< Ezekieli 28 >
1 Kiugo kĩa Jehova nĩkĩanginyĩrĩire, ngĩĩrwo atĩrĩ:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
2 “Mũrũ wa mũndũ, ĩra mũnene wa Turo atĩrĩ, ‘Mwathani Jehova oigĩte ũũ: “‘Nĩ ũndũ ngoro yaku nĩĩyambararĩtie, uugaga atĩrĩ, “Niĩ ndĩ ngai; njikaragĩra gĩtĩ gĩa ũthamaki kĩa ngai kũu iria gatagatĩ.” No wee ũrĩ mũndũ na ndũrĩ ngai, o na watuĩka wĩciiragia atĩ ũrĩ mũũgĩ o ta ngai.
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún ọmọ-aládé Tire pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí tí ọkàn rẹ gbé sókè sí mi, ìwọ wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run; Èmi jókòó sí orí ìtẹ́ òrìṣà, ní àárín gbùngbùn Òkun.” Ṣùgbọ́n ènìyàn ni ọ́, kì i ṣe òrìṣà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ rò pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
3 Wee-rĩ, ũkĩrĩ mũũgĩ gũkĩra Danieli? Anga gũtirĩ hitho ũngĩhithwo?
Ìwọ gbọ́n ju Daniẹli lọ bí? Ṣé kò sí àṣírí kan tí ó pamọ́ fún ọ?
4 Tondũ wa ũũgĩ waku na ũmenyo waku, nĩwĩgĩĩrĩire na ũtonga, na ũkehaĩra thahabu na betha mĩthiithũ-inĩ yaku.
Pẹ̀lú ọgbọ́n àti ìmọ̀ rẹ, ìwọ tí jèrè ọrọ̀ fún ara rẹ, àti àkójọpọ̀ wúrà àti fàdákà, nínú àwọn ilé ìṣúra rẹ.
5 Tondũ wa ũmenyi waku mũnene wa wonjoria, nĩwĩongereire ũtonga, na nĩ tondũ wa ũtonga waku, ngoro yaku nĩĩgĩĩte na mwĩtĩĩo.
Nípa ọgbọ́n rẹ ńlá àti nípa òwò rẹ, ìwọ ti sọ ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, àti nítorí ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, ọkàn rẹ gbé sókè, nítorí ọrọ̀ rẹ.
6 “‘Nĩ ũndũ ũcio Mwathani Jehova ekuuga ũũ: “‘Tondũ wĩciiragia ũrĩ mũũgĩ, ũkohĩga o ta ngai-rĩ,
“‘Nítorí náà èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí pé ìwọ rò pé o gbọ́n, pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
7 nĩngũkũrehithĩria andũ a kũngĩ magũũkĩrĩre, nacio nĩ ndũrĩrĩ iria itarĩ tha o na hanini; nĩigacomora hiũ ciacio cia njora ciũkĩrĩre ũthaka waku na ũũgĩ waku, na itheecange riiri waku mũcangararu.
Èmi yóò mú kí àwọn àjèjì dìde sí ọ, ẹlẹ́rù nínú àwọn orílẹ̀-èdè; wọn yóò yọ idà wọn sí ọ, ẹwà rẹ àti ọgbọ́n rẹ, wọn yóò sì ba dídán rẹ̀ jẹ́.
8 Nĩmagagũikũrũkia magũkinyie irima-inĩ, na nĩũgaakua gĩkuũ kĩa ũhinya kũu gatagatĩ ka iria.
Wọn yóò mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá sínú ihò, ìwọ yóò sì kú ikú gbígbóná, àwọn tí a pa ní àárín Òkun.
9 Hĩndĩ ĩyo nĩũkoiga atĩ, “Niĩ ndĩ ngai,” ũrĩ mbere ya acio magaakũũraga? Ũgaakorwo ũrĩ o mũndũ, no ti ngai, ũrĩ moko-inĩ ma acio magaakũũraga.
Ṣé ìwọ yóò wá wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run,” ní ojú àwọn tí ó pa ọ́? Ìwọ yóò jẹ́ ènìyàn, kì í ṣe Ọlọ́run, ní ọwọ́ àwọn ti yóò pa ọ́.
10 Ũgaakua gĩkuũ ta kĩa andũ arĩa mataruaga, moko-inĩ ma andũ a kũngĩ. Nĩ niĩ njugĩte ũguo, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.’”
Ìwọ yóò kú ikú aláìkọlà, ní ọwọ́ àwọn àjèjì. Èmi ni ó ti sọ ọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
11 Kiugo kĩa Jehova nĩkĩanginyĩrĩire, ngĩĩrwo atĩrĩ:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
12 “Mũrũ wa mũndũ, ambĩrĩria macakaya makoniĩ mũthamaki wa Turo, ũmwĩre atĩrĩ: ‘Mwathani Jehova ekuuga ũũ: “‘Wee warĩ kĩonereria kĩa ũkinyanĩru, ũkaiyũrwo nĩ ũũgĩ, na ũgathakara o biũ.
“Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún sórí ọba Tire kí ó sì sọ fún un pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ìwọ jẹ́ àpẹẹrẹ ìjẹ́pípé náà, o kún fún ọgbọ́n, o sì pé ní ẹwà.
13 Wee watũũrĩte Edeni, mũgũnda wa Ngai; wagemetio na kahiga gothe ka goro ta: wakiki ĩrĩa ndune, na yakuti ĩrĩa ya rangi wa ngoikoni, na arimathi, na thumarati ĩrĩa theru, na onigithi, na njathibi, na yakuti ĩrĩa ya rangi wa bururu, na thumarati ĩrĩa nduru, na baregethu. Magemio maku maathondeketwo na thahabu; mũthenya ũrĩa wee wombirwo noguo maahaarĩirio.
Ìwọ ti wà ní Edeni, ọgbà Ọlọ́run; onírúurú òkúta oníyebíye ni ìbora rẹ; sardiu, topasi àti diamọndi, berili, óníkìsì, àti jasperi, safire, emeradi, turikuose, àti karbunkili, àti wúrà, ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ àti àwọn òkè rẹ ní a dà, láti ara wúrà, ní ọjọ́ tí á dá ọ ní a pèsè wọn.
14 Waitĩrĩirio maguta ũtuĩke ta kerubi mũgitanĩri, na nĩkĩo ndaakwamũrire. Wee warĩ kĩrĩma-igũrũ kĩrĩa gĩtheru kĩa Ngai; waceeragĩra mahiga-inĩ ma mwaki.
A fi àmì òróró yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí olùtọ́jú kérúbù, torí èyí ni mo fi yàn ọ́. Ìwọ wà lórí òkè mímọ́ Ọlọ́run; ìwọ rìn ni àárín òkúta a mú bí iná.
15 Ndwarĩ na ũcuuke mĩthiĩre-inĩ yaku, kuuma mũthenya ũrĩa wombirwo, nginya rĩrĩa waganu wonekire thĩinĩ waku.
Ìwọ pé ní ọ̀nà rẹ, láti ọjọ́ tí a ti dá ọ, títí a fi rí àìṣedéédéé ní inú rẹ.
16 Tondũ wa wonjoria waku kũingĩha, nawe ũkĩĩhia. Nĩ ũndũ ũcio ngĩkũrutũrũra kuuma kĩrĩma-inĩ kĩa Ngai ũnyararĩkĩte, na wee kerubi, wee ũgitanagĩra, ngĩkũingata wehere mahiga-inĩ macio ma mwaki.
Nípa ìtànkálẹ̀ òwò rẹ, ìwọ kún fún ìwà ipá; ìwọ sì dẹ́ṣẹ̀. Nítorí náà ni mo ṣe sọ ọ nù, bí ohun àìlọ́wọ̀ kúrò lórí òkè Ọlọ́run. Èmi sì pa ọ run, ìwọ kérúbù, tí ó bọ́ kúrò ní àárín òkúta a mú bí iná.
17 Ngoro yaku nĩyanyiitirwo nĩ mwĩtĩĩo nĩ ũndũ wa ũthaka waku, nawe ũgĩthũkia ũũgĩ waku nĩ ũndũ wa riiri waku. Nĩ ũndũ ũcio ngĩgũikia thĩ; ndaagũtuire kĩnyararo ũrĩ mbere ya athamaki.
Ọkàn rẹ gbéraga, nítorí ẹwà rẹ. Ìwọ sì ba ọgbọ́n rẹ jẹ́, nítorí dídára rẹ. Nítorí náà mo le ọ sórí ayé; mo sọ ọ di awòojú níwájú àwọn ọba.
18 Nĩ ũndũ wa mehia maku maingĩ na wonjoria ũtarĩ wa ma, nĩũthaahĩtie kũndũ gwaku kũrĩa-gũtheru. Nĩ ũndũ ũcio ngĩtũma mwaki uume thĩinĩ waku, naguo ũgĩkũniina, na ngĩgũtua mũhu hau thĩ, maitho-inĩ ma arĩa meeroragĩra.
Nípa ẹ̀ṣẹ̀ púpọ̀ rẹ àti òwò àìṣòótọ́ rẹ, ìwọ ti ba àwọn ibi mímọ́ rẹ jẹ́. Nítorí náà mo mú kí iná jáde wá, láti inú rẹ, yóò sì jó ọ run, èmi yóò sì sọ ọ́ di eérú lórí ilẹ̀, lójú gbogbo àwọn tí ó ń wò ọ́.
19 Ndũrĩrĩ ciothe iria ciakũũĩ, nĩcigegetio nĩwe; nĩũkinyĩte mũthia wa kũguoyohithia, nawe ndũgacooka kuonwo rĩngĩ.’”
Gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó mọ̀ ọ́n, ní ẹnu ń yà sí ọ; ìwọ yóò sì jẹ́ ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́ láéláé.’”
20 Kiugo kĩa Jehova nĩkĩanginyĩrĩire, ngĩĩrwo atĩrĩ:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
21 “Mũrũ wa mũndũ, erekeria ũthiũ waku Sidoni; rĩrathĩre ũhoro wa kũrĩũkĩrĩra,
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú sí Sidoni; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ sí i,
22 ũrĩĩre atĩrĩ: ‘Mwathani Jehova ekuuga ũũ: “‘Wee Sidoni, nĩngũgũũkĩrĩra, na nĩngegĩĩra na riiri thĩinĩ waku. Nao nĩmakamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova, hĩndĩ ĩrĩa ngaarĩrehere iherithia, na ndĩĩonanie atĩ ndĩ mũtheru thĩinĩ warĩo.
kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Sidoni, a ó sì ṣe mí lógo láàrín rẹ. Wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú ìdájọ́ mi ṣẹ nínú rẹ, tí a sì yá mí sí mímọ́ nínú rẹ.
23 Nĩngarĩrehithĩria mũthiro, na ndũme thakame ĩtherere njĩra-inĩ ciarĩo. Arĩa oorage nĩmakaagũa thĩinĩ warĩo, naruo rũhiũ rwa njora rũrĩũkĩrĩre mĩena yothe. Hĩndĩ ĩyo nĩmakamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova.
Èmi yóò sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn sínú rẹ, èmi yóò sì mú kí ẹ̀jẹ̀ sàn ní ìgboro rẹ, ẹni ti á pa yóò ṣubú ní àárín rẹ, pẹ̀lú idà lára rẹ ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, nígbà náà wọn yóò mọ̀ wí pé èmi ni Olúwa.
24 “‘Gũtirĩ hĩndĩ ĩngĩ andũ a Isiraeli makaagĩa na thũ mariganĩtie nacio, nĩguo ituĩke congʼe ũrĩ ruo, na mĩigua mĩũgĩ. Hĩndĩ ĩyo nĩmakamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Mwathani Jehova.
“‘Kì yóò sì ṣí ẹ̀gún tí ń gun ni ní ilẹ̀ Israẹli mọ́, tàbí ẹ̀gún bíbani nínú jẹ́ ti gbogbo àwọn tí wọn wà ní àyíká wọn, tí wọ́n sì ń fi ojú yẹpẹrẹ wò wọ́n, nígbà náà ni wọn yóò mọ́ wí pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.
25 “‘Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Hĩndĩ ĩrĩa ngaacookanĩrĩria andũ a Isiraeli moime ndũrĩrĩ-inĩ kũrĩa maahurunjirwo, hĩndĩ ĩyo nĩngonania maitho-inĩ ma ndũrĩrĩ atĩ ndĩ mũtheru ndĩ thĩinĩ wao. Hĩndĩ ĩyo nĩmagatũũra bũrũri wao kĩũmbe ũrĩa ndaaheire ndungata yakwa Jakubu.
“‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí èmi yóò bá sa àwọn ènìyàn Israẹli jọ kúrò ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti fọ́nká sí, tí a ó sì yà mí sí mímọ́ láàrín wọn lójú àwọn aláìkọlà. Nígbà náà ni wọn yóò gbé ní ilẹ̀ àwọn tìkálára wọn, èyí tí mo fún ìránṣẹ́ mi Jakọbu.
26 Magaatũũra kuo marĩ agitĩre, na nĩmagaka nyũmba, na mahaande mĩgũnda ya mĩthabibũ; nao magaatũũra marĩ agitĩre rĩrĩa ngaarehe iherithia kũrĩ andũ arĩa othe mariganĩtie nao arĩa maamacambagia. Hĩndĩ ĩyo nĩmakamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova Ngai wao.’”
Wọn yóò sì máa gbé ní inú rẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì kọ́lé, wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà; nítòótọ́ wọn yóò wà ní ìbàlẹ̀ àyà, nígbà tí èmi bá ti mú ìdájọ́ mi ṣẹ̀ sí ara àwọn tí ń ṣátá wọn ní gbogbo àyíká wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.’”