< Kĩambĩrĩria 32 >

1 Jakubu nĩathiire na mbere na rũgendo rwake, na agĩtũngwo nĩ araika a Ngai.
Jakọbu sì ń bá ọ̀nà tirẹ̀ lọ, àwọn angẹli Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀.
2 Na rĩrĩa Jakubu aamoonire, akiuga atĩrĩ, “Ĩno nĩ mbũtũ ya Ngai!” Nĩ ũndũ ũcio agĩĩta handũ hau Mahanaimu.
Nígbà tí Jakọbu rí wọn, ó wí pé, “Àgọ́ Ọlọ́run ni èyí!” Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ni Mahanaimu.
3 Ningĩ Jakubu agĩtũma andũ mathiĩ mbere yake kũrĩ mũrũ wa nyina Esaũ kũu Seiru, bũrũri-inĩ wa Edomu.
Jakọbu sì rán àwọn oníṣẹ́ ṣáájú ara rẹ̀ sí Esau arákùnrin rẹ̀ ni ilẹ̀ Seiri ní orílẹ̀-èdè Edomu.
4 Akĩmataara, akĩmeera atĩrĩ, “Ũũ nĩguo mũgũthiĩ kwĩra mwathi wakwa Esaũ: ‘Ndungata yaku Jakubu ĩkuuga atĩrĩ, ndĩraikaraga na Labani, na ngoretwo kuo nginya rĩu.
Ó pàṣẹ fún wọn pé, “Èyí ni ẹ̀yin yóò wí fún Esau olúwa mi, Jakọbu ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, ‘Mo ti ṣe àtìpó lọ́dọ̀ Labani títí ó fi di àsìkò yìí.
5 Ndĩ na ngʼombe na ndigiri, na ngʼondu na mbũri, ndungata cia arũme na cia andũ-a-nja. Na rĩu ndagũtũmĩra ndũmĩrĩri, we mwathi wakwa, nĩgeetha njĩtĩkĩrĩke maitho-inĩ maku.’”
Mo ní màlúù, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn àti ewúrẹ́. Mo tún ni àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin. Mo ń ránṣẹ́ yìí sí olúwa mi kí èmi le è rí ojúrere rẹ.’”
6 Rĩrĩa atũmwo maacookire kũrĩ Jakubu makĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩtũrathiire kũrĩ mũrũ wa nyũkwa Esaũ, na rĩu nĩarooka gũgũtũnga, na arĩ na andũ magana mana.”
Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ náà padà tọ Jakọbu wà, wọ́n wí pé “Esau arákùnrin rẹ ti múra láti wá pàdé rẹ pẹ̀lú irinwó ọkùnrin.”
7 Jakubu akĩmaka mũno na akĩnyamarĩka, akĩgayania andũ arĩa aarĩ nao ikundi igĩrĩ, o na ndũũru cia mbũri na ndũũru cia ngʼombe o na ngamĩĩra nacio.
Pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìbànújẹ́ ni Jakọbu fi pín àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sí ìpín méjì, ó sì pín àwọn ẹran ọ̀sìn, agbo ẹran àti ìbákasẹ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.
8 Agĩĩciiria atĩrĩ, “Esaũ angĩũka atharĩkĩre gĩkundi kĩmwe-rĩ, gĩkundi kĩu kĩngĩ no kĩũre.”
Nítorí ó rò ó nínú rẹ̀ pé, “Bí Esau bá kọjú ogun sí ìpín kan, ìpín kejì yóò sá àsálà.”
9 Ningĩ Jakubu akĩhooya, akiuga atĩrĩ, “Wee Ngai wa baba Iburahĩmu, o Wee Ngai wa baba Isaaka, Wee Jehova ũrĩa wanjĩĩrire atĩrĩ, ‘Cooka bũrũri waku na wa andũ anyu, na nĩngatũma ũgaacĩre,’
Nígbà náà ni Jakọbu gbàdúrà pe, “Ọlọ́run Abrahamu baba mi, àti Ọlọ́run Isaaki baba mi, Olúwa tí ó wí fún mi pé, ‘Padà sí orílẹ̀-èdè rẹ àti sọ́dọ̀ àwọn ìbátan rẹ, èmi yóò sì ṣe ọ́ ní rere,’
10 ndirĩ mwagĩrĩru wa kuonio ũtugi ũyũ wothe na wĩhokeku ũrĩa ũnyonetie niĩ ndungata yaku. Ngĩringa Jorodani-rĩ, ndaarĩ o na rũthanju rwakwa rwiki, no rĩu nduĩkĩte ikundi igĩrĩ.
èmi kò tilẹ̀ yẹ fún àánú àti òtítọ́ tí o ń fihàn fún ìránṣẹ́ rẹ. Nítorí pé, kìkì ọ̀pá mi ni mo mu kúrò ni ilé kọjá Jordani yìí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, èmi ti di ẹgbẹ́ méjì.
11 Ndagũthaitha honokia kuuma moko-inĩ ma mũrũ wa maitũ Esaũ, nĩgũkorwo nĩndĩretigĩra ndagoke gũũtharĩkĩra, niĩ hamwe na ciana ici, na manyina maacio.
Jọ̀wọ́ Olúwa gbà mí lọ́wọ́ Esau arákùnrin mi, nítorí ẹ̀rù ń bà mí pé yóò wá dojú ìjà kọ mí àti àwọn ìyàwó pẹ̀lú àwọn ọmọ mi.
12 No nĩ uugĩte atĩrĩ, ‘Ti-itherũ nĩngatũma ũgaacĩre na ndũme njiaro ciaku cingĩhe ta mũthanga wa iria-inĩ, ũrĩa ũtangĩtarĩka.’”
Ṣùgbọ́n ìwọ ti ṣèlérí pé, ‘Èmi yóò mú ọ gbilẹ̀, èmi yóò sì mú kí àwọn ìran rẹ dà bì í yanrìn òkun tí ẹnikẹ́ni kò le è kà.’”
13 Akĩraara hau ũtukũ ũcio, na kuuma kũrĩ kĩrĩa aarĩ nakĩo, agĩthuurĩra mũrũ wa nyina Esaũ kĩheo gĩkĩ;
Ó sì lo òru ọjọ́ náà níbẹ̀. Ó mú ẹ̀bùn fún Esau arákùnrin rẹ̀ nínú ohun ìní rẹ̀.
14 mbũri magana meerĩ cia mĩgoma na thenge mĩrongo ĩĩrĩ, ngʼondu magana meerĩ na ndũrũme mĩrongo ĩĩrĩ,
Igba ewúrẹ́, ogún òbúkọ, igba àgùntàn, ogún àgbò,
15 ngamĩĩra mĩrongo ĩtatũ cia mĩgoma na njaũ ciacio, ngʼombe mĩrongo ĩna na ndegwa ikũmi, na ndigiri mĩrongo ĩĩrĩ cia mĩgoma na ikũmi cia njamba.
ọgbọ̀n abo ìbákasẹ pẹ̀lú ọmọ wọn, ogójì abo màlúù àti akọ màlúù mẹ́wàá, ogún abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá.
16 Agĩcinengera ndungata ciake, o rũũru mwanya, na akĩĩra ndungata icio ciake atĩrĩ, “Thiiagai mbere yakwa, na mũtigithũkanie rũũru na rũũru rũrĩa rũngĩ.”
Ó sì fi wọ́n lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ṣáájú mi, kí ẹ sì jẹ́ kí àlàfo wà láàrín ọ̀wọ́ agbo ẹran kọ̀ọ̀kan sí èkejì.”
17 Ningĩ agĩtaara ũrĩa wamatongoretie, akĩmwĩra atĩrĩ, “Rĩrĩa mũrũ wa maitũ Esaũ arĩgũtũnga na akũũrie atĩrĩ, ‘Wee ũrĩ waũ? Na wathiĩ kũ? Na ũhiũ ũyũ wothe ũrĩ mbere yaku nĩ waũ?’
Ó pàṣẹ fún èyí tí ó ṣáájú pé, “Nígbà tí arákùnrin mi Esau bá pàdé rẹ tí ó sì béèrè ẹni tí ìwọ í ṣe àti ibi tí ìwọ ń lọ àti ẹni tí ó ni agbo ẹran tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ,
18 Nawe nĩũrĩmũcookeria ũmwĩre atĩrĩ, ‘Nĩ cia ndungata yaku Jakubu. Nĩ kĩheo gĩa kũhe mwathi wakwa Esaũ, na Jakubu arĩ thuutha witũ agĩũka.’”
nígbà náà ni ìwọ yóò wí pé, ‘Ti ìránṣẹ́ rẹ Jakọbu ni wọ́n. Ẹ̀bùn ni ó sì fi wọ́n ṣe fún Esau olúwa mi, òun pàápàá ń bọ̀ lẹ́yìn wa.’”
19 Agĩcooka agĩtaara wa keerĩ na wa gatatũ, na arĩa othe marũmagĩrĩra ndũũru icio, akĩmeera atĩrĩ, “Ũguo nĩguo mũrĩĩraga Esaũ mwamũtũnga.
Jakọbu sì pàṣẹ bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ fún ọ̀wọ́ kejì àti ẹ̀kẹta àti àwọn tókù tí ó tẹ̀lé agbo ẹran pé, “Ohun kan ṣoṣo yìí náà ni kí ẹ sọ fún Esau nígbà tí ẹ bá pàdé rẹ̀.
20 Na mũtikanaage kũmwĩra atĩrĩ, ‘Jakubu ndungata yaku arĩ thuutha witũ agĩũka.’” Tondũ eeciiririe atĩrĩ, “Ngũmũhooreria na iheo ici ngũtũma mbere yakwa; thuutha-inĩ ndamuona-rĩ, hihi ahota kũnyamũkĩra.”
Kí ẹ rí i dájú wí pé, ẹ sọ fún un pé, ‘Jakọbu ìránṣẹ́ rẹ̀ ń bọ̀ lẹ́yìn wa.’” Èrò Jakọbu ni láti fi àwọn ẹ̀bùn wọ̀nyí tu Esau lójú pé bóyá inú Esau yóò dùn sí òun nígbà tí àwọn bá pàdé.
21 Nĩ ũndũ ũcio iheo icio Jakubu aaheanĩte igĩthiiaga mbere yake, nowe akĩraara kũu kambĩ ũtukũ ũcio.
Nítorí náà ẹ̀bùn Jakọbu ṣáájú rẹ̀ lọ, Jakọbu pàápàá sì lo òru ọjọ́ náà nínú àgọ́.
22 Na ũtukũ o ro ũcio, Jakubu agĩũkĩra, akĩoya atumia ake eerĩ, na ndungata iria igĩrĩ cia andũ-a-nja, na ariũ ake ikũmi na ũmwe, na akĩmaringĩria iringĩro rĩa Jaboku.
Ó sì dìde ní òru ọjọ́ náà, ó mú àwọn aya rẹ̀ méjèèjì, àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ méjèèjì, àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mọ́kọ̀ọ̀kànlá, wọ́n sì kọjá ní ìwọdò Jabbok.
23 Aarĩkia kũmaringia, akĩringia indo iria ciothe aarĩ nacio.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti rán wọn kọjá odò tán sí òkè odò, ó sì rán àwọn ohun ìní rẹ̀ kọjá pẹ̀lú.
24 Nake Jakubu agĩtigwo arĩ o wiki, na hagĩũka mũndũ maagianire nake o nginya gũgĩthererũka.
Ó sì ku Jakọbu nìkan, ọkùnrin kan sì bá a ja ìjàkadì títí ó fi di àfẹ̀mọ́júmọ́.
25 Na rĩrĩa mũndũ ũcio onire atĩ ndangĩmũhoota-rĩ, akĩmũhutia ihĩndĩ rĩa gĩtina gĩa kũgũrũ, nakuo kũgũrũ kwa Jakubu gũgĩthenyũkĩra hau gĩtina-inĩ, o makĩgianaga na mũndũ ũcio.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkùnrin náà rí i pé òun kò le borí Jakọbu, ó fọwọ́ kàn án ní ọ̀ọ́kán ibi tí eegun itan ti bẹ̀rẹ̀, egungun náà sì yẹ̀ kúrò lórí ike, bí ó ti ń ja ìjàkadì.
26 Na mũndũ ũcio akĩmwĩra atĩrĩ, “Reke ndĩthiĩre tondũ nĩ gwathererũka.” No Jakubu akĩmũcookeria, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndingĩreka ũthiĩ ũtandathimĩte.”
Nígbà náà ni ọkùnrin náà wí fún un pé, “Jẹ́ kí ń máa lọ, nítorí ojúmọ́ ti mọ́.” Ṣùgbọ́n Jakọbu dá a lóhùn pé, “Èmi kò ní jẹ́ kí o lọ, àyàfi bí o bá súre fún mi.”
27 Nake mũndũ ũcio akĩmũũria atĩrĩ, “Wĩtagwo atĩa?” Jakubu akĩmũcookeria atĩrĩ, “Njĩtagwo Jakubu.”
Ọkùnrin náà béèrè orúkọ rẹ̀. Ó sì wí fún un pé, “Jakọbu ni òun ń jẹ́.”
28 Ningĩ mũndũ ũcio akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndũgũcooka gwĩtwo Jakubu, no ũrĩĩtagwo Isiraeli, tondũ nĩũgianĩte na Ngai o na andũ, na ũkahootana.”
Nígbà náà ni ọkùnrin náà wí pé, “Orúkọ rẹ kì yóò jẹ́ Jakọbu mọ́ bí kò ṣe Israẹli, nítorí pé ìwọ ti bá Ọlọ́run àti ènìyàn jà, o sì borí.”
29 Jakubu akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndagũthaitha, njĩĩra rĩĩtwa rĩaku.” Nowe akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ũranjũũria rĩĩtwa rĩakwa nĩkĩ?” Agĩcooka akĩmũrathima marĩ o hau.
Jakọbu sì bẹ ọkùnrin náà pé, “Sọ orúkọ rẹ fún mi.” Ṣùgbọ́n ọkùnrin náà sá à dáhùn pé, “Èéṣe tí o ń béèrè orúkọ mi?” Lẹ́yìn náà ó súre fún Jakọbu níbẹ̀.
30 Nĩ ũndũ ũcio Jakubu agĩĩta handũ hau Penieli, akiuga atĩrĩ, “Tondũ nĩnyonete Ngai ũthiũ kwa ũthiũ, na akahonokia muoyo wakwa.”
Jakọbu sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Penieli pé, “Mo rí Ọlọ́run ní ojúkojú, síbẹ̀ a dá ẹ̀mí mi sí.”
31 Narĩo riũa rĩkĩmũrathĩra akĩhĩtũka hau Penieli, na nĩathuaga nĩ ũndũ nĩathenyũkĩtwo nĩ ihĩndĩ rĩa gĩtina gĩa kũgũrũ.
Bí ó sì ti ń kọjá Penieli, oòrùn ràn bá a, ó sì ń tiro nítorí itan rẹ̀.
32 Nĩ tondũ ũcio, nginyagia ũmũthĩ ũyũ andũ a Isiraeli matirĩĩaga mũkiha ũrĩa ũnyiitanĩte na ihĩndĩ rĩa gĩtina gĩa kũgũrũ, tondũ ihĩndĩ rĩa gĩtina gĩa kũgũrũ kwa Jakubu rĩahutĩirio hakuhĩ na mũkiha ũcio.
Ìdí nìyí tí àwọn ọmọ Israẹli kì í fi í jẹ iṣan tí ó wà ní ọ̀ọ́kán ibi tí eegun itan ti bẹ̀rẹ̀ títí di òní olónìí, nítorí níbi iṣan náà ni a ti fọwọ́ kan ibi tí egungun itan Jakọbu ti bẹ̀rẹ̀.

< Kĩambĩrĩria 32 >