufu agĩcookanĩrĩria irio ciothe cia bũrũri wa Misiri iria ciagĩire kuo mĩaka ĩyo mũgwanja ya bũthi, na agĩciigithia matũũra-inĩ marĩa manene. O itũũra inene akaiga irio iria ciakũragio mĩgũnda-inĩ ĩrĩa yarĩthiũrũrũkĩirie.
Josẹfu kó gbogbo oúnjẹ tí a pèsè ni ilẹ̀ Ejibiti ní ọdún méje ọ̀pọ̀ yìí, ó sì pa wọ́n mọ́ sí àwọn ìlú. Ní ìlú kọ̀ọ̀kan ni ó kó gbogbo oúnjẹ tí wọ́n gbìn ní àyíká ìlú wọn sí.
49 Jusufu agĩkĩigithia ngano nyingĩ mũno, o ta mũthanga wa iria-inĩ; yarĩ nyingĩ mũno, o nginya agĩtiga kũiga maandĩko ma mũigana wayo tondũ ndĩngĩathimĩkire.
Josẹfu pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkà mọ́ bí iyanrìn Òkun; ó pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́ tí kò ṣe àkọsílẹ̀ mọ́ nítorí, ó tayọ kíkà.
50 Mĩaka ya ngʼaragu ĩtaanakinya-rĩ, Jusufu nĩaciarĩirwo tũhĩĩ twĩrĩ nĩ Asenathu mwarĩ wa Potifera, mũthĩnjĩri-ngai wa Onu.
Kí ó tó di pé ọdún ìyàn dé, Asenati ọmọ Potifẹra alábojútó Oni bí ọmọkùnrin méjì fún Josẹfu.
51 Jusufu agĩĩta irigithathi rĩake Manase, akiuga atĩrĩ, “Nĩ tondũ Ngai nĩatũmĩte ndiganĩrwo nĩ thĩĩna wakwa wothe na nyũmba ya baba yothe.”
Josẹfu sọ orúkọ àkọ́bí rẹ̀ ni Manase, ó sì wí pé, “Nítorí tí Ọlọ́run ti mú mi gbàgbé gbogbo ìdààmú mi àti gbogbo ilé baba mi.”
52 Nako kahĩĩ ga keerĩ, agĩgeeta Efiraimu, akiuga atĩrĩ, “Nĩ tondũ Ngai nĩatũmĩte ngĩe na maciaro bũrũri-inĩ wa mĩnyamaro yakwa.”
Ó sì sọ orúkọ èkejì ní Efraimu, ó sì wí pé, “Nítorí pé Ọlọ́run fún mi ní ọmọ ní ilẹ̀ ìpọ́njú mi.”
53 Nayo mĩaka mũgwanja ya bũthi kũu Misiri ĩgĩthira,
Ọdún méje ọ̀pọ̀ oúnjẹ sì wá sí òpin ní ilẹ̀ Ejibiti,
54 na mĩaka mũgwanja ya ngʼaragu ĩkĩambĩrĩria, o ta ũrĩa Jusufu oigĩte. Kwarĩ na ngʼaragu mabũrũri-inĩ marĩa mangĩ mothe, no bũrũri wa Misiri wothe warĩ na irio.
ọdún méje ìyàn sì bẹ̀rẹ̀, bí Josẹfu ti wí gan an. Ìyàn sì mú ní gbogbo ilẹ̀ tókù, ṣùgbọ́n oúnjẹ wà ní gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
55 Na rĩrĩa andũ a Misiri othe maambĩrĩirie kũigua ngʼaragu-rĩ, magĩkaĩra Firaũni amahe irio. Nake Firaũni akĩmeera atĩrĩ, “Thiĩi kũrĩ Jusufu na mwĩke ũrĩa ekũmwĩra.”
Nígbà tí àwọn ará Ejibiti bẹ̀rẹ̀ sí ní rí ipá ìyàn náà, wọ́n kígbe sí Farao. Nígbà náà ni Farao wí fún wọn pé, “Ẹ lọ bá Josẹfu, ẹ ṣe ohun tí ó bá wí fún un yín.”
56 Rĩrĩa ngʼaragu yagĩire bũrũri wothe-rĩ, Jusufu akĩhingũra makũmbĩ ma irio, akĩenderia andũ a Misiri ngano, nĩgũkorwo ngʼaragu yarĩ nene mũno Misiri guothe.
Nígbà tí ìyàn sì ti tàn ká gbogbo ilẹ̀ náà, Josẹfu ṣí inú àká, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ta ọkà fún àwọn ènìyàn, nítorí ìyàn náà mú gan an ní gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
57 Namo mabũrũri mothe magĩũka Misiri kũrĩ Jusufu kũgũra ngano, tondũ ngʼaragu ĩyo yarĩ nene mũno thĩ yothe.
Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè sì ń wá sí Ejibiti láti ra oúnjẹ lọ́wọ́ Josẹfu, nítorí ìyàn náà pọ̀ gidigidi káàkiri gbogbo ayé.

< Kĩambĩrĩria 41 >