< Kĩambĩrĩria 26 >

1 Na rĩrĩ, nĩ kwagĩire ngʼaragu ĩngĩ bũrũri-inĩ ũcio, tiga ĩrĩa ya mbere ya hĩndĩ ya Iburahĩmu, nake Isaaka agĩthiĩ Gerari kũrĩ Abimeleku mũthamaki wa Afilisti.
Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, yàtọ̀ fún èyí tí ó mú ní ìgbà ayé Abrahamu, Isaaki sì lọ sọ́dọ̀ Abimeleki ọba àwọn Filistini ni Gerari.
2 Jehova akiumĩrĩra Isaaka, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndũgaikũrũke ũthiĩ Misiri; tũũra bũrũri o ũrĩa ndĩrĩkwĩra ũtũũre.
Olúwa sì fi ara han Isaaki, ó sì wí pé, “Má ṣe sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, jókòó ní ilẹ̀ tí èmi ó fún ọ.
3 Ikara bũrũri-inĩ ũyũ kwa ihinda, na nĩngũkorwo hamwe nawe na nĩngũkũrathima. Nĩgũkorwo nĩwe na njiaro ciaku ngũhe mabũrũri maya mothe na hingie mwĩhĩtwa ũrĩa ndehĩtire kũrĩ thoguo Iburahĩmu.
Máa ṣe àtìpó ní ilẹ̀ yìí fún ìgbà díẹ̀, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì bùkún fún ọ. Nítorí ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ni èmi yóò fi gbogbo àwọn ilẹ̀ wọ̀nyí fún, èmi yóò sì fi ìdí ìbúra tí mo ṣe fún Abrahamu baba rẹ múlẹ̀.
4 Nĩngatũma njiaro ciaku cingĩhe ta njata cia matu-inĩ na nĩngamahe mabũrũri maya mothe, na nĩ ũndũ wa rũciaro rwaku, ndũrĩrĩ ciothe cia thĩ nĩikarathimwo,
Èmi yóò sọ ìran rẹ di púpọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, èmi yóò sì fi gbogbo ilẹ̀ yìí fún irú àwọn ọmọ rẹ, àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé,
5 tondũ Iburahĩmu nĩanjathĩkĩire na akĩrũmia ũrĩa ndendaga, akĩrũmĩrĩra maathani makwa, na matuĩro makwa ma kũrũmĩrĩrwo, na mawatho makwa.”
nítorí tí Abrahamu gba ohùn mi gbọ́, ó sì pa gbogbo ìkìlọ̀, àṣẹ, ìlànà àti òfin mi mọ́.”
6 Nĩ ũndũ ũcio Isaaka agĩikara o kũu Gerari.
Nítorí náà Isaaki jókòó ní Gerari.
7 Rĩrĩa andũ a kũu maamũririe ũhoro wa mũtumia wake-rĩ, we akiuga atĩrĩ, “Nĩ mwarĩ wa baba,” tondũ nĩetigĩrire kuuga, “Nĩ mũtumia wakwa.” Eeciiririe atĩrĩ, “Andũ a gũkũ mahota kũnjũraga nĩ ũndũ wa Rebeka, tondũ aarĩ mũthaka.”
Nígbà tí àwọn ọkùnrin ìlú náà bi í léèrè ní ti aya rẹ̀, ó sì wí pé, “Arábìnrin mi ní í ṣe,” nítorí tí ó bẹ̀rù láti jẹ́wọ́ wí pé, “Aya mi ni.” Ó ń rò wí pé, “Kí àwọn ọkùnrin ibẹ̀ náà má ba à pa mí nítorí Rebeka, nítorí tí òun ní ẹwà púpọ̀.”
8 Na thuutha wa Isaaka arĩkĩtie gũikara kũu kahinda karaihu-rĩ, Abimeleku mũthamaki wa Afilisti nĩacũthĩrĩirie nja na ndirica, nake akĩona Isaaka akĩhambata mũtumia wake Rebeka.
Nígbà tí Isaaki sì ti wà níbẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, Abimeleki ọba Filistini yọjú lójú fèrèsé, ó sì rí Isaaki ń bá Rebeka aya rẹ̀ tage.
9 Nĩ ũndũ ũcio Abimeleku agĩtũmanĩra Isaaka, akĩmũũria atĩrĩ, “Ti-itherũ ũyũ nĩ mũtumia waku! Nĩ kĩĩ gĩatũmire uuge atĩ, ‘Ũyũ nĩ mwarĩ wa baba’?” Isaaka akĩmũcookeria atĩrĩ, “Tondũ ndeciiririe ndahota kũũragwo nĩ ũndũ wake.”
Nígbà náà ni Abimeleki ránṣẹ́ pe Isaaki ó sì wí fun pé, “Nítòótọ́, aya rẹ ni obìnrin yìí í ṣe, èéṣe tí ìwọ fi wí fún wa pé arábìnrin mi ni?” Isaaki sì fèsì pé, “Nítorí mo rò pé mo le pàdánù ẹ̀mí mi nítorí rẹ̀.”
10 Ningĩ Abimeleku akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ atĩa ũguo ũtwĩkĩte? Ĩ mũndũ mũrũme ũmwe wa gũkũ angĩrakorirwo akomete na mũtumia waku, nawe ũgĩtũme tũnyiitwo nĩ ihĩtia?”
Nígbà náà ni Abimeleki dáhùn pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Bí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá ti bá a lòpọ̀ ń kọ́? Ìwọ ìbá wá mú ẹ̀bi wá sórí wa.”
11 Nĩ ũndũ ũcio Abimeleku akĩruta watho kũrĩ andũ othe, akiuga atĩrĩ, “Mũndũ o na ũrĩkũ ũngĩthĩĩnia mũndũ ũyũ kana mũtumia wake no kũũragwo akooragwo.”
Nígbà náà ni Abimeleki pàṣẹ fún gbogbo ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ọkùnrin yìí tàbí aya rẹ̀ yóò jẹ̀bi ikú.”
12 Nake Isaaka akĩhaanda irio bũrũri ũcio, na mwaka o ro ũcio akĩgetha maita igana, tondũ Jehova nĩamũrathimire.
Ní ọdún náà, Isaaki gbin ohun ọ̀gbìn sí ilẹ̀ náà, ó sì kórè rẹ̀ ní ìlọ́po ọgọ́rùn-ún ọdún ni ọdún kan náà, nítorí Olúwa bùkún un.
13 Nake Isaaka agĩtonga, naguo ũtonga wake ũgĩthiĩ o ũkĩingĩhaga o nginya agĩtonga mũno.
Ọkùnrin náà sì di ọlọ́rọ̀ púpọ̀, ọrọ̀ rẹ̀ sì ń pọ̀ si, títí ó fi di ènìyàn ńlá.
14 Aarĩ na ndũũru nyingĩ cia mbũri na cia ngʼombe, na ndungata nyingĩ, o nginya Afilisti makĩmũiguĩra ũiru.
Ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn àti agbo ẹran àti àwọn ìránṣẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn Filistini ń ṣe ìlara rẹ̀.
15 Tondũ ũcio, ithima iria ciothe ndungata cia ithe cienjete hĩndĩ ya ithe Iburahĩmu-rĩ, Afilisti magĩcithika, magĩciyũria tĩĩri.
Nítorí náà àwọn ará Filistini ru erùpẹ̀ di gbogbo kànga tí àwọn ìránṣẹ́ Abrahamu baba rẹ̀ ti gbẹ́.
16 Ningĩ Abimeleku akĩĩra Isaaka atĩrĩ, “Ũkĩra ũthiĩ, ũtweherere, tondũ nĩũgĩĩte na hinya mũno gũtũkĩra.”
Nígbà náà ni Abimeleki wí fún Isaaki pé, “Jáde kúrò ní ilẹ̀ wa, nítorí tí ìwọ ti di alágbára púpọ̀ jù wá lọ.”
17 Nĩ ũndũ ũcio Isaaka agĩthaama, akĩehera kũu, agĩthiĩ kwamba hema Gĩtuamba-inĩ kĩa Gerari, na agĩtũũra kuo.
Isaaki sì ṣí kúrò níbẹ̀, ó sì pàgọ́ sí àfonífojì Gerari ó sì ń gbé ibẹ̀.
18 Isaaka agĩthikũria ithima iria cienjetwo hĩndĩ ya ithe Iburahĩmu, o icio Afilisti maathikĩte thuutha wa Iburahĩmu gũkua, na agĩciĩta marĩĩtwa o marĩa ithe aacihete.
Isaaki sì ṣe àtúngbẹ́ àwọn kànga tí Abrahamu baba rẹ̀ ti gbẹ́ nígbà ayé rẹ̀, èyí tí àwọn Filistini ti dí lẹ́yìn ikú Abrahamu baba rẹ̀, ó sì fún wọn lórúkọ tí baba rẹ̀ ti sọ wọ́n tẹ́lẹ̀.
19 Na rĩrĩ, ndungata cia Isaaka nĩcienjire kũu gĩtuamba-inĩ na igĩkora gĩthima kĩa maaĩ mega kuo.
Àwọn ìránṣẹ́ Isaaki sì gbẹ́ kànga ní àfonífojì náà, wọ́n kan ìsun omi níbẹ̀.
20 No rĩrĩ, arĩithi a Gerari makĩnegenania na arĩithi a Isaaka, makĩmeera atĩrĩ, “Maaĩ maya nĩ maitũ!” Nake agĩĩta gĩthima kĩu Eseku, tondũ nĩmakararanirie nake.
Ṣùgbọ́n àwọn darandaran Gerari ń bá àwọn darandaran Isaaki jà sí kànga náà pé àwọn ni àwọn ni í. Nítorí náà ni ó fi pe orúkọ kànga náà ní Eseki, nítorí pé wọ́n bá a jà sí kànga náà.
21 Ningĩ ndungata icio ciake ikĩenja gĩthima kĩngĩ, no-o nakĩo makĩnegenanĩria, nake Isaaka agĩgĩĩta Sitina.
Àwọn ìránṣẹ́ Isaaki tún gbẹ́ kànga mìíràn, wọ́n sì tún jà nítorí rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Sitna.
22 Nake agĩthaama kũu, agĩthiĩ akĩenja gĩthima kĩngĩ, na matianegenanirie na mũndũ. Nake agĩgĩĩta Rehobothu, akiuga atĩrĩ, “Rĩu Jehova nĩatũheete ũikaro mũiganu, na nĩtũgũtheeremera bũrũri-inĩ ũyũ.”
Ó sì tún kúrò níbẹ̀, ó sì gbẹ́ kànga mìíràn, wọn kò sì jásí èyí rárá, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Rehoboti, ó wí pé, “Nísinsin yìí, Olúwa ti fi ààyè gbà wá, a ó sì gbilẹ̀ si ní ilẹ̀ náà.”
23 Agĩcooka akiuma kũu, agĩthiĩ Birishiba.
Láti ibẹ̀, ó kúrò lọ sí Beerṣeba.
24 Ũtukũ ũcio aakinyire kũu, Jehova akĩmuumĩrĩra, akĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩ niĩ Ngai wa thoguo Iburahĩmu. Ndũkanetigĩre, tondũ ndĩ hamwe nawe; nĩngũkũrathima na nyingĩhie njiaro ciaku nĩ ũndũ wa Iburahĩmu ndungata yakwa.”
Ní òru ọjọ́ tí ó dé ibẹ̀, Olúwa sì fi ara hàn án, ó sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run Abrahamu baba rẹ. Má ṣe bẹ̀rù nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì bùsi fún ọ, èmi yóò sì sọ iye ìran rẹ di púpọ̀, nítorí Abrahamu ìránṣẹ́ mi.”
25 Isaaka agĩaka kĩgongona kũu, na agĩkaĩra rĩĩtwa rĩa Jehova. Akĩamba hema yake o kũu, nacio ndungata ciake ikĩenja gĩthima o kuo.
Isaaki sì kọ́ pẹpẹ kan síbẹ̀, ó sì pe orúkọ Olúwa. Níbẹ̀ ni ó pàgọ́ rẹ̀ sí, àwọn ìránṣẹ́ rẹ sì gbẹ́ kànga kan níbẹ̀.
26 Hĩndĩ ĩyo Abimeleku agĩthiĩ kũrĩ Isaaka oimĩte Gerari, marĩ na Ahuzathu ũrĩa wamũtaaraga, na Fikolu mũnene wa ita ciake.
Nígbà náà ni Abimeleki tọ̀ ọ́ wá láti Gerari, àti Ahussati, olùdámọ̀ràn rẹ̀ àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀.
27 Isaaka akĩmooria atĩrĩ, “Muoka kũrĩ niĩ nĩkĩ, kuona atĩ nĩmwathũũrire na mũkĩnyingata?”
Isaaki sì bi wọ́n léèrè pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin tọ̀ mí wá, níwọ̀n ìgbà tí ẹ̀yin kórìíra mi tí ẹ sì lé mi jáde kúrò lọ́dọ̀ yín?”
28 Nao makĩmũcookeria atĩrĩ, “Nĩtuonete hatarĩ nganja atĩ Jehova arĩ hamwe nawe, na nĩ ũndũ ũcio tuoiga atĩrĩ, ‘Nĩ kwagĩrĩire tũgĩe na mwĩhĩtwa wa ũiguano gatagatĩ gaitũ’: ĩĩ, gatagatĩ gaitũ nawe. Reke tũgĩe na kĩrĩkanĩro nawe,
Wọ́n dáhùn pé, “A rí i dájú pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nítorí náà ni a fi rò ó wí pé, ó yẹ kí májẹ̀mú kí o wà láàrín àwa àti ìwọ. Jẹ́ kí a ṣe àdéhùn
29 atĩ ndũgatwĩka ũũru, o ta ũrĩa o na ithuĩ tũtaagũthĩĩnirie, no hĩndĩ ciothe twagwĩkaga wega, na tũgĩkumagaria ũthiĩ na thayũ. Na rĩu nĩũrathimĩtwo nĩ Jehova.”
pé ìwọ kì yóò ṣe wá ní ibi, bí àwa pẹ̀lú kò ti ṣe ọ́ ní aburú, tí a sì ń ṣe ọ́ dáradára, tí a sì rán ọ jáde ní àlàáfíà láìṣe ọ́ ní ibi, kíyèsi Olúwa sì ti bùkún fún ọ.”
30 Isaaka akĩmarugithĩria iruga, nao makĩrĩa na makĩnyua.
Isaaki sì ṣe àsè fún wọn, wọn sì jẹ, wọ́n sì mu.
31 Mũthenya ũyũ ũngĩ, rũciinĩ tene, andũ acio na Isaaka makĩĩhĩtanĩra mwĩhĩtwa mũndũ na ũrĩa ũngĩ. Isaaka agĩcooka akĩmoimagaria, magĩĩthiĩra, makĩmũtiga na thayũ.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì wọn búra fún ara wọn. Isaaki sì rán wọn lọ, wọ́n sì lọ ní àlàáfíà.
32 Mũthenya o ro ũcio maathiire, ndungata cia Isaaka igĩũka, ĩkĩmwĩra ũhoro wa gĩthima kĩrĩa cienjete, ikiuga atĩrĩ, “Nĩtwakinyĩra maaĩ!”
Ní ọjọ́ náà gan an ni àwọn ìránṣẹ́ Isaaki wá sọ fún un pé àwọn ti kan omi ní kànga kan tí àwọn gbẹ́.
33 Nake agĩĩta gĩthima kĩu Shiba, na nginya ũmũthĩ itũũra rĩu rĩtũũraga rĩĩtagwo Birishiba.
Ó sì pe orúkọ kànga náà ní Ṣiba, títí di òní olónìí, orúkọ ìlú náà ni Beerṣeba.
34 Esaũ aakinyia mĩaka mĩrongo ĩna, akĩhikia Judithi mwarĩ wa Beeri ũrĩa Mũhiti, o na ningĩ akĩhikia Basemathu mwarĩ wa Eloni ũrĩa Mũhiti.
Nígbà tí Esau pé ọmọ ogójì ọdún ó fẹ́ ọmọbìnrin kan tí a ń pè ní Juditi, ọmọ Beeri, ará Hiti, ó sì tún fẹ́ Basemati, ọmọ Eloni ará Hiti.
35 Nao magĩtuĩka kĩhumo gĩa kĩeha kũrĩ Isaaka na Rebeka.
Fífẹ́ tí a fẹ́ àwọn obìnrin wọ̀nyí jẹ́ ìbànújẹ́ fún Isaaki àti Rebeka.

< Kĩambĩrĩria 26 >