< Thaama 34 >

1 Nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Icũhia ihengere igĩrĩ cia mahiga o ta iria cia mbere, na nĩngũciandĩka ciugo iria ciaandĩkĩtwo ihengere-inĩ iria cia mbere, iria woragire.
Olúwa sọ fún Mose pé, “E gé òkúta wàláà méjì jáde bí i ti àkọ́kọ́, Èmi yóò sì kọ àwọn ọ̀rọ̀ ìwé tó wà lára tí àkọ́kọ́ tí ìwọ ti fọ́ sára wọn.
2 Wĩhaarĩrie rũciinĩ, ũcooke wambate kĩrĩma gĩa Sinai. Ũrũgame mbere yakwa hau kĩrĩma igũrũ.
Múra ní òwúrọ̀, kí o sì wá sórí òkè Sinai. Kí o fi ara rẹ hàn mí lórí òkè náà.
3 Gũtikagĩe mũndũ ũkwambatania hamwe nawe kana onekane handũ o hothe kũu kĩrĩma-inĩ; o na gũtikagĩe ndũũru cia mbũri kana cia ngʼombe ingĩrĩithio kũu mbere ya kĩrĩma.”
Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá pẹ̀lú rẹ tàbí kí a rí wọn lórí òkè náà; bẹ́ẹ̀ ni agbo àgùntàn tàbí ọwọ́ ẹran kó má ṣe jẹ níwájú òkè náà.”
4 Nĩ ũndũ ũcio Musa agĩicũhia ihengere igĩrĩ cia mahiga o ta iria cia mbere na akĩroka kwambata kĩrĩma gĩa Sinai rũciinĩ tene, o ta ũrĩa Jehova aamwathĩte; agĩthiĩ akuuĩte ihengere icio igĩrĩ na moko.
Bẹ́ẹ̀ Mose sì gbẹ́ òkúta wàláà méjì bí ti àkọ́kọ́, ó sì gun orí òkè Sinai lọ ní kùtùkùtù òwúrọ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un; Ó sì gbé òkúta wàláà méjèèjì náà sí ọwọ́ rẹ̀.
5 Nake Jehova agĩikũrũka arĩ itu-inĩ, akĩrũgama hau harĩ we, na akĩanĩrĩra rĩĩtwa rĩake, Jehova.
Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọsánmọ̀, ó sì dúró níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì pòkìkí orúkọ Olúwa.
6 Agĩkĩhĩtũkĩra mbere ya Musa akĩanagĩrĩra akoiga atĩrĩ, “Jehova, Jehova, Ngai ũrĩa mũcaayanĩri na mũtugi, ũtahiũhaga kũrakara, ũiyũrĩtwo nĩ wendani na wĩhokeku,
Ó sì kọjá níwájú Mose, ó sì ń ké pé, “Olúwa, Olúwa, Ọlọ́run aláàánú àti olóore-ọ̀fẹ́, Ẹni tí ó lọ́ra láti bínú, tí ó pọ̀ ní ìfẹ́ àti olóòtítọ́,
7 ũtũũragia wendani kũrĩ andũ ngiri na ngiri, na akohanagĩra waganu, na ũremi, o na mehia. No rĩrĩ, ndaagaga kũherithia arĩa mehĩtie; nĩaherithagia ciana na ciana ciacio nĩ ũndũ wa mehia ma maithe mao, nginya rũciaro rwa gatatũ na rwa kana.”
Ẹni tí ó ń pa ìfẹ́ mọ́ fún ẹgbẹ̀rún, ó sì ń dáríjì àwọn ẹni búburú, àwọn ti ń ṣọ̀tẹ̀ àti ẹlẹ́ṣẹ̀. Síbẹ̀ kì í fi àwọn ẹlẹ́bi sílẹ̀ láìjìyà; Ó ń fi ìyà jẹ ọmọ àti àwọn ọmọ wọn fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba dé ìran kẹta àti ẹ̀kẹrin.”
8 Musa agĩkĩinamĩrĩra thĩ o rĩmwe, akĩhooya.
Mose foríbalẹ̀ lẹ́ẹ̀kan náà ó sì sìn.
9 Akiuga atĩrĩ, “Wee Mwathani, angĩkorwo nĩnjĩtĩkĩrĩkĩte maitho-inĩ maku, ndagũthaitha Mwathani twarana na ithuĩ. O na gũtuĩka aya nĩ andũ momĩtie ngingo-rĩ, tuohere waganu witũ o na mehia maitũ, na ũtũme tũtuĩke igai rĩaku.”
Ó wí pé, “Olúwa, bí èmi bá rí ojúrere rẹ, nígbà náà jẹ́ kí Olúwa lọ pẹ̀lú wa. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, ènìyàn ọlọ́rùn líle ni wọn, dárí búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wa jì, kí o sì gbà wá gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ.”
10 Ningĩ Jehova akiuga atĩrĩ, “Nĩngũgĩa na kĩrĩkanĩro nawe. Nĩndĩrĩĩkaga morirũ matarĩ mekwo rũrĩrĩ-inĩ o na rũrĩkũ thĩinĩ wa thĩ yothe mbere ya andũ aya aku othe. Andũ arĩa mũtũũranagia nao nĩmakeyonera ũrĩa niĩ, Jehova, ngeeka ũndũ wa kũmakania nĩ ũndũ waku.
Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Èmi dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú yín. Níwájú gbogbo ènìyàn rẹ Èmi yóò ṣe ìyanu, tí a kò tí ì ṣe ní orílẹ̀-èdè ní gbogbo ayé rí. Àwọn ènìyàn tí ìwọ ń gbé láàrín wọn yóò rí i bí iṣẹ́ tí Èmi Olúwa yóò ṣe fún ọ ti ní ẹ̀rù tó.
11 Athĩkĩra ũrĩa ngũgwatha ũmũthĩ. Nĩngarutũrũra Aamori, na Akaanani, na Ahiti, na Aperizi, na Ahivi na Ajebusi mbere yaku makweherere.
Ṣe ohun tí Èmi pàṣẹ fún ọ lónìí. Èmi lé àwọn ará Amori, àwọn ará Kenaani, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hiti, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi jáde níwájú rẹ.
12 Wĩmenyerere ndũkagĩe kĩrĩĩko na andũ arĩa matũũraga bũrũri-inĩ ũcio ũrathiĩ, matigatuĩke mũtego harĩwe.
Máa ṣọ́ra kí o má ba à bá àwọn ti ó n gbé ilẹ̀ náà tí ìwọ ń lọ dá májẹ̀mú, nítorí wọn yóò jẹ́ ìdẹwò láàrín rẹ.
13 Nĩmũkoinanga igongona ciao, na mũthethere mahiga mao maamũre, na mũtemange itugĩ ciao cia Ashera.
Wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, fọ́ òkúta mímọ́ wọn, kí o sì gé òpó Aṣerah wọn. (Ère òrìṣà wọn.)
14 Mũtikanahooe ngai ĩngĩ o na ĩrĩkũ, nĩgũkorwo Jehova, ũrĩa rĩĩtwa rĩake arĩ Mũigua Ũiru, nĩ Ngai ũrĩ ũiru.
Ẹ má ṣe sin ọlọ́run mìíràn, nítorí Olúwa, orúkọ ẹni ti ń jẹ́ Òjòwú, Ọlọ́run owú ni.
15 “Mwĩmenyererei mũtikagĩe kĩrĩĩko na andũ arĩa matũũraga bũrũri-inĩ ũcio; nĩgũkorwo rĩrĩa maahũũra ũmaraya na ngai ciao na magacirutĩra iruta, nĩmarĩmwĩtaga, na inyuĩ nĩmũrĩrĩĩaga indo cia magongona macio mao.
“Máa ṣọ́ra kí ẹ má ṣe bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ilẹ̀ náà dá májẹ̀mú; nígbà tí wọ́n bá ń ṣe àgbèrè tọ òrìṣà wọn, tí wọ́n sì rú ẹbọ sí wọn, wọn yóò pè yín, ẹ̀yin yóò sì jẹ ẹbọ wọn.
16 Na rĩrĩa mũngĩthuura airĩtu amwe ao matuĩke atumia a aanake anyu, nao airĩtu acio mahũũre ũmaraya na ngai ciao, nĩmakonereria ariũ anyu gwĩka ũguo.
Nígbà tí ìwọ bá yàn nínú àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin rẹ ní ìyàwó, àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí yóò ṣe àgbèrè tọ òrìṣà wọn, wọn yóò sì mú kí àwọn ọmọkùnrin yín náà ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
17 “Ndũkanathondeke mĩhianano ya gũtwekio.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ dá ère òrìṣàkórìṣà fún ara rẹ.
18 “Kũngũyagĩra Gĩathĩ kĩa Mĩgate ĩtarĩ mĩĩkĩre ndawa ya kũimbia. Handũ-inĩ ha mĩthenya mũgwanja, rĩĩagai mĩgate ĩtarĩ mĩĩkĩre ndawa ya kũimbia, o ta ũrĩa ndaamwathire. Ĩkagai ũndũ ũyũ ihinda rĩaguo rĩakinya mweri-inĩ wa Abibu, nĩgũkorwo nĩguo mweri ũrĩa mwoimire bũrũri wa Misiri.
“Àjọ àkàrà àìwú ni kí ìwọ máa pamọ́. Fún ọjọ́ méje ni ìwọ yóò jẹ àkàrà aláìwú, gẹ́gẹ́ bí Èmi ti pa á láṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní ìgbà tí a yàn nínú oṣù Abibu, nítorí ní oṣù náà ni ẹ jáde láti Ejibiti wá.
19 “Irigithathi rĩa nda o yothe nĩ rĩakwa, hamwe na marigithathi mothe ma njamba ma mahiũ manyu, marĩ ma kuuma ndũũru-inĩ cia ngʼombe kana cia mbũri.
“Gbogbo àkọ́bí inú kọ̀ọ̀kan tèmi ní i ṣe, pẹ̀lú àkọ́bí gbogbo ohun ọ̀sìn rẹ, bóyá ti màlúù tàbí ti àgùntàn.
20 Irigithathi rĩa ndigiri ũrĩrĩkũũraga na gatũrũme, no ũngĩaga kũrĩkũũra, riune ngingo. Nao ariũ aku a marigithathi ũmakũũrage. “Gũtikanagĩe mũndũ o na ũmwe ũrĩũkaga mbere yakwa moko matheri.
Àkọ́bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ni kí ìwọ kí ó fi ọ̀dọ́-àgùntàn rà padà, ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá rà á padà, dá ọrùn rẹ̀. Ra gbogbo àkọ́bí ọkùnrin rẹ padà. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá síwájú mi ní ọwọ́ òfo.
21 “Rutaga wĩra mĩthenya ĩtandatũ, no mũthenya wa mũgwanja ũhurũkage; o na hĩndĩ ya icimba na ya magetha no nginya ũhurũke.
“Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ keje ìwọ yóò sinmi; kódà ní àkókò ìfúnrúgbìn àti ní àkókò ìkórè ìwọ gbọdọ̀ sinmi.
22 “Kũngũyagĩra Gĩathĩ-gĩa-Ciumia, na maciaro ma mbere ma magetha ma ngano, na Gĩathĩ-gĩa-Gũcookereria irio makũmbĩ-inĩ mũthia-inĩ wa mwaka.
“Ṣe àjọ ọ̀sẹ̀ pẹ̀lú àkọ́so èso alikama àti àjọ ìkórè ní òpin ọdún.
23 Arũme anyu othe no nginya mokage mbere ya Mwathani Jehova, o we Ngai wa Isiraeli, maita matatũ o mwaka.
Ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lọ́dún, gbogbo àwọn ọkùnrin ni kí ó farahàn níwájú Olúwa Olódùmarè, Ọlọ́run Israẹli.
24 Nĩngarutũrũra ndũrĩrĩ imweherere, na nĩnganenehia mĩhaka ya bũrũri wanyu na gũtirĩ mũndũ ũgaacumĩkĩra bũrũri wanyu rĩrĩa mũrĩkoragwo mũkĩambata maita matatũ o mwaka mbere ya Jehova Ngai wanyu.
Èmi yóò lé orílẹ̀-èdè jáde níwájú rẹ, Èmi yóò sì mú kí ìpín rẹ fẹ̀, ẹnikẹ́ni kì yóò gba ilẹ̀ rẹ nígbà tí ìwọ bá gòkè lọ ní ìgbà mẹ́ta lọ́dún kọ̀ọ̀kan láti farahàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
25 “Ndũkanandutĩre thakame ya igongona ĩtukanĩte na kĩndũ gĩĩkĩre ndawa ya kũimbia, na mũtikanareke kĩndũ kĩa igongona rĩa Bathaka kĩraare nginya rũciinĩ.
“Má ṣe ta ẹ̀jẹ̀ ẹbọ sí mi pẹ̀lú ohunkóhun tí ó bá ní ìwúkàrà, kí o má sì ṣe jẹ́ kí ẹbọ ìrékọjá kù títí di òwúrọ̀.
26 “Rehagai maciaro ma mbere marĩa mega mũno ma mĩgũnda yanyu, mũmarehage nyũmba ya Jehova Ngai wanyu. “Mũtikanaruge koori na iria rĩa nyina.”
“Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ. “Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.”
27 Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Andĩka ciugo ici, nĩgũkorwo kũringana na ciugo ici, nĩndagĩa na kĩrĩkanĩro nawe o na Isiraeli.”
Olúwa sì wí fún Mose pé, “Kọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sílẹ̀, nítorí nípa àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni Èmi bá ìwọ àti Israẹli dá májẹ̀mú.”
28 Musa aikarire na Jehova hau matukũ mĩrongo ĩna, mũthenya na ũtukũ, atekũrĩa irio kana akanyua maaĩ. Na agĩkĩandĩka ihengere-inĩ icio ciugo cia kĩrĩkanĩro kĩu, na nĩcio Maathani marĩa Ikũmi.
Mose wà níbẹ̀ pẹ̀lú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru láìjẹ oúnjẹ tàbí mu omi. Ó sì kọ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú náà òfin mẹ́wàá sára wàláà.
29 Rĩrĩa Musa aikũrũkire kuuma kĩrĩma gĩa Sinai arĩ na ihengere igĩrĩ cia Ũira moko-inĩ make, ndaamenyaga atĩ ũthiũ wake nĩwakengaga nĩ ũndũ nĩarĩtie na Jehova.
Nígbà tí Mose sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè Sinai pẹ̀lú wàláà ẹ̀rí méjì ní ọwọ́ rẹ̀, òun kò mọ̀ pé ojú òun ń dán nítorí ó bá Olúwa sọ̀rọ̀.
30 Rĩrĩa Harũni na andũ a Isiraeli othe moonire Musa, ũthiũ wake nĩwakengaga, nao magĩĩtigĩra kũmũkuhĩrĩria.
Nígbà tí Aaroni àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli rí Mose, ojú rẹ̀ ń dán, ẹ̀rù sì ń bà wọ́n láti súnmọ́ ọn.
31 No Musa akĩmeeta; nĩ ũndũ ũcio Harũni na atongoria othe a mũingĩ magĩcooka harĩ we, nake akĩmaarĩria.
Ṣùgbọ́n Mose pè wọn; Aaroni àti gbogbo àwọn olórí àjọ padà wá bá a, ó sì bá wọn sọ̀rọ̀.
32 Thuutha ũcio andũ a Isiraeli othe makĩmũkuhĩrĩria, nake akĩmahe mawatho mothe marĩa Jehova amũheete kũu Kĩrĩma-inĩ gĩa Sinai.
Lẹ́yìn èyí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli súnmọ́ ọn, ó sì fún wọn ní gbogbo àṣẹ tí Olúwa fún un lórí òkè Sinai.
33 Rĩrĩa Musa aarĩkirie kũmaarĩria, akĩĩhumbĩra ũthiũ wake na taama wa kwĩhumbĩra ũthiũ.
Nígbà tí Mose parí ọ̀rọ̀ sísọ fún wọn. Ó fi ìbòjú bo ojú rẹ̀.
34 No rĩrĩa rĩothe aatoonyaga harĩ Jehova maranĩrie, nĩarutaga taama ũcio wa kwĩhumbĩra ũthiũ nginya oime ho. Na rĩrĩa oka kũrĩ andũ a Isiraeli na aameera ũrĩa aathĩtwo,
Ṣùgbọ́n nígbàkígbà tí Mose bá wà níwájú Olúwa láti bá a sọ̀rọ̀, á ṣí ìbòjú náà títí yóò fi jáde. Nígbà tí ó bá sì jáde, á sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli ohun tí a ti pàṣẹ fún un,
35 makona ũthiũ wake o ũkengete. Nake Musa agacookia taama ũcio wa kwĩhumbĩra ũthiũ nginya rĩrĩa rĩngĩ agaathiĩ kwaria na Jehova.
àwọn ọmọ Israẹli sì rí i pé ojú rẹ̀ ń dán. Mose á sì tún fi ìbòjú bo ojú rẹ̀ títí á fi lọ bá Olúwa sọ̀rọ̀.

< Thaama 34 >