< Ezekieli 24 >

1 Mwaka-inĩ wa kenda, mũthenya wa ikũmi wa mweri wa ikũmi, kiugo kĩa Jehova nĩkĩanginyĩrĩire, ngĩĩrwo atĩrĩ:
Ní ọdún kẹsànán, oṣù kẹwàá, ọjọ́ kẹwàá, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 “Mũrũ wa mũndũ, andĩka mũthenya wa ũmũthĩ nĩ tarĩki ciigana, o ũyũ wa ũmũthĩ, tondũ mũthenya ũyũ wa ũmũthĩ mũthamaki wa Babuloni nĩarigiicĩirie Jerusalemu.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ọjọ́ náà sílẹ̀, ọjọ́ náà gan an, nítorí ọba Babeli náà ti da ojú ti Jerusalẹmu ní ọjọ́ yìí gan an.
3 Arĩria andũ aya a nyũmba ĩno nemi na ngerekano, ũmeere atĩrĩ, ‘Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ: “‘Hagĩra nyũngũ ya kũruga; mĩhagĩre na ũmĩitĩrĩre maaĩ.
Sì pa òwe yìí fún ilé ọlọ́tẹ̀ náà, sọ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Gbé ìkòkò ìdáná náà ka iná, gbé e ka iná kí o sì da omi sí i nínú.
4 Ĩkĩra icunjĩ cia nyama thĩinĩ wayo, icunjĩ ciothe iria njega, ta cia kũgũrũ na guoko. Mĩiyũrie na mahĩndĩ marĩa mega mũno;
Kó àwọn ègé ẹran tí a gé náà sínú rẹ̀, gbogbo àwọn ègé ẹran tí ó tóbi, itan àti apá. Kó àwọn egungun tí ó dára jù sínú rẹ̀,
5 oya nyamũ ĩrĩa njega mũno rũũru-inĩ. Igĩrĩra ngũ rungu rwayo nĩ ũndũ wa mahĩndĩ; reke ĩtherũke, namo mahĩndĩ mahĩĩre o kũu thĩinĩ wayo.
mú àwọn tí ó jọjú nínú agbo ẹran. Kó àwọn egungun sí abẹ́ ẹ rẹ̀; sì jẹ́ kí ó hó dáradára sì jẹ́ kí àwọn egungun náà bọ̀ nínú rẹ̀.
6 “‘Nĩgũkorwo Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ: “‘Kaĩ itũũra rĩu inene rĩitithagia thakame rĩrĩ na haro-ĩ, o na nyũngũ ĩyo ĩrĩ na mũcura, ĩrĩa gĩkũrĩ kĩayo gĩtangĩthira! Mĩonorie kĩrungʼo, o kĩrungʼo, itegũcuukĩrwo mĩtĩ.
Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà, fún ìkòkò náà tí èérí rẹ̀ wà nínú rẹ̀, tí èérí kò dà kúrò lójú rẹ̀! Mú ẹran náà jáde ní ekìrí ekìrí má ṣe ṣà wọ́n mú.
7 “‘Nĩgũkorwo thakame ĩrĩa rĩitithĩtie ĩrĩ o thĩinĩ warĩo: Rĩamĩitire o kũu rwaro-inĩ rwa ihiga itheri; rĩtiamĩitire tĩĩri-inĩ, harĩa rũkũngũ rũngĩamĩthikire.
“‘Nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ó ta sílẹ̀ wà ní àárín rẹ̀; à á sí orí àpáta kan lásán kò dà á sí orí ilẹ̀, níbi ti erùpẹ̀ yóò ti bò ó.
8 Nĩgeetha njarahũre mangʼũrĩ na ndĩĩrĩhĩrie-rĩ, ndaitire thakame yarĩo rwaro-inĩ rwa ihiga itheri, nĩguo ndĩgathikwo.
Láti bá à le jẹ́ kí ìbínú kí ó dé láti gbẹ̀san mo da ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sí orí àpáta kan lásán, kí o ma bà á wà ni bíbò.
9 “‘Nĩ ũndũ ũcio, ũũ nĩguo Mwathani Jehova ekuuga: “‘Kaĩ itũũra rĩu inene rĩitithagia thakame rĩrĩ na haaro-ĩ! O na niĩ nĩngacookanĩrĩria ngũ hĩba ndaaya na igũrũ.
Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà! Èmi pàápàá yóò jẹ́ kí òkìtì iná náà tóbi.
10 Nĩ ũndũ ũcio iganĩrĩra ngũ, na wakie mwaki. Ruga nyama icio wega, na ũtukanie na indo cia gũcamia wega; namo mahĩndĩ ũreke macure.
Nítorí náà kó igi náà jọ sí i, kí o sì fi iná sí i. Ṣe ẹran náà dáradára, fi tùràrí dùn ún; kí o sì jẹ́ kí egungun náà jóná.
11 Ningĩ ũhagĩre nyũngũ ĩyo theri makara-inĩ, nginya ĩhiũhe na gĩcango kĩayo gĩtunĩhe, nĩguo gĩko kĩayo gĩtweke, na gĩkũrĩ kĩayo gĩcinwo, gĩthire.
Lẹ́yìn náà gbé òfìfo ìkòkò náà lórí ẹyin iná kí idẹ rẹ̀ lè gbóná, kí ó lè pọ́n àti ki ìfófó rẹ̀ le di yíyọ́ nínú rẹ̀ kí èérí rẹ̀ le jó dànù.
12 Nĩkĩremete njĩra ciothe; gĩkũrĩ kĩu kĩayo ti kĩrute, o na gĩacinwo na mwaki.
Ó ti ba gbogbo akitiyan jẹ: èérí rẹ̀ kò sì jáde kúrò lára rẹ̀, èérí náà gan an yóò wà nínú iná.
13 “‘Rĩu-rĩ, gĩko gĩaku nĩ ũũra-thoni. Tondũ ngeretie gũgũtheria, no wee ndũngĩthera gĩko gĩaku, wee ndũngĩthera rĩngĩ nginya mangʼũrĩ makwa ma gũgũũkĩrĩra makahũahũa.
“‘Nísinsin yìí èérí rẹ̀ ni ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wà. Nítorí mo gbìyànjú láti wẹ̀ ọ́ mọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò sì mọ́ kúrò nínú ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, a kì yóò sì tún wẹ̀ ọ mọ́ kúrò nínú èérí rẹ, títí èmi yóò fi jẹ́ kí ìbínú mi balẹ̀ sórí rẹ̀.
14 “‘Niĩ Jehova nĩnjarĩtie. Ihinda nĩikinyu njĩke ũndũ. Ndikerigĩrĩria; na ndikaiguanĩra tha kana ndĩĩricũkwo. Ũgaatuĩrwo ciira kũringana na mĩtugo yaku, na ciĩko ciaku, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.’”
“‘Èmi Olúwa ni ó sọ ọ́, yóò sì ṣe, èmi yóò sì ṣe é. Èmi kì yóò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá sí i, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọkàn mi padà; gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ, ni wọn yóò dá ọ lẹ́jọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
15 Kiugo kĩa Jehova nĩkĩanginyĩrĩire, ngĩĩrwo atĩrĩ:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá pé:
16 “Mũrũ wa mũndũ, atĩrĩ, ndĩ hakuhĩ gũkwehereria kĩrĩa gĩkenagia maitho maku mũno na igũtha o rĩmwe. No rĩrĩ, ndũgacakae kana ũrĩre, o na kana ũite maithori.
“Ọmọ ènìyàn, kíyèsi i, mo mú ìfẹ́ ojú rẹ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, nípa lílù kan. Ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ gbààwẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sọkún, bẹ́ẹ̀ ni omijé ojú rẹ kò gbọdọ̀ kán sílẹ̀.
17 Caaya ũkirĩte; tiga kũrĩrĩra ũcio ũkuĩte. Ikara wĩohete kĩremba mũtwe na wĩkĩrĩte iraatũ magũrũ; ndũkehumbĩre kanua kana ũrĩe irio cia mũtugo wa hĩndĩ ya macakaya.”
Má ṣe sọkún, má ṣe gbààwẹ̀ fún òkú. Wé ọ̀já sí orí rẹ, sì bọ bàtà sí ẹsẹ̀ rẹ, má ṣe bo ètè ìsàlẹ̀ rẹ, ma ṣe jẹ oúnjẹ tí àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.”
18 Nĩ ũndũ ũcio ngĩrooka kwarĩria andũ rũciinĩ, na hwaĩ-inĩ ũcio mũtumia wakwa agĩkua. Rũciinĩ rũrũ rũngĩ ngĩĩka o ta ũrĩa ndaathĩtwo njĩke.
Báyìí ni mo sọ̀rọ̀ fún àwọn ènìyàn ní òwúrọ̀, ní àṣálẹ́ ìyàwó mi sì kú. Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo ṣe bí a ti pàṣẹ fún mi.
19 Nao andũ acio makĩnjũũria atĩrĩ, “Kaĩ ũtangĩtwĩra ũhoro wa maũndũ maya na ũrĩa matũkoniĩ?”
Lẹ́yìn náà àwọn ènìyàn bi mí léèrè pé, “Ṣe o kò ni sọ fún wa ohun ti nǹkan wọ̀nyí ní láti ṣe pẹ̀lú wa?”
20 Nĩ ũndũ ũcio ngĩmeera atĩrĩ, “Kiugo kĩa Jehova nĩkĩanginyĩrĩire, ngĩĩrwo atĩrĩ:
Mo sọ báyìí fún wọn pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
21 Ĩra andũ a nyũmba ya Isiraeli atĩrĩ, ‘Ũũ nĩguo Mwathani Jehova ekuuga: Ngirie gũthaahia handũ-hakwa-harĩa-haamũre, hau gĩikaro kĩa hinya kĩrĩa mwĩtĩĩaga nakĩo, o kĩu gĩkenagia maitho manyu, kĩrĩa mwendete. Ariũ na aarĩ anyu arĩa mwatigire na thuutha makaaniinwo na rũhiũ rwa njora.
Sọ fún ilé Israẹli, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, èmi yóò sọ ibi mímọ́ mi di ibi àìmọ́ tayọ agbára yín, ìfẹ́ ojú yín, ìkáàánú yín, àti ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin tí ẹ̀yin fi sílẹ̀ sẹ́yìn yóò ṣubú nípa idà.
22 Na inyuĩ nĩmũgeeka o ta ũguo niĩ njĩkĩte. Mũtikehumbĩra kanua kana mũrĩe irio cia mũtugo wa hĩndĩ ya macakaya.
Ẹyin yóò sì ṣe bí mo ti ṣe. Ẹ̀yin kì yóò bo ìsàlẹ̀ ojú yín tàbí jẹ oúnjẹ ti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.
23 Nĩmũgaikara mwĩohete iremba mĩtwe na mwĩkĩrĩte iraatũ magũrũ. Mũtigacakaya kana mũrĩre, no nĩmũkahwererekera tondũ wa mehia manyu na mũcaayage thĩinĩ wanyu.
Ẹ̀yin yóò fi àwọn ọ̀já wé àwọn orí yín àti àwọn bàtà ni ẹsẹ̀ yín, ẹ̀yin kì yóò ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò ṣòfò dànù nítorí àwọn àìṣedéédéé yín, ẹ̀yin yóò sì máa kérora láàrín ara yín.
24 Ezekieli agaatuĩka rũũri harĩ inyuĩ; mũgeeka o ta ũguo we ekĩte. Hĩndĩ ĩrĩa maũndũ macio mageekĩka-rĩ, nĩrĩo mũkaamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Mwathani Jehova.’
Esekiẹli yóò jẹ àmì fún un yín; ẹ̀yin yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe. Nígbà tí èyí bá ṣẹlẹ̀, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’
25 “Nawe mũrũ wa mũndũ, mũthenya ũrĩa ngeeheria gĩikaro kĩao kĩa hinya, gĩkeno kĩao na riiri wao, na kĩndũ kĩrĩa gĩkenagia maitho mao, na wendi wa ngoro ciao, na aanake na airĩtu ao o nao,
“Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ, Ọmọ ènìyàn, kì yóò ha jẹ́ pé, ní ọjọ́ náà, nígbà ti mo bá gba agbára wọn, ayọ̀ wọn àti ògo wọn, ìfẹ́ ojú wọn, ohun tí wọn gbé ọkàn wọn lé, àti àwọn ọmọ ọkùnrin wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ obìnrin wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn,
26 mũthenya ũcio mũndũ ũũrĩte kwao nĩagakũrehera ũhoro.
ní ọjọ́ náà ẹni tí ó bá sálà yóò tọ̀ ọ́ wá láti sọ ìròyìn náà fún ọ.
27 Hĩndĩ ĩyo kanua gaku nĩgagatumũka; nĩũkaria nake, na ndũgacooka gũkira. Nĩ ũndũ ũcio wee ũgaatuĩka rũũri harĩo, nao nĩmakamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova.”
Ní ọjọ́ náà ẹnu rẹ yóò sì ṣí; ìwọ yóò sọ̀rọ̀, ìwọ kì yóò sì yadi mọ́. Báyìí ìwọ yóò jẹ́ àmì fún wọn; wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ní Olúwa.”

< Ezekieli 24 >