< Thaama 31 >

1 Nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
Olúwa wí fún Mose pé,
2 “Ta rora wone, nĩthuurĩte Bezaleli mũrũ wa Uri ũrĩa mũriũ wa Huri wa mũhĩrĩga wa Juda,
“Wò ó, Èmi ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
3 na nĩndĩmũiyũrĩtie na Roho wa Ngai, na ũũgĩ na ũhoti na ũmenyo mawĩra-inĩ ma mĩthemba yothe ya moko;
Èmi sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
4 ya gũcora mĩcoro ya ũũgĩ indo-inĩ cia thahabu, na betha na gĩcango, na
Láti ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ,
5 gwacũhia tũhiga twa goro twa gũthecererwo indo-inĩ, na kũruta wĩra wa gũkaaya mbaũ, na kũruta mawĩra ma mĩthemba yothe ya ũbundi.
láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
6 O na rĩrĩ, nĩthuurĩte Oholiabu mũrũ wa Ahisamaku, wa mũhĩrĩga wa Dani, nĩguo ateithagie Bezaleli wĩra. Ningĩ nĩheete mabundi mothe ũũgĩ wa gũthondeka indo ciothe iria ngwathĩte:
Síwájú sí i, èmi ti yan Oholiabu ọmọ Ahisamaki, ti ẹ̀yà Dani, láti ràn án lọ́wọ́. “Bákan náà, Èmi ti fi ọgbọ́n fún gbogbo àwọn oníṣẹ́-ọnà láti ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún ọ:
7 nacio nĩ Hema-ya-Gũtũnganwo, na ithandũkũ rĩa Ũira, na gĩtĩ gĩa tha kĩrĩa kĩrĩ igũrũ rĩarĩo, na indo iria ingĩ ciothe cia hema,
“àgọ́ àjọ náà, àpótí ẹ̀rí pẹ̀lú ìtẹ́ àánú tí ó wà lórí rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò àgọ́ náà,
8 nacio nĩ metha na indo ciayo, na mũtĩ wa thahabu therie wa kũigĩrĩrwo matawa na indo ciaguo ciothe, na kĩgongona gĩa gũcinĩra ũbumba, na
tábìlì àti ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà tí ó jẹ́ kìkì wúrà àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, pẹpẹ tùràrí,
9 kĩgongona kĩa iruta rĩa njino na indo ciakĩo, na kĩraĩ na kĩgũrũ gĩakĩo,
pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀,
10 o na nguo iria ndume, iria theru cia kwĩhumbwo nĩ Harũni ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai na nguo cia kwĩhumbwo nĩ ariũ ake rĩrĩa megũtungata marĩ athĩnjĩri-Ngai,
àti aṣọ híhun pẹ̀lú, papọ̀ pẹ̀lú aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ bí àlùfáà,
11 na maguta ma gũitanĩrĩrio, na ũbumba mũnungi wega wa Handũ-harĩa-Hatheru. Mathondeke indo icio o ta ũrĩa ngwathĩte.”
òróró ìtasórí àti tùràrí olóòórùn dídùn fún Ibi Mímọ́. “Kí wọ́n ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ.”
12 Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
Olúwa wí fún Mose pé,
13 “Ĩra andũ a Isiraeli ũũ: ‘No nginya mũrũmagie Thabatũ ciakwa. Rũrũ nĩruo rũgatuĩka rũũri gatagatĩ gakwa na inyuĩ njiarwa iria igooka, nĩguo mũmenye atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova ũrĩa ũmũtheragia.
“Kí ìwọ kí ó sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ máa pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́. Èyí ni yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti ẹ̀yin fún ìrandíran tó ń bọ̀, nítorí kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa, ẹni tí ó yà yín sí mímọ́.
14 “‘Menyagĩrĩrai Thabatũ tondũ nĩ mũthenya mũtheru harĩ inyuĩ. Mũndũ ũngĩũthaahia no nginya ooragwo; mũndũ ũngĩruta wĩra mũthenya ũcio nĩakaingatwo kuuma kũrĩ andũ ao.
“‘Nítorí náà, kí ẹ̀yin kí ó máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, nítorí mímọ́ ni fún un yín. Ẹnikẹ́ni tí ó bá bà á jẹ́, ni a yóò pa; ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà ni a yóò gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ.
15 Wĩra nĩũrutagwo mĩthenya ĩtandatũ, no mũthenya wa mũgwanja nĩ Thabatũ theru ya Jehova ya andũ kũhurũka. Ũrĩa wothe ũkaaruta wĩra mũthenya wa Thabatũ no nginya ooragwo.
Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ní ọjọ́ ìsinmi tí ẹ̀yin yóò fi sinmi, mímọ́ ni fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ni a ó pa nítòótọ́.
16 andũ a Isiraeli nĩmathĩkagĩre Thabatũ, mamĩkũngũyagĩre ĩtuĩke kĩrĩkanĩro gĩa gũtũũra njiarwa iria igooka.
Nítorí náà ni àwọn ọmọ Israẹli yóò ṣe máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, ẹ máa ṣe àkíyèsí rẹ̀ dé ìrandíran tó ń bọ̀ bí i májẹ̀mú títí láé.
17 Rũrũ nĩruo rũgaatuĩka rũũri gatagatĩ gakwa na andũ a Isiraeli nginya tene, nĩgũkorwo Jehova ombire igũrũ na thĩ na mĩthenya ĩtandatũ na mũthenya wa mũgwanja ndaigana kũruta wĩra, akĩhurũka.’”
Yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti àwọn ọmọ Israẹli títí láé, nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, àti ní ọjọ́ keje ni ó fi iṣẹ́ sílẹ̀, ó sì sinmi.’”
18 Rĩrĩa Jehova aarĩkirie kwaria na Musa kũu igũrũ rĩa Kĩrĩma gĩa Sinai, akĩmũnengera ihengere icio igĩrĩ cia Ũira, o ihengere icio cia mahiga, o icio ciandĩkĩtwo na kĩara kĩa Ngai.
Nígbà tí Olúwa parí ọ̀rọ̀ sísọ fún Mose lórí òkè Sinai, ó fún un ní òkúta wàláà ẹ̀rí méjì, òkúta wàláà òkúta tí a fi ìka Ọlọ́run kọ.

< Thaama 31 >