< Ezekieli 14 >
1 Athuuri amwe a Isiraeli nĩmookire harĩ niĩ, magĩikara thĩ hau mbere yakwa.
Díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá sọ́dọ̀ mi, wọ́n sì jókòó níwájú mi.
2 Hĩndĩ ĩyo kiugo kĩa Jehova gĩkĩnginyĩrĩra, ngĩĩrwo atĩrĩ,
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
3 “Mũrũ wa mũndũ, andũ aya nĩmeigĩire mĩhianano ngoro-inĩ ciao, na makeigĩra mĩhĩnga ya waganu mbere ya maitho mao. Nĩnjagĩrĩirwo kũreka matuĩrie ũndũ o na ũrĩkũ harĩ niĩ?
“Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ti gbé òrìṣà kalẹ̀ sínú ọkàn wọn, wọ́n sì gbé àwọn ohun tó lè mú wọn ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú wọn; Èmi yóò ha jẹ́ kí wọ́n béèrè lọ́wọ́ mi rárá bí?
4 Nĩ ũndũ ũcio maarĩrie, ũmeere ũũ, ‘Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ: Hĩndĩ ĩrĩa Mũisiraeli o wothe angĩgĩa mĩhianano ngoro-inĩ yake, na eigĩre waganu wa kũmũhĩngithia mbere ya maitho make, angĩcooka athiĩ harĩ mũnabii-rĩ, niĩ Jehova nĩ niĩ mwene ngaamũcookeria ũhoro kũringana na ũrĩa ũhooi wake wa mĩhianano ũigana,
Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tó gbé òrìṣà sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun ìkọ̀sẹ̀ síwájú rẹ̀, tí ó sì wá sọ́dọ̀ wòlíì, Èmi Olúwa fúnra mi ni yóò dá ẹni tí ó wa lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà ìbọ̀rìṣà rẹ.
5 Ngeeka ũguo nĩguo ndĩnyiitĩre ngoro cia andũ a Isiraeli rĩngĩ, arĩa othe mandiganĩirie nĩ ũndũ wa mĩhianano ĩyo yao.’
Èmi yóò ṣe èyí láti gba ọkàn àwọn ará Israẹli tó ti tẹ̀lé òrìṣà wọn lọ padà sí ọ̀dọ̀ mi.’
6 “Nĩ ũndũ ũcio ĩra andũ a nyũmba ya Isiraeli atĩrĩ, ‘Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ: Mwĩrirei! Garũrũkai mũtigane na mĩhianano ĩyo yanyu, na mũregane na maũndũ marĩa mothe mwĩkaga marĩ magigi!
“Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ẹ ronúpìwàdà! Ẹ yípadà kúrò lọ́dọ̀ òrìṣà yín, kí ẹ̀yin sì kọ gbogbo ìwà ìríra yín sílẹ̀!
7 “‘Hĩndĩ ĩrĩa Mũisiraeli o wothe, kana mũndũ wa kũngĩ ũrĩa ũtũũraga Isiraeli angĩehera harĩ niĩ, na eigĩre mĩhianano ngoro-inĩ yake, na agĩe na waganu wa kũmũhĩngithia mbere ya maitho make, angĩcooka athiĩ harĩ mũnabii agatuĩrie ũhoro kũrĩ niĩ-rĩ, niĩ Jehova nĩ niĩ mwene ngaamũcookeria ũhoro.
“‘Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tàbí àlejò tó ń gbé ní ilẹ̀ Israẹli, bá ya ara rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi, tó gbé òrìṣà rẹ̀ sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun tó mú ni ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú rẹ, lẹ́yìn èyí tó tún lọ sọ́dọ̀ wòlíì láti béèrè nǹkan lọ́wọ́ mi! Èmi Olúwa fúnra ara mi ní èmi yóò dá a lóhùn.
8 Nĩngatũma ũthiũ wakwa ũũmĩre mũndũ ũcio, na ndũme atuĩke kĩonereria harĩ arĩa angĩ, o na ndũme atuĩke wa kuunagwo thimo. Nĩngamweheria harĩ andũ akwa. Hĩndĩ ĩyo nĩmũkamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova.
Èmi yóò lòdì si irú ọkùnrin bẹ́ẹ̀ lọ́nà òdì, Èmi yóò sì fi i ṣe àmì àti òwe. Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi. Nígbà náà, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
9 “‘Mũnabii angĩkaaheenererio nĩguo aarie ũhoro wakwa, niĩ Jehova nĩ niĩ ngaakorwo heenereirie mũnabii ũcio, na nĩngamũtambũrũkĩria guoko gwa kũmũũkĩrĩra, ndĩmũniine ehere gatagatĩ-inĩ ka andũ akwa a Isiraeli.
“‘Bí wọ́n bá sì tan wòlíì náà láti sọtẹ́lẹ̀, Èmi Olúwa ló tan wòlíì náà, Èmi yóò nawọ́ sí i, èmi yóò sì pa á run kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi Israẹli.
10 Andũ acio nĩmakaherithĩrio wĩhia wao; mũnabii ũcio agaatuuo mwĩhia o ta mũndũ ũcio ũtuĩrĩtie ũhoro harĩ we.
Wọn yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wọn—ìjìyà kan náà là ó fún wòlíì àti ẹni tó lọ béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀.
11 Hĩndĩ ĩyo andũ a Isiraeli matigacooka kũhĩtia njĩra mehere harĩ niĩ, kana macooke gwĩthaahia na mehia macio mao mothe. Nĩmagatuĩka andũ akwa, na niĩ nduĩke Ngai wao, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.’”
Kí ilé Israẹli má ba à ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi mọ, kí wọ́n má ba à fi gbogbo ìrékọjá ba ara wọn jẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n kí wọ́n le jẹ́ ènìyàn mi, kí Èmi náà sì le jẹ́ Ọlọ́run wọn, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
12 Kiugo kĩa Jehova nĩkĩanginyĩrĩire, ngĩĩrwo atĩrĩ:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
13 “Mũrũ wa mũndũ, bũrũri ũngĩnjĩhĩria nĩ ũndũ wa kwaga kwĩhokeka, na ndambũrũkie guoko ndĩũũkĩrĩre, na ndĩũniinĩre kĩhumo kĩa irio, na ndĩũrehere ngʼaragu, na njũrage andũ aguo na mahiũ mao,
“Ọmọ ènìyàn bí orílẹ̀-èdè kan bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi nípa ìwà àìṣòdodo, èmi yóò nawọ́ mi jáde sí wọn, láti gé ìpèsè oúnjẹ wọn, èmi yóò rán ìyàn sí wọn, èmi yóò sì pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀,
14 andũ aya atatũ, Nuhu, na Danieli, na Ayubu, o na mangĩkorwo maarĩ thĩinĩ wa bũrũri ũcio, no mehonokirie o oiki nĩ ũndũ wa ũthingu wao, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.
bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí. Noa, Daniẹli àti Jobu tilẹ̀ wà nínú rẹ, kìkì ẹ̀mí ara wọn nìkan ni wọ́n lé fi òdodo wọn gbàlà, Olúwa Olódùmarè wí.
15 “Ningĩ korwo ndarekereria nyamũ cia gĩthaka igerere bũrũri ũcio nacio ciũtige ũtarĩ ciana, naguo ũkire ihooru kwage mũndũ ũngĩtuĩkanĩria kuo nĩ ũndũ wa nyamũ icio,
“Tàbí bí mo bá jẹ́ kí ẹranko búburú gba orílẹ̀-èdè náà kọjá, tí wọn sì bà á jẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí ó di ahoro, tí kò sí ẹni tó le gba ibẹ̀ kọjá torí ẹranko búburú yìí,
16 Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ, ti-itherũ o ta ũrĩa niĩ ndũũraga muoyo, o na andũ acio atatũ mangĩgakorwo marĩ kuo, matikahota kũhonokia ariũ ao kana aarĩ ao. O oiki no mahonoke, no bũrũri ũcio no ũkire ihooru.
bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta wọ̀nyí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, wọn kì yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là: àwọn nìkan ni a ó gbàlà, ṣùgbọ́n ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
17 “O na kana ingĩrehithia rũhiũ rwa njora njũkĩrĩre bũrũri ũcio, njuge atĩrĩ, ‘Rũhiũ rwa njora nĩrũtuĩkanĩrie bũrũri ũyũ wothe,’ na njũrage andũ akuo na mahiũ mao-rĩ,
“Tàbí tí mo bá mú idà kọjá láàrín orílẹ̀-èdè náà tí mo wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí idà kọjá láàrín ilẹ̀ náà,’ tí mo sì tú ìbínú gbígbóná lé wọn lórí nípa ìtàjẹ̀ sílẹ̀, tí mo pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ.
18 Mwathani Jehova oigĩte atĩrĩ, ti-itherũ o ta ũrĩa niĩ ndũũraga muoyo, o na andũ acio atatũ mangĩgakorwo marĩ kuo, matikahota kũhonokia ariũ ao kana aarĩ ao. O oiki no-o mangĩhonokio.
Bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà, wọn ki yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là, ṣùgbọ́n àwọn tìkára wọn nìkan ni a ó gbàlà.
19 “O na ningĩ korwo ndarehithia mũthiro bũrũri ũcio, na niĩ ndĩũitĩrĩrie mangʼũrĩ makwa na ũndũ wa gũitithia thakame, na njũragithie andũ akuo na mahiũ mao,
“Tàbí bí mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn si ilẹ̀ náà, ti mo si da ìrunú mi lé e lórí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀, láti gé ènìyàn àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀,
20 Mwathani Jehova oigĩte atĩrĩ, ti-itherũ o ta ũrĩa niĩ ndũũraga muoyo, o na Nuhu, na Danieli, na Ayubu, mangĩgakorwo marĩ kuo, matikahonokia mũriũ kana mwarĩ. O oiki no mehonokie nĩ ũndũ wa ũthingu wao.
bó tilẹ̀ jẹ́ pé Noa, Daniẹli àti Jobu wà nínú rẹ, bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, wọn kò le gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin wọn lá. Ara wọn nìkan ni ìwà òdodo wọn lè gbàlà.
21 “Nĩgũkorwo Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ: Gũtigagĩkorwo kũrĩ kũũru makĩria hĩndĩ ĩrĩa ngaarehera Jerusalemu matuĩro makwa mana ma ciira ma kũguoyohithia: namo nĩmo rũhiũ rwa njora, na ngʼaragu, na nyamũ cia gĩthaka, o na mũthiro, nĩguo njũrage andũ akuo na mahiũ mao!
“Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, báwo ni yóò ti burú tó nígbà tí mo bá rán ìdájọ́ kíkan mi mẹ́rin sórí Jerusalẹmu, èyí ni idà àti ìyàn, ẹranko búburú àti àjàkálẹ̀-ààrùn láti pa àwọn ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀!
22 No rĩrĩ, kũrĩ amwe magaatigara; nao nĩo ariũ na aarĩ arĩa magaatharwo marutwo kuo. Nĩmagooka kũrĩ inyuĩ, na rĩrĩa mũkoona mĩtugo na ciĩko ciao, nĩmũkahoorerio ngoro igũrũ rĩa mwanangĩko ũcio ndeheire Jerusalemu, naguo nĩ mwanangĩko o wothe ndĩrĩrehithĩirie.
Síbẹ̀, yóò ṣẹ́kù àwọn díẹ̀, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin tí a ó kó jáde nínú rẹ̀. Wọn yóò wá bá yin, ẹ̀yin yóò rí ìwà àti ìṣe wọn, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìtùnú nípa àjálù tí mo mú wá sórí Jerusalẹmu—àní gbogbo àjálù ní mo ti mú wá sórí rẹ̀.
23 Nĩmũkahoorerio ngoro rĩrĩa mũkoona mĩtugo yao na ciĩko ciao, nĩgũkorwo nĩmũkamenya atĩ gũtirĩ ũndũ o na ũmwe njĩkĩte kuo ũtarĩ na gĩtũmi, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.”
Nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìwà àti ìṣe wọn, a ó tù yín nínú, nítorí pé ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi kò ṣe nǹkan kan láìnídìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.”