< Thaama 7 >

1 Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “We ngũtuĩte ta Ngai harĩ Firaũni, nake mũrũ wa nyũkwa Harũni egũtuĩka mũnabii waku.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Wò ó, Èmi ti ṣe ọ bí Ọlọ́run fún Farao, Aaroni arákùnrin rẹ ni yóò jẹ́ agbẹnusọ rẹ.
2 Wee ũriugaga ũrĩa wothe ndĩgwathaga, nake mũrũ wa nyũkwa Harũni nĩwe ũrĩĩraga Firaũni arekererie andũ a Isiraeli moime bũrũri wake.
Ìwọ yóò sì sọ ohun gbogbo tí Èmi ti pàṣẹ fún ọ, Aaroni arákùnrin rẹ yóò sísọ fún Farao kí ó jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ rẹ̀.
3 No nĩngũtũma ngoro ya Firaũni yũme, na o na ndaingĩhia ciama ciakwa na morirũ gũkũ bũrũri wa Misiri-rĩ,
Ṣùgbọ́n èmi yóò sé Farao lọ́kàn le. Bí Mo tilẹ̀ ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àmì àti ìyanu ni Ejibiti,
4 ndakamũigua. Ningĩ nĩngatambũrũkia guoko gwakwa kũu bũrũri wa Misiri, na ndute ikundi cia andũ akwa a Isiraeli moime kuo na ũndũ wa ciĩko nene cia ũtuanĩri ciira.
síbẹ̀ òun kì yóò fi etí sí ọ. Nígbà náà ni Èmi yóò gbé ọwọ́ mi lé Ejibiti, pẹ̀lú agbára ìdájọ́ ńlá mi ni èmi yóò mú àwọn ènìyàn mi Israẹli jáde ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́.
5 Nao andũ a Misiri nĩmakamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova, rĩrĩa ngataambũrũkia guoko gwakwa njũkĩrĩre bũrũri wa Misiri na ndute andũ a Isiraeli moime kuo.”
Àwọn ará Ejibiti yóò sì mọ̀ pé Èmi ni Olúwa ní ìgbà tí mo bá na ọwọ́ mi jáde lé Ejibiti, tí mo sì mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò níbẹ̀.”
6 Musa na Harũni magĩĩka o ũrĩa Jehova aamaathĩte meke.
Mose àti Aaroni sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn.
7 Musa aarĩ na mĩaka mĩrongo ĩnana nake Harũni mĩaka mĩrongo ĩnana na ĩtatũ hĩndĩ ĩrĩa maaragia na Firaũni.
Mose jẹ́ ọmọ ọgọ́rin ọdún Aaroni sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́tàlélọ́gọ́rin ni ìgbà tí wọ́n bá Farao sọ̀rọ̀.
8 Jehova akĩĩra Musa na Harũni atĩrĩ,
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni,
9 “Rĩrĩa Firaũni arĩmwĩra atĩrĩ, ‘Ringai kĩama,’ nawe Musa wĩre Harũni atĩrĩ, ‘Oya rũthanju rwaku, ũrũikie thĩ o hau mbere ya Firaũni,’ naruo rũtuĩke nyoka.”
“Ní ìgbà tí Farao bá sọ fún un yín pé, ‘Ẹ ṣe iṣẹ́ ìyanu kan,’ sọ fún Aaroni ní ìgbà náà pé, ‘Mú ọ̀pá rẹ kí ó sì sọ ọ́ sílẹ̀ níwájú Farao,’ yóò sì di ejò.”
10 Nĩ ũndũ ũcio Musa na Harũni magĩthiĩ kũrĩ Firaũni, nao magĩĩka o ta ũrĩa maathĩtwo nĩ Jehova. Harũni agĩikia rũthanju rwake thĩ mbere ya Firaũni na anene ake, naruo rũgĩtuĩka nyoka.
Nígbà náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, wọ́n sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn, Aaroni ju ọ̀pá rẹ̀ sílẹ̀ ní iwájú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀, ọ̀pá náà sì di ejò.
11 Nake Firaũni agĩĩta andũ arĩa oogĩ o na ago, na aringi ciama a Misiri, nao magĩĩka o ũguo magĩtũmĩra maũgĩ mao ma ũgo.
Farao sì pe àwọn amòye, àwọn oṣó àti àwọn onídán ilẹ̀ Ejibiti jọ, wọ́n sì fi idán wọn ṣe ohun tí Mose àti Aaroni ṣe.
12 O mũndũ agĩikia rũthanju rwake thĩ na rũgĩtuĩka nyoka. No rũthanju rwa Harũni rũkĩmeria thanju ciao.
Ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn sọ ọ̀pá rẹ̀ sílẹ̀, ọ̀pá náà sì di ejò. Ṣùgbọ́n ọ̀pá Aaroni gbé ọ̀pá tiwọn mì.
13 No rĩrĩ, ngoro ya Firaũni ĩkĩũma nake akĩrega kũmaigua, o ta ũrĩa Jehova oigĩte.
Síbẹ̀ ọkàn Farao sì yigbì, kò si fetí sí wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
14 Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Ngoro ya Firaũni ndĩngĩororoa; nĩaregete kũrekereria andũ mathiĩ.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Ọkàn Farao ti di líle, ó kọ̀ láti jẹ́ kí àwọn ènìyàn náà ó lọ.
15 Nĩũgathiĩ kũrĩ Firaũni rũciinĩ agĩthiĩ rũũĩ. Weterere mũcemanie nake hũgũrũrũ-inĩ cia Rũũĩ rwa Nili, na ũthiĩ na rũthanju rũrĩa rwagarũrũkĩte rũgatuĩka nyoka.
Tọ Farao lọ ni òwúrọ̀ kùtùkùtù bí ó ti ń lọ sí etí odò, dúró ni etí bèbè odò Naili láti pàdé rẹ, mú ọ̀pá rẹ tí ó di ejò ni ọwọ́ rẹ.
16 Ũcooke ũmwĩre atĩrĩ, ‘Jehova, o we Ngai wa Ahibirania, nĩandũmĩte ngwĩre ũũ: Rekereria andũ akwa mathiĩ nĩgeetha makandungatĩre marĩ werũ-inĩ. No nginya rĩu nĩũregete gũthikĩrĩria.
Sọ fún un pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu rán mi sí ọ láti sọ fún ọ pé, Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó lè sìn mi ni aginjù. Ṣùgbọ́n títí di àkókò yìí, ìwọ kò gba.
17 Jehova ekuuga atĩrĩ: Ũndũ ũyũ nĩguo ũgũtũma ũmenye atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova: Ngũgũtha maaĩ ma Rũũĩ rwa Nili na rũthanju rũrũ rũrĩ guoko-inĩ gwakwa, namo magarũrũke matuĩke thakame.
Èyí ni Olúwa wí, nípa èyí ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa. Wò ó, èmi yóò fi ọ̀pá ti ó wà ní ọwọ́ mi, èmi yóò ná omi tí ó wà nínú odò Naili yóò sì di ẹ̀jẹ̀.
18 Thamaki iria irĩ thĩinĩ wa Rũũĩ rwa Nili nĩigũkua, naruo rũũĩ rũnunge; andũ a Misiri maremwo nĩ kũnyua maaĩ maruo.’”
Àwọn ẹja tí ó wà nínú odò Naili yóò kú, odò náà yóò sì máa rùn, àwọn ará Ejibiti kò sì ni lè mu omi rẹ̀.’”
19 Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Ĩra Harũni atĩrĩ, ‘Oya rũthanju rwaku na ũtambũrũkie guoko igũrũ rĩa maaĩ ma bũrũri wa Misiri, na igũrũ rĩa tũrũũĩ, na mĩtaro, na tũmaria o na kũrĩa guothe kũhingĩrĩrie maaĩ nakuo guothe gũtuĩke thakame. Thakame ĩkaiyũra kũndũ guothe bũrũri wa Misiri, o na kũu ndoo-inĩ cia mĩtĩ na mĩtũngi-inĩ ya mahiga.’”
Olúwa sọ fún Mose, “Sọ fún Aaroni, ‘Mú ọ̀pá rẹ kí ó sì na ọwọ́ rẹ jáde lórí àwọn omi Ejibiti. Lórí àwọn odò kéékèèké àti odò ńlá, lórí àbàtà àti adágún omi, wọn yóò sì di ẹ̀jẹ̀.’ Ẹ̀jẹ̀ yóò wà ni ibi gbogbo ni Ejibiti, àní nínú ọpọ́n àti nínú kete omi àti nínú ìkòkò tí a pọn omi sí nínú ilé.”
20 Musa na Harũni magĩĩka o ũrĩa Jehova aathanĩte. Agĩkĩambararia rũthanju rwake arĩ mbere ya Firaũni na anene ake, nake akĩgũtha maaĩ ma Rũũĩ rwa Nili, namo maaĩ mothe makĩgarũrũka magĩtuĩka thakame.
Mose àti Aaroni sí ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn. Ó gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè ni iwájú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀, ó sì lu omi odò Naili, omi odò náà sì yípadà sí ẹ̀jẹ̀.
21 Thamaki iria ciarĩ Rũũĩ rwa Nili igĩkua, naruo rũũĩ rũkĩnunga ũũru mũno, nginya andũ a bũrũri wa Misiri makĩremwo nĩ kũnyua maaĩ maruo. Bũrũri wa Misiri wothe ũkĩiyũra thakame.
Ẹja inú odò Naili sì kú, odò náà ń rùn gidigidi tí ó fi jẹ́ pé àwọn ará Ejibiti kò le è mu omi inú rẹ̀. Ẹ̀jẹ̀ sì wà ni ibi gbogbo ni ilẹ̀ Ejibiti.
22 No aringi ciama a bũrũri wa Misiri magĩĩka maũndũ o ta macio na ũndũ wa maũgĩ mao ma ũgo, nayo ngoro ya Firaũni ĩkĩũma; akĩrega kũigua Musa na Harũni, o ta ũrĩa Jehova oigĩte.
Ṣùgbọ́n àwọn apidán ilẹ̀ Ejibiti sì ṣe bákan náà pẹ̀lú agbára òkùnkùn wọn, ọkàn Farao sì yigbì síbẹ̀ kò sì fetí sí wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
23 Handũ ha kũigua-rĩ, akĩhũndũka agĩthiĩ nyũmba-inĩ yake ya ũthamaki, na ndaigana kũrũmbũiya ũhoro ũcio ngoro-inĩ yake.
Dípò bẹ́ẹ̀, ó yíjú padà, ó sì lọ sí ààfin rẹ̀, kò sì jẹ́ kí àwọn nǹkan wọ̀nyí wà ni oókan àyà rẹ̀.
24 Nao andũ othe a Misiri makĩenja ithima gũkuhĩ na Rũũĩ rwa Nili nĩguo mone maaĩ ma kũnyua, tondũ matingĩahotire kũnyua maaĩ ma rũũĩ rũu.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn ará Ejibiti bẹ̀rẹ̀ sí í gbẹ́ etí odò Naili láti wá omi tí wọn yóò mu, nítorí wọn kò le è mu omi tí ó wà nínú odò náà.
25 Mĩthenya mũgwanja nĩyahĩtũkire thuutha wa Jehova kũgũtha maaĩ ma Nili.
Ọjọ́ méje sì kọjá ti Olúwa ti lu odò Naili.

< Thaama 7 >