< Kĩambĩrĩria 11 >

1 Hĩndĩ ĩyo ya tene-rĩ, andũ othe a thĩ maarĩ na rũthiomi rũmwe na mwario o ũmwe.
Lẹ́yìn náà, gbogbo àgbáyé sì ń sọ èdè kan ṣoṣo.
2 Na rĩrĩa andũ maathiiaga na mwena wa irathĩro, magĩkinya werũ-inĩ ũrĩa mwaraganu wa Shinaru, na magĩtũũra kuo.
Bí àwọn ènìyàn ṣe ń tẹ̀síwájú lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, wọ́n rí pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan ní ilẹ̀ Ṣinari, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
3 Nao makĩĩrana atĩrĩ, “Ũkai tũũmbe maturubarĩ na tũmacine wega.” Magĩtũmĩra maturubarĩ handũ ha mahiga, na rami handũ ha thimiti.
Wọ́n sì wí fún ara wọn pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a mọ bíríkì kí a sì sún wọ́n jìnà.” Bíríkì ni wọ́n ń lò ní ipò òkúta, àti ọ̀dà ilẹ̀ tí wọn ń lò láti mú wọn papọ̀ dípò ẹfun (òkúta láìmù tí wọ́n fi ń ṣe símẹ́ńtì àti omi).
4 Ningĩ magĩcooka makiuga atĩrĩ, “Ũkai, rekei twĩyakĩre itũũra inene, rĩna mũthiringo mũraaya na igũrũ, ũkinye o matu-inĩ, nĩgeetha twĩgĩĩre igweta, na nĩguo tũtikaanahurunjwo thĩ yothe.”
Nígbà náà ni wọ́n wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tẹ ìlú kan dó fún ara wa, kí a sì kọ́ ilé ìṣọ́ kan tí yóò kan ọ̀run, kí a ba à lè ní orúkọ, kí a má sì tú káàkiri sórí gbogbo ilẹ̀ ayé.”
5 No rĩrĩ, Jehova agĩikũrũka oke one itũũra rĩu na mũthiringo ũcio andũ acio maakaga.
Ṣùgbọ́n, Olúwa sọ̀kalẹ̀ láti wo ìlú àti ilé ìṣọ́ tí àwọn ènìyàn náà ń kọ́.
6 Jehova akiuga atĩrĩ na ngoro yake, “Angĩkorwo na ũndũ wa ũrũmwe wa kwaria rũthiomi rũmwe andũ aya nĩmambĩrĩria gwĩka ũũ-rĩ, gũtirĩ ũndũ makaabanga gwĩka ũkaamarema.
Olúwa wí pé, “Bí àwọn ènìyàn bá ń jẹ́ ọ̀kan àti èdè kan tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe iṣẹ́ yìí, kò sí ohun tí wọ́n gbèrò tí wọn kò ní le ṣe yọrí.
7 Ũkai, tũikũrũke tũkahĩngĩcanie rũthiomi rwao, nĩgeetha matigacooke kũiguithania mĩario mũndũ na ũrĩa ũngĩ.”
Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ lọ, kí a da èdè wọn rú kí èdè wọn má ba à yé ara wọn mọ́.”
8 Nĩ ũndũ ũcio, kuuma hau Jehova akĩmahurunja thĩ yothe, nao magĩtiga gwaka itũũra rĩu inene.
Olúwa sì tú wọn ká sórí ilẹ̀ gbogbo, wọ́n sì ṣíwọ́ ìlú náà tí wọn ń tẹ̀dó.
9 Na nĩkĩo itũũra rĩu rĩetirwo Babeli, tondũ nĩkuo Jehova aahĩngĩcanĩirie rũthiomi rwa andũ a thĩ yothe. Kuuma kũu, Jehova akĩmahurunja thĩ yothe.
Ìdí èyí ni a fi pè é ní Babeli nítorí ní ibẹ̀ ni Olúwa ti da èdè gbogbo ayé rú. Olúwa tí sì tú àwọn ènìyàn ká sí gbogbo orí ilẹ̀ ayé.
10 Ũyũ nĩguo ũhoro wa Shemu. Mĩaka ĩĩrĩ thuutha wa mũiyũro wa maaĩ-rĩ, rĩrĩa Shemu aarĩ na ũkũrũ wa mĩaka igana rĩmwe-rĩ, nĩguo aatuĩkire ithe wa Arafakasadi.
Wọ̀nyí ni ìran Ṣemu. Ọdún méjì lẹ́yìn ìkún omi, tí Ṣemu pé ọgọ́rùn-ún ọdún ni ó bí Arfakṣadi.
11 Shemu aatũũrire muoyo mĩaka magana matano thuutha wa gũtuĩka ithe wa Arafakasadi, na akĩgĩa na ciana ingĩ cia aanake na cia airĩtu.
Lẹ́yìn tí ó bí Arfakṣadi, Ṣemu tún wà láààyè fún ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọdún, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
12 Nake Arafakasadi aakinyia mĩaka mĩrongo ĩtatũ na ĩtano, agĩtuĩka ithe wa Shela.
Nígbà tí Arfakṣadi pé ọdún márùndínlógójì ni ó bí Ṣela.
13 Na thuutha wa gũtuĩka ithe wa Shela, Arafakasadi agĩtũũra muoyo mĩaka ĩngĩ magana mana na ĩtatũ, na akĩgĩa na ciana ingĩ cia aanake na cia airĩtu.
Arfakṣadi sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó lẹ́yìn tí ó bí Ṣela, ó sì bí àwọn ọmọbìnrin àti àwọn ọmọkùnrin mìíràn.
14 Nake Shela aakinyia mĩaka mĩrongo ĩtatũ, agĩtuĩka ithe wa Eberi.
Nígbà tí Ṣela pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Eberi.
15 Na thuutha wa gũtuĩka ithe wa Eberi, Shela agĩtũũra muoyo mĩaka ĩngĩ magana mana na ĩtatũ, na akĩgĩa na ciana ingĩ cia aanake na cia airĩtu.
Ṣela sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó lẹ́yìn tí ó bí Eberi tán, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
16 Nake Eberi aakinyia mĩaka mĩrongo ĩtatũ na ĩna, agĩtuĩka ithe wa Pelegu.
Eberi sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n, ó sì bí Pelegi.
17 Na thuutha wa gũtuĩka ithe wa Pelegu, Eberi agĩtũũra muoyo mĩaka ĩngĩ magana mana na mĩrongo ĩtatũ, na akĩgĩa na ciana ingĩ cia aanake na cia airĩtu.
Eberi sì wà láààyè fún irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n lẹ́yìn tí ó bí Pelegi, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
18 Nake Pelegu aakinyia mĩaka mĩrongo ĩtatũ, agĩtuĩka ithe wa Reu.
Nígbà tí Pelegi pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Reu.
19 Na thuutha wa gũtuĩka ithe wa Reu, Pelegu agĩtũũra muoyo mĩaka ĩngĩ magana meerĩ na kenda na akĩgĩa na ciana ingĩ cia aanake na cia airĩtu.
Pelegi sì tún wà láààyè fún igba ọdún ó lé mẹ́sàn-án lẹ́yìn tí ó bí Reu, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
20 Nake Reu aakinyia mĩaka mĩrongo ĩtatũ na ĩĩrĩ, agĩtuĩka ithe wa Serugu.
Nígbà tí Reu pé ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ni ó bí Serugu.
21 Na thuutha wa gũtuĩka ithe wa Serugu, Reu agĩtũũra muoyo mĩaka ĩngĩ magana meerĩ na mũgwanja na akĩgĩa na ciana ingĩ cia aanake na cia airĩtu.
Reu tún wà láààyè lẹ́yìn tí ó bí Serugu fún igba ọdún ó lé méje, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn.
22 Nake Serugu aakinyia mĩaka mĩrongo ĩtatũ, agĩtuĩka ithe wa Nahoru.
Nígbà tí Serugu pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Nahori.
23 Na thuutha wa gũtuĩka ithe wa Nahoru, Serugu agĩtũũra muoyo mĩaka ĩngĩ magana meerĩ na akĩgĩa na ciana ingĩ cia aanake na cia airĩtu.
Serugu sì wà láààyè fún igba ọdún lẹ́yìn tí ó bí Nahori, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
24 Nake Nahoru aakinyia mĩaka mĩrongo ĩĩrĩ na kenda, agĩtuĩka ithe wa Tera.
Nígbà tí Nahori pé ọmọ ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n, ó bí Tẹra.
25 Na thuutha wa gũtuĩka ithe wa Tera, Nahoru agĩtũũra muoyo mĩaka ĩngĩ igana na ikũmi na kenda, na akĩgĩa na ciana ingĩ cia aanake na cia airĩtu.
Nahori sì wà láààyè fún ọdún mọ́kàn dín lọ́gọ́fà lẹ́yìn ìbí Tẹra, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
26 Thuutha wa Tera gũkinyia mĩaka mĩrongo mũgwanja, agĩtuĩka ithe wa Aburamu, na Nahoru na Harani.
Lẹ́yìn tí Tẹra pé ọmọ àádọ́rin ọdún ó bí Abramu, Nahori àti Harani.
27 Ũyũ nĩguo ũhoro wa Tera. Tera nĩwe warĩ ithe wa Aburamu, na Nahoru na Harani. Nake Harani agĩtuĩka ithe wa Loti.
Wọ̀nyí ni ìran Tẹra. Tẹra ni baba Abramu, Nahori àti Harani. Harani sì bí Lọti.
28 Ithe wao Tera arĩ o muoyo-rĩ, Harani nĩakuire arĩ bũrũri-inĩ wa Uri-kwa-Akalidei, kũrĩa aaciarĩirwo.
Harani sì kú ṣáájú Tẹra baba rẹ̀ ní ilẹ̀ ìbí rẹ̀ ní Uri ti ilẹ̀ Kaldea.
29 Aburamu na Nahoru o eerĩ nĩmahikanirie. Mũtumia wa Aburamu eetagwo Sarai, nake mũtumia wa Nahoru eetagwo Milika; Milika aarĩ mwarĩ wa Harani. Harani nĩwe warĩ ithe wa Milika na Isika.
Abramu àti Nahori sì gbéyàwó. Orúkọ aya Abramu ni Sarai, nígbà tí aya Nahori ń jẹ́ Milka, tí ṣe ọmọ Harani. Harani ni ó bí Milka àti Iska.
30 Na rĩrĩ, Sarai aarĩ thaata; ndaarĩ na ciana.
Sarai sì yàgàn, kò sì bímọ.
31 Nake Tera akĩoya mũriũ wake Aburamu, na Loti mũrũ wa mũrũwe Harani, na Sarai mũtumia wa mũriũ wake Aburamu; nao makiumagara hamwe moime bũrũri wa Uri-kwa-Akalidei mathiĩ Kaanani. No rĩrĩa maakinyire bũrũri wetagwo Harani, magĩtũũra kuo.
Tẹra sì mú ọmọ rẹ̀ Abramu àti Lọti ọmọ Harani, ọmọ ọmọ rẹ̀, ó sì mú Sarai tí i ṣe aya ọmọ rẹ̀. Abramu pẹ̀lú gbogbo wọn sì jáde kúrò ní Uri ti Kaldea láti lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Ṣùgbọ́n nígbà tí wọn dé Harani wọ́n tẹ̀dó síbẹ̀.
32 Tera agĩtũũra muoyo mĩaka ĩngĩ magana meerĩ na ĩtano, na agĩkuĩra kũu Harani.
Nígbà tí Tẹra pé ọmọ igba ọdún ó lé márùn-ún ni ó kú ní Harani.

< Kĩambĩrĩria 11 >