< Kĩambĩrĩria 27 >

1 Rĩrĩa Isaaka aakũrire na maitho make makĩaga hinya ũndũ atangĩahotire kuona-rĩ, agĩtũmanĩra Esaũ mũriũ wake ũrĩa mũkũrũ, akĩmwĩra atĩrĩ, “Mũrũ wakwa.” Nake Esaũ akĩmũcookeria atĩrĩ, “Niĩ ũyũ haha.”
Nígbà ti Isaaki di arúgbó, ojú rẹ̀ sì ti di bàìbàì tó bẹ́ẹ̀ tí kò le ríran. Ó pe Esau àkọ́bí rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Ọmọ mi.” Esau sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
2 Isaaka akĩmwĩra atĩrĩ, “Rĩu niĩ ndĩ mũkũrũ na ndiũĩ mũthenya ũrĩa ingĩkua.
Isaaki sì wí pé, “Nísinsin yìí mo di arúgbó, èmi kò sì mọ ọjọ́ tí èmi yóò kú.
3 Rĩu-rĩ, oya indo ciaku cia ũguĩmi; ũta na mĩguĩ yaku, na uumagare ũthiĩ werũ-inĩ ũkanguĩmĩre nyamũ cia gĩthaka.
Nítorí náà, mú ohun èlò ọdẹ rẹ, apó àti ọrún, nísinsin yìí kí o sì lọ pa ẹran wá fún mi nínú igbó.
4 Thondekera irio njega iria nyendete na ũndehere ndĩe, nĩgeetha ngũrathime na kĩrathimo gĩakwa itanakua.”
Kí o sì ṣe ẹran àdídùn fún mi, irú èyí tí mo fẹ́ràn, kí o gbe wá fún mi kí n jẹ, kí n sì súre fún ọ kí n tó kú.”
5 Na rĩrĩ, Rebeka agĩkorwo nĩathikĩrĩirie Isaaka akĩhe mũriũ Esaũ ũhoro ũcio. Na rĩrĩa Esaũ aathiire werũ-inĩ kũguĩma nyamũ nĩguo amĩinũkie-rĩ,
Ṣùgbọ́n Rebeka ń fetí léko gbọ́ nígbà tí Isaaki ń bá Esau ọmọ rẹ̀ sọ̀rọ̀. Nítorí náà, nígbà ti Esau ti ṣe ọdẹ lọ sínú igbó,
6 Rebeka akĩĩra mũriũ Jakubu atĩrĩ, “Nĩ ndaigua thoguo akĩĩra Esaũ mũrũ wa nyũkwa atĩrĩ,
Rebeka sọ fún Jakọbu ọmọ rẹ̀ pé, “Wò ó, mo gbọ́ tí baba rẹ ń wí fún Esau ẹ̀gbọ́n rẹ pé,
7 ‘Ndehere nyamũ ya kũguĩma na ũthondekere irio njega ndĩe, nĩgeetha ngũrathime na kĩrathimo gĩakwa ndĩ mbere ya Jehova itanakua.’
‘Pa ẹran fún mi wá, kí o sì ṣe oúnjẹ àdídùn fún mi láti jẹ, kí n ba à le súre fún ọ níwájú Olúwa kí èmi tó kú.’
8 Rĩu, wee mũrũ wakwa-rĩ, thikĩrĩria wega na wĩke ũrĩa ngũkwĩra:
Nísinsin yìí ọmọ mi, gbọ́ tèmi, kí o sì ṣe ohun tí èmi yóò wí fún ọ.
9 Thiĩ rũũru-inĩ rwa mbũri ũndehere tũũri twĩrĩ twa mbũri tũrĩa twega biũ, nĩguo thondekere thoguo irio njega, o ta ũrĩa endaga ithondekwo.
Lọ sínú agbo ẹran, kí o sì mú ọmọ ewúrẹ́ méjì, kí ó lè ṣe oúnjẹ àdídùn fún baba rẹ, irú èyí tí ó fẹ́ràn dáradára.
10 Ũcooke ũcioe ũcitwarĩre thoguo arĩe nĩgeetha akũrathime na kĩrathimo gĩake atanakua.”
Ìwọ yóò sì gbé e tọ baba rẹ lọ, kí òun ba à lè jẹ ẹ́, kí ó sì súre fún ọ, kí ó tó kú.”
11 No Jakubu akĩĩra nyina Rebeka atĩrĩ, “Esaũ mũrũ wa maitũ nĩ wa mwĩrĩ ũrĩ guoya, na mwĩrĩ wakwa ndũrĩ guoya.
Jakọbu sì wí fún Rebeka ìyá rẹ̀ pé, “Ṣùgbọ́n Esau ẹ̀gbọ́n mi jẹ́ ènìyàn onírun lára, bẹ́ẹ̀ alára ọ̀bọ̀rọ́ sì ni èmi,
12 Ĩĩ baba angĩĩhaambata? Ingĩonekana ngĩmũheenia na niĩ ndĩĩreherere kĩrumi handũ ha kĩrathimo.”
bí baba mi bá fọwọ́ kàn mi ń kọ́? Èmi yóò jọ ẹlẹ́tàn lójú rẹ̀, dípò kí ó súre fún mi, èmi yóò sì mú ègún wá sórí ara mi.”
13 Nyina akĩmwĩra atĩrĩ, “Mũrũ wakwa, reke kĩrumi kĩu kĩnjookerere, wee ĩka o ũrĩa ndĩrakwĩra; thiĩ ũndehere tũũri tũu.”
Ìyá rẹ̀ wá wí fun un pé, “Ọmọ mi jẹ́ kí ègún náà wá sórí mi, sá à ṣe ohun tí mo wí, kí o sì mú wọn wá fún mi.”
14 Nĩ ũndũ ũcio Jakubu agĩthiĩ, akĩgĩĩra tũũri, na agĩtũrehere nyina, nake agĩthondeka irio njega o ta iria ithe eendete.
Jakọbu sì ṣe ohun gbogbo tí ìyá rẹ̀ wí fun un, Rebeka sì ṣe oúnjẹ àdídùn náà, irú èyí tí Isaaki fẹ́ràn.
15 Ningĩ Rebeka akĩoya nguo iria ciarĩ njega cia Esaũ mũriũ wake ũrĩa mũkũrũ iria aarĩ nacio nyũmba agĩcihumba Jakubu mũriũ wake ũrĩa mũnini.
Nígbà náà ni Rebeka mú èyí tí ó dára jù nínú aṣọ Esau ọmọ rẹ̀ àgbà tí ó wà nínú ilé Rebeka, ó sì fi wọ Jakọbu ọmọ rẹ̀ àbúrò.
16 Agĩcooka akĩhumbĩra moko make na ngingo kũrĩa gũtaarĩ guoya na njũũa cia tũũri tũu.
Ó sì fi awọ ewúrẹ́ wọ̀n-ọn-nì bo ọwọ́ àti ibi tí ọ̀bọ̀rọ́ ọrùn.
17 Agĩcooka akĩnengera Jakubu mũriũ wake irio icio ciarĩ njega na mũgate ũrĩa aathondekete.
Nígbà náà ni ó gbé ẹran dídùn náà àti oúnjẹ tí ó ti sè lé Jakọbu ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́.
18 Nake Jakubu agĩthiĩ kũrĩ ithe, akiuga atĩrĩ, “Baba.” Nake Isaaka agĩcookia atĩrĩ, “Niĩ ũyũ, mũrũ wakwa; wee nĩwe ũ?”
Jakọbu wọlé lọ sí ọ̀dọ̀ baba rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi.” Baba rẹ sì dáhùn pé, “Èmi nìyí, ìwọ ta ni, ọmọ mi?”
19 Jakubu akĩĩra ithe atĩrĩ, “Nĩ niĩ Esaũ mũriũ waku wa irigithathi. Njĩkĩte o ta ũrĩa ũnjĩĩrire. Ndagũthaitha wĩtiire ũrĩe nyama imwe cia ũguĩmi wakwa nĩgeetha ũndathime na kĩrathimo gĩaku.”
Jakọbu sì fèsì pé, “Èmi ni Esau àkọ́bí rẹ, èmi ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ fún mi, jọ̀wọ́ dìde jókòó, kí o sì jẹ nínú ẹran igbó mi tí mo ti sè, kí o ba à le súre fún mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.”
20 Nake Isaaka akĩũria mũriũ atĩrĩ, “Mũrũ wakwa, kaĩ waciona narua atĩa?” Nake akĩmũcookeria atĩrĩ, “Nĩ tondũ Jehova Ngai waku nĩaheire ũhootani.”
Isaaki tún béèrè pé, “Ọmọ mi, báwo ni ó ṣe tètè yá ọ bẹ́ẹ̀?” Jakọbu sì tún dáhùn pé, “Olúwa Ọlọ́run rẹ ló fún mi pa.”
21 Ningĩ Isaaka akĩĩra Jakubu atĩrĩ, “Ta ũka hakuhĩ mũrũ wakwa, nĩguo ngũhambate menye kana ti-itherũ nĩwe Esaũ mũrũ wakwa kana tiguo.”
Nígbà náà ni Isaaki wí fún Jakọbu pé, “Súnmọ́ mi, kí n le è fọwọ́ kàn ọ́, kí n lè mọ̀ bóyá Esau ọmọ mi ni nítòótọ́ tàbí òun kọ́.”
22 Nĩ ũndũ ũcio Jakubu agĩkuhĩrĩria ithe Isaaka, nake akĩmũhambata, akiuga atĩrĩ, “Mũgambo nĩ wa Jakubu, no moko nĩ ma Esaũ.”
Jakọbu sì súnmọ́ Isaaki baba rẹ̀. Isaaki sì fọwọ́ kàn án, ó sì wí pé, “Ohùn ni ohùn Jakọbu; ṣùgbọ́n ọwọ́ ni ọwọ́ Esau.”
23 Na ndaigana kũmũkũũrana tondũ moko make maarĩ na guoya ta ma mũrũ wa nyina Esaũ; nĩ ũndũ ũcio akĩmũrathima.
Kò sì dá Jakọbu mọ̀ nítorí ọwọ́ rẹ̀ ní irun bí i ti Esau arákùnrin rẹ, nítorí náà, ó súre fún un
24 O rĩngĩ akĩmũũria atĩrĩ, “Ti-itherũ nĩwe mũrũ wakwa Esaũ?” Nake agĩcookia atĩrĩ, “Ĩĩ nĩ niĩ.”
ó sì bi í léèrè pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni Esau ọmọ mi ni tòótọ́?” Jakọbu sì dáhùn pé, “Èmi ni.”
25 Agĩcooka akĩmwĩra atĩrĩ, “Mũrũ wakwa ndehere nyama imwe cia ũguĩmi waku ndĩe nĩgeetha ngũrathime na kĩrathimo gĩakwa.” Jakubu akĩmũrehera nake akĩrĩa, na akĩmũrehera ndibei na akĩnyua.
Nígbà náà ni Isaaki wí pé, “Gbé ẹran igbó náà súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi, kí èmi kí ó jẹ ẹ́, kí èmi sì súre fún ọ láti inú ọkàn mi wá.” Jakọbu sì gbé e wá ó sì jẹ ẹ́, ó sì tún fún un ní wáìnì, ó sì mú un pẹ̀lú.
26 Ningĩ ithe Isaaka akĩmwĩra atĩrĩ, “Mũrũ wakwa, ũka haha ũũmumunye”.
Nígbà náà ni Isaaki baba rẹ̀ wí fun un pé, “Súnmọ́ mi, ọmọ mi, kí o sì fẹnukò mí ní ẹnu.”
27 Nake agĩthiĩ harĩ we na akĩmũmumunya. Rĩrĩa Isaaka aiguire kĩheera kĩa nguo ciake, akĩmũrathima, akiuga atĩrĩ, “Hĩ, kĩheera kĩa mũrũ wakwa nĩ ta kĩheera gĩa gĩthaka kĩrĩa kĩrathimĩtwo nĩ Jehova.
Ó sì súnmọ́ ọn, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu. Nígbà tí Isaaki gbọ́ òórùn aṣọ rẹ̀, ó súre fún un ó wí pé, “Wò ó òórùn ọmọ mi dàbí òórùn oko tí Olúwa ti bùkún.
28 Ngai arokũhe ime rĩa igũrũ o na ũnoru wa thĩ, na ũingĩ wa ngano na wa ndibei ya mũhihano.
Kí Ọlọ́run kí ó fún ọ nínú ìrì ọ̀run àti nínú ọ̀rá ilẹ̀ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkà àti wáìnì tuntun.
29 Ndũrĩrĩ irogũtungatagĩra nayo mĩhĩrĩga ya andũ ĩkũinamagĩrĩre. Tuĩka mwathi wa ariũ a thoguo, nao ariũ a nyũkwa marokũinamagĩrĩra. Arĩa mangĩkũruma na kĩrumi marocookererwo nĩkĩo, nao arĩa magaakũrathima marorathimagwo.”
Kí àwọn orílẹ̀-èdè kí ó máa sìn ọ́, kí àwọn ènìyàn sì máa tẹríba fún ọ, máa ṣe olórí àwọn arákùnrin rẹ, kí àwọn iyèkan rẹ sì máa wólẹ̀ fún ọ Fífibú ni àwọn ẹni tó fi ọ́ bú, ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ó súre fún ọ.”
30 Na rĩrĩ, Isaaka aarĩkia kũmũrathima na Jakubu aarĩkia kuuma harĩ ithe o ro ũguo-rĩ, mũrũ wa nyina Esaũ agĩũka kuuma kũguĩma.
Bí Isaaki ti súre tán tí Jakọbu ṣẹ̀ṣẹ̀ jáde kúrò ní ọ̀dọ̀ baba rẹ̀ ni Esau ti oko ọdẹ dé.
31 O nake agĩthondeka irio njega na agĩcirehere ithe. Agĩcooka akĩmwĩra atĩrĩ, “Baba, wĩtiire ũrĩe nyama imwe cia ũguĩmi wakwa nĩgeetha ũndathime na kĩrathimo gĩaku.”
Òun pẹ̀lú ṣe ẹran dídùn, ó sì gbé e tọ baba rẹ̀ wá, ó sì wí fún un pé, “Baba mi, dìde jókòó, kí o sì jẹ nínú ẹran igbó tí mo ti ṣè, kí o sì súre fún mi.”
32 Nake ithe Isaaka akĩmũũria atĩrĩ, “We nĩwe ũ?” Nake akĩmũcookeria atĩrĩ, “Nĩ niĩ Esaũ, mũrũ waku wa irigithathi.”
Isaaki baba rẹ̀ sì bi í wí pé, “Ìwọ ta ni?” Ó sì dáhùn pé, “Èmi Esau, àkọ́bí rẹ ni.”
33 Isaaka agĩkĩinaina mũno akĩũria atĩrĩ, “Nũũ ũcio ũngĩ ũkũguĩmĩte, na andehera nyama? Ndacirĩa o ro rĩu ũtanooka, na ndamũrathima, na ti-itherũ nĩ mũrathime.”
Nígbà náà ni Isaaki wárìrì gidigidi, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni náà, tí ó ti pa ẹran igbó tí ó sì ti gbe wá fún mi, tí mo sì ti jẹ ẹ́ kí ó tó dé? Mo sì ti súre fún un, sì wò ó dájúdájú a ó sì bùkún un!”
34 Rĩrĩa Esaũ aiguire ciugo cia ithe, agĩtumũka na kĩrĩro kĩnene na kĩa ruo, akĩĩra ithe atĩrĩ, “Ndaathima! O na niĩ baba ndaathima!”
Nígbà tí Esau gbọ́ ọ̀rọ̀ baba rẹ̀, ó ké, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún kíkorò, ó sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Baba mi súre fún èmi náà, àní fún èmi náà pẹ̀lú.”
35 No ithe akĩmwĩra atĩrĩ, “Mũrũ wa nyũkwa okire na wara, aheenia, na oya kĩrathimo gĩaku.”
Ṣùgbọ́n Isaaki wí pé, “Àbúrò rẹ ti fi ẹ̀tàn wá, ó sì ti gba ìbùkún rẹ lọ.”
36 Esaũ akiuga atĩrĩ, “Githĩ nĩ ma nĩkĩo etagwo Jakubu? Arĩ kũũheenia maita maya meerĩ; nĩoire ũrigithathi wakwa, na rĩu nĩoya kĩrathimo gĩakwa!” Agĩcooka akĩũria ithe atĩrĩ, “Ndũnandigĩria kĩrathimo o na kĩmwe?”
Esau sì wí pé, “Lásán ni a pe orúkọ rẹ̀ ní Jakọbu bí? Ní ìgbà méjì yìí ni ó ti tàn mí jẹ: ní àkọ́kọ́, ó gba ogún ìbí mi, nísinsin yìí, ó tún gba ìbùkún mi!” O sì béèrè pé, “Ṣe o kò wá fi ìre kankan sílẹ̀ fun mi ni?”
37 Isaaka agĩcookeria Esaũ atĩrĩ, “Ndĩmũtuire mwathi waku na andũ ao othe ndaamatua ndungata ciake, na ndamũhe ngano na ndibei ya mũhihano imũtũũragie. Nĩ ũndũ ũcio nĩ atĩa ingĩhota gũgwĩkĩra, mũrũ wakwa?”
Isaaki sì dá Esau lóhùn pé, “Mo ti fi ṣe olórí rẹ àti àwọn ìbátan rẹ ni mo fi ṣe ìránṣẹ́ fún un, àti ọkà àti wáìnì ni mo ti fi lé e lọ́wọ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀, kí ni ó tún kù tí ǹ bá tún fún ọ báyìí ọmọ mi?”
38 Esaũ akĩũria ithe atĩrĩ, “Baba, ndũrĩ na kĩrathimo o na kĩmwe ũndigĩirie? Ndaathima o na niĩ, baba!” Na hĩndĩ ĩyo Esaũ akĩrĩra anĩrĩire.
Esau sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Ṣe ìre kan ṣoṣo ni ìwọ ní lẹ́nu ni baba mi? Súre fún èmi náà, baba mi.” Esau sì sọkún kíkankíkan.
39 Nake ithe Isaaka akĩmũcookeria atĩrĩ, “Wee ũgaatũũraga kũraihu na ũnoru wa thĩ, kũraihu na ime rĩrĩa riumaga igũrũ.
Isaaki baba rẹ̀ sì dá a lóhùn pé, “Ibùjókòó rẹ yóò jìnnà sí ọ̀rá ilẹ̀, àti sí ibi ìrì ọ̀run láti òkè wá.
40 Ũgaatũũragio nĩ rũhiũ rwa njora na nĩũgatungataga mũrũ wa nyũkwa. No rĩrĩ, rĩrĩa ũkaaremwo nĩgũkirĩrĩria-rĩ, nĩũkeruta icooki rĩake ngingo, ũrĩte.”
Nípa idà rẹ ni ìwọ yóò máa gbé, ìwọ yóò sì máa sin àbúrò rẹ, ṣùgbọ́n ní ìkẹyìn, nígbà tí ìwọ bá di alágbára ìwọ yóò já àjàgà rẹ̀ kúrò lọ́rùn rẹ.”
41 Esaũ agĩthũũra Jakubu nĩ ũndũ wa kĩrathimo kĩu aaheirwo nĩ ithe. Nake akiuga na ngoro atĩrĩ, “Matukũ ma gũcakaĩra baba makiriĩ gũkinya; maathira nĩguo ngooraga mũrũ wa maitũ Jakubu.”
Esau sì kórìíra Jakọbu nítorí ìre tí baba rẹ̀ sú fún un, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, “Baba mi sá à ti fẹ́rẹ kú, nígbà náà ni èmi ó pa Jakọbu, arákùnrin mi.”
42 Rĩrĩa Rebeka eerirwo ũrĩa Esaũ mũriũ ũcio wake mũkũrũ oigĩte, agĩtũmanĩra Jakubu mũriũ wake ũrĩa mũnini, akĩmwĩra atĩrĩ, “Esaũ mũrũ wa nyũkwa arehooreria marakara na gwĩciiria ũrĩa egũkũũraga.
Nígbà tí Rebeka sì gbọ́ ohun tí Esau àkọ́bí rẹ̀ wí, ó sì ránṣẹ́ sí Jakọbu, ó sì wí fun un pé, “Esau ẹ̀gbọ́n rẹ ń tu ara rẹ̀ nínú pẹ̀lú èrò à ti pa ọ́.
43 Rĩu mũrũ wakwa-rĩ, ĩka o ũrĩa ngũkwĩra. Thiĩ o ro rĩu ũũrĩre Harani, kwa mũrũ wa maitũ Labani.
Nítorí náà ọmọ mi, ṣe ohun tí èmi yóò sọ fún ọ, sálọ sọ́dọ̀ Labani ẹ̀gbọ́n mi ní Harani.
44 Nawe ũikare nake kwa ihinda nginya mangʼũrĩ ma mũrũ wa nyũkwa mahũahũe.
Jókòó sí ibẹ̀ títí di ìgbà tí ìbínú ẹ̀gbọ́n rẹ yóò fi rọ̀.
45 Rĩrĩa mũrũ wa nyũkwa agaatiga gũkũrakarĩra, na ariganĩrwo nĩ ũrĩa wamwĩkire-rĩ, nĩngagũtũmanĩra ũcooke mũciĩ. Ingĩkĩũrwo nĩ inyuĩ mũrĩ eerĩ mũthenya o ro ũmwe nĩkĩ?”
Nígbà tí ẹ̀gbọ́n rẹ kò bá bínú sí ọ mọ́, tí ó sì ti gbàgbé ohun tí ìwọ ṣe sí i, èmí ó ránṣẹ́ sí ọ láti padà wá. Èéṣe tí èmi ó fi pàdánù ẹ̀yin méjèèjì ní ọjọ́ kan náà?”
46 Ningĩ Rebeka akĩĩra Isaaka atĩrĩ, “Nĩnogetio nĩ mũtũũrĩre nĩ ũndũ wa andũ-a-nja aya a Ahiti. Jakubu angĩhikania kuuma kũrĩ andũ-a-nja aya a Ahiti a bũrũri ũyũ-rĩ, ta andũ-a-nja aya Esaũ ahikĩtie-rĩ, hatirĩ bata wa gũtũũra muoyo.”
Nígbà náà ni Rebeka wí fún Isaaki pé, “Ayé sì sú mi nítorí àwọn ọmọbìnrin Hiti wọ̀nyí. Bí Jakọbu bá fẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin Hiti wọ̀nyí, ó kúkú sàn kí n má wà láààyè.”

< Kĩambĩrĩria 27 >