< Ezekieli 3 >

1 Nake mũndũ ũcio akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Mũrũ wa mũndũ, rĩa kĩrĩa kĩrĩ mbere yaku, rĩa ibuku rĩĩrĩ rĩa gĩkũnjo; ũcooke ũthiĩ ũkaarĩrie andũ a nyũmba ya Isiraeli.”
Síwájú sí i, ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ ohun tí ó wà níwájú rẹ, jẹ ìwé kíká yìí; kí o sì lọ fi bá ilé Israẹli sọ̀rọ̀.”
2 Nĩ ũndũ ũcio ngĩathamia kanua, nake akĩĩhe ibuku rĩu rĩa gĩkũnjo ndĩrĩrĩe.
Mo sì ya ẹnu mi, ó sì mú mi jẹ ìwé kíká náà.
3 Ningĩ akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Mũrũ wa mũndũ, rĩa ibuku rĩĩrĩ rĩa gĩkũnjo ndĩrakũhe ũiyũrie nda yaku.” Nĩ ũndũ ũcio ngĩrĩrĩa, na rĩrĩ kanua-inĩ gakwa rĩarĩ na mũrĩo ta ũũkĩ.
Ó tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ ìwé kíká tí mo fún ọ yìí, fi bọ́ inú àti ikùn rẹ.” Nígbà náà ni mo jẹ ẹ́, dídùn rẹ̀ dàbí oyin ní ẹnu mi.
4 Ningĩ agĩcooka akĩnjĩĩra atĩrĩ: “Mũrũ wa mũndũ, thiĩ o rĩu kũrĩ andũ a nyũmba ya Isiraeli ũmaarĩrie ciugo ciakwa.
Ó sì tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, lọ ni ìsinsin yìí bá mi sọ ọ̀rọ̀ mi fún ilé Israẹli.
5 Ndũratũmwo kũrĩ andũ a mwarĩrie ũtooĩ kana rũthiomi rũritũ, no nĩ kũrĩ andũ a nyũmba ya Isiraeli;
A kò rán ọ sí àwọn tó ń sọ èdè àjèjì tàbí tí èdè wọn ṣòro láti gbọ́, ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè Israẹli ni mo rán ọ sí
6 ti kũrĩ ndũrĩrĩ nyingĩ iria ciaragia mwarĩrie ũtooĩ kana rũthiomi rũritũ, kana rũrĩ na ciugo iria ũtangĩmenya. Ti-itherũ, korwo nĩndagũtũmĩte kũrĩ o, nĩmangĩagũthikĩrĩirie.
kì í ṣe sí ọ̀pọ̀ ènìyàn tó ń sọ àjèjì èdè tàbí tí èdè wọn ṣòro láti gbọ́, àwọn tí ọ̀rọ̀ wọn le fún ọ láti gbọ́ yé. Dájúdájú bí mo bá rán ọ sí wọn, wọn ìbá sì fetísílẹ̀ sí ọ.
7 No rĩrĩ, andũ a nyũmba ya Isiraeli matingĩenda gũkũigua, nĩ ũndũ matiendaga kũnjigua, nĩgũkorwo nyũmba yothe ya Isiraeli nĩyũmĩtie ngoro na ĩkangʼathia.
Ṣùgbọ́n ilé Israẹli kò fẹ́ gbọ́ tìrẹ nítorí pé wọn kò fẹ́ láti gbọ́ tèmi, torí pé aláìgbọ́ràn àti ọlọ́kàn líle ni gbogbo ilé Israẹli.
8 No rĩrĩ, niĩ ngũtũma wage kuororoa na ũũmie ngoro o ta o.
Ṣùgbọ́n bí i tiwọn lèmi náà yóò ṣe jẹ́ kí ojú àti ọkàn rẹ le.
9 Nĩngũtũma gĩthiithi gĩaku kĩũme ta ihiga rĩrĩa rĩũmũ mũno, rĩrĩa rĩũmũ gũkĩra ihiga rĩa nyaigĩ. Ndũkametigĩre kana ũmakio nĩo, o na akorwo nĩ a nyũmba ya ũremi.”
Èmi yóò ṣe iwájú orí rẹ bí òkúta tó le jùlọ, ànító le ju òkúta-ìbọn lọ. Má ṣe bẹ̀rù wọn tàbí jẹ́ kí wọn ó dáyà já ọ. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìdílé ọlọ̀tẹ̀ ni wọ́n.”
10 Ningĩ akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Mũrũ wa mũndũ, thikĩrĩria wega na wĩkĩre ciugo iria ciothe ngũkwarĩria ngoro-inĩ.
Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ń sọ, kí o sì gba gbogbo ọ̀rọ̀ yìí sí ọkàn rẹ.
11 Thiĩ o rĩu kũrĩ andũ anyu arĩa matahĩtwo warie nao. Meere atĩrĩ, ‘Ũũ nĩguo Mwathani Jehova ekuuga,’ kana nĩmegũthikĩrĩria kana matigũthikĩrĩria.”
Lọ nísinsin yìí sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ tó wà ní ìgbèkùn. Sọ fún wọn pé báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí yálà wọ́n gbọ́ tàbí wọn kò gbọ́.”
12 Ningĩ Roho akĩnjoya na igũrũ, na ngĩigua mũgambo mũnene thuutha wakwa ũkĩruruma. (Riiri wa Jehova ũrogoocwo arĩ o kũu gĩikaro-inĩ gĩake!)
Nígbà náà ni ẹ̀mí gbé mi sókè, mo sì gbọ́ ohùn ìró ńlá lẹ́yìn mi tó sọ pé, kí a gbé ògo Olúwa ga láti ibùgbé rẹ̀ wá!
13 Naguo warĩ mũgambo wa mathagu ma ciũmbe icio irĩ muoyo makĩhutania mo mene, na wa magũrũ ma ngaari marĩa maarĩ mĩena yacio, naguo warĩ mũgambo mũnene warurumaga.
Bẹ́ẹ̀ ni mo tún gbọ́ ariwo ìyẹ́ apá àti kẹ̀kẹ́ àwọn ẹ̀dá alààyè náà pẹ̀lú ariwo tó dàbí àrá ńlá.
14 Roho agĩcooka akĩnjoya na igũrũ akĩnjeheria, na niĩ ngĩthiĩ ndĩ na marũrũ na marakara ngoro-inĩ, nakuo guoko kwa Jehova kũrĩa kwa hinya kwarĩ igũrũ rĩakwa.
Ẹ̀mí náà sì gbé mi sókè, ó sì mú mi lọ, mo lọ pẹ̀lú ọkàn kíkorò àti ìbínú nínú ẹ̀mí mi, pẹ̀lú ọwọ́ líle Olúwa ni ara mi.
15 Ngĩkinya kũrĩ arĩa maatahĩtwo, arĩa maatũũraga kũu Teli-Abibu, gũkuhĩ na Rũũĩ rwa Kebari, na ngĩikarania nao kwa ihinda rĩa mĩthenya mũgwanja, makĩte mũno.
Nígbà náà ni mo lọ sí etí odò Kebari níbi tí àwọn ìgbèkùn ń gbé ni Teli-Abibu. Níbẹ̀ níbi tí wọ́n ń gbé, mo jókòó láàrín wọn pẹ̀lú ìyanu, fún ọjọ́ méje.
16 Thuutha wa mĩthenya ĩyo mũgwanja-rĩ, kiugo kĩa Jehova gĩkĩnginyĩrĩra, ngĩĩrwo atĩrĩ,
Lẹ́yìn ọjọ́ méje, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
17 “Mũrũ wa mũndũ, nĩngũtuĩte mũrangĩri wa andũ a nyũmba ya Isiraeli, nĩ ũndũ ũcio igua kiugo kĩrĩa ngwaria, na ũmeere ũrĩa ndĩramakaania.
“Ọmọ ènìyàn, mo ti fi ọ́ ṣe olùṣọ́ fún ilé Israẹli; nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ tí mo ń sọ, fún wọn ní ìkìlọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.
18 Rĩrĩa ngwĩra mũndũ mwaganu atĩrĩ, ‘Ti-itherũ, nĩũgaakua,’ nawe wage kũmũkaania, kana kũmwarĩria atigane na mĩthiĩre yake ya waganu nĩguo ahonokie muoyo wake-rĩ, mũndũ ũcio mwaganu nĩagaakua nĩ ũndũ wa mehia make, nawe nĩwe ngooria thakame yake.
Bí mo bá sọ fún ènìyàn búburú pé, dájúdájú, ‘Ìwọ yóò kú,’ tí ìwọ kò sì kìlọ̀ fún ènìyàn búburú yìí láti dáwọ́ ìwà ibi rẹ̀ dúró, kí o sì gba ẹ̀mí rẹ̀ là, ènìyàn búburú náà yóò kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ní ọwọ́ rẹ ni èmi yóò ti béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
19 No wee ũngĩkaania mũndũ ũcio mwaganu, nake arege kũgarũrũka atigane na waganu wake kana mĩthiĩre yake mĩũru-rĩ, we nĩagaakua nĩ ũndũ wa mehia make; no wee-rĩ, nĩũgaakorwo ũhonoketie muoyo waku.
Ṣùgbọ́n bí o bá kìlọ̀ fún ènìyàn búburú, tí ó kọ̀ tí kò fi ìwà búburú rẹ̀ sílẹ̀, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; ṣùgbọ́n ọrùn tìrẹ ti mọ́.
20 “Ningĩ-rĩ, mũndũ mũthingu angĩgarũrũka atigane na ũthingu wake eke maũndũ mooru, na niĩ ndĩmwĩkĩrĩre mũhĩnga mbere yake-rĩ, nĩagaakua. Kũngĩkorwo ndwamũkaanirie-rĩ, nĩagaakua nĩ ũndũ wa mehia make. Maũndũ marĩa aneeka ma ũthingu matikaaririkanwo, nawe nĩwe ngooria thakame yake.
“Bákan náà, bí olódodo kan bá yípadà, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àìṣòdodo, tí mo sì fi ohun ìkọ̀sẹ̀ sí ọ̀nà rẹ̀, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Nítorí pé ìwọ kọ̀ láti kìlọ̀ fún un, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, a ó gbàgbé gbogbo ìwà rere tó ti hù tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n ní ọwọ́ rẹ̀ ni èmi yóò ti béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
21 No rĩrĩ, wee ũngĩkaania mũndũ ũcio mũthingu atige kwĩhia, nake aage kwĩhia-rĩ, ti-itherũ nĩagatũũra muoyo nĩ ũndũ nĩathikĩrĩirie ũguo wamũkaanirie, nawe-rĩ, nĩũgaakorwo ũhonoketie muoyo waku.”
Ṣùgbọ́n bí o bá kìlọ̀ fún olódodo tó sì dáwọ́ ìwà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ dúró, dájúdájú òun yóò yè nítorí pé ó ti gba ìkìlọ̀, ọrùn tìrẹ sì mọ́.”
22 Guoko kwa Jehova kwarĩ igũrũ rĩakwa ndĩ o kũu, nake akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Ũkĩra ũthiĩ werũ-inĩ ũrĩa mwaraganu, na kũu nĩkuo ngũkwarĩria.”
Ọwọ́ Olúwa wà lára mi níbẹ̀, ó sì wí fún mi pé, “Dìde, lọ sí ibi tí ó tẹ́jú, èmi yóò sì bá ọ sọ̀rọ̀ níbẹ̀.”
23 Nĩ ũndũ ũcio ngĩũkĩra ngĩthiĩ werũ-inĩ ũcio mwaraganu, naguo riiri wa Jehova warũngiĩ kuo, ũhaana ta riiri ũrĩa ndoonete hũgũrũrũ-inĩ cia Rũũĩ rwa Kebari, na niĩ ngĩĩgũithia, ngĩturumithia ũthiũ thĩ.
Mo sì dìde, mo lọ sí ibi tí ó tẹ́jú. Ògo Olúwa dúró níbẹ̀, ó dàbí irú ògo tí mo rí létí odò Kebari, mo sì dojúbolẹ̀.
24 Hĩndĩ ĩyo Roho agĩtoonya thĩinĩ wakwa, akĩnjoya akĩndũgamia na magũrũ makwa. Akĩnjarĩria, akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Thiĩ ũkehingĩre gwaku nyũmba.
Nígbà náà ni Ẹ̀mí wọ inú mi, tí ó sì tún gbé mi dúró. Ó sì wí fún mi pé, “Lọ, ti ara rẹ mọ́ inú ilé rẹ
25 No rĩrĩ, wee mũrũ-wa-mũndũ, nĩmagakuoha na mĩhĩndo; ũgaikara ũrĩ muohe nĩguo ndũkoime ũthiĩ gatagatĩ-inĩ ka andũ.
ṣùgbọ́n ìwọ, ọmọ ènìyàn, wọn yóò fi okùn dè ọ́ mọ́lẹ̀; dé ibi pé ìwọ kò ní í le rìn káàkiri láàrín àwọn ènìyàn.
26 Niĩ nĩngatũma rũrĩmĩ rwaku rũnyiitane na karakara nĩguo ũkire wage kũmanegenia, o na akorwo o nĩ andũ a nyũmba ya ũremi.
Èmi yóò mú kí ahọ́n rẹ lẹ̀ mọ́ àjà ẹnu rẹ, tó bẹ́ẹ̀ ti ìwọ yóò wà ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́. Ìwọ kò sì ní lè bá wọn wí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ilé ní wọn.
27 No rĩrĩa ngaakwarĩria-rĩ, nĩngakũhingũra kanua, nawe nĩũkameera ũũ, ‘Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ.’ Ũrĩa wothe ũngĩthikĩrĩria nĩathikĩrĩrie, nake ũrĩa wothe ũkũrega nĩarege; nĩgũkorwo o nĩ andũ a nyũmba ya ũremi.
Ṣùgbọ́n nígbà tí èmi bá bá ọ sọ̀rọ̀, Èmi yóò ṣí ọ lẹ́nu, ìwọ yóò sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí.’ Ẹni tó bá fẹ́ kí ó gbọ́, ẹni tó bá fẹ́ kọ̀, kó kọ̀ nítorí ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n.

< Ezekieli 3 >